< Job 30 >
1 “Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, àwọn tí mo gbà ní àbúrò ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà baba ẹni tí èmi kẹ́gàn láti tò pẹ̀lú àwọn ajá nínú agbo ẹran mi.
Nu derimod ler de ad mig, Folk, der er yngre end jeg, hvis Fædre jeg fandt for ringe at sætte iblandt mine Hyrdehunde.
2 Kí ni ìwúlò agbára ọwọ́ wọn sí mi, níwọ̀n ìgbà tí agbára wọn ti fi wọ́n sílẹ̀?
Og hvad skulde jeg med deres Hænders Kraft? Deres Ungdomskraft har de mistet,
3 Wọ́n rù nítorí àìní àti ìyàn wọ́n ń rìn káàkiri ní ilẹ̀ gbígbẹ ní ibi ìkọ̀sílẹ̀ ní òru.
tørrede hen af Trang og Sult. De afgnaver Ørk og Ødemark
4 Àwọn ẹni tí ń já ewé iyọ̀ ní ẹ̀bá igbó; gbogbo igikígi ni oúnjẹ jíjẹ wọn.
og plukker Melde ved Krattet, Gyvelrødder er deres Brød.
5 A lé wọn kúrò láàrín ènìyàn, àwọn ènìyàn sì pariwo lé wọn lórí bí ẹní pariwo lé olè lórí.
Fra Samfundet drives de bort, som ad Tyve råbes der efter dem.
6 A mú wọn gbe inú pàlàpálá òkúta àfonífojì, nínú ihò ilẹ̀ àti ti òkúta.
De bor i Kløfter, fulde af Rædsler, i Jordens og Klippernes Huler.
7 Wọ́n ń dún ní àárín igbó wọ́n kó ara wọn jọ pọ̀ ní abẹ́ ẹ̀gún neteli.
De brøler imellem Buske, i Tornekrat kommer de sammen,
8 Àwọn ọmọ ẹni tí òye kò yé, àní àwọn ọmọ lásán, a sì lé wọn jáde kúrò ní orí ilẹ̀.
en dum og navnløs Æt, de joges med Hug af Lande.
9 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, àwọn ọmọ wọn ń fi mí ṣe ẹlẹ́yà nínú orin; àní èmi di ẹni ìṣọ̀rọ̀ sí láàrín wọn.
Men nu er jeg Hånsang for dem, jeg er dem et Samtaleemne;
10 Wọ́n kórìíra mi; wọ́n sá kúrò jìnnà sí mi, wọn kò sì bìkítà láti tutọ́ sí mi lójú.
de afskyr mig, holder sig fra mig, nægter sig ikke af spytte ad mig.
11 Nítorí Ọlọ́run ti tú okùn ìyè mi, ó sì pọ́n mi lójú; àwọn pẹ̀lú sì dẹ ìdẹ̀kùn níwájú mi.
Thi han løste min Buestreng, ydmyged mig, og foran mig kasted de Tøjlerne af.
12 Àwọn ènìyàn lásán dìde ní apá ọ̀tún mi; wọ́n tì ẹsẹ̀ mi kúrò, wọ́n sì la ipa ọ̀nà ìparun sílẹ̀ dè mí.
Til højre rejser sig Ynglen, Fødderne slår de fra mig, bygger sig Ulykkesveje imod mig
13 Wọ́n da ipa ọ̀nà mi rú; wọ́n sì sọ ìparun mi di púpọ̀, àwọn tí kò ní olùrànlọ́wọ́.
min Sti har de opbrudt, de hjælper med til mit Fald, og ingen hindrer dem i det;
14 Wọ́n ya sí mi bí i omi tí ó ya gbuuru; ní ariwo ńlá ni wọ́n rọ́ wá.
de kommer som gennem et gabende Murbrud, vælter sig frem under Ruiner,
15 Ẹ̀rù ńlá bà mí; wọ́n lépa ọkàn mi bí ẹ̀fúùfù, àlàáfíà mi sì kọjá lọ bí àwọ̀ sánmọ̀.
Rædsler har vendt sig imod mig; min Værdighed joges bort som af Storm, min Lykke svandt som en Sky.
16 “Àti nísinsin yìí, ayé mi n yòrò lọ díẹ̀díẹ̀; ọjọ́ ìpọ́njú mi dì mímú.
Min Sjæl opløser sig i mig; Elendigheds Dage har ramt mig:
17 Òru gún mi nínú egungun mi, èyí tí ó bù mí jẹ kò sì sinmi.
Natten borer i mine Knogler, aldrig blunder de nagende Smerter.
18 Nípa agbára ńlá rẹ̀ Ọlọ́run wà bí aṣọ ìbora fún mi, ó sì lẹ̀ mọ́ mi ní ara yíká bí aṣọ ìlekè mi.
Med vældig Kraft vanskabes mit Kød, det hænger om mig, som var det min Kjortel.
19 Ọlọ́run ti mú mi lọ sínú ẹrẹ̀, èmi sì dàbí eruku àti eérú.
Han kasted mig ud i Dynd, jeg er blevet som Støv og Aske.
20 “Èmi ké pè ọ́ ìwọ Ọlọ́run, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi lóhùn; èmi dìde dúró ìwọ sì wò mí lásán.
Jeg skriger til dig, du svarer mig ikke, du står der og ænser mig ikke;
21 Ìwọ padà di ẹni ìkà sí mi; ọwọ́ agbára rẹ ni ìwọ fi dè mí ní ọ̀nà.
grum er du blevet imod mig, forfølger mig med din vældige Hånd.
22 Ìwọ gbé mi sókè sí inú ẹ̀fúùfù, ìwọ mú mi fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ sì sọ mí di asán pátápátá.
Du løfter og vejrer mig hen i Stormen, og dens Brusen gennemryster mig;
23 Èmi sá à mọ̀ pé ìwọ yóò mú mi lọ sínú ikú, sí ilé ìpéjọ tí a yàn fún gbogbo alààyè.
thi jeg ved, du fører mig hjem til Døden, til det Hus, hvor alt levende samles.
24 “Bí ó ti wù kí ó rí, ẹnìkan kí yóò ha nawọ́ rẹ̀ nígbà ìṣubú rẹ̀, tàbí kì yóò ké nínú ìparun rẹ̀.
Dog, mon den druknende ej rækker Hånden ud og råber om Hjælp, når han går under?
25 Èmi kò ha sọkún bí fún ẹni tí ó wà nínú ìṣòro? Ọkàn mi kò ha bàjẹ́ fún tálákà bí?
Mon ikke jeg græder over den, som havde det hårdt, sørgede ikke min Sjæl for den fattiges Skyld?
26 Nígbà tí mo fojú ṣọ́nà fún àlàáfíà, ibi sì dé; nígbà tí mo dúró de ìmọ́lẹ̀, òkùnkùn sì dé.
Jeg biede på Lykke, men Ulykke kom, jeg håbed på Lys, men Mørke kom;
27 Ikùn mí n ru kò sì sinmi, ọjọ́ ìpọ́njú ti dé bá mi.
ustandseligt koger det i mig, Elendigheds Dage traf mig;
28 Èmí ń rìn kiri nínú ọ̀fọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nínú oòrùn; èmi dìde dúró ní àwùjọ mo sì kígbe fún ìrànlọ́wọ́.
trøstesløs går jeg i Sorg, i Forsamlingen rejser jeg mig og råber;
29 Èmi ti di arákùnrin ìkookò, èmi di ẹgbẹ́ àwọn ògòǹgò.
Sjakalernes Broder blev jeg, Strudsenes Fælle.
30 Àwọ̀ mi di dúdú ní ara mi; egungun mi sì jórun fún ooru.
Min Hud er sort, falder af, mine Knogler brænder af Hede;
31 Ohun èlò orin mi pẹ̀lú sì di ti ọ̀fọ̀, àti ìpè orin mi sì di ohùn àwọn tí ń sọkún.
min Citer er blevet til Sorg, min Fløjte til hulkende Gråd!