< Jeremiah 44 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá nípa àwọn Júù tí ń gbé ní ìsàlẹ̀ Ejibiti ní Migdoli, Tafanesi àti Memfisi àti ní apá òkè Ejibiti:
Riječ koja se javi Jeremiji za sve Judejce što življahu u zemlji egipatskoj, što življahu u Migdolu, u Tafnisu, u Memfisu i u zemlji Patrosu.
2 “Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Wo ibi tí mo mú bá Jerusalẹmu àti gbogbo ìlú Juda. Lónìí, wọ́n wà ní ìyapa àti ìparun.
Ovako govori Jahve nad Vojskama, Bog Izraelov: “I sami vidjeste svu nesreću koju sam svalio na Jeruzalem i na sve gradove judejske: evo danas su to gomile ruševina, a u njima nitko više ne živi,
3 Nítorí pé ibi tí wọ́n ti ṣe. Wọ́n mú mi bínú nípa tùràrí fínfín àti nípa bíbọ àwọn òrìṣà, yálà èyí tí ìwọ tàbí àwọn baba rẹ kò mọ̀.
zbog nedjela njihovih što ih učiniše da bi mene vrijeđali, polazeći drugim bogovima kojih nisu poznavali ni oni, ni vi, ni oci vaši, da im kade i da im služe.
4 Ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìgbà ní mo rán wòlíì mi, èyí tí ó wí báyìí pé, ‘Má ṣe àwọn ohun ìríra yìí tí èmi kórìíra.’
A ja sam vam jednako slao svoje sluge proroke da vam kažu: 'Ne činite tih gnusoba koje su mi ogavne!'
5 Ṣùgbọ́n wọn kò fetísílẹ̀ láti fi ọkàn si. Wọn kò sì yípadà kúrò nínú búburú wọn tàbí dáwọ́ ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà dúró.
Ali me oni nisu slušali, niti su uho svoje priklonili da se okane zloće svoje i prestanu kaditi tuđim bogovima.
6 Fún ìdí èyí, ìbínú gbígbóná mi ni èmi yóò yọ sí àwọn ìlú Juda àti òpópó Jerusalẹmu àti sísọ wọ́n di ìparun bí ó ṣe wà lónìí yìí.
Zato se izli gnjev moj i srdžba moja i rasplamtje se u gradovima judejskim i po ulicama jeruzalemskim, te se pretvoriše u pustoš i razvaline, kao što su danas.
7 “Báyìí tún ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí, kí ló dé tí ẹ fi ń mu ibi ńlá yìí wá sí orí ara yín nípa yíyapa kúrò lára Juda ọkùnrin àti obìnrin, ọmọdé àti èwe, tí ẹ kò sì ku ọ̀kankan?
Zašto sami svaljujete na se tako golemu nesreću” - govori Jahve, Bog nad Vojskama, Bog Izraelov - “te sami do korijena istrebljujete iz Judeje sve muško i žensko, djecu i dojenčad, te vam ni ostatka ostati neće,
8 Èéṣe tí ẹ fi mú mi bínú pẹ̀lú ohun tí ọwọ́ yín ṣe pẹ̀lú ẹbọ sísun sí àwọn òrìṣà Ejibiti, níbi tí ẹ wá láti máa gbé? Ẹ̀ ò pa ara yín run, ẹ̀ ó sì sọ ara yín di ẹni ìfiré àti ẹ̀gàn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè ayé gbogbo.
jer me vrijeđate djelima ruku svojih, kadeći tuđim bogovima u zemlji egipatskoj, u koju ste došli prebivati, a bit ćete iskorijenjeni i postat ćete kletva i ruglo među svim narodima na zemlji?
9 Ṣé ẹ̀yin ti gbàgbé ibi tí àwọn baba ńlá yín àti àwọn ọba; àwọn ayaba Juda, àti àwọn ibi tí ẹ ti ṣe àti àwọn ìyàwó yín ní ilẹ̀ Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
Jeste li zaboravili bezakonja otaca svojih, bezakonja kraljeva judejskih, bezakonja knezova svojih i žena njihovih i bezakonja svoja, bezakonja žena svojih, počinjena u zemlji judejskoj i po ulicama jeruzalemskim?
10 Láti ìgbà náà sí àkókò yìí, wọn kò rẹ ara wọn sílẹ̀ tàbí fi ìtẹríba hàn tàbí kí wọn ó tẹ̀lé òfin àti àṣẹ tí mo pa fún un yín àti àwọn baba yín.
Do dana današnjega nisu se pokajali, nisu se bojali, nisu živjeli po Zakonu mojemu ni po odredbama mojim, koje dadoh vama i ocima vašim.”
11 “Fún ìdí èyí, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: Mo ti pinnu láti mú ibi wá sí orí yín àti láti pa Juda run.
Zato ovako govori Jahve nad Vojskama, Bog Izraelov: “Evo, okrećem svoje lice vama, na nesreću vašu, da zatrem svu zemlju judejsku.
12 Èmi yóò sì mú àwọn èérún tí ó kù ní Juda, tí wọ́n ṣetán láti lọ Ejibiti. Wọn yóò ṣubú pẹ̀lú idà tàbí kí wọn kú pẹ̀lú ìyàn láti orí ọmọdé títí dé àgbà ni wọn yóò kú láti ọwọ́ ìyàn tàbí idà. Wọn yóò di ẹni ìfiré àti ìparun, ẹni ẹ̀kọ̀ àti ẹni ẹ̀gàn.
Odnijet ću ostatak Judeje koji je odlučio da ide u zemlju egipatsku da se ondje stani; svi će izginuti u zemlji egipatskoj, past će od mača, od gladi će pogibati, poginut će svi, malo i veliko, pomrijet će od mača i gladi, i bit će prokletstvo, užas, kletva i poruga.
13 Èmi yóò fi ìyà jẹ ẹni tí ó bá ń gbé ní Ejibiti pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn bí mo ṣe fi ìyà jẹ Jerusalẹmu.
Kaznit ću sve koji budu u zemlji egipatskoj, kao što sam kaznio Jeruzalem: mačem, glađu i kugom.
14 Kò sí èyí tí ó kéré jù nínú Juda tí ó kù, tí ó ń gbé ilẹ̀ Ejibiti tí yóò sá àsálà padà sórí ilẹ̀ Juda, èyí tí wọ́n nífẹ̀ẹ́ láti padà sí, àti láti máa gbé; àyàfi àwọn aṣàtìpó mélòó kan.”
A od ostatka Judeje koji je došao da se stani u Egiptu, nitko neće uteći ni preživjeti da bi se mogao vratiti u zemlju judejsku za kojom im duše čeznu, da se u nju vrate i ondje nastane. Jer se nitko neće vratiti, osim izbjeglica.”
15 Lẹ́yìn èyí, gbogbo àwọn ọkùnrin tí ẹ bá mọ̀ pé, ìyàwó wọn sun tùràrí sí àwọn òrìṣà pẹ̀lú àwọn obìnrin tí ó bá wá àwọn ènìyàn púpọ̀, pàápàá àwọn ènìyàn tí wọ́n ń gbé ní òkè àti ìsàlẹ̀ Ejibiti, bẹ́ẹ̀ ni a wí fún Jeremiah.
I tada svi muškarci koji su znali da im žene kade tuđim bogovima, i sve nazočne žene, u velikom mnoštvu, i sav narod što življaše u zemlji egipatskoj i u Patrosu odgovoriše Jeremiji:
16 “Wọn sì wí pé, àwa kò ní fetísílẹ̀ ọ̀rọ̀ tí o bá bá wa sọ ní orúkọ Olúwa.
“Riječi koje si u ime Jahvino nama objavio mi ne slušamo;
17 Dájúdájú, à ó ṣe gbogbo nǹkan tí a sọ pé à ò ṣe. A ó sun tùràrí sí ayaba ọ̀run, à ó sì da ohun mímu sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí àwa àti àwọn baba wa, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ ti ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ni àwọn ìgboro Jerusalẹmu. Nígbà náà àwa ní oúnjẹ púpọ̀, a sì ṣe rere a kò sì rí ibi.
naprotiv, i dalje ćemo se držati zadane riječi: kadit ćemo nebeskoj kraljici i lijevati ljevanice, kao što smo i mi i oci naši, naši kraljevi i knezovi činili u gradovima judejskim i po ulicama jeruzalemskim: tada imadosmo kruha izobila, bijasmo sretni i ne trpjesmo nikakvih nesreća.
18 Ṣùgbọ́n láti ìgbà tí a ti dáwọ́ tùràrí sísun sí Ayaba Ọ̀run àti láti da ẹbọ ohun mímu fún un, àwa ti ṣaláìní ohun gbogbo, a sì run nípa idà àti nípa ìyàn.”
Ali otkako prestadosmo kaditi nebeskoj kraljici i lijevati joj ljevanice, u svemu smo oskudijevali i od mača i gladi pogibali.”
19 Àwọn obìnrin náà fi kún un pé, “Nígbà tí à ń jó tùràrí sí ayaba ọ̀run, tí a sì ń fi ohun mímu rú ẹbọ si; ǹjẹ́ àwọn ọkọ wa kò mọ pé àwa ń ṣe àkàrà bí i, àwòrán rẹ, àti wí pé à ń da ọtí si gẹ́gẹ́ bi ohun ìrúbọ?”
A žene rekoše: “Kad kadimo kraljici nebeskoj i lijevamo joj ljevanice, zar joj bez znanja svojih muževa pečemo kolače u obliku lika njezina i lijevamo ljevanice?”
20 Wàyí o, Jeremiah sọ fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, ọkùnrin àti obìnrin, tí wọn sì ń dáhùn pé,
Tada Jeremija svemu narodu, muškarcima i ženama, i svim ljudima koji su mu tako govorili reče:
21 “Ṣe Olúwa kò rántí ẹbọ sísun ní ìlú Juda àti àwọn ìgboro Jerusalẹmu láti ọ̀dọ̀ rẹ àti ọ̀dọ̀ àwọn baba rẹ, àwọn ọba àti àwọn aláṣẹ àti àwọn ènìyàn ìlú.
“Nije li se Jahve spomenuo i nije li ga u srce dirnuo tamjan što ste ga palili po ulicama jeruzalemskim, vi i oci vaši, vaši kraljevi, knezovi i puk zemaljski?
22 Nígbà tí Olúwa kò lè fi ara da ìwà búburú yín àti àwọn nǹkan ìríra gbogbo tí ẹ ṣe, ilẹ̀ yín sì di ohun ìfiré àti ìkọ̀sílẹ̀, láìsí olùgbé gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe wà lónìí.
Jahve više nije mogao podnositi zlodjela vaših i gnusoba koje počiniste, i zato se zemlja vaša pretvorila u pustoš i ruševine, u prokletstvo, bez stanovnika, kao što je i danas.
23 Nítorí pé ẹ ti sun ẹbọ, tí ẹ sì ti ṣẹ̀ sí Olúwa àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, àti pé ẹ kò sì tẹ̀lé òfin rẹ̀ àti àwọn àṣẹ. Ibi náà yóò wá sórí rẹ àti bí o ṣe rí i.”
Zbog toga što ste, prinoseći tamjan, zgriješili Jahvi, što Jahvina glasa ne slušaste i Jahvina se Zakona i njegovih se naredaba i svjedočanstava ne držaste, snađe vas ova nevolja, kakva je danas.”
24 Nígbà náà ni Jeremiah dáhùn pẹ̀lú obìnrin náà pé, “Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin ọmọ Juda tí ó wà ní Ejibiti.
Zatim reče Jeremija svemu narodu, osobito ženama: “Čujte riječ Jahvinu, svi Judejci koji ste u zemlji egipatskoj:
25 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí. Ìwọ àti àwọn ìyàwó rẹ fihàn pẹ̀lú àwọn ìhùwà rẹ àti àwọn ohun tí ó ṣèlérí nígbà tí o wí pé, ‘Àwa yóò mú ẹ̀jẹ́ tí a jẹ́ ṣẹ lórí sísun tùràrí àti dída ẹbọ ohun mímu sí orí ère Ayaba Ọ̀run.’ “Tẹ̀síwájú nígbà náà, ṣe ohun tí o sọ, kí o sì mú ẹ̀jẹ́ rẹ ṣẹ.
Ovako govori Jahve nad Vojskama, Bog Izraelov: 'Vi žene, ono što vaša usta obećaju, to vaše ruke moraju i izvršiti. Rekoste: 'Mi ćemo se tvrdo držati zavjeta što ih učinismo: kaditi kraljici nebeskoj i lijevati joj ljevanice.' Držite se samo svojih zavjeta i lijevajte revno ljevanice!
26 Ṣùgbọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè, gbogbo ẹ̀yin Júù tí ń gbé ilẹ̀ Ejibiti, mo gégùn ún: ‘Mo búra pẹ̀lú títóbi orúkọ mi,’ bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí, ‘pé kò sí ẹnikẹ́ni láti Juda tí ń gbé ibikíbi ní Ejibiti tí ó gbọdọ̀ ké pe orúkọ mi tàbí búra, “Gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run tí ó dá wa ti wà láààyè.”
Ali čujte zato riječ Jahvinu, svi vi Judejci nastanjeni u zemlji egipatskoj! Evo, zaklinjem se velikim imenom svojim,' govori Jahve. 'U svoj zemlji egipatskoj nijedna usta judejska neće više izustiti mojega imena; nitko neće reći: 'Živoga mi Jahve!'
27 Nítorí náà, èmi ó ṣọ wọ́n fún ibi, kì í ṣe fún rere. Àti gbogbo àwọn ọkùnrin Juda tí ó wà ní ilẹ̀ Ejibiti ni a ó parun pẹ̀lú idà àti ìyàn títí tí gbogbo wọn yóò fi tán.
Evo, bdim nad njima, na nesreću, a ne na dobro njihovo: svi ljudi judejski što su u zemlji egipatskoj poginut će od mača i gladi do potpunog istrebljenja.
28 Àwọn tí ó bá sá àsálà kúrò lọ́wọ́ ìparun idà àti pípadà sí ilẹ̀ Juda láti Ejibiti yóò kéré níye. Gbogbo àwọn tí ó bá kú ní ilẹ̀ Juda, tí ó wá gbé ilẹ̀ Ejibiti yóò mọ ọ̀rọ̀ ẹni tí yóò dúró yálà tèmi tàbí tiyín.
I bit će malo onih koji će izbjeći maču i vratiti se iz egipatske zemlje u zemlju judejsku. Onda će sav ostatak judejski, svi koji dođoše u zemlju egipatsku da ondje žive, spoznati čija riječ vrijedi, moja ili njihova.
29 “‘Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún un yín pé èmi yóò fi ìyà jẹ yín níbi tí Olúwa ti sọ láti lè jẹ́ kí ẹ mọ̀ pé ìjìyà mi tí mo sọ pé ẹ̀ ó jẹ yóò ṣẹ.’
A ovo neka vam bude znamenje - riječ je Jahvina - da ću vas kazniti na ovome mjestu, da biste znali da će se vama na nesreću ispuniti prijetnje moje protiv vas.'
30 Báyìí ni Olúwa wí: ‘Èmi yóò fi Farao Hofira ọba Ejibiti lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́, èyí tí ó lè pa ayé rẹ́; gẹ́gẹ́ bí mo ti fi Sedekiah ọba Juda lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́ ọ̀tá tó ń lépa ẹ̀mí rẹ̀.’”
Ovako govori Jahve: 'Gle, predat ću faraona Hofru, kralja egipatskoga, u ruke njegovim neprijateljima i u ruke onih koji mu rade o glavi, baš kao što sam Sidkiju, kralja Judejskoga, predao u ruke Nabukodonozora, kralja babilonskoga, neprijatelja njegova, koji mu je radio o glavi.'”