< Jeremiah 13 >

1 Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ kí o sì ra àmùrè aṣọ ọ̀gbọ̀, kí o sì dì í mọ́ ẹ̀gbẹ́ rẹ, kí o má sì ṣe jẹ́ kí omi kí ó kàn án.”
Så sa Herren til mig: Gå og kjøp dig et lerretsbelte og legg det om dine lender, men la det ikke komme i vann!
2 Bẹ́ẹ̀ ni mo ra àmùrè gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí, mo sì dì í mọ́ ẹ̀gbẹ́ mi.
Og jeg kjøpte beltet efter Herrens ord og la det om mine lender.
3 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá nígbà kejì,
Og Herrens ord kom til mig annen gang, og det lød så:
4 “Mú àmùrè tí o rà, kí o sì fiwé ẹ̀gbẹ́ rẹ, kí o sì lọ sí Perati, kí o lọ pa á mọ́ sí pàlàpálá òkúta.”
Ta det belte du kjøpte, det som er om dine lender, og stå op, gå til Eufrat og skjul det der i en bergkløft!
5 Nígbà náà ni mo lọ pa á mọ́ ní Perati gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wí fún mi.
Og jeg gikk og skjulte det ved Eufrat, som Herren hadde befalt mig.
6 Lẹ́yìn ọjọ́ díẹ̀, Olúwa sọ fún mi, “Lọ sí Perati kí o lọ mú àmùrè tí mo ní kí o pamọ́ síbẹ̀.”
Og lang tid efter sa Herren til mig: Stå op, gå til Eufrat og hent derfra det belte som jeg bød dig å skjule der.
7 Nígbà náà ni mo lọ sí Perati mo lọ wá àmùrè mi níbi tí mo pa á mọ́ sí, ṣùgbọ́n nísinsin yìí àmùrè náà ti bàjẹ́, kò sì wúlò fún ohunkóhun mọ́.
Og jeg gikk til Eufrat og gravde og tok beltet fra det sted hvor jeg hadde skjult det; og se, beltet var ødelagt, det dudde ikke til noget.
8 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
Da kom Herrens ord til mig:
9 “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Bákan náà ni èmi yóò run ìgbéraga Juda àti ìgbéraga ńlá ti Jerusalẹmu.
Så sier Herren: Således vil jeg gjøre ende på Judas og Jerusalems store overmot.
10 Àwọn ènìyàn búburú tí ó kùnà láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí wọ́n ń lo agídí ọkàn wọn, tí ó sì ń rìn tọ àwọn òrìṣà láti sìn wọ́n, àti láti foríbalẹ̀ fún wọn, yóò sì dàbí àmùrè yìí tí kò wúlò fún ohunkóhun.
Dette onde folk, som ikke vil høre på mine ord, som følger sitt hårde hjerte og går efter andre guder for å dyrke og tilbede dem, det skal bli lik dette belte som ikke duer til noget!
11 Nítorí bí a ti lẹ àmùrè mọ́ ẹ̀gbẹ́ ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni a lẹ agbo ilé Israẹli àti gbogbo ilé Juda mọ́ mi,’ ni Olúwa wí, ‘kí wọn kí ó lè jẹ́ ènìyàn ògo àti ìyìn fún mi, ṣùgbọ́n wọn kò fẹ́ gbọ́.’
For likesom beltet fester sig til en manns lender, således festet jeg hele Israels hus og hele Judas hus til mig, sier Herren, forat det skulde være mitt folk og være mig til navnkundighet og til pris og til pryd; men de hørte ikke.
12 “Sọ fún wọn, ‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ Israẹli wí, gbogbo ìgò ni à ó fi ọtí wáìnì kún.’ Bí wọ́n bá sì sọ fún ọ pé, ‘Ṣé a kò mọ̀ pé gbogbo ìgò ni ó yẹ láti bu ọtí wáìnì kún?’
Og du skal si til dem dette ord: Så sier Herren, Israels Gud: Hver vinkrukke blir fylt med vin. Og de skal si til dig: Vet vi da ikke at hver vinkrukke blir fylt med vin?
13 Nítorí náà sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí: Èmi yóò fi ìmutípara kún gbogbo olùgbé ilẹ̀ yìí pẹ̀lú ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi, àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì gbogbo àwọn tó ń gbé ní Jerusalẹmu.
Og da skal du si til dem: Så sier Herren: Se, jeg fyller alle dette lands innbyggere og kongene som sitter på Davids trone, og prestene og profetene og alle Jerusalems innbyggere, så de blir drukne.
14 Èmi yóò ti èkínní lu èkejì, àwọn baba àti ọmọkùnrin pọ̀ ni Olúwa wí. Èmi kì yóò dáríjì, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò ṣàánú, èmi kì yóò ṣe ìyọ́nú láti máa pa wọ́n run.’”
Og jeg vil knuse dem, den ene mot den andre, både fedrene og barna alle sammen, sier Herren; jeg vil ikke skåne og ikke spare og ikke forbarme mig, så jeg lar være å ødelegge dem.
15 Gbọ́ kí o sì fetísílẹ̀, ẹ má ṣe gbéraga, nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀.
Hør og gi akt, vær ikke overmodige! For Herren taler.
16 Ẹ fi ògo fún Olúwa Ọlọ́run yín, kí ó tó mú òkùnkùn wá, àti kí ó tó mú ẹsẹ̀ yín tàsé lórí òkè tí ó ṣókùnkùn. Nígbà tí ẹ̀yin sì ń retí ìmọ́lẹ̀, òun yóò sọ ọ́ di òjìji yóò sì ṣe bi òkùnkùn biribiri.
Gi Herren eders Gud ære, før han lar det bli mørkt, og før eders føtter støter sig på de mørke fjell! I venter på lys, og han gjør det til dødsskygge, lar det bli til belgmørke!
17 Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá fetísílẹ̀, Èmi yóò sọkún ní ìkọ̀kọ̀ nítorí ìgbéraga yín. Ojú mi yóò sun ẹkún kíkorò, tí omi ẹkún, yóò sì máa sàn jáde, nítorí a kó agbo Olúwa lọ ìgbèkùn.
Men vil I ikke høre på dette, da skal min sjel gråte i lønndom over slikt overmot, og mitt øie skal gråte så tårene triller, fordi Herrens hjord blir bortført i fangenskap.
18 Sọ fún ọba àti ayaba pé, “Ẹ rẹ ara yín sílẹ̀, ẹ sọ̀kalẹ̀ láti orí ìtẹ́ yín, adé ògo yín bọ́ sí ilẹ̀ láti orí yín.”
Si til kongen og til kongens mor: Sett eder ned i det lave! For eders prektige krone er falt av eders hode.
19 Àwọn ìlú tí ó wà ní gúúsù ni à ó tì pa, kò sì ní sí ẹnikẹ́ni láti ṣí wọn. Gbogbo Juda ni a ó kó lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn, gbogbo wọn ni a ó kó lọ ní ìgbèkùn pátápátá.
Sydlandets byer er lukket, og det er ingen som lukker op; hele Juda er bortført, det er bortført, til siste mann.
20 Gbé ojú rẹ sókè, kí o sì wo àwọn tí ó ń bọ̀ láti àríwá. Níbo ni agbo ẹran tí a fi sí abẹ́ àkóso rẹ wà; àgùntàn tí ò ń mú yangàn.
Løft eders øine og se dem som kommer fra Norden! Hvor er nu den hjord som var gitt dig, dine herlige får?
21 Kí ni ìwọ yóò wí nígbà tí Olúwa bá dúró lórí rẹ àwọn tí o mú bí ọ̀rẹ́ àtàtà. Ǹjẹ́ kò ní jẹ́ ìrora fún ọ bí aboyún tó ń rọbí?
Hvad vil du si når han setter fortrolige venner til høvdinger over dig, dem som du selv har oplært til det? Skulde ikke veer gripe dig, som en fødende kvinne?
22 Tí o bá sì bi ara rẹ léèrè, “Kí ni ìdí rẹ̀ tí èyí fi ṣẹlẹ̀ sí mi?” Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ tí o ṣẹ̀ ni aṣọ rẹ fi fàya tí a sì ṣe é ní ìṣekúṣe.
Og når du sier i ditt hjerte: Hvorfor har dette hendt mig? så vit: For dine mange misgjerningers skyld er kanten på din kjole løftet op, dine hæler blottet med vold.
23 Ǹjẹ́ Etiopia le yí àwọ̀ rẹ̀ padà? Tàbí ẹkùn lè yí àwọ̀ rẹ̀ padà? Bí èyí kò ti lè rí bẹ́ẹ̀ náà ni ẹ̀yin tí ìwà búburú bá ti mọ́ lára kò lè ṣe rere.
Kan en morian omskifte sin hud, eller en leopard sine flekker? - Da kan også I gjøre godt, I som er vant til å gjøre ondt.
24 “N ó fọ́n ọn yín ká bí i ìyàngbò tí ẹ̀fúùfù ilẹ̀ aṣálẹ̀ ń fẹ́.
Så vil jeg da adsprede dem likesom strå som farer avsted for ørkenens vind.
25 Èyí ni ìpín tìrẹ; tí mo ti fi sílẹ̀ fún ọ,” ni Olúwa wí, “Nítorí ìwọ ti gbàgbé mi o sì gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọlọ́run àjèjì.
Dette er din lodd, din tilmålte del fra mig, sier Herren, fordi du har glemt mig og satt din lit til løgn.
26 N ó sí aṣọ lójú rẹ, kí ẹ̀sín rẹ le hàn síta—
Så vil da også jeg løfte kanten på din kjole op over ditt ansikt, så din skam blir sett.
27 ìwà àgbèrè àti ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́, àìlójútì panṣágà rẹ! Mo ti rí ìwà ìríra rẹ, lórí òkè àti ní pápá. Ègbé ni fún ọ ìwọ Jerusalẹmu! Yóò ti pẹ́ tó tí o ó fi máa wà ní àìmọ́?”
Ditt horelevnet og din vrinsken, din skammelige utukt på haugene ute på marken, ja dine vederstyggeligheter har jeg sett. Ve dig, Jerusalem! Hvor lenge vil det ikke ennu vare før du blir ren!

< Jeremiah 13 >