< Galatians 2 >
1 Lẹ́yìn ọdún mẹ́rìnlá, ni mo tún gòkè lọ sì Jerusalẹmu pẹ̀lú Barnaba, mo sì mú Titu lọ pẹ̀lú mi.
After that, fourteen years later, I, again, went up unto Jerusalem, with Barnabas, taking with me Titus also;
2 Mo gòkè lọ nípa ohun ti a fihàn mi, mo fi ìyìnrere náà tí mo ń wàásù láàrín àwọn aláìkọlà yé àwọn tí ó jẹ́ ẹni ńlá nínú wọn, èyí i nì ní ìkọ̀kọ̀, kí èmi kí ó má ba á sáré, tàbí kí ó máa ba à jẹ́ pé mo ti sáré lásán.
And I went up by revelation, and laid before them the glad-message which I proclaim among the nations; privately, however, to them of repute, —lest, by any means, in vain, I should be running, or had run.
3 Ṣùgbọ́n a kò fi agbára mú Titu tí ó wà pẹ̀lú mi, ẹni tí í ṣe ara Giriki láti kọlà.
But, not even Titus, who was with me, though he was a Greek, was compelled to be circumcised; —
4 Ọ̀rọ̀ yìí wáyé nítorí àwọn èké arákùnrin tí wọn yọ́ wọ inú àárín wa láti yọ́ òmìnira wa wò, èyí tí àwa ni nínú Kristi Jesu, kí wọn lè mú wa wá sínú ìdè.
But, [this was] because of the false brethren secretly introduced, —who, indeed, came in secretly to spy out our freedom, which we have in Christ Jesus, that they might bring us into bondage: —
5 Àwọn ẹni ti a kò fún ni àǹfààní láti gbọ́ ọ̀rọ̀ wọn fún ìṣẹ́jú kan; kí ẹ̀yin kí o lè máa tẹ̀síwájú nínú òtítọ́ ìyìnrere náà.
Unto whom, not even for an hour, gave we place by the [required] submission, —in order that, the truth of the glad-message, might still abide with you.
6 Ṣùgbọ́n ní ti àwọn tí ó dàbí ẹni pàtàkì—ohunkóhun tí ó wù kì wọn jásí, kò jẹ́ nǹkan kan fún mi; Ọlọ́run kò fi bí ẹnikẹ́ni ṣe rí ṣe ìdájọ́ rẹ̀—àwọn ènìyàn yìí kò fi ohunkóhun kún ọ̀rọ̀ mi.
Moreover, from them who were reputed to be something, —whatsoever at one time, they were, maketh no difference to me, God accepteth not a man’s person, —unto me, in fact, they who were of repute added nothing further;
7 Ṣùgbọ́n kàkà bẹ́ẹ̀, nígbà tí wọn rí i pé a tí fi ìyìnrere tí àwọn aláìkọlà le mi lọ́wọ́, bí a tí fi ìyìnrere tí àwọn onílà lé Peteru lọ́wọ́.
But, on the contrary, —when they saw that I had been entrusted with the glad-message to the uncircumcision, even as, Peter, [with that] to the circumcision,
8 Nítorí Ọlọ́run, ẹni tí ó ṣiṣẹ́ nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ Peteru gẹ́gẹ́ bí aposteli sí àwọn Júù, òun kan náà ni ó ṣiṣẹ́ nínú iṣẹ́ ìránṣẹ́ mi gẹ́gẹ́ bí aposteli sí àwọn aláìkọlà.
For, he that energised in Peter, into an apostleship to the circumcision, energised also in me, for the nations, —
9 Jakọbu, Peteru, àti Johanu, àwọn ẹni tí ó dàbí ọ̀wọ́n, fún èmi àti Barnaba ni ọwọ́ ọ̀tún ìdàpọ̀ nígbà tí wọ́n rí oore-ọ̀fẹ́ tí a fi fún mi, wọ́n sì gbà pé kí àwa náà tọ àwọn aláìkọlà lọ, nígbà ti àwọn náà lọ sọ́dọ̀ àwọn Júù.
And when they perceived the favour which had been given unto me, James and Cephas and John, who were reputed to be pillars, gave, the right hand of fellowship, unto me and Barnabas, in order that, we, [should go] unto the nations, and, they, unto the circumcision: —
10 Ohun gbogbo tí wọ́n béèrè fún ni wí pé, kí a máa rántí àwọn tálákà, ohun kan náà gan an tí mo ń làkàkà láti ṣe.
Only that we should remember, the destitute, —as to which I had given diligence, this very thing, to do.
11 Ṣùgbọ́n nígbà tí Peteru wá sí Antioku, mo takò ó lójú ara rẹ̀, nítorí tí ó jẹ̀bi, mo sì bá a wí.
But, when Cephas came unto Antioch, to the face, [even], him, I resisted, because he stood condemned;
12 Nítorí pé kí àwọn kan tí ó ti ọ̀dọ̀ Jakọbu wá tó dé, ó ti ń ba àwọn aláìkọlà jẹun; ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n dé, ó fàsẹ́yìn, ó sì ya ara rẹ̀ sọ́tọ̀ kúrò lọ́dọ̀ àwọn aláìkọlà nítorí ó bẹ̀rù àwọn ti ó kọlà.
For, before that certain came from James, with them of the nations, used he to eat; whereas, when they came, he used to withdraw, and keep himself separate, fearing them of the circumcision;
13 Àwọn Júù tí ó kù pawọ́pọ̀ pẹ̀lú rẹ̀ láti jùmọ̀ ṣe àgàbàgebè, tó bẹ́ẹ̀ tí wọn sì fi àgàbàgebè wọn si Barnaba lọ́nà.
And the rest of the Jews [also] used hypocrisy with him, so that, even Barnabas, was carried away by their hypocrisy.
14 Nígbà tí mo rí i pé wọn kò rìn déédé gẹ́gẹ́ bí òtítọ́ ìyìnrere, mo wí fún Peteru níwájú gbogbo wọn pé, “Bí ìwọ, tí ì ṣe Júù ba ń rìn gẹ́gẹ́ bí ìwà àwọn kèfèrí, èéṣe tí ìwọ fi ń fi agbára mu àwọn kèfèrí láti máa rìn bí àwọn Júù?
But, when I saw that they were not walking with straightforwardness as regardeth the truth of the glad-message, I said unto Cephas, before all: If, thou, although, a Jew, like them of the nations, and not like the Jews, dost live, how dost thou compel, them of the nations, to live like Jews?
15 “Àwa tí i ṣe Júù nípa ìbí, tí kì i sí ì ṣe aláìkọlà ẹlẹ́ṣẹ̀,
We, by nature Jews, and not sinners from among the nations,
16 tí a mọ̀ pé a kò dá ẹnikẹ́ni láre nípa iṣẹ́ òfin, bí kò ṣe nípa ìgbàgbọ́ nínú Jesu Kristi, àní àwa pẹ̀lú gbà Jesu Kristi gbọ́, kí a bá a lè dá wa láre nípa ìgbàgbọ́ tí Kristi, kì í sì i ṣe nípa iṣẹ́ òfin, nítorí pé nípa iṣẹ́ òfin kò sí ènìyàn kan tí a ó dá láre.
Knowing, however, that a man is not declared righteous by works of law, [nor at all] save through faith in Christ Jesus; even we, on Christ Jesus, believed, that we might be declared righteous—by faith in Christ, and not by works of law; because, by works of law, shall no flesh be declared righteous.
17 “Ṣùgbọ́n nígbà tí àwa bá ń wá ọ̀nà láti rí ìdáláre nípa Kristi, ó di ẹ̀rí wí pé àwa pẹ̀lú jẹ́ ẹlẹ́ṣẹ̀, ǹjẹ́ èyí ha jásí wí pé Kristi ń ṣe ìránṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ bí? Kí a má rí ì!
Now, if in seeking to be declared righteous in Christ we, ourselves also, were found sinners, —is Christ, therefore, a minister, of sin? Far be it!
18 Nítorí pé bí mo bá sì tún gbé àwọn ohun tí mo tí wó palẹ̀ ró, mo fi ara mi hàn bí arúfin.
For, if, the things that I pulled down, these, again, I build, a transgressor, I prove, myself, to be.
19 “Nítorí pé nípa òfin, mo tí di òkú sí òfin, kí èmi lè wà láààyè sí Ọlọ́run.
For, I, through means of law, unto law, died, that, unto God, I might live: —
20 A ti kàn mí mọ́ àgbélébùú pẹ̀lú Kristi, èmí kò sì wà láààyè mọ́, ṣùgbọ́n Kristi ń gbé inú mi wíwà tí mo sì wà láààyè nínú ara, mo wà láààyè nínú ìgbàgbọ́ Ọmọ Ọlọ́run, ẹni tí o fẹ́ mi, tí ó sì fi òun tìkára rẹ̀ fún mi.
With Christ, have I been crucified; and, living no longer, am, I, but, living in me, is, Christ, —while, so far as I now do live in flesh, by faith, I live—The faith in the Son of God, who loved me, and gave himself up in my behalf.
21 Èmi kò ya oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run sí apá kan, nítorí pé bí a bá le ti ipasẹ̀ òfin jèrè òdodo, a jẹ́ pé Kristi kú lásán.”
I do not set aside the favour of God; for, if, through law, is righteousness, then, Christ, without cause, died.