< Deuteronomy 33 >

1 Èyí ni ìbùkún tí Mose ènìyàn Ọlọ́run bùkún fún àwọn ọmọ Israẹli kí ó tó kú.
Ko te manaaki tenei i manaaki ai a Mohi, te tangata a te Atua, i nga tama a Iharaira i mua ake o tona matenga.
2 Ó sì wí pé, “Olúwa ti Sinai wá, ó sì yọ sí wọn láti Seiri wá ó sì tàn án jáde láti òkè Parani wá. Ó ti ọ̀dọ̀ ẹgbẹgbàarùn-ún àwọn mímọ́ wá láti ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni òfin kan a mú bí iná ti jáde fún wọn wá.
Na ka mea ia, I haere mai a Ihowa i Hinai, i rere mai i Heira ki runga ki a ratou; i whiti mai ia i Maunga Parana, a haere mai ana ia i nga mano tini o te hunga tapu: he ture i tona ringa matau mo ratou, e mura ana.
3 Nítòótọ́, ó fẹ́ràn àwọn ènìyàn an rẹ̀, gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ wà ní ọwọ́ rẹ̀. Ní ẹsẹ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti foríbalẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti ń gba ọ̀rọ̀,
Ina, e aroha ana ia ki nga iwi; kei roto i tou ringa ana tangata tapu katoa: a noho ana ratou i ou waewae; ka riro i a ratou katoa au korero.
4 òfin tí Mose fi fún wa, ìní ti ìjọ ènìyàn Jakọbu.
Na Mohi te ture i ako ki a tatou, hei taonga tuku iho, tuku iho mo te huihui o Hakopa.
5 Òun ni ọba lórí Jeṣuruni ní ìgbà tí olórí àwọn ènìyàn péjọpọ̀, pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Ko ia ano te kingi o Iehuruna i te huihuinga o nga upoko o te iwi, ratou ko nga iwi katoa o Iharaira.
6 “Jẹ́ kí Reubeni yè kí ó má ṣe kú, tàbí kí ènìyàn rẹ mọ níwọ̀n.”
Kia ora a Reupena, kaua hoki e mate, otiia kia tokoouou ona tangata.
7 Èyí ni ohun tí ó sọ nípa Juda: “Olúwa gbọ́ ohùn Juda kí o sì mú tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ wá. Kí ọwọ́ rẹ̀ kí ó tó fún un, kí ó sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀!”
A tenei ano te manaaki mo Hura: na ka mea ia, Whakarongo, e Ihowa, ki te reo o Hura, mau ano hoki ia e kawe ki tona iwi: i kaha hoki ona ringa ki te tohe mona ake; a mau ia e awhina ki ona hoariri.
8 Ní ti Lefi ó wí pé, “Jẹ́ kí Tumimu àti Urimu rẹ kí ó wà pẹ̀lú ẹni mímọ́ rẹ. Ẹni tí ó dánwò ní Massa, ìwọ bá jà ní omi Meriba.
A mo Riwai i mea ia, Kei tou tangata tapu ou Tumime me ou Urimi, i whakamatautauria ra ia e koe ki Maha, i ngangautia ra e koe ki nga wai o Meripa;
9 Ó wí fún baba àti ìyá rẹ pé, ‘Èmi kò buyì fún wọn.’ Kò mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, tàbí mọ àwọn ọmọ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó dúró lórí ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
I mea nei mo tona papa raua ko tona whaea, Kahore ahau i kite i a ia; kihai ano hoki ia i mohio ki ona tuakana, kihai i matau ki ana ake tamariki; he mea hoki, e pupuri ana ratou i tau kupu, e tiaki ana i tau kawenata.
10 Ó kọ́ Jakọbu ní ìdájọ́ rẹ̀ àti Israẹli ní òfin rẹ̀. Ó mú tùràrí wá síwájú rẹ̀ àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ẹbọ sísun sórí i pẹpẹ rẹ̀.
Ma ratou a Hakopa e whakaako ki au whakaritenga, a Iharaira hoki ki tau ture: ma ratou hoki te paowa kakara e hoatu ki tou aroaro, me te tahunga tinana ki runga ki tau aata.
11 Bùsi ohun ìní rẹ̀, Olúwa, kí o sì tẹ́wọ́gbà iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀. Lu ẹgbẹ́ àwọn tí ó dìde sí i; àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, kí wọn kí ó má ṣe dìde mọ́.”
Manaakitia ona rawa, e Ihowa, kia aro mai hoki koe ki te mahi a ona ringa: whatiia nga hope o te hunga e whakatika ana ki a ia, o nga mea hoki e kino ana ki a ia, kei whakatika mai ano ratou.
12 Ní ti Benjamini ó wí pé, “Jẹ́ kí olùfẹ́ Olúwa máa gbé ní àlàáfíà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun a máa bò ó ní gbogbo ọjọ́, ẹni tí Olúwa fẹ́ràn yóò máa sinmi láàrín èjìká rẹ̀.”
Ko tana kupu mo Pineamine, Ko ta Ihowa i aroha ai ka noho humarie ki tona taha; ko ia e uhi ana i a ia a pau noa te ra, e noho ana i waenganui o ona pokohiwi.
13 Ní ti Josẹfu ó wí pé, “Kí Olúwa bùkún ilẹ̀ rẹ, fún ohun iyebíye láti ọ̀run pẹ̀lú ìrì àti ibú tí ó ń bẹ níṣàlẹ̀;
Ko tana kupu mo Hohepa, He manaakitanga tona whenua na Ihowa; ki nga mea papai o te rangi, ki te tomairangi, ki te wai hohonu e takoto ake ana i raro,
14 àti fún èso iyebíye tí ọ̀run mú wá àti ti ohun iyebíye tí ń dàgbà ní oṣooṣù;
Ki nga hua papai o te ra, ki nga mea papai hoki e whakaputaina mai ana e te marama,
15 pẹ̀lú ohun pàtàkì òkè ńlá ìgbàanì àti fún ohun iyebíye ìgbà ayérayé;
Ki nga mea nunui hoki o nga maunga onamata, ki nga mea papai o nga maunga tu tonu,
16 Pẹ̀lú ohun iyebíye ayé àti ẹ̀kún un rẹ̀ àti fún ìfẹ́ ẹni tí ó ń gbé inú igbó. Jẹ́ kí gbogbo èyí sinmi lé orí Josẹfu, lórí àtàrí ẹni tí ó yàtọ̀ láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀.
Ki nga mea papai hoki o te whenua me ona tini mea; ki te manakohanga hoki ana i noho i te rakau: kia tae mai te manaaki ki runga ki te mahunga o Hohepa, ki te tumuaki hoki ona i wehea i ona tuakana.
17 Ní ọláńlá ó dàbí àkọ́bí akọ màlúù; ìwo rẹ̀, ìwo àgbáǹréré ni. Pẹ̀lú wọn ni yóò fi ti àwọn orílẹ̀-èdè, pàápàá títí dé òpin ayé. Àwọn sì ni ẹgbẹẹgbàárùn mẹ́wàá Efraimu, àwọn sì ni ẹgbẹẹgbẹ̀rún Manase.”
He kororia kei te matamua a tana puru; ko ona haona kei nga haona o te unikanga: ka pana e ia nga iwi, ratou katoa, ki era, tae noa ki nga pito o te whenua: a ko enei nga mano tini o Eparaima, ko enei hoki nga mano o Manahi.
18 Ní ti Sebuluni ó wí pé, “Yọ̀ Sebuluni, ní ti ìjáde lọ rẹ, àti ìwọ Isakari, nínú àgọ́ rẹ.
A, ko tana kupu mo Hepurona, Kia koa, e Hepurona, i tou putanga ki waho; e Ihakara hoki, i ou teneti.
19 Wọn yóò pe àwọn ènìyàn sórí òkè àti níbẹ̀ wọn yóò rú ẹbọ òdodo, wọn yóò mu nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ Òkun, nínú ìṣúra tí ó pamọ́ nínú iyanrìn.”
Ma ratou nga iwi e karanga ki te maunga; ki reira ratou patu ai i nga patunga o te tika: no te mea ka ngongo ratou te raneatanga o nga moana, i nga taonga huna hoki o te onepu.
20 Ní ti Gadi ó wí pé, “Ìbùkún ni ẹni tí ó mú Gadi gbilẹ̀! Gadi ń gbé níbẹ̀ bí kìnnìún, ó sì fa apá ya, àní àtàrí.
Ko tana kupu mo Kara, Ka manaakitia te kaiwhakawhanui i a Kara: noho ana ia me he raiona katua, haea iho e ia te ringa, ae ra me te tumuaki.
21 Ó sì yan ilẹ̀ tí ó dára jù fún ara rẹ̀; ìpín olórí ni a sì fi fún un. Nígbà tí ó rí tí gbogbo àwọn ènìyàn péjọ, ó mú òdodo Olúwa ṣẹ, àti ìdájọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli.”
A tangohia ana e ia te wahi tuatahi mona; no te mea kei reira te wahi a te kaiwhakahaere tikanga e tiakina ana; a haere mai ana me nga upoko o te iwi, a oti ana i a ia, ratou tahi ko Iharaira, te tikanga a Ihowa, me ana whakaritenga.
22 Ní ti Dani ó wí pé, “Ọmọ kìnnìún ni Dani, tí ń fò láti Baṣani wá.”
A, ko tana kupu mo Rana, Hei kuao raiona a Rana: ka mokowhiti mai ia i Pahana.
23 Ní ti Naftali ó wí pé, “Ìwọ Naftali, kún fún ojúrere Ọlọ́run àti ìbùkún Olúwa; yóò jogún ìhà ìwọ̀-oòrùn àti gúúsù.”
A, ko tana kupu mo Napatari, E Napatari, e makona nei i te manakohanga, e ki ana hoki i te manaaki a Ihowa: nohoia e koe te taha ki te hauauru me te tonga.
24 Ní ti Aṣeri ó wí pé, “Ìbùkún ọmọ ni ti Aṣeri; jẹ́ kí ó rí ojúrere láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kí ó sì ri ẹsẹ̀ rẹ̀ sínú òróró.
A, ko tana kupu mo Ahera, Ko nga tamariki te manaaki mo Ahera; kia arongia mai ia e ona tuakana, kia toua hoki tona waewae ki te hinu.
25 Bàtà rẹ̀ yóò jẹ́ irin àti idẹ, agbára rẹ̀ yóò sì rí bí ọjọ́ rẹ̀.
Ko ou tutaki he rino, he parahi; a ka rite tou kaha ki ou ra.
26 “Kò sí ẹlòmíràn bí Ọlọ́run Jeṣuruni, ẹni tí ń gun ọ̀run fún ìrànlọ́wọ́ rẹ àti ní ojú ọ̀run nínú ọláńlá rẹ̀.
Kahore he rite mo te Atua, e Iehuruna, e eke hoiho nei i nga rangi ki te whakauru i a koe, ki nga kapua hoki, i runga ano i tona kororia.
27 Ọlọ́run ayérayé ni ibi ìsádi rẹ, àti ní ìsàlẹ̀ ni apá ayérayé wà. Yóò lé àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ, ó sì wí pé, ‘Ẹ máa parun!’
Ko te Atua ora tonu tou nohoanga, a kei raro ko nga ringa o tua iho: a i peia e ia te hoariri i tou aroaro, i mea hoki, Whakangaromia.
28 Israẹli nìkan yóò jókòó ní àlàáfíà, orísun Jakọbu nìkan ní ilẹ̀ ọkà àti ti ọtí wáìnì, níbi tí ọ̀run ti ń sẹ ìrì sílẹ̀.
Na ka noho humarie a Iharaira, me te matapuna o Hakopa ko ia anake, ki te whenua witi, waina; ae ra, ka maturuturu iho te tomairangi o ona rangi.
29 Ìbùkún ni fún ọ, Israẹli, ta ni ó dàbí rẹ, ẹni tí a gbàlà láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Òun ni asà àti ìrànwọ́ rẹ̀ àti idà ọláńlá rẹ̀. Àwọn ọ̀tá rẹ yóò tẹríba fún ọ, ìwọ yóò sì tẹ ibi gíga wọn mọ́lẹ̀.”
Ka hari koe, e Iharaira: ko wai hei rite mou, mo te iwi i whakaorangia nei e Ihowa, te pukupuku hei whakapuru mou, ko te hoari hoki e whai kororia ai koe! a ka tuku mai ou hoariri i a ratou ki a koe; a ka takatakahi koe i o ratou wahi teitei.

< Deuteronomy 33 >