< Amos 7 >

1 Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Ó pèsè ọwọ́ eṣú lẹ́yìn ìgbà tí a kórè ìpín ọba, ní ìgbà ti èso ẹ̀ẹ̀kejì ń jáde bọ̀.
Saaledes lod den Herre, Herre mig se et Syn: Og se, han dannede Græshopper, da Græsset til anden Slæt begyndte at komme frem; og se der kom Græs til anden Slæt efter Kongens Høslæt.
2 Nígbà tí wọ́n jẹ koríko ilẹ̀ náà mọ́ féfé nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè, mo bẹ̀ ọ́, dáríjì! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”
Og det skete, der de vare færdige med at æde Urterne i Landet, at jeg sagde: Herre, Herre, tilgiv dog! hvorledes skal Jakob kunne bestaa? thi liden er han.
3 Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí. “Èyí kò ni ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa wí.
Herren angrede dette; det skal ikke ske, sagde Herren.
4 Èyí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè fihàn mí: Olúwa Olódùmarè ń pè fún ìdájọ́ pẹ̀lú iná; ó jó ọ̀gbun ńlá rún, ó sì jẹ ilẹ̀ run.
Saaledes lod den Herre, Herre mig se et Syn: Og se, den Herre, Herre kaldte for at holde Ret ved Ild; og den fortærede det store Dyb, og den fortærede Ageren.
5 Nígbà náà ni mo gbé ohùn mi sókè pé, “Olúwa Olódùmarè jọ̀wọ́ má ṣe ṣe é! Báwo ni Jakọbu yóò ha ṣe lè dìde? Òun kéré jọjọ!”
Og jeg sagde: Herre, Herre, lad dog af! hvorledes skal Jakob kunne bestaa? thi liden er han.
6 Olúwa ronúpìwàdà nípa èyí. “Èyí náà kò ní ṣẹlẹ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
Herren angrede dette; heller ikke det skal ske, sagde den Herre, Herre.
7 Èyí ni ohun tí ó fihàn mí: Olúwa dúró ní ẹ̀gbẹ́ odi ti a fi okùn ìwọ̀n mọ́, ti òun ti okùn ìwọ̀n tí ó rún ni ọwọ́ rẹ̀.
Saaledes lod han mig se et Syn: Og se, Herren stod paa en lodret Mur, og han havde et Blylod i sin Haand.
8 Olúwa sì bi mi pé, “Amosi, kí ni ìwọ rí?” Mo dáhùn pé, “Okùn ìwọ̀n.” Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Wò ó, Èmí ń gbé okùn ìwọ̀n kalẹ̀ láàrín àwọn Israẹli ènìyàn mi; Èmi kì yóò sì tún kọjá lọ́dọ̀ wọn mọ́.
Og Herren sagde til mig: Hvad ser du, Amos? og jeg sagde: Et Blylod; da sagde Herren: Se, jeg vil bruge et Blylod midt iblandt mit Folk Israel; jeg vil ikke ydermere blive ved at skaane det.
9 “Ibi gíga Isaaki wọ̀n-ọn-nì yóò sì di ahoro àti ibi mímọ Israẹli wọ̀n-ọn-nì yóò di ahoro. Èmi yóò sì fi idà dìde sí ilé Jeroboamu.”
Men Isaks Høje skulle ødelægges, og Israels Helligdomme skulle blive øde, og jeg vil rejse mig imod Jeroboams Hus med Sværdet.
10 Nígbà náà Amasiah àlùfáà Beteli ránṣẹ́ sí Jeroboamu ọba Israẹli, wí pé: “Amosi ti dìde láti dìtẹ̀ sí ọ ni àárín gbùngbùn Israẹli. Ilẹ̀ kò sì le gba gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ̀.
Da sendte Amazia, Præsten i Bethel, Bud til Jeroboam, Israels Konge, og lod sige: Amos har stiftet Sammensværgelse imod dig, midt i Israels Hus, Landet kan ikke udholde alle hans Ord.
11 Nítorí èyí ni ohun ti Amosi ń sọ: “‘Jeroboamu yóò ti ipa idà kú, lóòtítọ́ Israẹli yóò lọ sí ìgbèkùn, jìnnà kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’”
Thi saa har Amos sagt: Jeroboam skal dø ved Sværdet, og Israel skal visselig bortføres fra sit Land.
12 Nígbà náà ni Amasiah sọ fún Amosi pé, “Lọ jáde, ìwọ aríran! Padà sí ilẹ̀ àwọn Juda. Kí o máa jẹun rẹ níbẹ̀, kí o sì máa sọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ níbẹ̀.
Og Amazia sagde til Amos: Du Seer! gak bort, fly du til Judas Land, og æd der Brød, og spaa der!
13 Má ṣe sọtẹ́lẹ̀ mọ ni Beteli nítorí ibi mímọ́ ọba ni àti ibi tẹmpili ìjọba rẹ̀.”
Men i Bethel maa du ikke ydermere blive ved at spaa; thi det er Kongens Helligdom, og det er Rigets Hus.
14 Amosi dá Amasiah lóhùn pé, “Èmi kì í ṣe wòlíì tàbí àwọn ọmọ wòlíì, ṣùgbọ́n mo jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn, mo sì ń ṣe ìtọ́jú igi ọ̀pọ̀tọ́ sikamore.
Da svarede Amos og sagde til Amazia: Jeg er ikke en Profet, og jeg er ikke en Profets Søn, men jeg er en Hyrde og en Mand, som sanker vilde Morbær.
15 Ṣùgbọ́n Olúwa mu mi bí mo ti ń tọ́ agbo ẹran lẹ́yìn, ó sì wí fun mi pé, ‘Lọ sọtẹ́lẹ̀ fun àwọn Israẹli ènìyàn mi.’
Men Herren tog mig fra Hjorden, og Herren sagde til mig: Gak hen, vær Profet for mit Folk Israel!
16 Nítorí náà nísinsin yìí, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa. Ìwọ wí pé, “‘Má ṣe sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí Israẹli, má sì ṣe wàásù sí ilé Isaaki.’
Og nu, hør Herrens Ord; du siger: Du maa ikke spaa imod Israel og ikke lade dine Ord dryppe over Isaks Hus.
17 “Nítorí náà, èyí ni ohun ti Olúwa wí: “‘Ìyàwó rẹ yóò di panṣágà ni ìlú, àwọn ọmọ ọkùnrin àti obìnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú. A ó fi okùn wọn ilẹ̀ rẹ, a ó sì pín in àti ìwọ pẹ̀lú yóò kú ni ilẹ̀ àìmọ́. Israẹli yóò sì lọ sí ìgbèkùn, kúrò ní ilẹ̀ ìní wọn.’”
Derfor sasi siger Herren: Din Hustru skal blive en Skøge i Staden, og dine Sønner og dine Døtre skulle falde ved Sværdet, og din Jord skal deles med Maalesnoren, og du selv skal dø i et urent Land, og Israel skal visselig bortføres fra sit Land.

< Amos 7 >