< 2 Chronicles 14 >
1 Abijah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi. Asa ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Ní àwọn ọjọ́ rẹ̀, orílẹ̀-èdè wà ní àlàáfíà fún ọdún mẹ́wàá.
Абия а адормит ку пэринций луй ши а фост ынгропат ын четатя луй Давид. Ши, ын локул луй, а домнит фиул сэу Аса. Пе время луй, цара а авут одихнэ зече ань.
2 Asa ṣe ohun tí ó dára, tí ó sì tọ́ ní ojú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
Аса а фэкут че есте бине ши плэкут ынаинтя Домнулуй Думнезеулуй сэу.
3 Ó gbé àwọn pẹpẹ àjèjì kúrò àti àwọn ibi gíga. Ó fọ́ àwọn òkúta tí a yà sọ́tọ̀, ó sì gé àwọn ère Aṣerah bolẹ̀.
А ындепэртат алтареле думнезеилор стрэинь ши ынэлцимиле, а сфэрымат стылпий идолешть ши а тэят астартееле.
4 Ó pa á láṣẹ fún Juda láti wá Olúwa Ọlọ́run àwọn baba a wọn àti láti tẹ̀lé àwọn òfin rẹ̀ àti àṣẹ.
А порунчит луй Иуда сэ кауте пе Домнул Думнезеул пэринцилор сэй ши сэ ымплиняскэ Леӂя ши порунчиле.
5 Ó gbé àwọn ibi gíga kúrò àti àwọn pẹpẹ tùràrí ní gbogbo ìlú ní Juda. Ìjọba sì wà ní àlàáfíà ní abẹ́ rẹ̀.
А ындепэртат дин тоате четэциле луй Иуда ынэлцимиле ши стылпий ынкинаць соарелуй. Ши ымпэрэция а авут паче суб ел.
6 Ó mọ àwọn ìlú ààbò ti Juda, níwọ̀n ìgbà tí ìlú ti wà ní àlàáfíà. Kò sí ẹnikẹ́ni ti o jagun pẹ̀lú rẹ̀ nígbà náà, nítorí Olúwa fún un ní ìsinmi.
А зидит четэць ынтэрите ын Иуда, кэч цара а фост лиништитэ ши ымпотрива луй н-а фост рэзбой ын аний ачея, пентру кэ Домнул й-а дат одихнэ.
7 “Ẹ jẹ́ kí a kọ́ àwọn ìlú wọ̀nyí,” ó wí fún Juda, “kí ẹ sì mọ odi yí wọn ká pẹ̀lú àwọn ilé ìṣọ́ gíga, àwọn ẹnu-ọ̀nà òde, àti àwọn ìpẹ́ẹ̀rẹ̀. Ilé náà ti wà, nítorí a ti béèrè lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run wa; a béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, ó sì ti fún wa ní ìsinmi ní gbogbo ọ̀nà.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kọ́ ọ, wọn sì ṣe rere.
Ел а зис луй Иуда: „Сэ зидим ачесте четэць ши сэ ле ынконжурэм ку зидурь, ку турнурь, ку порць ши ку зэвоаре; цара есте ынкэ а ноастрэ, кэч ам кэутат пе Домнул Думнезеул ностру. Л-ам кэутат, ши Ел не-а дат одихнэ дин тоате пэрциле.” Ау зидит дар ши ау избутит.
8 Asa ní àwọn ọmọ-ogun ti ó jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àwọn ọkùnrin láti Juda. Pẹ̀lú àwọn ohun èlò àwọn àpáta ńlá àti ọ̀kọ̀ àti ọ̀kẹ́ mẹ́rìnlá láti Benjamini wọ́n dira pẹ̀lú àwọn àpáta kéékèèké àti àwọn ọrun. Gbogbo àwọn wọ̀nyí jẹ́ ògbójú jagunjagun ọkùnrin.
Аса авя о оштире де трей суте де мий де оамень дин Иуда, каре пуртау скут ши сулицэ, ши доуэ суте оптзечь де мий дин Бениамин, каре пуртау скут ши трэӂяу ку аркул, тоць оамень витежь.
9 Sera ará Etiopia yàn láti dojúkọ wọ́n, pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ọmọ-ogun pẹ̀lú ọ̀ọ́dúnrún kẹ̀kẹ́, wọ́n sì wá láti jìnnà réré bí Meraṣa.
Зерах, Етиопиянул, а ешит ымпотрива лор ку о оштире де ун милион де оамень ши трей суте де каре ши а ынаинтат пынэ ла Мареша.
10 Asa jáde lọ láti lọ bá a. Wọ́n sì mú ibi ogun ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Sefata lẹ́bàá Meraṣa.
Аса а мерс ынаинтя луй ши с-ау ыншируит де бэтае ын валя Цефата, лынгэ Мареша.
11 Nígbà náà, Asa ké pe Olúwa Ọlọ́run baba a rẹ̀, ó sì wí pé “Olúwa kò sí ẹnìkan bí rẹ láti rán aláìlágbára lọ́wọ́ láti dójú kọ alágbára. Ràn wá lọ́wọ́, Olúwa Ọlọ́run wa, nítorí tí àwa gbẹ́kẹ̀lé ọ àti ní orúkọ rẹ ni àwa fi wá láti dojúkọ àwọn ọ̀pọ̀ ọmọ-ogun yìí. Olúwa, ìwọ ni Ọlọ́run wa; má ṣe jẹ́ kí ènìyàn kó ṣẹ́gun rẹ.”
Аса а кемат пе Домнул Думнезеул луй ши а зис: „Доамне, нумай Ту поць вени ын ажутор челуй слаб ка ши челуй таре, вино ын ажуторул ностру, Доамне, Думнезеул ностру! Кэч пе Тине не сприжиним ши ын Нумеле Тэу ам венит ымпотрива ачестей мулцимь. Доамне, Ту ешть Думнезеул ностру: сэ ну ясэ бируитор омул ымпотрива Та!”
12 Olúwa lu àwọn ará Kuṣi bolẹ̀ níwájú Asa àti Juda. Àwọn ará Kuṣi sálọ.
Домнул а ловит пе етиопень динаинтя луй Аса ши динаинтя луй Иуда, ши етиопений ау луат-о ла фугэ.
13 Asa àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ sá tẹ̀lé wọn ní jìnnà réré sí Gerari. Ọ̀pọ̀lọpọ̀, àwọn ará Kuṣi ṣubú, wọn kò sì le sán padà mọ́. Wọn rún wọn mọ́lẹ̀ níwájú Olúwa àti ọmọ-ogun rẹ̀. Àwọn ọkùnrin Juda kó ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkógun.
Аса ши попорул каре ера ку ел й-ау урмэрит пынэ ла Герар, ши етиопений ау кэзут фэрэ сэ-шь поатэ скэпа вяца, кэч ау фост нимичиць де Домнул ши де оштиря Луй. Аса ши попорул луй ау фэкут о прадэ маре;
14 Wọ́n pa gbogbo àwọn ìletò tí ó wà ní ẹ̀bá Gerari, nítorí tí ìpayà Olúwa ti sọ̀kalẹ̀ sórí wọn. Wọ́n kó gbogbo ìkógun àwọn ìletò yìí lọ, níwọ̀n ìgbà tí ọ̀pọ̀ ìkógun ti wà níbẹ̀.
ау бэтут тоате четэциле дин ымпрежуримиле Герарулуй, кэч гроаза Домнулуй кэзусе песте еле, ши ау жефуит тоате четэциле а кэрор прадэ ера маре.
15 Wọ́n kọlu àwọn ibùdó àwọn darandaran, wọ́n sì gbé àwọn ọ̀wọ́ ẹran àgùntàn àti àwọn ewúrẹ́ àti àwọn ìbákasẹ. Nígbà náà wọ́n padà sí Jerusalẹmu.
Ау ловит ши кортуриле турмелор ши ау луат ку ей о маре мулциме де ой ши де кэмиле. Апой с-ау ынторс ла Иерусалим.