< 1 Kings 3 >
1 Solomoni sì bá Farao ọba Ejibiti dá àna, ó sì fẹ́ ọmọbìnrin rẹ̀ ní ìyàwó. Ó sì mú un wá sí ìlú Dafidi títí tí ó fi parí kíkọ́ ààfin rẹ̀ àti tẹmpili Olúwa, àti odi tí ó yí Jerusalẹmu ká.
Salomon je sklenil svaštvo s faraonom, egiptovskim kraljem in vzel faraonovo hčer ter jo privedel v Davidovo mesto, dokler ni končal gradnje svoje lastne hiše, Gospodove hiše in obzidja okoli Jeruzalema.
2 Síbẹ̀síbẹ̀, àwọn ènìyàn ṣì ń rú ẹbọ ní ibi gíga, nítorí a kò tí ì kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa títí di ìgbà náà
Vendar pa je ljudstvo žrtvovalo na visokih krajih, ker do tistih dni ni bilo zgrajene hiše Gospodovemu imenu.
3 Solomoni sì fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn sí Olúwa nípa rírìn gẹ́gẹ́ bí òfin Dafidi baba rẹ̀, àti pé, ó rú ẹbọ, ó sì fi tùràrí jóná ní ibi gíga.
Salomon je ljubil Gospoda, hodeč po zakonih svojega očeta Davida, vendar je žrtvoval in zažigal kadilo na visokih krajih.
4 Ọba sì lọ sí Gibeoni láti rú ẹbọ, nítorí ibẹ̀ ni ibi gíga tí ó ṣe pàtàkì jù, Solomoni sì rú ẹgbẹ̀rún ọrẹ ẹbọ sísun lórí pẹpẹ.
Kralj je odšel do Gibeóna, da tam žrtvuje, kajti to je bil ugleden visok kraj [in] na tistem oltarju je Salomon daroval tisoč žgalnih daritev.
5 Ní Gibeoni, Olúwa fi ara han Solomoni lójú àlá ní òru, Ọlọ́run sì wí pé, “Béèrè fún ohunkóhun tí o bá ń fẹ́ kí èmi ó fi fún ọ.”
V Gibeónu se je Gospod v sanjah ponoči prikazal Salomonu in Bog je rekel: »Prosi, kaj naj ti dam.«
6 Solomoni sì dáhùn wí pé, “O ti fi inú rere oore ńlá hàn sí ìránṣẹ́ rẹ, Dafidi baba mi, nítorí ó jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ àti olódodo àti ẹni tí ó ní ọkàn ìdúró ṣinṣin. Ìwọ sì tẹ̀síwájú nínú oore ńlá yìí fún un, ìwọ sì ti fún un ní ọmọkùnrin láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ ní gbogbo ọjọ́.
Salomon je rekel: »Svojemu služabniku, mojemu očetu Davidu, si izkazal veliko milost, kakor je hodil pred teboj v resnici, v pravičnosti in v iskrenosti srca s teboj in si zanj ohranil to veliko prijaznost, da si mu dal sina, da sedi na njegovem prestolu, kakor je to ta dan.
7 “Nísinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run mi, o ti mú ìránṣẹ́ rẹ jẹ ọba ní ipò Dafidi baba mi. Ṣùgbọ́n ọmọ kékeré ni mí, èmi kò sì mọ jíjáde àti wíwọlé mi.
Sedaj, oh Gospod, moj Bog, svojega služabnika si naredil kralja namesto mojega očeta Davida. Jaz pa sem samo majhen otrok. Ne vem kako odhajati ali prihajati.
8 Ìránṣẹ́ rẹ nìyí láàrín àwọn ènìyàn tí o ti yàn, àwọn ènìyàn ńlá, wọ́n pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí a kò sì lè kà wọ́n tàbí mọye wọn.
Tvoj služabnik je v sredi tvojega ljudstva, ki si ga izbral, velikega ljudstva, ki zaradi množice ne more biti niti našteto niti prešteto.
9 Nítorí náà fi ọkàn ìmòye fún ìránṣẹ́ rẹ láti le ṣàkóso àwọn ènìyàn rẹ àti láti mọ ìyàtọ̀ láàrín rere àti búburú. Nítorí ta ni ó lè ṣe àkóso àwọn ènìyàn ńlá rẹ yìí?”
Daj torej svojemu služabniku razumevajoče srce, da sodi tvoje ljudstvo, da bom lahko razločeval med dobrim in slabim, kajti kdo je zmožen soditi to tvoje tako veliko ljudstvo?«
10 Inú Olúwa sì dùn pé Solomoni béèrè nǹkan yìí.
Govor je ugajal Gospodu, da je Salomon prosil to stvar.
11 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ ti béèrè fún èyí, tí kì í ṣe ẹ̀mí gígùn tàbí ọrọ̀ fún ara rẹ, tàbí béèrè fún ikú àwọn ọ̀tá rẹ, ṣùgbọ́n fún òye láti mọ ẹjọ́ dá,
Bog mu je rekel: »Ker si prosil to stvar in zase nisi prosil dolgega življenja, niti zase nisi prosil bogastev, niti nisi prosil za življenja svojih sovražnikov, temveč si zase prosil razumevanje, da razsojaš sodbo;
12 èmi yóò ṣe ohun tí ìwọ ti béèrè. Èmi yóò fún ọ ní ọgbọ́n àti ọkàn ìmòye, tó bẹ́ẹ̀ tí kò fi ní sí ẹnìkan tí ó dàbí rẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò dìde tí yóò dàbí rẹ lẹ́yìn rẹ.
glej, storil sem glede na tvoje besede, glej, dal sem ti modrost in razumevajoče srce, tako da pred teboj ni bilo nikogar podobnega tebi niti za teboj ne bo vstal nihče podoben tebi.
13 Síwájú sí i, èmi yóò fi ohun tí ìwọ kò béèrè fún ọ: ọrọ̀ àti ọlá ní gbogbo ayé rẹ, tí kì yóò sí ẹnìkan nínú àwọn ọba tí yóò dàbí rẹ.
Dal sem ti tudi to, česar nisi prosil, tako bogastva kakor čast, tako da vse tvoje dni med kralji ne bo nobenega kralja podobnega tebi.
14 Àti bí ìwọ bá rìn ní ọ̀nà mi, tí o sì pa òfin àti àṣẹ mi mọ́ bí Dafidi baba rẹ ti ṣe, èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.”
Če boš hodil po mojih poteh, da varuješ moje zakone in moje zapovedi, kakor je hodil tvoj oče David, potem bom podaljšal tvoje dni.«
15 Solomoni jí: ó sì mọ̀ pé àlá ni. Ó sì padà sí Jerusalẹmu, ó sì dúró níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà. Nígbà náà ni ó ṣe àsè fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
Salomon se je prebudil in glej, to so bile sanje. Prišel je v Jeruzalem, stopil pred skrinjo Gospodove zaveze in daroval žgalne daritve, mirovne daritve in vsem svojim služabnikom priredil gostijo.
16 Lẹ́yìn náà ni àwọn obìnrin alágbèrè méjì wá sọ́dọ̀ ọba, wọ́n sì dúró níwájú rẹ̀.
Potem sta prišli h kralju dve ženski, ki sta bili pocestnici in obstali pred njim.
17 Ọ̀kan nínú wọn sì wí pé, “Olúwa mi, èmi àti obìnrin yìí ń gbé nínú ilé kan. Èmi sì bí ọmọ ní ilé pẹ̀lú rẹ̀.
Ena ženska je rekla: »Oh moj gospod, jaz in ta ženska stanujeva v eni hiši in rodila sem otroka, z njo v hiši.
18 Ní ọjọ́ kẹta lẹ́yìn ìgbà tí mo bímọ tan, obìnrin yìí sì bímọ pẹ̀lú. A sì nìkan dá wà; kò sí àlejò ní ilé bí kò ṣe àwa méjèèjì nìkan.
Tretji dan pa se je pripetilo, potem ko sem rodila, da je tudi ta ženska rodila in bili sva skupaj. Z nama v hiši ni bilo nobenega tujca, razen naju dveh v hiši.
19 “Ní òru, ọmọ obìnrin yìí kú nítorí tí ó sùn lé e.
Otrok te ženske pa je ponoči umrl, ker ga je prekrila.
20 Nígbà náà ni ó sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó sì gbé ọmọ tèmi lẹ́gbẹ̀ẹ́ mi, nígbà tí èmi ìránṣẹ́ rẹ̀ ti sùn lọ. Ó sì tẹ́ ẹ sí àyà rẹ̀, ó sì tẹ́ òkú ọmọ tirẹ̀ sí àyà mi.
Ona pa je opolnoči vstala in mojega sina vzela od mene, medtem ko je tvoja pomočnica spala in si ga položila v svoje naročje, svojega mrtvega pa je položila v moje naročje.
21 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo sì dìde láti fi ọmú fún ọmọ mi: ó sì ti kú! Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo sì wò ó fín ní òwúrọ̀, mo sì rí i pé kì í ṣe ọmọ mi tí mo bí.”
Ko sem zjutraj vstala, da podojim svojega otroka, glej, je bil ta mrtev. Toda ko sem to zjutraj preudarjala, glej, to ni bil moj sin, ki sem ga rodila.«
22 Obìnrin kejì sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí alààyè ni ọmọ mi, èyí òkú ni ọmọ tirẹ̀.” Èyí òkú ni tirẹ̀; èyí alààyè ni tèmi. Ṣùgbọ́n èyí àkọ́kọ́ tún wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí òkú ni tìrẹ; èyí alààyè ni tèmi.” Báyìí ni wọ́n sì ń jiyàn níwájú ọba.
Druga ženska pa je rekla: »Ne, temveč živi je moj sin, mrtvi pa je tvoj sin.« Ta pa je rekla: »Ne, temveč mrtvi je tvoj sin, živi pa je moj sin.« Tako sta govorili pred kraljem.
23 Ọba sì wí pé, “Ẹni yìí wí pé, ‘Ọmọ mi ni ó wà láààyè, ọmọ tirẹ̀ ni ó kú,’ nígbà tí ẹni èkejì náà ń wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́! Ọmọ tirẹ̀ ni ó kú, ọmọ tèmi ni ó wà láààyè.’”
Potem je kralj rekel: »Ena pravi: ›Ta je moj sin, ki živi, tvoj sin pa je mrtev.‹ Druga pa pravi: ›Ne, temveč je mrtvi tvoj sin, moj sin pa živi.‹«
24 Nígbà náà ni ọba wí pé, “Ẹ mú idà fún mi wá.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú idà wá fún ọba.
Kralj je rekel: »Prinesite mi meč.« Meč so prinesli pred kralja.
25 Ọba sì pàṣẹ pé, “Ẹ gé alààyè ọmọ sí méjì, kí ẹ sì mú ìdajì fún ọ̀kan, àti ìdajì fún èkejì.”
Kralj je rekel: »Živega otroka razdelite na pol in polovico dajte eni, polovico pa drugi.«
26 Obìnrin tí ọmọ tirẹ̀ wà láààyè sì kún fún àánú fún ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, olúwa mi, ẹ fún un ní alààyè ọmọ! Ẹ má ṣe pa á!” Ṣùgbọ́n obìnrin èkejì sì wí pé, “Kì yóò jẹ́ tèmi tàbí tìrẹ. Ẹ gé e sí méjì!”
Potem je kralju spregovorila ženska, od katere je bil živi otrok, kajti njena notranjost je hrepenela za svojim sinom in rekla: »Oh moj gospod, izročite ji živega otroka in nikakor ga ne ubijte.« Druga pa je rekla: »Naj ne bo niti moj niti tvoj, temveč ga razdelite.«
27 Nígbà náà ni ọba dáhùn, ó wí pé, “Ẹ fi alààyè ọmọ fún obìnrin àkọ́kọ́. Ẹ má ṣe pa á: òun ni ìyá rẹ̀.”
Potem je kralj odgovoril in rekel: »Njej dajte živega otroka in ga nikakor ne ubijte. Ona je njegova mati.«
28 Nígbà tí gbogbo Israẹli gbọ́ ìdájọ́ tí ọba ṣe, wọ́n sì bẹ̀rù níwájú ọba, nítorí wọ́n ti rí í pé ó ní ọgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run láti ṣe ìdájọ́.
Ves Izrael je slišal o sodbi, ki jo je kralj razsodil in bali so se kralja, kajti videli so, da je bila v njem Božja modrost, da razsoja.