< 1 Kings 16 >

1 Ó sì ṣe, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jehu ọmọ Hanani wá sí Baaṣa pé,
La parole de Yahvé fut adressée à Jéhu, fils de Hanani, contre Baescha, en ces termes:
2 “Èmi ti gbé ọ ga láti inú erùpẹ̀ wá, mo sì fi ọ́ ṣe olórí Israẹli ènìyàn mi, ṣùgbọ́n ìwọ sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu, ó sì mú kí Israẹli ènìyàn mi dẹ́ṣẹ̀, láti mú mi bínú nípa ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
« Parce que je t'ai élevé de la poussière et que je t'ai établi chef de mon peuple d'Israël, et que tu as suivi la voie de Jéroboam et fait pécher mon peuple d'Israël, pour m'irriter par ses péchés,
3 Nítorí náà, èmi yóò mú Baaṣa àti ilé rẹ̀ kúrò, èmi yóò sì ṣe ilé rẹ̀ bí ilé Jeroboamu ọmọ Nebati.
voici, je vais exterminer Baescha et sa maison, et je rendrai ta maison semblable à la maison de Jéroboam, fils de Nebat.
4 Àwọn ajá yóò jẹ ẹni Baaṣa tí ó bá kú ní ìlú, ẹyẹ ojú ọ̀run yóò sì jẹ àwọn tí ó kú ní oko.”
Les chiens mangeront les descendants de Baasha qui mourront dans la ville; et celui qui mourra des siens dans les champs, les oiseaux du ciel le mangeront. »
5 Àti ìyókù ìṣe Baaṣa, ohun tí ó ṣe àti agbára rẹ̀, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Et le reste des actes de Baasha, et ce qu'il a fait, et sa puissance, cela n'est-il pas écrit dans le livre des chroniques des rois d'Israël?
6 Baaṣa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní Tirsa. Ela ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Baasha se coucha avec ses pères et fut enterré à Thirtsa; et Éla, son fils, régna à sa place.
7 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì wá nípa ọwọ́ Jehu wòlíì ọmọ Hanani pẹ̀lú sí Baaṣa àti ilé rẹ̀, nítorí gbogbo búburú tí ó ti ṣe níwájú Olúwa, ní mímú un bínú nípa ohun tó ti ṣe àti wíwà bí ilé Jeroboamu, àti nítorí tí ó pa á run pẹ̀lú.
La parole de l'Éternel fut adressée par le prophète Jéhu, fils de Hanani, contre Baescha et contre sa maison, à cause de tout le mal qu'il avait fait aux yeux de l'Éternel, pour l'irriter par l'ouvrage de ses mains, en étant semblable à la maison de Jéroboam, et parce qu'il l'avait frappé.
8 Ní ọdún kẹrìndínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Ela ọmọ Baaṣa bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ní Israẹli, ó sì jẹ ọba ní Tirsa ní ọdún méjì.
La vingt-sixième année d'Asa, roi de Juda, Éla, fils de Baescha, régna sur Israël à Thirtsa pendant deux ans.
9 Simri, ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, olórí ìdajì kẹ̀kẹ́ rẹ̀, dìtẹ̀ sí i. Ela sì wà ní Tirsa nígbà náà, ó sì mu àmupara ní ilé Arsa, ìríjú ilé rẹ̀ ni Tirsa.
Son serviteur Zimri, chef de la moitié de ses chars, conspira contre lui. Or il était à Thirtsa, s'enivrant dans la maison d'Arza, qui était à la tête de la maison à Thirtsa;
10 Simri sì wọlé, ó sì kọlù ú, ó sì pa á ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa, ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
et Zimri entra, le frappa et le tua, la vingt-septième année d'Asa, roi de Juda, et régna à sa place.
11 Bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba, bí ó sì ti jókòó lórí ìtẹ́, ó lu gbogbo ilé Baaṣa pa, kò ku ọkùnrin kan sílẹ̀, bóyá ìbátan tàbí ọ̀rẹ́.
Lorsqu'il commença à régner, dès qu'il fut assis sur son trône, il attaqua toute la maison de Baasha. Il ne lui laissa pas un seul de ceux qui urinent sur un mur parmi ses parents ou ses amis.
12 Bẹ́ẹ̀ ni Simri pa gbogbo ilé Baaṣa run, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ sí Baaṣa nípa ọwọ́ Jehu wòlíì:
Ainsi Zimri détruisit toute la maison de Baasha, selon la parole de l'Éternel qu'il avait prononcée contre Baasha par Jéhu, le prophète,
13 nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí Baaṣa àti Ela ọmọ rẹ̀ ti ṣẹ̀ àti tí wọ́n ti mú Israẹli ṣẹ̀, tí wọ́n fi mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú, wọ́n mú u bínú nípa òrìṣà asán wọn.
à cause de tous les péchés de Baasha et des péchés d'Éla, son fils, qu'ils avaient commis et par lesquels ils avaient fait pécher Israël, pour irriter par leurs vanités l'Éternel, le Dieu d'Israël.
14 Ìyókù ìṣe Ela àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Le reste des actes d'Éla, et tout ce qu'il a fait, n'est-il pas écrit dans le livre des chroniques des rois d'Israël?
15 Ní ọdún kẹtàdínlọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, ni Simri jẹ ọba ọjọ́ méje ní Tirsa. Àwọn ọmọ-ogun sì dó ti Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini.
La vingt-septième année d'Asa, roi de Juda, Zimri régna sept jours à Thirtsa. Or le peuple campait contre Gibbethon, qui appartenait aux Philistins.
16 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli tí ó dó tì gbọ́ wí pé Simri ti dìtẹ̀ sí ọba, ó sì ti pa á, wọ́n kéde Omri, olórí ogun, bí ọba lórí Israẹli ní ọjọ́ náà ní ibùdó.
Le peuple qui campait apprit que Zimri avait conspiré et qu'il avait aussi tué le roi. C'est pourquoi tout Israël établit Omri, chef de l'armée, roi d'Israël ce jour-là dans le camp.
17 Nígbà náà ni Omri àti gbogbo Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ kúrò ní Gibetoni, wọ́n sì dó ti Tirsa.
Omri monta de Gibbethon, et tout Israël avec lui, et ils assiégèrent Tirza.
18 Nígbà tí Simri sì ri pé a ti gba ìlú, ó sì wọ inú ààfin ilé ọba lọ, ó sì tẹ iná bọ ilé ọba lórí ara rẹ̀, ó sì kú,
Lorsque Zimri vit que la ville était prise, il entra dans la partie fortifiée de la maison du roi, brûla par le feu la maison du roi et mourut,
19 nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣẹ̀, ní ṣíṣe búburú níwájú Olúwa àti ní rírìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ tí ó ti ṣe àti tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.
à cause des péchés qu'il avait commis en faisant ce qui est mal aux yeux de l'Éternel, en marchant dans la voie de Jéroboam, et du péché qu'il avait commis pour faire pécher Israël.
20 Ní ti ìyókù ìṣe Simri, àti ọ̀tẹ̀ rẹ̀ tí ó dì, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Le reste des actes de Zimri, et la trahison qu'il a commise, ne sont-ils pas écrits dans le livre des Chroniques des rois d'Israël?
21 Nígbà náà ní àwọn ènìyàn Israẹli dá sí méjì; apá kan wọn ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn, láti fi í jẹ ọba, apá kan tókù sì ń tọ Omri lẹ́yìn.
Alors le peuple d'Israël se divisa en deux parties: la moitié du peuple suivit Tibni, fils de Ginath, pour le faire roi, et l'autre moitié suivit Omri.
22 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn tí ń tọ Omri lẹ́yìn borí àwọn tí ń tọ Tibni ọmọ Ginati lẹ́yìn. Bẹ́ẹ̀ ni Tibni kú, Omri sì jẹ ọba.
Mais le peuple qui suivait Omri l'emporta sur le peuple qui suivait Tibni, fils de Ginath; Tibni mourut donc, et Omri régna.
23 Ní ọdún kọkànlélọ́gbọ̀n Asa ọba Juda, Omri bẹ̀rẹ̀ sí ń jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì jẹ ọba ní ọdún méjìlá, ọdún mẹ́fà ní Tirsa.
La trente et unième année d'Asa, roi de Juda, Omri régna sur Israël pendant douze ans. Il régna six ans à Thirtsa.
24 Ó sì ra òkè Samaria lọ́wọ́ Ṣemeri ní tálẹ́ǹtì méjì fàdákà, ó sì kọ́ ìlú sórí rẹ̀, ó sì pe ìlú náà ní Samaria, nípa orúkọ Ṣemeri, orúkọ ẹni tí ó kọ́kọ́ ni òkè náà.
Il acheta la colline de Samarie à Shemer pour deux talents d'argent; il bâtit sur la colline et donna à la ville qu'il bâtit le nom de Samarie, du nom de Shemer, propriétaire de la colline.
25 Ṣùgbọ́n Omri sì ṣe búburú níwájú Olúwa, Ó sì ṣe búburú ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
Omri fit ce qui est mal aux yeux de l'Éternel, et il se montra méchant envers tous ceux qui étaient avant lui.
26 Ó rìn ní gbogbo ọ̀nà Jeroboamu ọmọ Nebati àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀, láti fi ohun asán wọn mú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli bínú.
Car il marcha dans toute la voie de Jéroboam, fils de Nebath, et dans les péchés par lesquels il avait fait pécher Israël, pour irriter Yahvé, le Dieu d'Israël, par leurs vanités.
27 Ìyókù ìṣe àti ohun tí Omri ṣe, àti agbára rẹ tí ó fihàn, a kò ha kọ, wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Le reste des actes d'Omri, ce qu'il a fait, et la puissance qu'il a déployée, cela n'est-il pas écrit dans le livre des Chroniques des rois d'Israël?
28 Omri sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ a sì sin ín ní Samaria. Ahabu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Omri se coucha avec ses pères et fut enterré à Samarie, et Achab, son fils, régna à sa place.
29 Ní ọdún kejìdínlógójì Asa ọba Juda, Ahabu ọmọ Omri jẹ ọba ní Israẹli, o si jẹ ọba lórí Israẹli ní Samaria ní ọdún méjìlélógún.
La trente-huitième année d'Asa, roi de Juda, Achab, fils d'Omri, commença à régner sur Israël. Achab, fils d'Omri, régna sur Israël à Samarie pendant vingt-deux ans.
30 Ahabu ọmọ Omri sì ṣe búburú ní ojú Olúwa ju gbogbo àwọn tí ó wà ṣáájú rẹ̀ lọ.
Achab, fils d'Omri, fit ce qui est mal aux yeux de Yahvé, plus que tous ceux qui l'ont précédé.
31 Ó sì ṣe bí ẹni pé ó ṣe ohun kékeré fún un láti máa rìn nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, ó sì mú Jesebeli, ọmọbìnrin Etibaali, ọba àwọn ará Sidoni ní aya, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ń sin Baali, ó sì bọ ọ́.
Comme si c'était une chose légère pour lui de marcher dans les péchés de Jéroboam, fils de Nebat, il prit pour femme Jézabel, fille d'Ethbaal, roi des Sidoniens, et il alla servir Baal et se prosterner devant lui.
32 Ó sì tẹ́ pẹpẹ kan fún Baali nínú ilé Baali tí ó kọ́ sí Samaria.
Il éleva un autel à Baal dans la maison de Baal qu'il avait bâtie à Samarie.
33 Ahabu sì túnṣe ère òrìṣà Aṣerah, ó sì ṣe púpọ̀ láti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú ju èyí tí gbogbo ọba Israẹli tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀ ti ṣe lọ.
Achab fit l'Astre. Et Achab fit encore plus pour irriter Yahvé, le Dieu d'Israël, que tous les rois d'Israël qui l'ont précédé.
34 Ní ìgbà ayé Ahabu, Hieli ará Beteli kọ́ Jeriko. Ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀ ní Abiramu, àkọ́bí rẹ, ó sì gbé àwọn ìlẹ̀kùn ibodè rẹ̀ kọ́ ní Segubu àbíkẹ́yìn rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó ti ipa Joṣua ọmọ Nuni sọ.
De son temps, Hiel, le Béthélite, bâtit Jéricho. Il en posa les fondations avec la perte d'Abiram, son premier-né, et en dressa les portes avec la perte de Segub, son plus jeune fils, selon la parole de Yahvé, qu'il avait prononcée par Josué, fils de Nun.

< 1 Kings 16 >