< 1 Kings 15 >

1 Ní ọdún kejìdínlógún ìjọba Jeroboamu ọmọ Nebati, Abijah jẹ ọba lórí Juda,
Mwaka wa ikũmi na ĩnana wa ũthamaki wa Jeroboamu mũrũ wa Nebati-rĩ, nĩguo Abija aatuĩkire mũthamaki wa Juda,
2 ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́ta ní Jerusalẹmu. Orúkọ ìyá rẹ̀ sì ni Maaka, ọmọbìnrin Absalomu.
na agĩthamaka arĩ Jerusalemu mĩaka ĩtatũ. Nyina eetagwo Maaka mwarĩ wa Abisalomu.
3 Ó sì rìn nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí baba rẹ̀ ti dá ṣáájú rẹ̀; ọkàn rẹ̀ kò sì pé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọkàn Dafidi baba ńlá rẹ̀ ti ṣe.
Nĩekire mehia marĩa mothe ithe eekĩte mbere yake; ndeyamũrĩire Jehova Ngai wake na ngoro yake yothe, ta ũrĩa ngoro ya ithe Daudi yatariĩ.
4 Ṣùgbọ́n, nítorí i Dafidi Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ fún un ní ìmọ́lẹ̀ kan ní Jerusalẹmu nípa gbígbé ọmọ rẹ̀ ró láti jẹ ọba ní ipò rẹ̀ àti láti fi ìdí Jerusalẹmu múlẹ̀.
No rĩrĩ, nĩ ũndũ wa Daudi, Jehova Ngai wake akĩmũhe tawa kũu Jerusalemu na ũndũ wa gũtua mũriũ mũthamaki ithenya rĩake, na gũtũma itũũra rĩa Jerusalemu rĩrũme.
5 Nítorí tí Dafidi ṣe èyí tí ó dára ní ojú Olúwa, tí kò sì kùnà láti pa gbogbo èyí tí Olúwa pàṣẹ fún un mọ́ ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo; bí kò ṣe ní kìkì ọ̀ràn Uriah ará Hiti.
Nĩgũkorwo Daudi nĩekĩte ũrĩa kwagĩrĩire maitho-inĩ ma Jehova, na ndaagire kũrũmia watho o na ũmwe wa Jehova matukũ-inĩ mothe ma muoyo wake, tiga ũhoro-inĩ wa Uria ũrĩa Mũhiti.
6 Ogun sì wà láàrín Rehoboamu àti Jeroboamu ní gbogbo ọjọ́ ayé Abijah.
Na rĩrĩ, gwatũũraga mbaara gatagatĩ ka Rehoboamu na Jeroboamu hĩndĩ ĩrĩa yothe Abija aarĩ muoyo.
7 Ní ti ìyókù ìṣe Abijah, àti gbogbo èyí tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? Ogun sì wà láàrín Abijah àti Jeroboamu.
Maũndũ marĩa mangĩ makoniĩ wathani wa Abija na ũrĩa wothe eekire-rĩ, githĩ matiandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa maũndũ ma athamaki a Juda? Na nĩ kwarĩ mbaara gatagatĩ ka Abija na Jeroboamu.
8 Abijah sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi. Asa ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Nake Abija akĩhurũka hamwe na maithe make, na agĩthikwo thĩinĩ wa itũũra inene rĩa Daudi. Nake mũriũ Asa agĩtuĩka mũthamaki ithenya rĩake.
9 Ní ogún ọdún Jeroboamu ọba Israẹli, Asa jẹ ọba lórí Juda,
Mwaka wa mĩrongo ĩĩrĩ wa ũthamaki wa Jeroboamu mũthamaki wa Isiraeli-rĩ, nĩguo Asa aatuĩkire mũthamaki wa Juda,
10 Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu ní ọdún mọ́kànlélógójì. Orúkọ ìyá ńlá rẹ̀ sì ni Maaka, ọmọbìnrin Absalomu.
nake agĩthamaka arĩ Jerusalemu mĩaka mĩrongo ĩna na ũmwe. Cũwe wake eetagwo Maaka mwarĩ wa Abisalomu.
11 Asa sì ṣe èyí tí ó dára lójú Olúwa, bí Dafidi baba rẹ̀ ti ṣe.
Asa nĩekire ũrĩa kwagĩrĩire maitho-inĩ ma Jehova, o ta ũrĩa ithe Daudi eekĩte.
12 Ó sì mú àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà kúrò ní ilẹ̀ náà, ó sì kó gbogbo ère tí àwọn baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
Nĩaingatire maraya ma arũme ma mahooero-inĩ moime bũrũri ũcio, na akĩeheria mĩhianano yothe ya kũhooyagwo ĩrĩa maithe make maathondekete.
13 Ó sì mú Maaka ìyá ńlá rẹ̀ kúrò láti máa ṣe ayaba, nítorí tí ó yá ère kan fún Aṣerah òrìṣà rẹ̀. Asa sì ké ère náà lulẹ̀, ó sì jó o ní àfonífojì Kidironi.
O na nĩeheririe cũwe wake Maaka atige gũtuĩka mũthamaki-mũndũ-wa-nja, tondũ nĩathondekete gĩtugĩ kĩa Ashera, kĩndũ kĩrĩ magigi mũno. Asa agĩkĩmomora, agĩgĩcinĩra kĩanda-inĩ gĩa Kidironi.
14 Ṣùgbọ́n kò mú àwọn ibi gíga kúrò, síbẹ̀ ọkàn Asa pé pẹ̀lú Olúwa ní ọjọ́ ayé rẹ̀ gbogbo.
O na gũtuĩka ndaathengirie mahooero marĩa maarĩ kũndũ gũtũũgĩru-rĩ, ngoro ya Asa nĩyerutĩire Jehova mũtũũrĩre-inĩ wake wothe.
15 Ó sì mú wúrà àti fàdákà àti àwọn ohun èlò tí òun àti baba rẹ̀ ti yà sí mímọ́ wọ ilé Olúwa.
Nĩarehire kũu hekarũ ya Jehova betha, na thahabu, na indo iria ciothe we mwene hamwe na ithe maamũrĩte.
16 Ogun sì wà láàrín Asa àti Baaṣa ọba Israẹli ní gbogbo ọjọ́ ayé wọn.
Gwatũire mbaara gatagatĩ ka Asa na Baasha mũthamaki wa Isiraeli, hĩndĩ yothe ya wathani wao.
17 Baaṣa, ọba Israẹli sì gòkè lọ sí Juda, ó sì kọ́ Rama láti má jẹ́ kí ẹnikẹ́ni jáde tàbí wọlé tọ Asa ọba lọ.
Baasha mũthamaki wa Isiraeli nĩambatire agĩũkĩrĩra Juda na agĩaka rũthingo rwa hinya kũu Rama, nĩgeetha agirĩrĩrie andũ matikoime kana matoonye bũrũri wa Asa mũthamaki wa Juda.
18 Nígbà náà ni Asa mú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ó kù nínú ìṣúra ilé Olúwa àti ìṣúra ilé ọba. Ó sì fi lé àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́, ó sì rán wọn lọ sí ọ̀dọ̀ Beni-Hadadi ọmọ Tabrimoni, ọmọ Hesioni ọba Siria tí ó ń gbé ní Damasku.
Ningĩ Asa akĩruta betha na thahabu ciothe iria ciatigarĩte kĩgĩĩna-inĩ kĩa hekarũ ya Jehova na kĩa nyũmba yake ya ũthamaki. Nake agĩciĩhokera anene ake macitwarĩre Beni-Hadadi mũrũ wa Taburimoni, mũrũ wa Hezioni, mũthamaki wa Suriata, ũrĩa waathanaga Dameski.
19 Ó sì wí pé, “Jẹ́ kí májẹ̀mú kí ó wà láàrín èmi àti ìwọ, bí ó sì ti wà láàrín baba mi àti baba rẹ. Wò ó, Èmi rán ọrẹ fàdákà àti wúrà sí ọ. Ǹjẹ́ nísinsin yìí, da májẹ̀mú rẹ pẹ̀lú Baaṣa, ọba Israẹli, kí ó lè lọ kúrò lọ́dọ̀ mi.”
Nake akĩmwĩra atĩrĩ, “Reke hakorwo harĩ na kĩrĩĩko giitũ nawe, o ta ũrĩa haarĩ kĩrĩĩko gatagatĩ ka baba na thoguo. Ta kĩone, kĩheo kĩa betha na thahabu nĩkĩo ndagũtũmĩra. Rĩu tharia kĩrĩĩko kĩanyu na Baasha mũthamaki wa Isiraeli nĩguo atigane na niĩ.”
20 Beni-Hadadi gba ti Asa ọba, ó sì rán àwọn alágbára olórí ogun rẹ̀ sí àwọn ìlú Israẹli. Ó sì ṣẹ́gun Ijoni, Dani àti Abeli-Beti-Maaka, àti gbogbo Kinnereti pẹ̀lú gbogbo ilẹ̀ Naftali.
Beni-Hadadi agĩĩtĩkĩra ũhoro wa Mũthamaki Asa, agĩtũma anene a ikundi cia thigari ciake makahũũre matũũra ma Isiraeli. Nake agĩtooria Ijoni, na Dani, na Abeli-Bethi-Maaka, na Kinerethu guothe, hamwe na Nafitali.
21 Nígbà tí Baaṣa sì gbọ́ èyí, ó sì ṣíwọ́ kíkọ́ Rama, ó sì lọ kúrò sí Tirsa.
Hĩndĩ ĩrĩa Baasha aiguire ũhoro ũcio, agĩtiga gwaka Rama, agĩthiĩ gũikara Tiriza.
22 Nígbà náà ni Asa ọba kéde ká gbogbo Juda, kò dá ẹnìkan sí, wọ́n sì kó òkúta Rama kúrò àti igi rẹ̀, tí Baaṣa fi kọ́lé. Asa ọba sì fi wọ́n kọ́ Geba ti Benjamini àti Mispa.
Ningĩ Mũthamaki Asa akĩruta watho kũu Juda guothe, gũtirĩ mũndũ watigĩrĩirwo, nao magĩkuua mahiga na mbaũ iria Baasha aahũthagĩra Rama. Indo icio nĩcio Mũthamaki Asa aakire nacio Geba kũu Benjamini, o na agĩaka kũu Mizipa.
23 Ní ti ìyókù gbogbo ìṣe Asa, àti gbogbo agbára rẹ̀, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, àti àwọn ìlú tí ó kọ́, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda? Ṣùgbọ́n, ní ìgbà ogbó rẹ̀, ààrùn ṣe é ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
Ha ũhoro wa maũndũ marĩa mangĩ mothe makoniĩ wathani wa Asa, marĩa mothe aahingirie, na ũrĩa wothe eekire, o na matũũra marĩa aakire-rĩ, githĩ matiandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa maũndũ ma athamaki a Juda? Na rĩrĩ, Asa aakũra akĩrwara magũrũ.
24 Asa sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi baba rẹ̀. Jehoṣafati ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Hĩndĩ ĩyo Asa akĩhurũka hamwe na maithe make, agĩthikwo hamwe nao thĩinĩ wa itũũra inene rĩa ithe Daudi. Nake mũriũ Jehoshafatu agĩtuĩka mũthamaki ithenya rĩake.
25 Nadabu ọmọ Jeroboamu sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún kejì Asa ọba Juda, ó sì jẹ ọba lórí Israẹli ní ọdún méjì.
Nadabu mũrũ wa Jeroboamu aatuĩkire mũthamaki wa Isiraeli mwaka wa keerĩ wa Asa mũthamaki wa Juda, nake agĩthamakĩra Isiraeli mĩaka ĩĩrĩ.
26 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà baba rẹ̀ àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó mú Israẹli dá.
Nĩekire maũndũ ma waganu maitho-inĩ ma Jehova, akĩrũmĩrĩra mĩthiĩre ya ithe na mehia make marĩa maatũmire andũ a Isiraeli meehie.
27 Baaṣa ọmọ Ahijah ti ilé Isakari sì dìtẹ̀ sí i, Baaṣa sì kọlù ú ní Gibetoni, ìlú àwọn ará Filistini, nígbà tí Nadabu àti gbogbo Israẹli dó ti Gibetoni.
Baasha mũrũ wa Ahija wa nyũmba ya Isakaru nĩaciirĩire kũmũũkĩrĩra, nake akĩmũũragĩra kũu Gibethoni, itũũra rĩa Afilisti, rĩrĩa Nadabu na Isiraeli othe marĩrigiicĩirie.
28 Baaṣa sì pa Nadabu ní ọdún kẹta Asa ọba Juda, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
Baasha ooragire Nadabu mwaka wa gatatũ wa Asa mũthamaki wa Juda na agĩtuĩka mũthamaki ithenya rĩake.
29 Ó sì ṣe, bí ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba ó pa gbogbo ilé Jeroboamu, kò sì ku ẹnìkan tí ń mí fún Jeroboamu, ṣùgbọ́n ó run gbogbo wọn, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa, tí ó sọ nípa ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ Ahijah ará Ṣilo.
Aambĩrĩria gũthamaka-rĩ, nĩooragire andũ a nyũmba ya Jeroboamu othe. Ndaatigĩirie Jeroboamu mũndũ o na ũmwe arĩ muoyo, no aamaniinire othe, kũringana na kiugo kĩa Jehova kĩrĩa aaririe na kanua ka ndungata yake Ahija ũrĩa Mũshiloni,
30 Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí Jeroboamu ti ṣẹ̀ àti tí ó mú Israẹli ṣẹ̀, àti nítorí tí ó ti mú Olúwa Ọlọ́run Israẹli bínú.
nĩ ũndũ wa mehia marĩa Jeroboamu ekĩte na agĩtũma Isiraeli mehie, na nĩ ũndũ nĩarakarĩtie Jehova, Ngai wa Isiraeli.
31 Ní ti ìyókù ìṣe Nadabu àti gbogbo ohun tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Israẹli?
Ha ũhoro wa maũndũ marĩa mangĩ makoniĩ wathani wa Nadabu, na marĩa mothe eekire-rĩ, githĩ matiandĩkĩtwo ibuku-inĩ rĩa maũndũ ma athamaki a Isiraeli?
32 Ogun sì wà láàrín Asa àti Baaṣa ọba Israẹli ní gbogbo ọjọ́ wọn.
Gwatũire mbaara gatagatĩ ka Asa na Baasha mũthamaki wa Isiraeli hĩndĩ yothe ya wathani wao.
33 Ní ọdún kẹta Asa ọba Juda, Baaṣa ọmọ Ahijah sì jẹ ọba lórí gbogbo Israẹli ní Tirsa, ó sì jẹ ọba ní ọdún mẹ́rìnlélógún.
Mwaka wa gatatũ wa Asa, mũthamaki wa Juda-rĩ, nĩguo Baasha mũrũ wa Ahija aatuĩkire mũthamaki wa Isiraeli guothe arĩ kũu Tiriza, na agĩthamaka mĩaka mĩrongo ĩĩrĩ na ĩna.
34 Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ó sì rìn ní ọ̀nà Jeroboamu àti nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èyí tí ó ti mú Israẹli ṣẹ̀.
Nĩekire maũndũ ma waganu maitho-ini ma Jehova, akĩrũmĩrĩra mĩthiĩre ya Jeroboamu, na mehia make marĩa maatũmire andũ a Isiraeli meehie.

< 1 Kings 15 >