< 1 Chronicles 14 >

1 Nísinsin yìí Hiramu àti ọba Tire rán oníṣẹ́ sí Dafidi, àti pẹ̀lú igi kedari pẹ̀lú àwọn ọ̀mọ̀lé àti gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ààfin fún un.
Na ka tonoa etahi karere e Hirama kingi o Taira ki a Rawiri, me etahi rakau, he hita, me nga kaimahi kohatu, me nga kaimahi rakau, hei hanga whare mona.
2 Dafidi sì mọ Israẹli àti pé Olúwa ti fi òun ṣe ọba lórí Israẹli àti pé ìjọba rẹ̀ ga jùlọ nítorí ti àwọn ènìyàn rẹ̀.
Na ka mohio a Rawiri kua whakapumautia ia e Ihowa hei kingi mo Iharaira; kua whakanuia hoki tona rangatiratanga, he whakaaro ki tana iwi, ki a Iharaira.
3 Ní Jerusalẹmu Dafidi mú ọ̀pọ̀ ìyàwó ó sì di baba àwọn ọmọ ọkùnrin púpọ̀ àti ọmọbìnrin.
Na ka tangohia ano e Rawiri he wahine mana ki Hiruharama; a ka whanau ano etahi atu tama, etahi atu tamahine ma Rawiri.
4 Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ náà tí wọ́n bí fún un níbẹ̀: Ṣammua, Ṣobabu, Natani, Solomoni,
A ko nga ingoa enei o ana i whanau ki Hiruharama; ko Hamua, ko Hopapa, ko Natana, ko Horomona;
5 Ibhari, Eliṣua, Elifeleti,
Ko Ipihara, ko Erihua, ko Ereparete;
6 Noga, Nefegi, Jafia,
Ko Noka, ko Nepeke, ko Iapia;
7 Eliṣama, Beeliada, àti Elifeleti.
Ko Erihama, ko Peeriara, ko Eriparete.
8 Nígbà tí àwọn ará Filistini gbọ́ pé a ti fi àmì òróró yàn Dafidi ní ọba lórí gbogbo Israẹli, wọ́n sì lọ sókè pẹ̀lú ipá láti wá a rí, ṣùgbọ́n Dafidi gbọ́ nípa rẹ̀ ó sì jáde lọ láti pàdé wọn.
A, no te rongonga o nga Pirihitini kua oti a Rawiri te whakawahi hei kingi mo Iharaira katoa, ka haere nga Pirihitini katoa ki te rapu i a Rawiri. A ka rongo a Rawiri, a ka puta ia ki te tu i a ratou.
9 Nísinsin yìí àwọn ará Filistini ti wá láti gbógun ti àfonífojì Refaimu;
Na, tera nga Pirihitini kua haere mai, a kua takahi i te raorao o Repaima.
10 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run wí pé, “Kí èmi kí ó gòkè tọ àwọn ará Filistini lọ bí? Ìwọ ó ha fi wọ́n lé mi lọ́wọ́?” Olúwa sì wí fún un pé, “Gòkè lọ èmi ó sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́.”
Na ka ui a Rawiri ki te Atua, ka mea, Me haere ranei ahau ki nga Pirihitini? E homai ranei ratou e koe ki toku ringa? Na ka mea a Ihowa ki a ia, Haere; ka hoatu hoki ratou e ahau ki tou ringa.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gòkè lọ sí Baali-Perasimu, níbẹ̀ ó sì kọlù wọ́n. Ó sí wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí omi tí ya jáde, Ọlọ́run ti ya Dafidi lórí àwọn ọ̀tá mi pẹ̀lú ọwọ́ mi.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń pè ibẹ̀ ní Baali-Perasimu.
Heoi kua tae mai ratou ki Paaraperatimi; patua iho ratou i reira e Rawiri. Na ka mea a Rawiri, Pakaru ana i te Atua oku hoariri, he mea na toku ringa; koia ano kei te pakaruhanga wai. Na reira i huaina ai te ingoa o taua wahi ko Paaraperatimi.
12 Àwọn ará Filistini sì ti fi àwọn òrìṣà wọn sílẹ̀ níbẹ̀. Dafidi sì pa á láṣẹ láti jó wọn nínú iná.
A mahue ana i a ratou o ratou atua ki reira; na ka whakahau a Rawiri, a tahuna ana ki te ahi.
13 Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn ará Filistini gbógun wọ́n sì fọ́nká àfonífojì,
Na ka takahia ano e nga Pirihitini te raorao.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì tún béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, Ọlọ́run sì dalóhùn pé, “Má ṣe gòkè tààrà, ṣùgbọ́n ẹ yí wọn ká, kí ẹ sì mú wọn níwájú igi muliberi.
A ka ui ano a Rawiri ki te Atua, a ka mea te Atua ki a ia, Kaua e haere ki te wahi i a ratou: me tahuri i a ratou, ka awhio haere ki a ratou, ka whakaeke i a ratou i te ritenga o nga maperi.
15 Tí ó bá sì ṣe, tí ẹ̀yin bá ti gbọ́ ìró ẹsẹ̀ ní orí òkè igi muliberi, ẹ jáde fún ogun, nítorí èyí yóò fihàn pé Ọlọ́run ti jáde níwájú rẹ láti kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini.”
A, ka rangona e koe te tapuwae haruru i runga i nga maperi, ko reira koe puta ai ki te whawhai; no te mea kua riro te Atua ki mua i a koe ki te patu i te ope o nga Pirihitini.
16 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ṣe ohun tí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún wọn, wọ́n sì kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini láti gbogbo ọ̀nà Gibeoni lọ sí Geseri.
Na peratia ana e Rawiri me ta te Atua i whakahau ai ki a ia; a patua iho e ratou te ope o nga Pirihitini i Kipeono, a tae noa ki Katere.
17 Bẹ́ẹ̀ ni òkìkí Dafidi tàn ká gbogbo ilẹ̀ káàkiri, Olúwa sì mú kí gbogbo orílẹ̀-èdè bẹ̀rù rẹ̀.
Na kua paku te ingoa o Rawiri ki nga whenua katoa; a ka mea a Ihowa i te wehi ki a ia kia pa ki nga iwi katoa.

< 1 Chronicles 14 >