< 1 Chronicles 14 >

1 Nísinsin yìí Hiramu àti ọba Tire rán oníṣẹ́ sí Dafidi, àti pẹ̀lú igi kedari pẹ̀lú àwọn ọ̀mọ̀lé àti gbẹ́nàgbẹ́nà láti kọ́ ààfin fún un.
Hiram, roi de Tyr, envoya aussi des messagers à David, et des bois de cèdre, et des maçons, et des charpentiers, pour lui bâtir une maison.
2 Dafidi sì mọ Israẹli àti pé Olúwa ti fi òun ṣe ọba lórí Israẹli àti pé ìjọba rẹ̀ ga jùlọ nítorí ti àwọn ènìyàn rẹ̀.
Et David reconnut que le Seigneur l’avait confirmé roi sur Israël, et qu’il avait élevé son royaume sur son peuple Israël.
3 Ní Jerusalẹmu Dafidi mú ọ̀pọ̀ ìyàwó ó sì di baba àwọn ọmọ ọkùnrin púpọ̀ àti ọmọbìnrin.
Il prit encore d’autres femmes à Jérusalem, et il engendra des fils et des filles.
4 Èyí ni orúkọ àwọn ọmọ náà tí wọ́n bí fún un níbẹ̀: Ṣammua, Ṣobabu, Natani, Solomoni,
Or voici les noms de ceux qui lui naquirent à Jérusalem: Samua et Sobad, Nathan et Salomon,
5 Ibhari, Eliṣua, Elifeleti,
Jébahar, Elisua, et Eliphalet,
6 Noga, Nefegi, Jafia,
Noga aussi, et Napheg et Japhia,
7 Eliṣama, Beeliada, àti Elifeleti.
Elisama, Baaliada et Eliphalet.
8 Nígbà tí àwọn ará Filistini gbọ́ pé a ti fi àmì òróró yàn Dafidi ní ọba lórí gbogbo Israẹli, wọ́n sì lọ sókè pẹ̀lú ipá láti wá a rí, ṣùgbọ́n Dafidi gbọ́ nípa rẹ̀ ó sì jáde lọ láti pàdé wọn.
Or les Philistins, apprenant que David avait été oint comme roi sur tout Israël, montèrent tous pour le chercher: ce qu’ayant appris David, il sortit au-devant d’eux.
9 Nísinsin yìí àwọn ará Filistini ti wá láti gbógun ti àfonífojì Refaimu;
Cependant les Philistins, venant, se répandirent dans la vallée de Raphaïm.
10 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run wí pé, “Kí èmi kí ó gòkè tọ àwọn ará Filistini lọ bí? Ìwọ ó ha fi wọ́n lé mi lọ́wọ́?” Olúwa sì wí fún un pé, “Gòkè lọ èmi ó sì fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́.”
Alors David consulta le Seigneur, disant: Monterai-je contre les Philistins, et les livrerez-vous en ma main? Et le Seigneur lui répondit: Monte, et je les livrerai en ta main.
11 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ gòkè lọ sí Baali-Perasimu, níbẹ̀ ó sì kọlù wọ́n. Ó sí wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí omi tí ya jáde, Ọlọ́run ti ya Dafidi lórí àwọn ọ̀tá mi pẹ̀lú ọwọ́ mi.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń pè ibẹ̀ ní Baali-Perasimu.
Lors donc que ceux-ci eurent monté à Baalpharasim, David les battit là, et dit: Le Seigneur a dispersé mes ennemis par ma main, comme les eaux se dispersent: et c’est pourquoi ce lieu fut appelé Baalpharasim.
12 Àwọn ará Filistini sì ti fi àwọn òrìṣà wọn sílẹ̀ níbẹ̀. Dafidi sì pa á láṣẹ láti jó wọn nínú iná.
Et les Philistins laissèrent là leurs dieux, et David commanda qu’ils fussent brûlés.
13 Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn ará Filistini gbógun wọ́n sì fọ́nká àfonífojì,
Les Philistins firent encore une autre fois irruption, et se répandirent dans la vallée.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì tún béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run, Ọlọ́run sì dalóhùn pé, “Má ṣe gòkè tààrà, ṣùgbọ́n ẹ yí wọn ká, kí ẹ sì mú wọn níwájú igi muliberi.
Et David consulta Dieu de nouveau; et Dieu lui dit: Ne monte pas après eux, mais éloigne-toi d’eux; et tu viendras contre eux, vis-à-vis des poiriers.
15 Tí ó bá sì ṣe, tí ẹ̀yin bá ti gbọ́ ìró ẹsẹ̀ ní orí òkè igi muliberi, ẹ jáde fún ogun, nítorí èyí yóò fihàn pé Ọlọ́run ti jáde níwájú rẹ láti kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini.”
Et lorsque tu entendras le bruit de quelqu’un qui marche au haut des poiriers, alors tu sortiras pour la bataille; car Dieu sortira devant toi pour battre le camp des Philistins.
16 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi ṣe ohun tí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún wọn, wọ́n sì kọlu àwọn ọmọ-ogun Filistini láti gbogbo ọ̀nà Gibeoni lọ sí Geseri.
David fit donc comme Dieu lui avait ordonné; et il battit le camp des Philistins, depuis Gabaon jusqu’à Gazer.
17 Bẹ́ẹ̀ ni òkìkí Dafidi tàn ká gbogbo ilẹ̀ káàkiri, Olúwa sì mú kí gbogbo orílẹ̀-èdè bẹ̀rù rẹ̀.
Ainsi le nom de David se répandit dans toutes les contrées, et le Seigneur inspira la terreur de ce prince à toutes les nations.

< 1 Chronicles 14 >