< Luuka 13 >

1 ku nsiki ughuo, kulyale na vaanhu vamonga valyampelile imhola savaGalatia vano u Pilato alyavabudile na kuhasing'ani a ni danda sa vanave.
Àwọn kan sì wá ní àkókò náà tí ó sọ ti àwọn ará Galili fún un, ẹ̀jẹ̀ ẹni tí Pilatu dàpọ̀ mọ́ ẹbọ wọn.
2 uYesu akavamula akavavula, “pe musagha kuuti avagalilaya avuo valyale ni sambi kukila avagalilaya avange voni fyenambe ghavaghile amavivi aghuo?
Jesu sì dáhùn ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin ṣe bí àwọn ará Galili wọ̀nyí ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ ju gbogbo àwọn ará Galili lọ, nítorí wọ́n jẹ irú ìyà bá-wọ̀n-ọn-nì?
3 Nambe, nikuvavula neke nave namulata najumue mulibudua vule vule.
Mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin pẹ̀lú ronúpìwàdà, gbogbo yín ni yóò ṣègbé bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.
4 nambe avaanhu vala kijigho nu ntanda ku Siloamu vanoghukaghua na kuvabuda, musagha aveene valyale vanya sambi kukila avaanhu avange ku Yelusalemu?
Tàbí àwọn méjìdínlógún, tí ilé ìṣọ́ ní Siloamu wó lù, tí ó sì pa wọ́n, ẹ̀yin ṣe bí wọ́n ṣe ẹlẹ́ṣẹ̀ ju gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ ní Jerusalẹmu lọ?
5 Nambe, une niti, neke nave namulata najumue mweni mufua.
Mo wí fún yín, bí kò ṣe pé ẹ̀yin ronúpìwàdà, gbogbo yín ni yóò ṣègbé bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́.”
6 uYesu akavavula ikihwani iki,” umuunhu jumonga layale nu mpiki ghuvyalilue mu mughunda ghwa mwene, akaluta kulonda imheeke mu mpiki ghula neke nakaghaghile.
Ó sì pa òwe yìí fún wọn pé, “Ọkùnrin kan ní igi ọ̀pọ̀tọ́ kan tí a gbìn sí ọgbà àjàrà rẹ̀; ó sì dé, ó ń wá èso lórí rẹ̀, kò sì rí nǹkan.
7 akam'bula juno ilolelela umughunda ghula, “lola mu maka ghatatu nisile na kughela kulonda imheeke mumpiki ughu neke nanipatile. udumule ulwakuva ghunangania ilihanga.
Ó sì wí fún olùṣọ́gbà rẹ̀ pé, ‘Sá à wò ó, láti ọdún mẹ́ta ni èmi ti ń wá í wo èso lórí igi ọ̀pọ̀tọ́ yìí, èmi kò sì rí nǹkan: ké e lulẹ̀; èéṣe tí ó fi ń gbilẹ̀ lásán pẹ̀lú?’
8 juno ilolelela umughunda akati, “ughuleke umwaka ughu neke nipile na kukuvikila imbolela.
“Ó sì dáhùn ó wí fún un pé, ‘Olúwa, jọ̀wọ́ rẹ̀ ní ọdún yìí pẹ̀lú, títí èmi ó fi tu ilẹ̀ ìdí rẹ̀ yíká, títí èmi ó sì fi bu ìlẹ̀dú sí i.
9 nave ghihola imheeke umwaka ghuno ghukwisa ke kanono, neke nave naghuhola nikughudumula.
Bí ó bá sì so èso, o dara bẹ́ẹ̀: bí kò bá sì so, ǹjẹ́ lẹ́yìn èyí nì kí ìwọ kí ó ké e lulẹ̀.’”
10 lino uYesu alyale ivulanisia mu nyumba jimonga ija kufunyila unsiki ghwa Sabati.
Ó sì ń kọ́ni nínú Sinagọgu kan ní ọjọ́ ìsinmi.
11 lola, pwe alyale umukimama jumonga juno ku maka kijigho nu ntanda alyale ni lipepo ililamafu lwa vuvotevote, umwene alyale mughogholo naalyale iwesia kukwima na kugholoka.
Sì kíyèsi i, obìnrin kan wà níbẹ̀ tí ó ní ẹ̀mí àìlera, láti ọdún méjìdínlógún wá, ẹni tí ó tẹ̀ tán, tí kò le gbé ara rẹ̀ sókè bí ó ti wù kí ó ṣe.
12 uYesu ati amwaghile an'kemheela akam'bula, “mama uvikilue vwavuke kuhuma mu vuvotevote vwako.”
Nígbà tí Jesu rí i, ó pè é sí ọ̀dọ̀, ó sì wí fún un pé, “Obìnrin yìí, a tú ọ sílẹ̀ lọ́wọ́ àìlera rẹ.”
13 akavika amavoko ghake pa kyanya jake, pe um'bili ghwake ghukagholoka ghwope akamughinia uNguluve.
Ó sì fi ọwọ́ rẹ̀ lé e, Lójúkan náà a sì ti sọ ọ́ di títọ́, ó sì ń yin Ọlọ́run lógo.
14 neke um'baha ghwa nyumba jila ja kufunyila akakalala ulwakuva uYesu alya nsosisie ikighono kya Sabati. pe untavulua akamwamula akalivula ilipugha,”kuli ni fighono, fino luvaghile kuvoma imbombo. mwise kusosia himbe, nakwekuti kikighono kya sabati kyene.
Olórí Sinagọgu sì kún fún ìrunú, nítorí tí Jesu mú ni láradá ní ọjọ́ ìsinmi, ó sì wí fún ìjọ ènìyàn pé, ọjọ́ mẹ́fà ní ń bẹ tí a fi í ṣiṣẹ́, nínú wọn ni kí ẹ̀yin kí ó wá kí á ṣe dídá ara yín, kí ó má ṣe ní ọjọ́ ìsinmi.
15 uMutwa akamwamula akati, “vakitule! nakwale nambe juno kulyumue juno idindulila idogovi nambe ing'ombe jako kuhuma muluvagha na kukuvalongosia kuluta kunyua ikighono kya Sabati?
Nígbà náà ni Olúwa dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ẹ̀yin àgàbàgebè, olúkúlùkù yín kì í tú màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ kúrò ní ibùso, kì í sì í fà á lọ mu omi ní ọjọ́ ìsinmi.
16 pe lino umhinja ghwa Ibulahamu, juno uSetano an'dindile ku maka kijigho nu ntanda, pe nalukamunoghile umhinja jula kusosivua ikighono kya Sabati.
Kò sì yẹ kí a tú obìnrin yìí tí í ṣe ọmọbìnrin Abrahamu sílẹ̀ ní ìdè yìí ní ọjọ́ ìsinmi, ẹni tí Satani ti dè, sá à wò ó láti ọdún méjìdínlógún yìí wá?”
17 pano alyale ijova amasio aghuo, voni vala vano valyale vikumpinga vakavona soni, pe ilipugha ilikome lya vange vakalulutila vwimila sino sinoavombile.
Nígbà tí ó sì wí nǹkan wọ̀nyí, ojú ti gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀, gbogbo ìjọ ènìyàn sì yọ̀ fún ohun ìyanu gbogbo tí ó ṣe.
18 uYesu akati, “uvwimike vwa Nguluve vuhwanine ni kiki, kange niwesia kuling'anisia ni kiki?
Ó sì wí pé, “Kín ni ìjọba Ọlọ́run jọ? Kín ni èmi ó sì fiwé?
19 ji ghwene mbeju jino umuunhu atolile na kuluta kuvyala ku mughunda ghwake, jikalela na kuva mpiki n'kome, ni njuni sa kukyanya sikatenda ifivwasu fyave mu matafi ghake.
Ó dàbí hóró musitadi, tí ọkùnrin kan mú, tí ó sì sọ sínú ọgbà rẹ̀; tí ó sì hù, ó sì di igi ńlá; àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ń gbé orí ẹ̀ka rẹ̀.”
20 kange akati, “nivuling'anisie ni kiki uvwimike vwa Nguluve?
Ó sì tún wí pé, “Kín ni èmi ìbá fi ìjọba Ọlọ́run wé?
21 ki kwene kilule kino un'dala itola na kuhasing'ania jujuo ifipimilo fitatu fya vutine nambe kughumuka”
Ó dàbí ìwúkàrà, tí obìnrin kan mú, tí ó fi sínú òsùwọ̀n ìyẹ̀fun mẹ́ta, títí gbogbo rẹ̀ ó fi di wíwú.”
22 uYesu alyaghendile mu mapulo ni fikaaja kuluta ku Yelusalemu na kuvavulanisia.
Ó sì ń la àárín ìlú àti ìletò lọ, ó ń kọ́ni, ó sì ń rìn lọ sí Jerusalẹmu.
23 umuunhu jumonga akaposia akati, “Mutwa, ve vaanhu vadebe vano vilipokua”. pe lino akavavula akati,”
Ẹnìkan sì bi í pé, Olúwa, díẹ̀ ha kọ ni àwọn tí a ó gbàlà? Ó sì wí fún wọn pé,
24 mujilolelelaghe kukilila umulyango unsekele, ulwakuva vinga vighela na kukunua kukwingila.
“Ẹ làkàkà láti gba ojú ọ̀nà tóóró wọlé, nítorí mo wí fún yín, ènìyàn púpọ̀ ni yóò wá ọ̀nà láti wọ̀ ọ́, wọn kì yóò sì lè wọlé.
25 pambele unyanyumba ati imile na pidinda umulyango, pe mulikwima panji na kuhodesia na kuuti, Mutwa, Mutwa, tudindulile umwene ikuvamula na kwiti, 'nanivamanyile umue nambe kuno muhuma'
Nígbà tí baálé ilé bá dìde lẹ́ẹ̀kan fùú, tí ó bá sí ti ìlẹ̀kùn, ẹ̀yin ó sì bẹ̀rẹ̀ sí í dúró lóde, tí ẹ ó máa kan ìlẹ̀kùn, wí pé, ‘Olúwa, Olúwa, ṣí i fún wa!’ “Òun ó sì dáhùn wí fún yín pé, ‘Èmi kò mọ̀ ibi tí ẹ̀yin ti wá.’ Bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mọ̀ yín.
26 pe muliti, 'tukalile na pinyua pavulungolo pako nuve ukatuvulanisie mu fikaaja fitu'
“Nígbà náà ni ẹ̀yin ó bẹ̀rẹ̀ sí wí pé, ‘Àwa ti jẹ, àwa sì ti mu níwájú rẹ, ìwọ sì kọ́ni ní ìgboro ìlú wa.’
27 neke umwene ikivamula, nikuvavula nanivamanye kuno muhuma, vuka palyune umue mwe vavomba vuhosi.
“Òun ó sì wí pé, ‘Èmi wí fún yín èmi kò mọ̀ ibi tí ẹ̀yin ti wá; ẹ lọ kúrò lọ́dọ̀ mi gbogbo ẹ̀yin tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.’
28 kwe kuliva na kulila kisila vusililo unsiki ghuno mulikuvagha uAbulahamu, Isaka nu Yakovo na vavili voni ku vwimike vwa Nguluve, neke umue jumue mutaghilue kunji.
“Níbẹ̀ ni ẹkún àti ìpayínkeke yóò wà, nígbà tí ẹ̀yin ó rí Abrahamu, àti Isaaki, àti Jakọbu, àti gbogbo àwọn wòlíì, ní ìjọba Ọlọ́run, tí a ó sì ti ẹ̀yin sóde.
29 vikwisa kuhuma imbale sooni, nakupuma pa mesa ja kyakulia kya pakivwilile mu vutwa vwa Nguluve.
Wọn ó sì ti ilẹ̀ ìlà-oòrùn, àti ìwọ̀-oòrùn wá, àti láti àríwá, àti gúúsù wá, wọn ó sì jókòó ní ìjọba Ọlọ́run.
30 kagula ili kuuti, ughwa vusililo ghwe ghwa kwanda nu ghwawanda iiva ghwa vusililo”.
Sì wò ó, àwọn ẹni ẹ̀yìn ń bẹ tí yóò di ẹni iwájú, àwọn ẹni iwájú ń bẹ tí yóò di ẹni ẹ̀yìn.”
31 unsiki undebe pambele, avafalisayi vamonga valisile na kukum'bula kuuti, “luta na kuvuka apa ulwakuva uHelode ilonda kukubuda”.
Ní wákàtí kan náà, díẹ̀ nínú àwọn Farisi tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Jáde, kí ìwọ sì lọ kúrò níhìn-ín yìí: nítorí Herodu ń fẹ́ pa ọ́.”
32 uYesu akati, “mulute mukakivule ikikanu, kila, lola nikughadagha amapepo na kusosia umusyughu nu lyakilavo, ni kighono kya vutatu nitekelesia uvufumbue vwango.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ, kí ẹ̀yin sì sọ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ náà pé, ‘Kíyèsi i, èmi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, èmi ń ṣe ìmúláradá lónìí àti lọ́la, àti ní ọjọ́ mẹ́ta èmi ó ṣe àṣepé.’
33 ku lwolwoni lunoghile vwimila jango kughedelela umusyughu, ulwakilavo ni fighono fino fikwisa, ulwakuva najikwiting'ana kum'buda m'bili kutali ni Yelusalemu.
Ṣùgbọ́n èmi kò jẹ́ má rìn lónìí, àti lọ́la, àti ní ọ̀túnla: dájúdájú wòlíì kan ki yóò ṣègbé lẹ́yìn odi Jerusalẹmu.
34 Yelusalemu, Yelusalemu ghwe veni juno ikivabuda avavili na kukuvatova amavue vala vano vasung'ilue kulyumue. ke kalingi ninoghilue kuvakong'ania avaanha vinu ndavule ing'uku vule jikong'ania ifayana fyake mumbavatilo sake. neke ili namukalighanile.
“Jerusalẹmu, Jerusalẹmu, ìwọ tí o pa àwọn wòlíì, tí o sì sọ òkúta lu àwọn tí a rán sí ọ pa; nígbà mélòó ni èmi ń fẹ́ ràgà bo àwọn ọmọ rẹ, bí àgbébọ̀ adìyẹ ti í ràgà bo àwọn ọmọ rẹ̀ lábẹ́ apá rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́!
35 lola ujilekile inyumba jako. najune nukivavula, namungawesie kukunyagha nambe mungati, 'afunyilue ujuo juno ikwisa ku litavua lya mutwa”.
Sá wò ó, a fi ilé yín sílẹ̀ fún yín ní ahoro. Lóòtítọ́ ni mo sì wí fún yín, ẹ̀yin kì yóò sì rí mi títí yóò fi di àkókò tí ẹ̀yin ó wí pé, ‘Olùbùkún ni ẹni tí ó ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa.’”

< Luuka 13 >