< 1 Crónicas 13 >
1 Entonces David consultó con los capitanes de miles y los capitanes de cientos y con cada jefe.
Dafidi sì gbèrò pẹ̀lú olúkúlùkù àwọn ìjòyè rẹ̀, àwọn aláṣẹ ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn aláṣẹ ọgọ́rùn-ún
2 Y David dijo a todos los hombres de Israel que se habían reunido allí: Si les parece bien y si es el propósito del Señor nuestro Dios, avisemos a todos los demás hermanos, a todas partes en la tierra de Israel, a los sacerdotes y a los levitas en sus ciudades y al país que los rodea, y que se junten aquí con nosotros;
Dafidi sì wí fún gbogbo àwọn ìjọ Israẹli pé, tí ó bá dára lójú yín àti tí ó bá ṣe jẹ́ àṣẹ Olúwa Ọlọ́run wa, jẹ́ kí a ránṣẹ́ sí ọ̀nà jíjìn àti gbígbòòrò sí àwọn arákùnrin wa tókù ní gbogbo àwọn agbègbè ìlú Israẹli àti pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn nínú ìlú wọn àti pápá oko tútù, láti wá kó ara wọn jọ pọ̀ sọ́dọ̀ wa.
3 Y volvamos por nosotros mismos el cofre del pacto de nuestro Dios: porque desde los días de Saúl no acudimos a él para pedir dirección.
Ẹ jẹ́ kí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa padà sọ́dọ̀ wa, nítorí wí pé àwa kò ṣe ìwádìí nípa rẹ̀ ní àsìkò ìjọba Saulu.
4 Y todas las personas dijeron que lo harían, porque les parecía correcto.
Gbogbo ìjọ náà sì gbà láti ṣe èyí nítorí ó dàbí wí pé ó tọ lójú gbogbo àwọn ènìyàn.
5 Entonces David envió a todo Israel para que se uniera, desde Shihor, el río de Egipto, hasta el camino de Hamat, para obtener el cofre del pacto de Dios de Quiriat-jearim.
Nígbà náà ni Dafidi pe gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jọ, láti ọ̀dọ̀ Ṣihori ní Ejibiti lọ sí Lebo ní ọ̀nà à bá wọ Hamati, láti gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run padà láti Kiriati-Jearimu.
6 Y subió David, con todo Israel, a Baala, es decir, a Quiriat-jearim en Judá, para subir desde allí el cofre de Dios, sobre la cual se nombra el santo Nombre, el nombre del Señor, cuyo lugar está entre los querubines.
Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pẹ̀lú rẹ̀ lọ sí Baalahi ti Juda (Kiriati-Jearimu) láti gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run Olúwa tí a fi orúkọ rẹ̀ pè, tí ó jókòó láàrín kérúbù gòkè wá.
7 Y pusieron el cofre de Dios en un carro nuevo, y lo sacaron de la casa de Abinadab; y Uza y Ahío eran los conductores del carro.
Wọ́n sì gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run láti ilé Abinadabu lórí kẹ̀kẹ́ tuntun, Ussa àti Ahio ń ṣọ́ ọ.
8 Entonces David y todo Israel hicieron una melodía ante Dios con toda su fuerza, con canciones e instrumentos musicales de cuerda, y con instrumentos de bronce y cuernos.
Dafidi àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ni wọ́n ṣe àjọyọ̀ pẹ̀lú gbogbo agbára wọn níwájú Ọlọ́run, pẹ̀lú orin àti pẹ̀lú dùùrù, ohun èlò orin olókùn, tambori, kimbali pẹ̀lú ìpè.
9 Y cuando llegaron al alfoli de Chidon, Uza extendió su mano para mantener el cofre del pacto, porque los bueyes se estaban tropezando.
Nígbà tí wọ́n dé sí ilẹ̀ ìpakà Kidoni, Ussa sì na ọwọ́ rẹ̀ síta láti di àpótí ẹ̀rí Olúwa mú, nítorí màlúù kọsẹ̀.
10 Y la ira del Señor, que arde contra Uza, envió destrucción sobre él porque había puesto su mano sobre el cofre del pacto, y la muerte le llegó allí delante de Dios.
Ìbínú Olúwa, sì ru sí Ussa, ó sì lù ú bolẹ̀ nítorí o ti fi ọwọ́ rẹ̀ lórí àpótí ẹ̀rí. Bẹ́ẹ̀ ni ó sì kú síbẹ̀ níwájú Ọlọ́run.
11 Y David se enojó por el arrebato de ira del Señor contra Uza, y le dio a ese lugar el nombre de Pérez-uza, hasta el día de hoy.
Nígbà náà Dafidi sì bínú nítorí ìbínú Olúwa ké jáde lórí Ussa, àti títí di òní, wọ́n sì ń pe ibẹ̀ ní Peresi-Usa.
12 Y tan grande fue el temor de David a Dios ese día, que dijo: ¿Cómo puedo permitir que el cofre del pacto de Dios venga a mí?
Dafidi sì bẹ̀rù Ọlọ́run ní ọjọ́ náà, ó sì béèrè pé, báwo ni èmi náà ó ṣe gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ mi?
13 Entonces, David no dejó que el arca volviera a él a la ciudad de David, sino que la rechazó y la puso en la casa de Obed-edom, de Gat.
Kò gbé àpótí ẹ̀rí náà wá sí ọ̀dọ̀ ará rẹ̀ ní ìlú ti Dafidi dípò èyí, ó sì gbé e yà sí ilé Obedi-Edomu ará Gitti.
14 Y el cofre del pacto de Dios estuvo en la casa de Obed-edom por tres meses; y el Señor envió una bendición sobre la casa de Obed-edom y sobre todo lo que tenía.
Àpótí ẹ̀rí Olúwa sì wà lọ́dọ̀ àwọn ará ilé Obedi-Edomu ní ilé rẹ̀ fún oṣù mẹ́ta, Olúwa sì bùkún agbo ilé àti gbogbo ohun tí ó ní.