< Jevrejima 10 >

1 Jer zakon imajuæi sjen dobara koja æe doæi, a ne samo oblièje stvari, ne može nikada savršiti one koji pristupaju svake godine i prinose one iste žrtve.
Nítorí tí òfin jẹ́ òjìji àwọn ohun rere ti ń bọ̀ tí kì í ṣe àwòrán tòótọ́ fún àwọn òtítọ́ náà, wọn kò lè fi ẹbọ kan náà tí wọn ń rú nígbà gbogbo lọ́dọọdún mu àwọn tí ń wá jọ́sìn di pípé.
2 Inaèe bi prestale prinositi se, kad oni koji služe ne bi više imali nikake savjesti za grijehe, kad se jednom oèiste;
Bí kò ṣe bẹ́ẹ̀, a kì ìbá tí dẹ́kun àti máa rú wọn, nítorí àwọn ti ń sìn ki ìbá tí ní ìmọ̀ ẹ̀ṣẹ̀, nígbà tí a bá ti wẹ̀ wọ́n mọ́ lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo.
3 Nego se njima svake godine èini spomen za grijehe.
Ṣùgbọ́n nínú ẹbọ wọ̀nyí ni a ń ṣe ìrántí ẹ̀ṣẹ̀ lọ́dọọdún.
4 Jer krv junèija i jarèija ne može uzeti grijeha.
Nítorí ko ṣe é ṣe fún ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù àti ti ewúrẹ́ láti mú ẹ̀ṣẹ̀ kúrò.
5 Zato ulazeæi u svijet govori: žrtava i darova nijesi htio, ali si mi tijelo pripravio.
Nítorí náà nígbà tí Kristi wá sí ayé, ó wí pé, “Ìwọ kò fẹ́ ẹbọ àti ọrẹ, ṣùgbọ́n ara ni ìwọ ti pèsè fún mi,
6 Žrtve i prilozi za grijeh nijesu ti bili ugodni.
ẹbọ sísun àti ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ ni ìwọ kò ní inú dídùn sí.
7 Tada rekoh: evo doðoh, u poèetku knjige pisano je za mene, da uèinim volju tvoju, Bože.
Nígbà náà ni mo wí pé, ‘Kíyèsi i (nínú ìwé kíká ni a gbé kọ ọ́ nípa ti èmi) mo dé láti ṣe ìfẹ́ rẹ, Ọlọ́run.’”
8 I više kazavši: priloga i prinosa i žrtava, i žrtava za grijehe nijesi htio, niti su ti bili ugodni, što se po zakonu prinose;
Nígbà tí o wí ni ìṣáájú pé, “Ìwọ kò fẹ́ ẹbọ àti ọrẹ àti ẹbọ sísun, àti ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò ni inú dídùn si wọn” (àwọn èyí tí a ń rú gẹ́gẹ́ bí òfin).
9 Tada reèe: evo doðoh da uèinim volju tvoju, Bože. Ukida prvo da postavi drugo.
Nígbà náà ni ó wí pé, “Kíyèsi i, mo de láti ṣe ìfẹ́ rẹ Ọlọ́run.” Ó mú ti ìṣáájú kúrò, kí a lè fi ìdí èkejì múlẹ̀.
10 Po kojoj smo volji mi osveæeni prinosom tijela Isusa Hrista jednom.
Nípa ìfẹ́ náà ni a ti sọ wá di mímọ́ nípa ẹbọ ti Jesu Kristi fi ara rẹ̀ rú lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo.
11 I svaki sveštenik stoji svaki dan služeæi i jedne žrtve mnogo puta prinoseæi koje nikad ne mogu uzeti grijeha.
Àti olúkúlùkù àlùfáà sì ń dúró lójoojúmọ́ láti ṣiṣẹ́ ìsìn, ó sì ń ṣe ẹbọ kan náà nígbàkígbà, tí kò lè mú ẹ̀ṣẹ̀ kúrò láé.
12 A on prinesavši jedinu žrtvu za grijehe sjedi svagda s desne strane Bogu,
Ṣùgbọ́n òun, lẹ́yìn ìgbà tí o ti rú ẹbọ kan fún ẹ̀ṣẹ̀ títí láé, o jókòó lọ́wọ́ ọ̀tún Ọlọ́run;
13 Èekajuæi dalje dok se polože neprijatelji njegovi podnožje nogama njegovima.
láti ìgbà náà, ó retí títí a o fi àwọn ọ̀tá rẹ̀ ṣe àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀.
14 Jer jednijem prinosom savršio je vavijek one koji bivaju osveæeni.
Nítorí nípa ẹbọ kan a ti mú àwọn tí a sọ di mímọ́ pé títí láé.
15 A svjedoèi nam i Duh sveti; jer kao što je naprijed kazano:
Ẹ̀mí Mímọ́ sì ń jẹ́rìí fún wa pẹ̀lú, nítorí lẹ́yìn tí ó wí pé,
16 Ovo je zavjet koji æu naèiniti s njima poslije onijeh dana, govori Gospod: daæu zakone svoje u srca njihova, i u mislima njihovijem napisaæu ih;
“Èyí ni májẹ̀mú ti èmi o ba wọn dá lẹ́hìn àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, ni Olúwa wí. Èmi o fi òfin mi sí wọn ní ọkàn, inú wọn pẹ̀lú ni èmi o sì kọ wọn sí.”
17 I grijeha njihovijeh i bezakonja njihovijeh neæu više spominjati.
Ó tún sọ wí pé: “Ẹ̀ṣẹ̀ wọn àti àìṣedéédéé wọn lèmi kì yóò sì rántí mọ́.”
18 A gdje je oproštenje ovijeh ondje više nema priloga za grijehe.
Ṣùgbọ́n níbi tí ìmúkúrò ìwọ̀nyí bá gbé wà, ìrúbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ kò sí mọ́.
19 Imajuæi dakle slobodu, braæo, ulaziti u svetinju krvlju Isusa Hrista, putem novijem i živijem,
Ará, ǹjẹ́ bí a ti ní ìgboyà láti wọ inú Ibi Mímọ́ Jùlọ nípasẹ̀ ẹ̀jẹ̀ Jesu,
20 Koji nam je obnovio zavjesom, to jest tijelom svojijem,
nípa ọ̀nà títún àti ààyè, tí o yà sí mímọ́ fún wa, àti láti kọjá aṣọ ìkélé èyí yìí ní, ara rẹ̀;
21 I sveštenika velikoga nad domom Božijim:
àti bí a ti ni àlùfáà gíga lórí ilé Ọlọ́run;
22 Da pristupamo s istinitijem srcem u punoj vjeri, oèišæeni u srcima od zle savjesti, i umiveni po tijelu vodom èistom;
ẹ jẹ́ kí a fi òtítọ́ ọkàn súnmọ́ tòsí ni ẹ̀kún ìgbàgbọ́, kí a sì wẹ ọkàn wa mọ́ kúrò nínú ẹ̀rí ọkàn búburú, kí a sì fi omi mímọ́ wẹ ara wa nù.
23 Da se držimo tvrdo priznanja nada: jer je vjeran onaj koji je obeæao;
Ẹ jẹ́ kí a di ìjẹ́wọ́ ìrètí wa mu ṣinṣin ni àìṣiyèméjì, nítorí pé olóòtítọ́ ní ẹni tí o ṣe ìlérí.
24 I da razumijevamo jedan drugoga u podbunjivanju k ljubavi i dobrijem djelima,
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ara wa wò láti ru ara wa sí ìfẹ́ àti sí iṣẹ́ rere,
25 Ne ostavljajuæi skupštine svoje, kao što neki imaju obièaj, nego jedan drugoga svjetujuæi, i toliko veæma koliko vidite da se približuje dan sudni.
kí a ma máa kọ ìpéjọpọ̀ ara wa sílẹ̀, gẹ́gẹ́ bi àṣà àwọn ẹlòmíràn; ṣùgbọ́n kí a máa gba ara ẹni níyànjú pẹ̀lúpẹ̀lú bí ẹ̀yin ti rí i pé ọjọ́ náà ń súnmọ́ etílé.
26 Jer kad mi griješimo navalice pošto smo primili poznanje istine, nema više žrtve za grijehe;
Nítorí bí àwa ba mọ̀ ọ́n mọ̀ dẹ́ṣẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí àwa bá ti gba ìmọ̀ òtítọ́ kò tún sí ẹbọ fún ẹ̀ṣẹ̀ mọ́.
27 Nego strašno èekanje suda, i revnost ognja koji æe da pojede one koji se suprote.
Bí kò ṣe ìrètí ìdájọ́ tí ó ba ni lẹ́rù, àti ti ìbínú ti o múná, tí yóò pa àwọn ọ̀tá run.
28 Ko prestupi zakon Mojsijev, bez milosti umire kod dva ili tri svjedoka.
Ẹnikẹ́ni tí ó ba gan òfin Mose, ó kú láìsí àánú nípa ẹ̀rí ẹni méjì tàbí mẹ́ta.
29 Koliko mislite da æe gore muke zaslužiti onaj koji sina Božijega pogazi, i krv zavjeta kojom se osveti za poganu uzdrži, i Duha blagodati naruži?
Mélòó mélòó ni ẹ rò pé a o jẹ ẹni náà ní ìyà kíkan, ẹni tí o tẹ Ọmọ Ọlọ́run mọ́lẹ̀ tí ó sì ti ka ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú ti a fi sọ ọ́ di mímọ́ si ohun àìmọ́, tí ó sì ti kẹ́gàn ẹ̀mí oore-ọ̀fẹ́.
30 Jer znamo onoga koji reèe: moja je osveta, ja æu vratiti, govori Gospod; i opet: Gospod æe suditi narodu svojemu.
Nítorí àwa mọ ẹni tí o wí pé, Ẹ̀san ni ti èmi, Olúwa wí pé, “Èmi ó gbẹ̀san.” Àti pẹ̀lú, “Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.”
31 Strašno je upasti u ruke Boga živoga.
Ohun ẹ̀rù ni láti ṣubú sí ọwọ́ Ọlọ́run alààyè.
32 Opominjite se pak prvijeh dana svojijeh, u koje se prosvijetliste i mnogu borbu stradanja podnesoste,
Ṣùgbọ́n ẹ rántí ọjọ́ ìṣáájú nínú èyí tí, nígbà tí a ti sí yin lójú, ẹ fi ara da wàhálà ńlá ti ìjìyà;
33 Koje postavši gledanje sa sramota i nevolja, a koje postavši drugovi onima koji žive tako.
lápákan, nígbà tí a sọ yín di ìran wíwò nípa ẹ̀gàn àti ìpọ́njú; àti lápákan, nígbà tí ẹ̀yin di ẹgbẹ́ àwọn tí a ṣe bẹ́ẹ̀ si.
34 Jer se na okove moje sažaliste, i dadoste s radošæu da se razgrabi vaše imanje, znajuæi da imate sebi imanje bolje i nepropadljivo na nebesima.
Nítorí ẹ̀yin bá àwọn tí ó wà nínú ìdè kẹ́dùn, ẹ sì fi ayọ̀ gba ìkólọ ẹrù yin, nítorí ẹ̀yin mọ nínú ara yin pé, ẹ ni ọrọ̀ tí ó wà títí, tí ó sì dára jù bẹ́ẹ̀ lọ.
35 Ne odbacujte dakle slobode svoje, koja ima veliku platu.
Nítorí náà ẹ má ṣe gbé ìgboyà yín sọnù, èyí ti o ni èrè ńlá.
36 Jer vam je trpljenje od potrebe da volju Božiju savršivši primite obeæanje.
Nítorí ẹ̀yin kò le ṣe aláìní sùúrù, nítorí ìgbà tí ẹ̀yin bá ti ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run tan kí ẹ̀yin le gba ìlérí náà.
37 Jer još malo, vrlo malo, pak æe doæi onaj koji treba da doðe i neæe odocniti.
Nítorí, “Ni ìwọ̀n ìgbà díẹ̀ sí i, ẹni náà ti ń bọ̀ yóò dé, kí yóò sì jáfara.
38 A pravednik življeæe od vjere; ako li otstupi neæe biti po volji moje duše.
Ṣùgbọ́n, “Olódodo ni yóò yè nípa ìgbàgbọ́. Ṣùgbọ́n bí o ba fàsẹ́yìn, ọkàn mi kò ní inú dídùn sí i.”
39 A mi, braæo, nijesmo od onijeh koji otstupaju na pogibao, nego od onijeh koji vjeruju da spasu duše.
Ṣùgbọ́n àwa kò sí nínú àwọn tí ń fàsẹ́yìn sínú ègbé; bí kò ṣe nínú àwọn tí o gbàgbọ́ sí ìgbàlà ọkàn.

< Jevrejima 10 >