< Neemia 6 >

1 Și s-a întâmplat, când Sanbalat și Tobia și Gheșem arabul, și ceilalți dușmani ai noștri au auzit că eu construisem zidul și că nu mai era spărtură rămasă în el (deși în acel timp nu pusesem ușile la porți),
Nígbà tí Sanballati, Tobiah Geṣemu ará Arabia àti àwọn ọ̀tá wa tókù gbọ́ pé, mo ti tún odi náà mọ, kò sì sí àlàfo kankan tí ó ṣẹ́kù nínú rẹ̀—bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò ì tí ì ri àwọn ìlẹ̀kùn ibodè ní àkókò náà.
2 Că Sanbalat și Gheșem au trimis la mine, spunând: Vino, să ne întâlnim împreună în unul din satele din câmpia Ono. Dar ei gândeau să îmi facă ticăloșie.
Sanballati àti Geṣemu rán iṣẹ́ yìí sí mi pé, “Wá jẹ́ kí a jọ pàdé pọ̀ nínú ọ̀kan lára àwọn ìletò ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ono.” Ṣùgbọ́n wọ́n ń gbèrò láti ṣe mí ní ibi;
3 Și le-am trimis mesageri, spunând: Eu fac o lucrare mare astfel încât nu pot să cobor; de ce să înceteze lucrarea, în timp ce o părăsesc și cobor la voi?
bẹ́ẹ̀ ni mo rán oníṣẹ́ padà pẹ̀lú èsì yìí pé, “Èmi ń ṣe iṣẹ́ ńlá kan, èmi kò le è sọ̀kalẹ̀ wá. Èéṣe tí iṣẹ́ náà yóò fi dúró, nígbà tí mo bá fi í sílẹ̀ tí mo sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá?”
4 Totuși ei au trimis la mine de patru ori în felul acesta; și eu le-am răspuns în același fel.
Wọ́n rán iṣẹ́ náà sí mi nígbà mẹ́rin ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, mo sì fún wọn ní èsì bákan náà fún ìgbà kọ̀ọ̀kan.
5 Atunci a trimis Sanbalat pe servitorul său la mine, în felul acesta a cincea oară cu o scrisoare deschisă în mâna sa;
Ní ìgbà karùn-ún, Sanballati rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sí mi pẹ̀lú irú iṣẹ́ kan náà, lẹ́tà kan tí a kò fi sínú àpò ìwé wà ní ọwọ́ rẹ̀
6 În care era scris: Se aude printre păgâni, și Gașmu spune aceasta, că tu și iudeii gândiți să vă răzvrătiți; din care cauză tu construiești zidul; ca tu să fii împăratul lor, conform acestor cuvinte.
tí a kọ sínú un rẹ̀ pé, “A ròyìn rẹ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, Geṣemu sì sọ pé, òtítọ́ ni, pé ìwọ àti àwọn Júù ń gbèrò láti ṣọ̀tẹ̀, nítorí náà ni ẹ ṣe ń mọ odi. Síwájú sí i, gẹ́gẹ́ bí ìròyìn yìí, ìwọ sì ń gbèrò láti di ọba wọn
7 Și tu de asemenea ai rânduit profeți să predice despre tine la Ierusalim, spunând: Este un împărat în Iuda; și acum se va face cunoscut împăratului conform acestor cuvinte. Vino de aceea acum și să ne sfătuim împreună.
àti pé ó ti yan àwọn wòlíì kí wọn lè kéde nípa rẹ̀ ní Jerusalẹmu: ‘Ọba kan wà ní Juda!’ Nísinsin yìí, ìròyìn yìí yóò padà sí ọ̀dọ̀ ọba; nítorí náà wá, jẹ́ kí a bá ara wa sọ̀rọ̀.”
8 Atunci am trimis la el, spunând: Nu sunt făcute astfel de lucruri precum spui, ci tu le inventezi din inima ta.
Mo dá èsì yìí padà sí i pé, “Kò sí ohun kan nínú irú ohun tí ìwọ sọ tí ó ṣẹlẹ̀; ìwọ kàn rò wọ́n ní orí ara rẹ ni.”
9 Pentru că toți ne-au înfricoșat, spunând: Mâinile lor vor fi slăbite de la lucrare și aceasta nu se va face. De aceea acum, O Dumnezeule, întărește mâinile mele.
Gbogbo wọn múra láti dẹ́rùbà wá, wọ́n ń rò ó wí pé, “Ọwọ́ wọn kò ní ran iṣẹ́ náà, àti wí pé wọn kò ní parí rẹ̀.” Ṣùgbọ́n mo gbàdúrà pé, “Nísinsin yìí Ọlọ́run fi agbára fún ọwọ́ mi.”
10 După aceasta eu am mers la casa lui Șemaia, fiul lui Delaia, fiul lui Mehetabeel, care era închis; și el a spus: Să ne întâlnim în casa lui Dumnezeu, înăuntrul templului, și să închidem ușile templului, pentru că ei vor veni să te ucidă: da, noaptea vor veni ei să te ucidă.
Ní ọjọ́ kan mo lọ sí ilé Ṣemaiah ọmọ Delaiah, ọmọ Mehetabeeli, ẹni tí a há mọ́ sínú ilé rẹ̀. Ó wí pé, “Jẹ́ kí a pàdé ní ilé Ọlọ́run nínú tẹmpili, kí o sì jẹ́ kí a pa àwọn ìlẹ̀kùn tẹmpili dé, nítorí àwọn ènìyàn ń bọ̀ láti pa ọ́, ní òru ni wọn yóò wá láti pa ọ́.”
11 Și eu am spus: Ar trebui un astfel de om ca mine să fugă? Și cine, fiind precum sunt eu, ar intra în templu pentru a-și salva viața? Nu voi intra.
Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí irú ènìyàn bí èmi sálọ? Tàbí kí ènìyàn bí èmi sálọ sínú tẹmpili láti gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là? Èmi kò ní lọ!”
12 Și, iată, am priceput că Dumnezeu nu îl trimisese; ci că el a vestit această profeție împotriva mea; fiindcă Tobia și Sanbalat îl angajaseră.
Èmi wòye pé Ọlọ́run kò rán an, ṣùgbọ́n ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí mi nítorí Tobiah àti Sanballati ti bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀.
13 Pentru aceasta a fost el angajat, ca să mă înfrice și să fac astfel și să păcătuiesc, și ca ei să poată avea ceva de spus pentru o purtare rea, ca să mă poată ocărî.
Wọ́n bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀ láti dẹ́rùbà mí nítorí kí èmi lè dẹ́ṣẹ̀ nípa ṣíṣe èyí, kí wọn lè bà mí lórúkọ jẹ́, kí n sì di ẹni ẹ̀gàn.
14 Dumnezeul meu, gândește-te la Tobia și la Sanbalat conform cu aceste lucrări ale lor și la profetesa Noadia și la restul profeților, care voiau să mă înfricoșeze.
A! Ọlọ́run mi, rántí Tobiah àti Sanballati, nítorí ohun tí wọ́n ti ṣe; kí o sì tún rántí Noadiah wòlíì obìnrin àti àwọn wòlíì tókù tí wọ́n ń gbèrò láti dẹ́rùbà mí.
15 Astfel zidul a fost terminat în a douăzeci și cincea zi a lunii Elul, în cincizeci și două de zile.
Bẹ́ẹ̀ ni a parí odi náà ní ọjọ́ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù Eluli, láàrín ọjọ́ méjìléláàádọ́ta.
16 Și s-a întâmplat că, atunci când toți dușmanii noștri au auzit despre aceasta și toți păgânii care erau în jurul nostru au văzut aceste lucruri, ei au fost mult doborâți în propriii lor ochi; fiindcă au priceput că această lucrare era făcută de la Dumnezeul nostru.
Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ èyí, gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká bẹ̀rù jìnnìjìnnì sì mú wọn, nítorí wọ́n wòye pé iṣẹ́ yìí di ṣíṣe pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run wa.
17 Mai mult, în acele zile, nobilii lui Iuda au trimis multe scrisori la Tobia și scrisorile de la Tobia veneau la ei.
Bákan náà, ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọlọ́lá Juda ń kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ lẹ́tà ránṣẹ́ sí Tobiah, èsì láti ọ̀dọ̀ Tobiah sì ń wá sí ọ̀dọ̀ wọn.
18 Pentru că erau mulți în Iuda jurați lui, deoarece el era ginerele lui Șecania, fiul lui Arah; și fiul său, Iohanan, luase pe fiica lui Meșulam, fiul lui Berechia.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Juda ti mulẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí ó jẹ́ àna Ṣekaniah ọmọ Arah (Sanballati fẹ́ ọmọ Ṣekaniah), ọmọ rẹ̀ Jehohanani sì tún fẹ́ ọmọbìnrin Meṣullamu ọmọ Berekiah.
19 De asemenea ei făceau cunoscute, înaintea mea, faptele lui bune, și rosteau cuvintele mele către el. Și Tobia trimitea scrisori pentru a mă înfricoșa.
Síwájú sí í, wọ́n túbọ̀ ń ròyìn iṣẹ́ rere rẹ̀ fún mi, wọ́n sì ń sọ ohun tí mo sọ fún un. Tobiah sì ń kọ àwọn lẹ́tà ránṣẹ́ sí mi láti dẹ́rùbà mí.

< Neemia 6 >