< Isaia 55 >
1 Voi, toţi cei însetaţi, veniţi la ape, şi cel ce nu are bani, veniţi, cumpăraţi şi mâncaţi; da, veniţi, cumpăraţi vin şi lapte fără bani şi fără preţ.
“Ẹ wá, gbogbo ẹ̀yin tí òǹgbẹ ń gbẹ, ẹ wá sí ibi omi; àti ẹ̀yin tí kò ní owó; ẹ wá, ẹ rà kí ẹ sì jẹ! Ẹ wá ra wáìnì àti wàrà láìsí owó àti láìdíyelé.
2 Pentru ce cheltuiţi bani pentru ce nu este pâine? Şi osteneala voastră pentru ceea ce nu satură? Daţi-mi atent ascultare şi mâncaţi ceea ce este bun şi să se desfete sufletul vostru în grăsime.
Èéṣe tí ẹ fi ń ná owó fún èyí tí kì í ṣe àkàrà àti làálàá yín lórí ohun tí kì í tẹ́nilọ́rùn? Tẹ́tí sílẹ̀, tẹ́tí sí mi, kí ẹ sì jẹ èyí tí ó dára, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn yín yóò láyọ̀ nínú ọrọ̀ tí ó bójúmu.
3 Plecaţi-vă urechile şi veniţi la mine, ascultaţi şi sufletul vostru va trăi; iar eu voi face un legământ veşnic cu voi, conform îndurărilor sigure ale lui David.
Tẹ́tí sílẹ̀ kí o sì wá sọ́dọ̀ mi; gbọ́ tèmi, kí ọkàn rẹ lè wà láààyè. Èmi yóò dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú rẹ, ìfẹ́ òtítọ́ tí mo ṣèlérí fún Dafidi.
4 Iată, l-am dat ca martor poporului, un conducător şi comandant poporului.
Kíyèsi i, mo ti fi òun ṣe ẹlẹ́rìí fún àwọn ènìyàn, olórí àti apàṣẹ fún àwọn ènìyàn.
5 Iată, vei chema o naţiune pe care nu o cunoşti, şi naţiuni care nu te-au cunoscut vor alerga la tine datorită DOMNULUI Dumnezeului tău şi pentru Cel Sfânt al lui Israel, căci el te-a glorificat.
Lóòtítọ́ ìwọ yóò ké sí àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ àti orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ ni yóò sáré tọ̀ ọ́ wá, nítorí Olúwa Ọlọ́run rẹ Ẹni Mímọ́ Israẹli nítorí pé ó ti fi ohun dídára dá ọ lọ́lá.”
6 Căutaţi pe DOMNUL cât mai poate fi găsit, chemaţi-l cât mai este aproape;
Ẹ wá Olúwa nígbà tí ẹ lè rí i; ẹ pè é nígbà tí ó wà nítòsí.
7 Să îşi părăsească cel stricat calea şi omul nedrept gândurile lui, şi să se întoarcă la DOMNUL, iar el va avea milă de el; şi la Dumnezeul nostru, căci el îşi înmulţeşte iertarea.
Jẹ́ kí ìkà kí ó kọ ọ̀nà rẹ̀ sílẹ̀ àti ènìyàn búburú èrò rẹ̀. Jẹ́ kí ó yípadà sí Olúwa, Òun yóò sì ṣàánú fún un, àti sí Ọlọ́run wa, nítorí Òun yóò sì dáríjì.
8 Fiindcă gândurile mele nu sunt gândurile tale, nici căile tale nu sunt căile mele, spune DOMNUL.
“Nítorí èrò mi kì í ṣe èrò yín, tàbí ọ̀nà yín a ha máa ṣe ọ̀nà mi,” ni Olúwa wí.
9 Căci aşa [cum] cerurile sunt mai sus decât pământul, tot așa căile mele sunt mai înalte decât căile voastre şi gândurile mele decât gândurile voastre.
“Gẹ́gẹ́ bí ọ̀run ti ga ju ayé lọ, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀nà mi ga ju ọ̀nà yín lọ àti èrò mi ju èrò yín lọ.
10 Căci aşa cum coboară ploaia şi zăpada din cer şi nu se întoarce acolo, ci udă pământul şi îl face să încolţească şi să înmugurească, pentru a da sămânţă semănătorului şi pâine celui ce mănâncă,
Gẹ́gẹ́ bí òjò àti yìnyín ti wálẹ̀ láti ọ̀run tí kì í sì padà sí ibẹ̀ láì bomirin ilẹ̀ kí ó sì mú kí ó tanná kí ó sì rudi, tó bẹ́ẹ̀ tí yóò fi mú irúgbìn fún afúnrúgbìn àti àkàrà fún ọ̀jẹun,
11 Tot așa va fi cuvântul meu care iese din gura mea, nu se va întoarce la mine gol, ci va împlini ceea ce îmi place şi va prospera în lucrul la care l-am trimis.
bẹ́ẹ̀ ni ọ̀rọ̀ mi tí ó jáde láti ẹnu mi wá; kì yóò padà sọ́dọ̀ mi lọ́wọ́ òfo, ṣùgbọ́n yóò ṣe ohun tí mo fẹ́, yóò sì mú ète mi tí mo fi rán an wá sí ìmúṣẹ.
12 Fiindcă veţi ieşi cu bucurie şi veţi fi conduşi cu pace, munţii şi dealurile vor izbucni înaintea voastră în cântare şi toţi copacii câmpului vor bate din palme.
Ẹ̀yin yóò jáde lọ ní ayọ̀ a ó sì darí i yín lọ ní àlàáfíà; òkè ńlá ńlá àti kéékèèké yóò bú sí orin níwájú yín àti gbogbo igi inú pápá yóò máa pàtẹ́wọ́.
13 În loc de spin va răsări bradul şi în loc de mărăcine va răsări pomul de mirt şi va fi DOMNULUI ca nume, ca un semn veşnic care nu va fi stârpit.
Dípò igi ẹ̀gún ni igi junifa yóò máa dàgbà, àti dípò ẹ̀wọ̀n, maritili ni yóò yọ. Èyí yóò wà fún òkìkí Olúwa, fún àmì ayérayé, tí a kì yóò lè parun.”