< Ezechiel 8 >

1 Și s-a întâmplat în anul al șaselea, în [luna] a șasea, în a cincea [zi] a lunii, [pe când] ședeam în casa mea și bătrânii lui Iuda ședeau înaintea mea, că mâna Domnului DUMNEZEU a căzut acolo peste mine.
Ní ọjọ́ karùn-ún, oṣù kẹfà ọdún kẹfà bí mo ṣe jókòó nílé mi pẹ̀lú àwọn àgbàgbà Juda níwájú mi, ọwọ́ Olúwa Olódùmarè bà lé mi níbẹ̀.
2 Atunci am privit și iată, o asemănare ca înfățișarea focului; de la înfățișarea coapselor lui drept în jos, foc; și de la coapsele lui drept în sus, ca înfățișarea unei străluciri, asemenea culorii chihlimbarului.
Nígbà tí mo wò, mo rí ohun kan tí ó jọ ènìyàn. Láti ibi ìbàdí rẹ lọ sísàlẹ̀ dàbí iná, láti ibi ìbàdí yìí sókè sì mọ́lẹ̀ bí idẹ tó ń kọ mọ̀nà.
3 Și el a întins forma unei mâini și m-a luat de o șuviță a capului meu; și duhul m-a ridicat între pământ și cer și m-a adus în viziunile lui Dumnezeu la Ierusalim, la ușa porții interioare care privește spre nord; unde [era] scaunul chipului geloziei, care provoacă la gelozie.
Ó na ohun tó dàbí ọwọ́ jáde, ó fi gba mi ní irun orí mú, Ẹ̀mí sì gbé mi sókè sí agbede-méjì ayé àti ọ̀run, ó sì mú mi lọ rí ìran Ọlọ́run, mo sì lọ sí Jerusalẹmu, ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òde àríwá níbi tí ère owú tí ó ń mú ni bínú wá níwájú mi.
4 Și, iată, gloria Dumnezeului lui Israel [era] acolo, conform viziunii pe care o văzusem în câmpie.
Sì kíyèsi i, ògo Ọlọ́run Israẹli wà níbẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìran ti mo rí ni pẹ̀tẹ́lẹ̀.
5 Atunci el mi-a spus: Fiu al omului, ridică-ți acum ochii spre calea dinspre nord. Astfel mi-am ridicat ochii spre calea dinspre nord și iată, spre nord la poarta altarului acest chip al geloziei la intrare.
Ó sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbójú sókè sí ìhà àríwá.” Èmi náà sì gbójú sókè sí ìhà àríwá mo sì rí ère tí ó ń mú ni jowú ní ẹnu-ọ̀nà ibi pẹpẹ.
6 El mi-a mai spus: Fiu al omului, vezi tu ce fac ei? Urâciunile cele mari pe care casa lui Israel le face aici, ca să mă îndepărtez de sanctuarul meu? Dar întoarce-te din nou [și] vei vedea urâciuni mai mari.
Ó sì wí fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o rí ohun tí wọ́n ń ṣe ohun ìríra ńlá tí ilé Israẹli ń ṣe, láti lé mi jìnnà réré sí ibi mímọ́ mi? Ṣùgbọ́n ìwọ yóò tún rí àwọn ìríra ńlá tó tóbi jù èyí lọ.”
7 Și m-a adus la ușa curții; și când am privit, iată, o gaură în zid.
Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà àgbàlá. Mo wò ó, mo sì rí ihò kan lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri.
8 Atunci el mi-a spus: Fiu al omului, sapă acum în zid; și după ce am săpat în zid, iată, o ușă.
Nígbà náà ló sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, gbẹ́ inú ògiri náà,” nígbà tí mo sì gbẹ́ inú ògiri, mo rí ìlẹ̀kùn kan.
9 Și el mi-a spus: Intră și privește urâciunile cele stricate pe care ei le fac aici.
Ó sì wí fún mi pé, “Wọlé kí ìwọ kí ó rí ohun ìríra búburú tí wọ́n ń ṣe níbẹ̀.”
10 Astfel eu am intrat și am văzut; și iată, fiecare formă de târâtoare și de fiare urâcioase și toți idolii casei lui Israel, gravați pe perete de jur împrejur.
Mo wọlé, mo sì rí àwòrán oríṣìíríṣìí ẹranko tí ń fà nílẹ̀ àti àwọn ẹranko ìríra àti gbogbo òrìṣà ilẹ̀ Israẹli tí wọ́n yà sára ògiri.
11 Și acolo stăteau în picioare înaintea lor șaptezeci de bărbați dintre bătrânii casei lui Israel și în mijlocul lor stătea în picioare Iaazania, fiul lui Șafan, cu fiecare bărbat [având] tămâietoarea sa în mână; și un nor gros de tămâie se ridica.
Níwájú wọn ni àádọ́rin ọkùnrin tó jẹ́ àgbàgbà ilé Israẹli dúró sí, Jaaṣaniah ọmọ Ṣafani sì dúró sí àárín wọn. Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sì mú àwo tùràrí lọ́wọ́, òórùn sì ń tú jáde.
12 Atunci el mi-a spus: Fiu al omului, ai văzut ce fac bătrânii casei lui Israel în întuneric, fiecare bărbat în camerele chipurilor lui? Pentru că ei spun: DOMNUL nu ne vede, DOMNUL a părăsit pământul.
Ó sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, ṣé o ti rí ohun tí àwọn àgbàgbà ilé Israẹli ń ṣe nínú òkùnkùn, olúkúlùkù ní yàrá òrìṣà rẹ̀? Wọ́n ní, ‘Olúwa kò rí wa; Olúwa ti kọ̀ ilé náà sílẹ̀.’”
13 El mi-a spus de asemenea: Întoarce-te din nou [și] vei vedea urâciuni mai mari pe care le fac ei.
Ó tún sọ fún mi pé, “Ìwọ yóò rí wọn tí wọ́n ń ṣe àwọn ohun ìríra tó burú jù bẹ́ẹ̀ lọ.”
14 Atunci m-a adus la ușa din poarta casei DOMNULUI care [era] spre nord; și, iată, acolo ședeau femei plângând pentru Tamuz.
Ó mú mi wá sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa tó wà ní ìhà àríwá, mo sì rí àwọn obìnrin tó jókòó, tí wọ́n sì ń ṣọ̀fọ̀ fún Tamusi.
15 Atunci el mi-a spus: Ai văzut [aceasta], fiu al omului? Întoarce-te din nou [și] vei vedea urâciuni mai mari decât acestea.
Ó sọ fún mi pé, “Ṣé ìwọ rí báyìí, ọmọ ènìyàn? Ìwọ yóò tún rí ìríra tó ga jù èyí lọ.”
16 Și m-a adus în curtea interioară a casei DOMNULUI și, iată, la ușa templului DOMNULUI, între portic și altar, [erau] vreo douăzeci și cinci de bărbați, cu spatele spre templul DOMNULUI și cu fețele spre est; și ei se închinau soarelui spre est.
Ó mú mi wá sí ibi àgbàlá ilé Olúwa, ní ẹnu-ọ̀nà tẹmpili Olúwa, láàrín ìloro àti pẹpẹ, ni ìwọ̀n ọkùnrin mẹ́ẹ̀dọ́gbọ̀n wà, tí wọ́n kẹ́yìn sí tẹmpili Olúwa tí wọn sì kọjú sí ìlà-oòrùn, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún oòrùn ní apá ìlà-oòrùn.
17 Atunci el mi-a spus: Ai văzut [aceasta], fiu al omului? Este un lucru ușor pentru casa lui Iuda că ei fac urâciunile pe care le fac aici? Fiindcă au umplut țara cu violență și s-au întors să mă provoace la mânie; și, iată, ei își pun ramura la nas.
Ó sì wí fún mi, “Ṣé ìwọ ti rí èyí ọmọ ènìyàn? Ǹjẹ́ ohun kékeré ni fún ilé Juda láti ṣe àwọn ohun ìríra tí wọn ń ṣe níbi yìí? Ṣé o tún yẹ kí wọ́n fi ìwà ipá kún ilẹ̀ kí wọn sì máa mú mi bínú ní gbogbo ìgbà? Wò wọn bi wọn ṣe n fi ẹ̀ka wọn sínú inú wọn.
18 De aceea și eu mă voi purta cu furie; ochiul meu nu va cruța, nici nu voi avea milă; și deși ei strigă cu voce tare în urechile mele, [totuși] nu îi voi asculta.
Nítorí náà, èmi yóò fi ìbínú bá wọn wí; èmi kò ní i dá wọn sí bẹ́ẹ̀ ni èmi kò sì ní fojú àánú wò wọ́n. Bí wọ́n tilẹ̀ ń pariwo sí mi létí, èmi kò ní fetí sí wọn.”

< Ezechiel 8 >