< Ezechiel 47 >

1 După aceasta m-a dus din nou la ușa casei și, iată, ape ieșeau de sub pragul casei spre est, pentru că fața casei [dădea spre] est și apele curgeau de sub partea dreaptă a casei, în [partea] de sud a altarului.
Ọkùnrin náà mú mi padà lọ sí àbáwọlé tẹmpili náà, mo sì rí omi tí ó ń tú jáde láti abẹ́ ìloro tẹmpili náà sí apá ìhà ìlà-oòrùn (nítorí tẹmpili náà dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn). Omi náà ń tú jáde sí ìsàlẹ̀ láti abẹ́, ní ìhà gúúsù tẹmpili náà, ní ìhà gúúsù pẹpẹ.
2 Apoi m-a dus pe calea porții dinspre nord și m-a condus împrejurul căii de afară până la poarta exterioară spre calea care dă spre est; și, iată, curgeau ape pe partea dreaptă.
Ó wá mú mi gba ojú ọ̀nà àríwá jáde, ó sì mú mi yí ìta ojú ọ̀nà ìta tí ó dojúkọ ìhà ìlà-oòrùn, omi náà sì ń sàn láti ìhà gúúsù wá.
3 Și când bărbatul care avea frânghia în mână a ieșit spre est, a măsurat o mie de coți și m-a trecut prin ape; apele [erau] până la glezne.
Bí ọkùnrin náà ti lọ sí apá ìhà ìlà-oòrùn pẹ̀lú okùn wíwọ̀n nǹkan lọ́wọ́ rẹ̀, ó wọn ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́, ó sì mú mi gba ibi odò kan tí kò jì jù kókósẹ̀ lọ.
4 Din nou a măsurat o mie și m-a trecut prin ape; apele [erau] până la genunchi. Din nou a măsurat o mie și m-a trecut; apele [erau] până la coapse.
Ó sì wọn ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́ mìíràn kúrò, ó sì mú mi gba ibi odò tí ó jì ní ìwọ̀n orúnkún. Ó tún wọn ẹgbẹ̀rún márùn-ún ìgbọ̀nwọ́ mìíràn kúrò, ó sì mú mi gba odò tí ó dé ìbàdí.
5 După aceea a măsurat o mie; [și era] un râu pe care nu-l puteam trece, pentru că apele crescuseră, ape de înotat, un râu care nu putea fi trecut.
Ó wọn ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́ mìíràn kúrò, ṣùgbọ́n nísinsin yìí odò tí ń kò lè kọjá rẹ̀ ni, nítorí pé odò tí ó kún, ó sì jì tó èyí tí wọ́n le lúwẹ̀ẹ́ nínú rẹ̀ odò tí ẹnikẹ́ni kò le dá kọjá ni.
6 Și mi-a spus: Fiu al omului, ai văzut [aceasta]? Apoi m-a dus și m-a făcut să mă întorc la marginea râului.
Ó bi mí léèrè pé, “Ọmọ ènìyàn, ǹjẹ́ o rí èyí?” Lẹ́yìn náà, ó mú mi padà sí etí odò.
7 Acum, când m-am întors, iată, pe malul râului [erau] foarte mulți pomi pe o parte și pe cealaltă.
Nígbà tí mo dé ibẹ̀, mo rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi ní ẹ̀gbẹ́ méjèèjì odò.
8 Apoi mi-a spus: Aceste ape ies spre țara de est și coboară înspre deșert și se varsă în mare, [când] se vor vărsa în mare, apele se vor vindeca.
Ó sọ fún mi pé, “Odò yìí ń tú jáde sí ìhà ìlà-oòrùn, wọ́n sì ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí pẹ̀tẹ́lẹ̀, wọ́n sì wọ inú Òkun lọ, a sì mú omi wọn láradá.
9 Și se va întâmpla, [că] orice lucru care trăiește, care se mișcă, oriunde râurile vor curge, va trăi; și va fi o foarte mare mulțime de pești, pentru că aceste ape vor curge până acolo, fiindcă aceștia vor fi vindecați; și orice lucru, pe unde va curge râul, va trăi.
Àwọn ohun alààyè tí ó ń rákò yóò máa gbé ní ibikíbi tí odò ti ń sàn. Ẹja yóò pọ̀ ni ọ̀pọ̀lọpọ̀, nítorí pé odò ń sàn síbẹ̀, ó sì mú kí omi iyọ̀ tutù nini; nítorí náà níbi tí omi ti ń sàn, gbogbo nǹkan ni yóò wà ni ààyè.
10 Și se va întâmpla, [că] pescarii vor sta în picioare pe el, de la En-Ghedi chiar până la En-Eglaim; vor fi [un loc] pentru a întinde plase; peștii lor vor fi conform cu felul lor, ca peștii mării celei mari, peste măsură de mulți.
Àwọn apẹja yóò dúró ní etí bèbè odò; láti En-Gedi títí dé En-Eglaimu ààyè yóò wa láti tẹ́ àwọ̀n wọn sílẹ̀. Oríṣìíríṣìí ẹja ni yóò wà gẹ́gẹ́ bí ẹja omi Òkun ńlá.
11 Dar locurile ei noroioase și mlaștinile ei nu vor fi vindecate; vor fi date pentru sare.
Ṣùgbọ́n ẹrẹ̀ àti àbàtà kò ní tòrò; àwa yóò fi wọn sílẹ̀ fún iyọ̀.
12 Și lângă râu, pe malul lui, de o parte și de cealaltă parte, vor crește tot [felul] de pomi pentru hrană, a căror frunză nu se veștejește, nici rodul lor nu va fi mistuit; el va aduce rod nou conform cu lunile lui, pentru că apele lui au ieșit din sanctuar; și rodul lui va fi pentru hrană și frunza lui pentru medicament.
Àwọn igi eléso ní oríṣìíríṣìí ni yóò máa hù ní bèbè odò ní ìhà ìhín àti ní ìhà ọ̀hún. Ewé wọn kì yóò sì rọ, bẹ́ẹ̀ ní èso wọn kì yóò run, wọn yóò máa ṣe èso tuntun rẹ̀ ní oṣù nítorí pé omi láti ibi mímọ́ ń sàn sí wọn. Èso wọn yóò sì jẹ́ fún jíjẹ àti ewé wọn fún ìwòsàn.”
13 Astfel spune Domnul DUMNEZEU: Aceasta [va fi] granița, în care veți moșteni țara conform cu cele douăsprezece triburi ale lui Israel; Iosif [va avea două] părți.
Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ̀nyí ni àwọn ààlà tí ìwọ yóò fi pín ilẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí ogún ìní ní àárín àwọn ẹ̀yà méjìlá Israẹli, pẹ̀lú ìpín méjì fún Josẹfu.
14 Și o veți moșteni, unul ca și celălalt, [referitor] la ea mi-am ridicat mâna pentru a o da părinților voștri; și această țară vă va cădea ca moștenire.
Ìwọ yóò pín ilẹ̀ náà déédé ní àárín wọn. Nítorí pé mo búra nípa nína ọwọ́ sókè láti fi fún àwọn baba ńlá yin, ilẹ̀ yìí yóò di ogún ìní yín.
15 Și acesta [va fi] granița țării spre latura de nord, de la marea cea mare, calea Hetlonului, precum se merge la Țedad;
“Èyí yìí ni yóò jẹ́ ààlà ilẹ̀ náà: “Ní ìhà àríwá yóò lọ láti omi Òkun ńlá ní ibi ọ̀nà Hetiloni gbà tí Hamati lọ sí Sedadi,
16 Hamat, Berota, Sibraim, care [este] între granița Damascului și granița Hamatului; Hațer-Haticon, care [este] lângă ținutul Hauranului.
Berota àti Sibraimu, èyí tí ó wà ní ààlà láàrín Damasku àti Hamati títí dé Hasari Hatikonu, èyí tí ó wà ní agbègbè Haurani.
17 Și granița de la mare va fi Hațar-Enon, granița Damascului și la nord spre nord și granița Hamatului. Aceasta [este] latura de nord.
Ààlà yóò fẹ̀ láti Òkun lọ sí Hasari Enanu, ní apá ààlà ti Damasku, pẹ̀lú ààlà tí Hamati lọ sí apá àríwá. Èyí ni yóò jẹ́ ààlà ní apá ìhà àríwá.
18 Și latura de est să o măsurați de la Hauran și de la Damasc și de la Galaad și de la țara lui Israel, [lângă] Iordan, de la graniță până la marea de est. Și [aceasta este] latura de est.
Ní ìhà ìlà-oòrùn ààlà yóò wá sí àárín Haurani àti Damasku, lọ sí apá Jordani láàrín Gileadi àti ilẹ̀ Israẹli, títí dé Òkun, àti títí dé Tamari. Èyí ní yóò jẹ́ ààlà ìlà-oòrùn.
19 Și latura de sud spre sud, de la Tamar până la apele certei [în] Cades, râul până la marea cea mare. Și a[ceasta este] latura de sud spre sud.
Ní ìhà gúúsù yóò lọ láti Tamari títí dé ibi omi Meriba Kadeṣi, lẹ́yìn náà ni ìhà Wadi tí Ejibiti lọ sí Òkun ńlá. Èyí ni yóò jẹ́ ààlà gúúsù.
20 Latura de vest de asemenea [va fi] marea cea mare de la graniță, precum vine cineva în fața Hamatului. Aceasta [este] latura de vest.
Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, Òkun ńlá ni yóò jẹ́ ààlà títí dé ibi kan ni òdìkejì lẹ́bàá Hamati. Èyí yìí ni yóò jẹ ààlà ìhà ìwọ̀-oòrùn.
21 Astfel să împărțiți această țară între voi conform cu triburile lui Israel.
“Ìwọ ní láti pín ilẹ̀ yìí ní àárín ara yín gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà Israẹli.
22 Și se va întâmpla, [că] o veți împărți prin sorț ca moștenire, vouă și străinilor, care locuiesc temporar în mijlocul vostru, care vor naște copii printre voi; și ei să vă fie ca născuți în țară printre copiii lui Israel; ei să aibă moștenire cu voi printre triburile lui Israel.
Ìwọ yóò pín gẹ́gẹ́ bí ìní fún ara yín àti fún àwọn àjèjì tí ó ń gbé ní àárín yín tí ó sì ní àwọn ọmọ. Ìwọ yóò sì ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí ọmọ ìbílẹ̀ àwọn ará Israẹli; papọ̀ mọ́ yin ni kí ẹ pín ìní fún wọn ní àárín àwọn ẹ̀yà Israẹli.
23 Și se va întâmpla [că, ] în tribul în care străinul locuiește temporar, acolo să [îi] dați moștenirea lui, spune Domnul DUMNEZEU.
Ní àárín gbogbo ẹ̀yà tí àwọn àlejò ń gbé; wọn gbọdọ̀ fi ìní tirẹ̀ fún un,” ní Olúwa Olódùmarè wí.

< Ezechiel 47 >