< Ezechiel 32 >

1 Și s-a întâmplat [că], în al doisprezecelea an, în luna a douăsprezecea, în [ziua] întâia a lunii, cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kejìlá, ọdún kejìlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Fiu al omului, înalță o plângere pentru Faraon, împăratul Egiptului, și spune-i: Ești asemenea unui leu tânăr al națiunilor și ca o balenă în mări; și înaintai cu râurile tale și tulburai apele cu picioarele tale și le murdăreai râurile.
“Ọmọ ènìyàn, ṣe ìpohùnréré ẹkún nítorí Farao ọba Ejibiti kí o sì wí fún un: “‘Ìwọ dàbí kìnnìún láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà; ìwọ dàbí ohun ẹ̀mí búburú inú àwọn omi okun to ń lọ káàkiri inú àwọn odò rẹ, ìwọ fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ omi láti mú kí àwọn odò ní ẹrẹ̀.
3 Astfel spune Domnul DUMNEZEU: De aceea îmi voi întinde plasa peste tine cu o ceată de multe popoare și ele te vor trage în plasa mea.
“‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ìpéjọ ènìyàn èmi yóò da àwọ̀n mi bò ọ́ wọn yóò sì fà ọ́ sókè nínú àwọ̀n mi.
4 Atunci te voi lăsa pe pământ, te voi arunca în câmp deschis și voi face toate păsările cerului să rămână pe tine și voi sătura fiarele întregului pământ cu tine.
Èmi yóò jù ọ́ sí orí ilẹ̀ èmi yóò sì fà ọ́ sókè sí orí pápá gbangba. Èmi yóò jẹ́ kí gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ní orí rẹ. Gbogbo àwọn ẹranko ayé yóò fi ìwọra gbé ara wọn lórí rẹ.
5 Și voi pune carnea ta pe munți și voi umple văile cu înălțimea ta.
Èmi yóò tan ẹran-ara rẹ ká sórí àwọn òkè gíga ìyókù ara rẹ ní wọn yóò fi kún àwọn àárín àwọn òkè gíga.
6 De asemenea voi uda cu sângele tău, până la munți, țara în care înoți; și râurile vor fi pline de tine.
Ẹ̀jẹ̀ rẹ ti ń sàn ní èmi yóò sì fi rin ilẹ̀ náà gbogbo ọ̀nà sí orí àwọn òkè gíga, àwọn àlàfo jíjìn ní wọn yóò kún fún ẹran-ara rẹ.
7 Și când te voi stinge, voi acoperi cerul și îi voi întuneca stelele; voi acoperi soarele cu un nor și luna nu își va da lumina.
Nígbà tí mo bá fọ́n ọ jáde, èmi yóò pa ọ̀run dé àwọn ìràwọ̀ wọn yóò sì ṣókùnkùn; èmi yóò sì fi ìkùùkuu bo oòrùn òṣùpá kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀ rẹ̀.
8 Pe toți luminătorii strălucitori ai cerului îi voi întuneca deasupra ta și voi pune întuneric peste țara ta, spune Domnul DUMNEZEU.
Gbogbo ìmọ́lẹ̀ títàn ní ojú ọ̀run ni èmi yóò mú ṣókùnkùn lórí rẹ; èmi yóò mú òkùnkùn wá sórí ilẹ̀ rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 De asemenea voi chinui inimile multor popoare, când voi aduce nimicirea ta printre națiuni, în țările pe care nu le-ai cunoscut.
Èmi yóò da ọkàn ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn rú nígbà tí mo bá mú ìparun rẹ wá ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò í tí ì mọ̀.
10 Da, voi face pe multe popoare să fie uimite de [starea] ta și împărații lor vor fi groaznic înfricoșați din cauza ta, când îmi voi învârti sabia înaintea lor; și vor tremura în [fiecare] clipă, fiecare om pentru viața lui, în ziua căderii tale.
Èmi yóò mú kí ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn dẹ́rùbà ọ́, àwọn ọba wọn yóò sì wárìrì fún ìbẹ̀rù pẹ̀lú ìpayà nítorí rẹ, nígbà tí mo bá ju idà mi ní iwájú wọn. Ní ọjọ́ ìṣubú rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú wọn yóò wárìrì ní gbogbo ìgbà fún ẹ̀mí rẹ.
11 Pentru că astfel spune Domnul DUMNEZEU: Sabia împăratului Babilonului va veni asupra ta.
“‘Nítorí èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Idà ọba Babeli yóò wá sí orí rẹ,
12 Prin săbiile celor puternici voi face mulțimea ta să cadă, pe tiranii națiunilor, pe toți; și vor prăda fastul Egiptului și toată mulțimea lui va fi nimicită.
Èmi yóò mú kí ìjọ ènìyàn rẹ kí ó tí ipa idà àwọn alágbára ènìyàn ṣubú àwọn orílẹ̀-èdè aláìláàánú jùlọ. Wọn yóò tú ìgbéraga Ejibiti ká, gbogbo ìjọ rẹ ní a yóò dá ojú wọn bolẹ̀.
13 Și voi nimici toate animalele lui de lângă apele cele mari; nici picior de om nu le va mai tulbura, nici copitele animalelor nu le vor tulbura.
Gbogbo ẹran ọ̀sìn rẹ ni èmi yóò parun ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kì i ṣe ẹsẹ̀ ènìyàn ní yóò tẹ ibẹ̀ ẹsẹ̀ ẹran ọ̀sìn kì yóò sì mú kí ibẹ̀ ni ẹrọ̀fọ̀.
14 Atunci le voi adânci apele și voi face râurile lor să curgă precum untdelemnul, spune Domnul DUMNEZEU.
Lẹ́yìn náà èmi yóò mú kí omi rẹ̀ tòrò kí àwọn odò rẹ̀ kí o sàn bí epo, ni Olúwa Olódùmarè wí.
15 Când voi pustii țara Egiptului, iar țara va fi lipsită de ceea ce o umplea, când voi lovi pe toți cei care locuiesc în ea, atunci vor cunoaște că eu [sunt] DOMNUL.
Nígbà tí mo bá sọ Ejibiti di ahoro, tí mo sì kó gbogbo ohun tí ó wà ní orí ilẹ̀ náà kúrò. Nígbà tí mo bá gé àwọn olùgbé ibẹ̀ lulẹ̀, nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
16 Aceasta [este] plângerea cu care îl vor plânge; fiicele națiunilor îl vor plânge; vor plânge pentru el, pentru Egipt și pentru toată mulțimea lui, spune Domnul DUMNEZEU.
“Èyí yìí ni ẹkún tí a yóò sun fún un. Àwọn ọmọbìnrin orílẹ̀-èdè yóò sun ún; nítorí Ejibiti àti gbogbo ìjọ rẹ, wọn yóò sun ún, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
17 S-a întâmplat de asemenea [că], în al doisprezecelea an, în a cincisprezecea [zi] a lunii, cuvântul DOMNULUI a venit la mine, spunând:
Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù, ọdún kejìlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mí wá:
18 Fiu al omului, bocește pentru mulțimea Egiptului și aruncă-le jos, pe ea și pe fiicele națiunilor faimoase, în părțile de jos ale pământului, cu cei ce coboară în groapă.
“Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún lórí Ejibiti kí o sì ránṣẹ́ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀ àti òun àti àwọn ọmọbìnrin orílẹ̀-èdè alágbára, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ìsàlẹ̀, kòtò.
19 Pe cine întreci tu în frumusețe? Coboară și culcă-te cu cei necircumciși.
Sọ fún wọn, ‘Ǹjẹ́ ìwọ ní ojúrere jù àwọn tí o kù lọ? Lọ sí ìsàlẹ̀ kí a sì tẹ́ ọ sí àárín àwọn aláìkọlà náà.’
20 Ei vor cădea în mijlocul celor uciși de sabie; ea este dată sabiei; trageți-o afară, pe ea și toate mulțimile ei.
Wọn yóò ṣubú láàrín àwọn tí a fi idà pa. A fa idà yọ; jẹ́ kí a wọ́ Ejibiti kúrò pẹ̀lú gbogbo ìjọ rẹ̀.
21 Cei tari printre puternici vor vorbi cu el din mijlocul iadului cu cei care îl ajută; ei au coborât, zac necircumciși, uciși de sabie. (Sheol h7585)
Láti inú isà òkú alágbára tí í ṣe aṣáájú yóò sọ nípa Ejibiti àti àwọn àlejò rẹ̀, ‘Wọn ti wá sí ìsàlẹ̀, wọn sì sùn pẹ̀lú aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa.’ (Sheol h7585)
22 Așurul [este] acolo și toată ceata lui; mormintele lor [sunt] în jurul său; cu toți cei uciși, căzuți prin sabie;
“Asiria wà níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo jagunjagun rẹ̀; àwọn isà òkú àwọn tí a ti pa sì yí i ká, gbogbo àwọn tí ó ti ipa idà ṣubú.
23 Al căror morminte sunt puse în laturile gropii, iar ceata lui este de jur împrejurul mormântului său; cu toții uciși, căzuți prin sabie, care cauzau teroarea în țara celor vii.
Isà òkú wọn wà ní ibi tí ó jinlẹ̀ gan an nínú kòtò. Gbogbo àwọn tí ó ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè ní a pa, tí ó ti ipa idà ṣubú.
24 Acolo [este] Elamul și toată mulțimea lui de jur împrejurul mormântului său, cu toții uciși, căzuți prin sabie; care au coborât necircumciși în părțile de jos ale pământului, care aduceau teroarea lor în țara celor vii; totuși ei și-au purtat rușinea cu cei care coboară în groapă.
“Elamu wà níbẹ̀, o yí isà òkú rẹ̀ ká pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀. Gbogbo wọn ni a pa, àwọn tí ó ti ipa idà ṣubú. Gbogbo àwọn tí ó ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè lọ sí ìsàlẹ̀ láìkọlà sí abẹ́ ilẹ̀. Wọ́n gba ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò.
25 Ei i-au pus un pat în mijlocul celor uciși cu toată mulțimea lui; mormintele lor [sunt] de jur împrejurul lui; cu toții necircumciși, uciși de sabie; deși groaza de ei a cuprins țara celor vii, totuși și-au purtat rușinea cu cei care coboară în groapă; el este pus în mijlocul celor uciși.
A ṣe ibùsùn fún un láàrín àwọn tí a pa, pẹ̀lú gbogbo ìjọ rẹ̀ tí ó yí isà òkú ká. Gbogbo wọn jẹ́ aláìkọlà, tí a fi idà pa. Nítorí pé a tan ẹ̀rù wọn ká ilẹ̀ alààyè, wọn ru ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò; a tẹ́ wọn pẹ̀lú àwọn tí a pa.
26 Acolo [este] Meșec, Tubal și toată mulțimea lui, mormintele lor [sunt] de jur împrejurul lui; cu toții necircumciși, uciși de sabie, deși groaza de ei a cuprins țara celor vii.
“Meṣeki àti Tubali wà níbẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ogun wọn yí isà òkú wọn ká. Gbogbo wọn jẹ́ aláìkọlà, wọ́n fi idà pa wọ́n nítorí ẹ̀rù tiwọn tàn ká ilẹ̀ alààyè.
27 Și nu se vor culca cu cei puternici, căzuți dintre cei necircumciși, care au coborât în iad cu armele lor de război; și ei și-au pus săbiile sub capetele lor, dar nelegiuirile lor vor fi asupra oaselor lor, deși [ei erau] groaza celor puternici în țara celor vii. (Sheol h7585)
Wọn kì yóò sì dùbúlẹ̀ ti àwọn tí ó ṣubú nínú àwọn aláìkọlà, tí wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí ipò òkú pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun wọn, wọ́n tí fi idà wọn rọ orí wọn. Ṣùgbọ́n àìṣedéédéé wọn yóò wà ní orí egungun wọn—bí wọ́n tilẹ̀ jẹ́ ẹ̀rù àwọn alágbára ní ilẹ̀ alààyè. (Sheol h7585)
28 Da, vei fi frânt în mijlocul celor necircumciși și te vei culca cu cei uciși cu sabia.
“Ìwọ náà, Farao, ní yóò ṣẹ, ti yóò dùbúlẹ̀ láàrín aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa.
29 Acolo [este] Edomul, împărații lui și toți prinții lui, care cu puterea lor, sunt puși lângă cei uciși de sabie; se vor culca împreună cu cei necircumciși și cu cei care coboară în groapă.
“Edomu wà níbẹ̀, àwọn ọba rẹ̀ àti gbogbo ọmọbìnrin ọba; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ní agbára, a tẹ́ wọn pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. Wọn dùbúlẹ̀ pẹ̀lú aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn ti o lọ sínú kòtò.
30 Acolo [sunt] prinții nordului, cu toții, și toți sidonienii care au coborât cu cei uciși; cu groaza lor ei sunt rușinați de puterea lor, și zac necircumciși cu cei uciși de sabie și își poartă rușinea cu cei care coboară în groapă.
“Gbogbo àwọn ọmọ-aládé ilẹ̀ àríwá àti gbogbo àwọn ará Sidoni wà níbẹ̀; wọn lọ sí ìsàlẹ̀ pẹ̀lú àwọn tí a pa ní ìtìjú, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn ṣe okùnfà ẹ̀rù pẹ̀lú agbára wọn. Wọn sùn ní àìkọlà pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa, wọn sì ru ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò.
31 Faraon îi va vedea și va fi mângâiat pentru toată mulțimea lui, Faraon și toată armata lui, uciși de sabie, spune Domnul DUMNEZEU.
“Farao, òun àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ yóò rí wọn, a yóò sì tù ú nínú nítorí gbogbo ogun rẹ̀ tí a fi idà pa, ní Olúwa Olódùmarè wí.
32 Pentru că am adus groaza mea în țara celor vii; și el se va culca în mijlocul celor necircumciși, cu cei uciși de sabie, Faraon și toată mulțimea lui, spune Domnul DUMNEZEU.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè, Farao àti gbogbo ogun rẹ̀ ni a yóò tẹ́ sí àárín aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa ní Olúwa Olódùmarè wí.”

< Ezechiel 32 >