< Deuteronomul 13 >
1 Dacă se ridică printre voi un profet sau un visător de vise şi îţi dă un semn sau o minune,
Bí wòlíì tàbí alásọtẹ́lẹ̀ nípa àlá lílá bá farahàn láàrín yín, tí ó sì ń kéde iṣẹ́ àmì tàbí iṣẹ́ ìyanu,
2 Şi se întâmplă semnul sau minunea despre care ţi-a vorbit, spunând: Să mergem după alţi dumnezei, pe care nu i-ai cunoscut şi să le servim,
bí iṣẹ́ àmì tàbí iṣẹ́ ìyanu tí ó sọ̀rọ̀ rẹ̀ bá ṣẹ tí òun sì wí pé, “ẹ wá ẹ jẹ́ kí a tẹ̀lé ọlọ́run mìíràn” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀ rí) “kí ẹ sì jẹ́ kí a máa sìn wọ́n,”
3 Să nu dai ascultare la cuvintele acelui profet sau acelui visător de vise, pentru că DOMNUL Dumnezeul vostru vă încearcă, pentru a şti dacă îl iubiţi pe DOMNUL Dumnezeul vostru cu toată inima voastră şi cu tot sufletul vostru.
ẹ má fetí sí ọ̀rọ̀ wòlíì tàbí àlá náà, Olúwa Ọlọ́run yín ń dán an yín wò ni, láti mọ̀ bóyá ẹ fẹ́ràn rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àyà yín àti gbogbo ọkàn an yín.
4 Voi să umblaţi după DOMNUL Dumnezeul vostru şi să vă temeţi de el şi să păziţi poruncile lui şi să ascultaţi de vocea lui şi să îi serviţi şi să vă alipiţi de el.
Olúwa Ọlọ́run yín ni kí ẹ tẹ̀lé, Òun ni kí ẹ bu ọlá fún, ẹ pa òfin rẹ̀ mọ́ kí ẹ sì gbọ́ tirẹ̀, ẹ sìn ín, kí ẹ sì dìímú ṣinṣin.
5 Şi acel profet, sau acel visător de vise să fie ucis, deoarece a vorbit ca să vă întoarcă de la DOMNUL Dumnezeul vostru, care v-a scos din ţara Egiptului şi v-a răscumpărat din casa robiei, ca să te depărteze de pe calea pe care ţi-a poruncit DOMNUL Dumnezeul tău să umbli pe ea. Astfel să îndepărtezi răul din mijlocul tău.
Wòlíì náà tàbí alálàá náà ni kí ẹ pa, nítorí pé wàásù ìṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó mú yín jáde láti Ejibiti wá, tí ó sì rà yín padà lóko ẹrú. Ó ti gbìyànjú láti fà yín kúrò lójú ọ̀nà tí Olúwa Ọlọ́run yín ti pàṣẹ fún un yín láti máa rìn. Ẹ gbọdọ̀ yọ ibi náà kúrò láàrín yín.
6 Dacă fratele tău, fiul mamei tale sau fiul tău sau fiica ta sau soţia sânului tău sau prietenul tău, care îţi este ca sufletul tău, te ademeneşte în secret, spunând: Să mergem şi să servim altor dumnezei, pe care nu i-ai cunoscut nici tu, nici părinţii tăi;
Bí arákùnrin tìrẹ gan an ọmọ ìyá rẹ tàbí ọmọ rẹ ọkùnrin tàbí obìnrin, aya tí o fẹ́ràn jù, tàbí ọ̀rẹ́ tímọ́tímọ́ bá tàn ọ́ jẹ níkọ̀kọ̀ wí pé, “Jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn” (ọlọ́run tí ìwọ tàbí baba rẹ kò mọ̀,
7 Adică, dintre dumnezeii poporului care este împrejurul vostru, aproape de tine sau departe de tine, de la o margine a pământului chiar până la cealaltă margine a pământului;
ọlọ́run àwọn tí ó wà láyìíká yín, yálà wọ́n jìnnà tàbí wọ́n wà nítòsí, láti òpin ilẹ̀ kan dé òmíràn),
8 Să nu te învoieşti cu el şi să nu îi dai ascultare, nici ochiul tău să nu îl compătimească, nici să nu îl cruţi, nici să nu îl ascunzi,
má ṣe fetí sí i, má sì dá sí i, má ṣe dáàbò bò ó.
9 Ci să îl ucizi; mâna ta să fie cea dintâi asupra lui ca să îl ucizi şi pe urmă mâna întregului popor.
Ṣùgbọ́n pípa ni kí o pa á. Ọwọ́ rẹ ni yóò kọ́kọ́ wà lára rẹ̀ láti pa á, lẹ́yìn náà ọwọ́ gbogbo ènìyàn.
10 Şi să îl ucizi cu pietre, ca să moară, pentru că a căutat să te îndepărteze de la DOMNUL Dumnezeul tău, care te-a scos din ţara Egiptului, din casa robiei.
Sọ ọ́ ní òkúta pa nítorí pé ó gbìyànjú láti fà ọ́ kúrò lẹ́yìn Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó mú ọ jáde ti Ejibiti wá kúrò ní oko ẹrú.
11 Şi tot Israelul să audă şi să se teamă şi să nu mai facă astfel de stricăciune, ca aceasta, printre voi.
Gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, kò sì sí ẹnikẹ́ni nínú yín tí yóò dán irú ibi bẹ́ẹ̀ wò mọ́.
12 Dacă într-una din cetăţile tale, pe care ţi le dă DOMNUL Dumnezeul tău, ca să locuieşti acolo, vei auzi spunându-se:
Bí ẹ̀yin bá gbọ́ tí a sọ nípa èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín láti máa gbé,
13 Anumiţi oameni, copiii lui Belial, au ieşit din mijlocul vostru şi au atras pe locuitorii cetăţii lor, spunând: Să mergem şi să servim altor dumnezei, pe care nu i-aţi cunoscut;
pé àwọn ènìyàn búburú, ti farahàn láàrín yín, tí ó sì ti mú kí àwọn ènìyàn ìlú wọn ṣìnà lọ, tí wọ́n wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn.” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀.)
14 Atunci să întrebi şi să faci cercetare şi să întrebi cu deamănuntul; şi, iată, dacă este adevărat şi lucrul este sigur, că această urâciune s-a făcut printre voi,
Kí ẹ wádìí, ẹ béèrè, kí ẹ sì tọpinpin ọ̀rọ̀ náà dájúṣáká, bí ó bá jẹ́ òtítọ́ ni, tí ó sì hàn dájú pé ìwà ìríra yìí ti ṣẹlẹ̀ láàrín yín.
15 Să loveşti pe locuitorii acelei cetăţi cu ascuţişul sabiei, distrugând-o în întregime şi tot ce este în ea şi vitele ei, cu ascuţişul sabiei.
Gbogbo àwọn tí ó ń gbé ìlú náà ni kí ẹ fi idà run pátápátá. Ẹ run ún pátápátá, àti ènìyàn àti ẹran ọ̀sìn inú rẹ̀.
16 Şi să aduni toată prada ei în mijlocul străzii ei şi să arzi cu foc cetatea şi toată prada ei în întregime, pentru DOMNUL Dumnezeul tău şi ea să fie o movilă pentru totdeauna, să nu se mai construiască din nou.
Ẹ kó gbogbo ìkógun ìlú náà, sí àárín gbogbo ènìyàn, kí ẹ sun ìlú náà àti gbogbo ìkógun rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Ó gbọdọ̀ wà ní píparun láéláé, ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ tún un kọ.
17 Şi nimic din lucrul blestemat să nu se lipească de mâna ta, ca DOMNUL să se întoarcă din înverşunarea furiei sale şi să îţi arate milă şi să aibă compasiune de tine şi să te înmulţească, precum a jurat părinţilor tăi;
A kò gbọdọ̀ rí ọ̀kan nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun wọ̀n-ọn-nì lọ́wọ́ yín, kí Olúwa ba à le yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀, yóò sì ṣàánú fún un yín, yóò sì bá a yín kẹ́dùn, yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i, bí ó ti fì búra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá yín.
18 Când vei da ascultare la vocea DOMNULUI Dumnezeul tău, ca să păzeşti toate poruncile lui pe care ţi le poruncesc astăzi, ca să faci ce este drept în ochii DOMNULUI Dumnezeul tău.
Nítorí pé ẹ̀yin gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ̀yin sì ń pa òfin rẹ̀ mọ́, tí mo ń fún un yín lónìí yìí, tí ẹ̀yin sì ń ṣe ohun tí ó tọ́ lójú rẹ̀.