< Amós 8 >

1 Assim o Senhor Javé me mostrou: eis que uma cesta de frutas de verão.
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mi: agbọ̀n èso pípọ́n.
2 Ele disse: “Amos, o que você vê?” Eu disse: “Uma cesta de frutas de verão”. Então Yahweh me disse, “O fim chegou ao meu povo Israel”. Não vou mais passar por eles.
Ó béèrè pé, “Amosi kí ni ìwọ rí.” Mo sì dáhùn pé, “Agbọ̀n èso pípọ́n.” Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Àsìkò náà pọ́n tó fún àwọn ènìyàn mi Israẹli; Èmi kì yóò dá wọn sí mọ́.”
3 As canções do templo estarão lamentando naquele dia”, diz o Senhor Javé. “Os cadáveres serão muitos. Em todos os lugares, eles os expulsarão em silêncio.
Olúwa Olódùmarè wí pé, “Ní ọjọ́ náà, àwọn orin tẹmpili yóò yí padà sí ohùn réré ẹkún. Ọ̀pọ̀, àní ọ̀pọ̀ ara òkú ni yóò wà ni ibi gbogbo! Àní ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́!”
4 Ouça isto, você que deseja engolir os necessitados, e causar o fracasso dos pobres da terra,
Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí ń tẹ aláìní lórí ba, tí ẹ sì ń sọ tálákà di ilẹ̀.
5 dizendo: 'Quando a lua nova vai desaparecer, para que possamos vender grãos? E o Sabbath, para que possamos comercializar trigo, tornando a efah pequena, e o shekel grande, e lidar falsamente com equilíbrios de enganos;
Tí ẹ ń wí pé, “Nígbà wo ni oṣù tuntun yóò parí kí àwa bá à lè ta ọkà kí ọjọ́ ìsinmi kí ó lè dópin kí àwa bá à le ta jéró?” Kí a sì dín ìwọ̀n wa kù kí a gbéraga lórí iye tí a ó tà á kí a sì fi òsùwọ̀n èké yàn wọ́n jẹ,
6 para que possamos comprar os pobres por prata, e os necessitados por um par de sandálias, e vender as varreduras com o trigo”...
kí àwa lè fi fàdákà ra àwọn tálákà, kí a sì fi bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì ra aláìní, kí a sì ta jéró tí a kó mọ́ ilẹ̀.
7 Yahweh jurou pelo orgulho de Jacob, “Certamente nunca vou esquecer nenhuma de suas obras.
Olúwa ti fi ìgbéraga Jakọbu búra pé, “Èmi kì yóò gbàgbé ọ̀kan nínú ohun tí wọ́n ṣe.
8 A terra não vai tremer por isso, e todos lamentam quem nela habita? Sim, ele se erguerá totalmente como o rio; e será agitado e afundará novamente, como o rio do Egito.
“Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kì yóò ha wárìrì fún èyí? Àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ kì yóò ha ṣọ̀fọ̀? Gbogbo ilẹ̀ yóò ru sókè bí omi Naili, yóò sì ru ú sókè pátápátá bí ìkún omi a ó sì tì í jáde, a ó sì tẹ̀ ẹ́ rì gẹ́gẹ́ bí odò Ejibiti.
9 Isso acontecerá naquele dia”, diz o Senhor Yahweh, “que farei com que o sol se ponha ao meio-dia”, e eu escurecerei a terra no dia claro.
“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò mú oòrùn wọ̀ ní ọ̀sán, Èmi yóò mú kí ayé ṣókùnkùn ní ọ̀sán gangan.
10 Vou transformar suas festas em luto, e todas as suas canções em lamentações; e farei você usar pano de saco em todos os seus corpos, e calvície em cada cabeça. Vou fazer com que seja como o luto por um filho único, e seu fim como um dia amargo.
Èmí yóò yí àsè ẹ̀sìn yín padà sí ọ̀fọ̀, gbogbo orin yín ni èmi yóò sọ di ẹkún. Èmi yóò mú kí gbogbo yín wọ aṣọ ọ̀fọ̀, kí a sì fá orí yín. Èmi yóò mú kí ìgbà náà rí bí ìṣọ̀fọ̀ fún ọmọkùnrin kan ṣoṣo tí a bí àti òpin rẹ̀ bí ọjọ́ kíkorò.
11 Eis que os dias vêm”, diz o Senhor Yahweh, “que eu enviarei uma fome na terra, não uma fome de pão, nem sede de água, mas de ouvir as palavras de Yahweh.
“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “nígbà tí èmi yóò rán ìyàn sí ilẹ̀ náà, kì í ṣe ìyàn oúnjẹ tàbí òǹgbẹ fún omi. Ṣùgbọ́n ìyàn gbígbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 Eles vagarão de mar a mar, e do norte até mesmo para o leste; eles correrão para trás e para frente em busca da palavra de Javé, e não o encontrará.
Àwọn ènìyàn yóò rìn kiri láti Òkun dé Òkun wọn yóò sì máa rìn ká láti gúúsù sí àríwá, wọn yóò máa wá ọ̀rọ̀ Olúwa ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí i.
13 Naquele dia as belas virgens e os jovens vão desmaiar de sede.
“Ní ọjọ́ náà “àwọn arẹwà wúńdíá àti àwọn alágbára ọ̀dọ́mọkùnrin yóò dákú fún òǹgbẹ omi.
14 Those que juram pelo pecado de Samaria, e dizer: 'Como seu deus, Dan, vive'. e, “Como o caminho de Beersheba vive, eles cairão, e nunca mais se levantarão”.
Àwọn tí ó fi ẹ̀ṣẹ̀ Samaria búra, tí wọ́n sì wí pé, ‘Bí ó ti dájú pé ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Dani,’ bí ó ti dájú pè ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Beerṣeba, wọ́n yóò ṣubú, wọn kì yóò si tún dìde mọ.”

< Amós 8 >