< Psalmów 79 >
1 Psalm Asafa. Boże, poganie wtargnęli do twego dziedzictwa, splugawili twoją świętą świątynię, Jeruzalem zamienili w ruiny.
Saamu ti Asafu. Ọlọ́run, àwọn orílẹ̀-èdè ti wá ilẹ̀ ìní rẹ; wọ́n ti ba tẹmpili mímọ́ rẹ jẹ́, wọn di Jerusalẹmu kù sí òkìtì àlàpà.
2 Zwłoki twoich sług dali na żer ptactwu niebieskiemu, ciała twoich świętych bestiom ziemskim.
Wọn ti fi ara òkú àwọn ìránṣẹ́ rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ní oúnjẹ, ẹran-ara àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ fún ẹranko ilẹ̀.
3 Rozlali ich krew jak wodę wokół Jeruzalem i nie było nikogo, kto by ich pogrzebał.
Wọ́n tu ẹ̀jẹ̀ jáde gẹ́gẹ́ bí omi yí Jerusalẹmu ká, kò sì ṣí àwọn tí yóò sìn wọ́n.
4 Staliśmy się hańbą dla naszych sąsiadów, pośmiewiskiem i drwiną dla tych, którzy są wokoło nas.
Àwa di ohun ẹ̀gàn sí àwọn tí ó yí wa ká, àbùkù àti ìfiṣe ẹlẹ́yà sí àwọn tí ó yí wa ká.
5 Jak długo, PANIE? Czy wiecznie będziesz się gniewać? Czy twoja zapalczywość będzie płonąć jak ogień?
Nígbà wo, Olúwa? Ní ìwọ ó máa bínú títí láé? Yóò ti pẹ́ tó ti owú rẹ yóò ha jò bí iná?
6 Wylej twój gniew na pogan, którzy cię nie znają, i na królestwa, które nie wzywają twego imienia.
Tú ìbínú rẹ jáde sí orílẹ̀-èdè tí kò ní ìmọ̀ rẹ, lórí àwọn ìjọba tí kò pe orúkọ rẹ;
7 Pożarli bowiem Jakuba i spustoszyli jego mieszkanie.
nítorí wọ́n ti run Jakọbu wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ di ahoro.
8 Nie pamiętaj nam dawnych nieprawości naszych, niech nas prędko spotka twoje miłosierdzie, bo jesteśmy bardzo wynędzniali.
Má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba wa sí wa lọ́rùn jẹ́ kí àánú rẹ wá kánkán láti bá wa, nítorí tí a rẹ̀ wá sílẹ̀ gidigidi.
9 Wspomóż nas, Boże naszego zbawienia, dla chwały imienia twego; ocal nas i przebacz nam grzechy ze względu na twoje imię.
Ràn wá lọ́wọ́, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, fún ògo orúkọ rẹ; gbà wá kí o sì dárí ẹ̀ṣẹ̀ wa jì nítorí orúkọ rẹ.
10 Dlaczego poganie mają mówić: Gdzież jest ich Bóg? Niech będzie znany wśród pogan na naszych oczach przez dokonanie zemsty za przelaną krew twoich sług.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wí pé, “Níbo ni Ọlọ́run wọn wà?” Ní ojú wa, kí a mọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè kí ó sì gbẹ̀san àwọn ẹ̀jẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ tí a tú jáde.
11 Niech dotrze do ciebie jęk więźniów, według potęgi twego ramienia zachowaj skazanych na śmierć.
Jẹ́ kí ìmí ẹ̀dùn oǹdè náà wá síwájú rẹ, gẹ́gẹ́ bí títóbi agbára rẹ ìwọ ṣe ìtọ́jú àwọn ti a dá lẹ́bi ikú.
12 I odpłać naszym sąsiadom siedmiokrotnie w ich zanadrze za zniewagę, którą ci wyrządzili, Panie!
San án padà sí àyà àwọn aládùúgbò wa nígbà méje nípa ẹ̀gàn tí wọn ti gàn ọ́ Olúwa.
13 My zaś, twój lud i owce twego pastwiska, będziemy cię wielbić na wieki, będziemy głosić twoją chwałę z pokolenia na pokolenie.
Nígbà náà àwa ènìyàn rẹ, àti àgùntàn pápá rẹ, yóò fi ọpẹ́ fún ọ títí láé; láti ìran dé ìran ni àwa ó fi ìyìn rẹ hàn.