< Przysłów 1 >

1 Przysłowia Salomona, syna Dawida, króla Izraela;
Àwọn òwe ti Solomoni, ọmọ Dafidi, ọba Israẹli.
2 Do poznania mądrości i karności, do zrozumienia słów roztropnych;
Láti le ní ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́, láti ní òye àwọn ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀.
3 Do zdobycia pouczenia w mądrości, w sprawiedliwości, w sądzie i w prawości;
Láti gba ẹ̀kọ́ ọgbọ́n, òdodo, àti ìdájọ́, àti àìṣègbè;
4 Do udzielenia prostym rozwagi, a młodemu – wiedzy i roztropności.
láti fi òye fún onírẹ̀lẹ̀, ìmọ̀ àti ìṣọ́ra fún àwọn èwe.
5 Mądry posłucha i przybędzie mu wiedzy, a rozumny nabędzie rad;
Jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n tẹ́tí kí ó sì ní ìmọ̀ kún ìmọ̀, sì jẹ́ kí ẹni òye gba ìtọ́sọ́nà.
6 Aby rozumieć przysłowia i [ich] wykładnię, słowa mądrych i ich zagadki.
Láti mọ ìtumọ̀ òwe àti ìtán-dòwe, àwọn ọ̀rọ̀ àti àlọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n.
7 Bojaźń PANA jest początkiem wiedzy, ale głupcy gardzą mądrością i karnością.
Ìbẹ̀rù Olúwa ni ìbẹ̀rẹ̀ ìmọ̀, ṣùgbọ́n aláìgbọ́n kẹ́gàn ọgbọ́n àti ẹ̀kọ́.
8 Synu mój, słuchaj pouczenia swego ojca i nie odrzucaj nauki swojej matki;
Tẹ́tí, ìwọ ọmọ mi sí ẹ̀kọ́ baba rẹ, má ṣe kọ ẹ̀kọ́ màmá rẹ sílẹ̀.
9 Bo one będą wdzięczną ozdobą na twojej głowie i [kosztownym] łańcuchem na szyi.
Wọn yóò jẹ́ òdòdó ẹ̀yẹ olóòórùn dídùn lórí rẹ àti ọ̀ṣọ́ tí ó dára yí ọrùn rẹ ká.
10 Synu mój, jeśli grzesznicy cię namawiają, nie pozwalaj.
Ọmọ mi, bí àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ bá ń tàn ọ́, má ṣe gbà fún wọn.
11 Jeśli mówią: Chodź z nami, czyhajmy na krew, zaczajmy się na niewinnego bez powodu;
Bí wọn bá wí pé, “Wá pẹ̀lú wa; jẹ́ kí á ba ní ibùba fún ẹ̀jẹ̀ ẹnìkan, jẹ́ kí á lúgọ ní ìkọ̀kọ̀ de aláìṣẹ̀ ní àìnídìí;
12 Pożremy ich żywcem jak grób, całych, jak zstępujących do dołu; (Sheol h7585)
jẹ́ ká gbé wọn mì láààyè, bí ibojì òkú, àti lódidi, bí àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀ lọ sínú kòtò; (Sheol h7585)
13 Znajdziemy wszelkie kosztowności, napełnimy swoje domy łupem;
a ó rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ nǹkan tó níye lórí a ó sì fi ìkógun kún inú ilé wa,
14 Dziel z nami swój los; miejmy wszyscy jedną sakiewkę.
da ìpín rẹ pọ̀ mọ́ àárín wa, a ó sì jọ pawó sínú àpò kan náà,”
15 Synu mój, nie wyruszaj z nimi w drogę; powstrzymaj swoją nogę od ich ścieżki.
ọmọ mi, má ṣe bá wọn lọ, má ṣe rìn ní ojú ọ̀nà wọn.
16 Ich nogi bowiem biegną do zła i spieszą się do przelania krwi.
Nítorí ẹsẹ̀ wọn ń sáré sí ẹ̀ṣẹ̀, wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀.
17 Na próżno zastawia się sieci na oczach wszelkiego ptactwa.
Wàhálà asán ni kí ènìyàn máa dẹ àwọ̀n sílẹ̀, ní ojú ẹyẹ!
18 Oni też czyhają na własną krew, czają się na własne życie.
Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ń lúgọ fún ẹ̀jẹ̀ ara wọn. Ara wọn ni wọ́n ń dá lọ́nà.
19 Takie są ścieżki każdego, który jest chciwy zysku; swojemu właścicielowi [taki zysk] odbiera życie.
Báyìí ni ìgbẹ̀yìn gbogbo àwọn tí ń wá èrè àìtọ́; yóò mú ẹ̀mí gbogbo ẹni tí ó rí i lọ.
20 Mądrość woła na dworze, podnosi swój głos na ulicach.
Ọgbọ́n kígbe sókè ní pópó ó gbé ohùn rẹ̀ sókè láàrín ọjà;
21 Woła w największym zgiełku, u wrót bram, w mieście wygłasza swoje słowa:
láàrín ọjà ni ó ti kígbe jáde ní ibodè ìlú ni ó ti sọ̀rọ̀ ọ rẹ̀:
22 Jak długo, prości, będziecie kochać głupotę, szydercy – lubować się w swoim szyderstwie, a głupi – nienawidzić wiedzy?
“Yóò ha ti pẹ́ tó tí ẹ̀yin aláìmọ̀kan yóò fi fẹ́ àìmọ̀kan yín tó? Yóò ha ti pẹ́ tó tí àwọn ẹlẹ́gàn yóò ṣe inú dídùn sí ìpẹ̀gàn tó? Àwọn aláìgbọ́n kórìíra ìmọ̀?
23 Nawróćcie się na moje upomnienie; oto wyleję na was mojego ducha, oznajmię wam moje słowa.
Bí ẹ bá ti gbọ́ ìbáwí ì mi ni, ǹ bá ti tú ohun tí ó wà nínú ọkàn mi jáde fún yín kí n sì fi inú mi hàn sí i yín.
24 Ponieważ wołałam, a odmawialiście; wyciągałam rękę, a nikt nie zważał;
Ṣùgbọ́n níwọ̀n bí ẹ ti kọ ìpè ní ìgbà tí mo pè kò sì sí ẹni tí ó kọ ibi ara sí mi gbà tí mo na ọwọ́ sí wọn,
25 Owszem, odrzuciliście całą moją radę i nie chcieliście [przyjąć] mojego upomnienia;
níwọ́n bí ẹ ti kọ gbogbo ìmọ̀ràn mi, tí ẹ̀yin kò sì gba ìbáwí mi,
26 Dlatego będę się śmiać z waszego nieszczęścia, będę szydzić z was, gdy przyjdzie to, czego się boicie.
Èmi pẹ̀lú yóò fi ìdààmú yín rẹ́rìn-ín; èmi yóò ṣẹ̀fẹ̀ nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín.
27 Gdy nadejdzie jak spustoszenie to, czego się boicie, i [gdy] wasze nieszczęście nadciągnie jak wicher, gdy nadejdzie na was ucisk i cierpienie;
Nígbà tí ìyọnu bá dé bá a yín bí ìjì líle, nígbà tí ìdààmú bá dé bá ọ bí ààjà, nígbà tí wàhálà àti ìbànújẹ́ ọkàn bá bò ọ́ mọ́lẹ̀.
28 Wtedy będą mnie wzywać, a nie wysłucham; będą mnie szukać pilnie, lecz mnie nie znajdą.
“Nígbà náà ni wọn yóò ké pè mí ṣùgbọ́n, èmi kò ní dáhùn; wọn yóò fi ara balẹ̀ wá mi ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí mi.
29 Bo znienawidzili wiedzę i nie wybrali bojaźni PANA;
Níwọ́n bí wọ́n ti kórìíra ìmọ̀ tí wọ́n sì kọ̀ láti bẹ̀rù Olúwa.
30 Ani nie chcieli mojej rady, [ale] gardzili każdym moim upomnieniem.
Níwọ́n bí wọn kò ti gbà ìmọ̀ràn mi tí wọ́n sì kẹ́gàn ìmọ̀ràn mi,
31 Dlatego spożyją owoc swoich dróg i będą nasyceni swymi radami.
wọn yóò jẹ èrè iṣẹ́ ọwọ́ wọn wọn yóò sì jèrè èso ètè wọn ní kíkún.
32 Bo odstępstwo prostych zabije ich i szczęście głupich zgubi ich.
Nítorí ìrìnkurìn àwọn aláìmọ̀kan ni yóò pa wọ́n ìkáwọ́gbera aláìgbọ́n ni yóò pa á run;
33 [Ale] kto mnie słucha, będzie mieszkać bezpiecznie i będzie wolny od strachu przed złem.
ṣùgbọ́n ẹnìkan tí ó bá fetí sí mi, yóò gbé láìléwu yóò sì wà nínú ìdẹ̀ra, láìsí ìbẹ̀rù ìpalára.”

< Przysłów 1 >