< Hioba 7 >

1 Czy człowiekowi nie jest wyznaczony czas na ziemi? Czy jego dni [nie są] jak dni najemnika?
“Ṣé ìjà kò ha si fún ènìyàn lórí ilẹ̀? Ọjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kò ha dàbí ọjọ́ alágbàṣe?
2 Jak sługa pragnie cienia, jak najemnik oczekuje [zapłaty] za swoją pracę;
Bí ọmọ ọ̀dọ̀ tí máa ń kánjú bojú wo òjìji, àti bí alágbàṣe ti í kánjú wo ọ̀nà owó iṣẹ́ rẹ̀.
3 Tak moim udziałem są miesiące próżne, a przeznaczono mi noce bolesne.
Bẹ́ẹ̀ ni a mú mi ní ìbànújẹ́ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oṣù, òru ìdáni-lágara ni a sì là sílẹ̀ fún mi.
4 Gdy się kładę, mówię: Kiedy minie noc, abym mógł wstać? I jestem pełny niepokoju aż do świtu.
Nígbà ti mo dùbúlẹ̀, èmi wí pé, ‘Nígbà wo ni èmi ó dìde?’ Tí òru yóò sì kọjá, ó sì tó fún mi láti yí síyìn-ín yí sọ́hùn-ún, títí yóò fi di àfẹ̀mọ́júmọ́.
5 Moje ciało pokryte jest robactwem i strupami w prochu, moja skóra pęka i ropieje.
Kòkòrò àti ògúlùtu erùpẹ̀ ni á fi wọ̀ mi ni aṣọ, awọ ara mi bù, o sì di bíbàjẹ́.
6 Moje dni biegną szybciej niż czółenko tkackie i przemijają bez nadziei.
“Ọjọ́ mi yára jù ọkọ̀ ìhunṣọ lọ, o sì di lílò ní àìní ìrètí.
7 Pamiętaj, że moje życie [jest] wiatrem, moje oko już nie zobaczy dobra.
Háà! Rántí pé afẹ́fẹ́ ni ẹ̀mí mi; ojú mi kì yóò padà rí rere mọ́.
8 Oko, które mnie widziało, już mnie nie zobaczy. Twoje oczy [są zwrócone] na mnie, a mnie [już] nie ma.
Ojú ẹni tí ó rí mi, kì yóò rí mi mọ́; ojú rẹ̀ tẹ̀ mọ́ra mi, èmi kò sí mọ́.
9 [Jak] obłok się rozchodzi i przemija, tak ten, kto zstępuje do grobu, nie wraca. (Sheol h7585)
Bí ìkùùkuu tí i túká, tí í sì fò lọ, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń lọ sí ipò òkú tí kì yóò padà wa mọ́. (Sheol h7585)
10 Nie wróci już do swego domu ani nie pozna go już jego miejsce.
Kì yóò padà sínú ilé rẹ̀ mọ́, bẹ́ẹ̀ ní ipò rẹ̀ kì yóò mọ̀ ọn mọ́.
11 Dlatego nie mogę powstrzymać swoich ust, będę mówił w utrapieniu swego ducha, będę narzekał w goryczy swojej duszy.
“Nítorí náà èmi kì yóò pa ẹnu mi mọ́, èmi yóò máa sọ nínú ìrora ọkàn mi, èmi yóò máa ṣe ìráhùn nínú kíkorò ọkàn mi.
12 Czy jestem morzem albo wielorybem, że postawiłeś przy mnie straż?
Èmi a máa ṣe Òkun tàbí ẹ̀mí búburú, tí ìwọ fi ń yan olùṣọ́ tì mi?
13 Gdy mówię: Pocieszy mnie moje łóżko i moje posłanie ulży mojemu narzekaniu;
Nígbà tí mo wí pé, ibùsùn mi yóò tù mí lára, ìtẹ́ mi yóò mú ara mi fúyẹ́ pẹ̀lú.
14 Wtedy straszysz mnie snami i przerażasz mnie widzeniami;
Nígbà náà ni ìwọ fi àlá da yọ mi lénu bò mi, ìwọ sì fi ìran òru dẹ́rùbà mí.
15 Tak że moja dusza wybrałaby sobie uduszenie, raczej śmierć niż życie.
Bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mí yàn láti fún pa àti ikú ju kí ń wà láààyè ní ipò tí ara mí wà yìí lọ.
16 Uprzykrzyło mi się [życie], nie chcę żyć wiecznie. Zostaw mnie, bo moje dni są marnością.
O sú mi, èmi kò le wà títí: jọ̀wọ́ mi jẹ́, nítorí pé asán ni ọjọ́ mi.
17 Czym [jest] człowiek, że go tak wywyższasz i że zwracasz ku niemu swoje serce?
“Kí ni ènìyàn tí ìwọ o máa kókìkí rẹ̀? Àti tí ìwọ ìbá fi gbé ọkàn rẹ lé e?
18 Że nawiedzasz go każdego ranka i w każdej chwili doświadczasz?
Àti ti ìwọ ó fi máa wá í bẹ̀ ẹ́ wò ni òròòwúrọ̀, ti ìwọ o sì máa dán an wò nígbàkígbà!
19 Kiedy odwrócisz się ode mnie i zostawisz mnie, abym mógł przełknąć swoją ślinę?
Yóò ti pẹ́ tó kí ìwọ kí ó tó fi mí sílẹ̀ lọ, tí ìwọ o fi mí sílẹ̀ jẹ́ẹ́ títí èmi yóò fi lè dá itọ́ mi mì.
20 Zgrzeszyłem, cóż mam czynić, stróżu człowieka? Czemu mnie wziąłeś za cel, abym był sam dla siebie ciężarem?
Èmi ti ṣẹ̀, ki ní èmi ó ṣe sí ọ. Ìwọ Olùsójú ènìyàn? Èéṣe tí ìwọ fi fi mí ṣe àmì itasi níwájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni èmi sì di ẹrẹ̀ wíwo fún ọ?
21 Czemu nie przebaczysz mojego przestępstwa i nie zmażesz mojej nieprawości? Teraz bowiem położę się w prochu i [gdy] rano będziesz mnie szukał, nie będzie mnie.
Èéṣe tí ìwọ kò sì dárí ìrékọjá mi jìn, kí ìwọ kí ó sì mú àìṣedéédéé mi kúrò? Ǹjẹ́ nísinsin yìí ni èmi ìbá sùn nínú erùpẹ̀, ìwọ ìbá sì wá mi kiri ní òwúrọ̀, èmi kì bá tí sí.”

< Hioba 7 >