< Hioba 37 >
1 I drży z tego powodu moje serce, i wyrywa się ze swego miejsca.
“Àyà sì fò mi sí èyí pẹ̀lú, ó sì kúrò ní ipò rẹ̀.
2 Słuchajcie uważnie grzmotu jego głosu i dźwięku, który wychodzi z jego ust.
Fetísílẹ̀! Fetísílẹ̀, kí ẹ sì gbọ́ ìró ohùn rẹ̀, àti èyí tí ó ti ẹnu rẹ̀ jáde wá.
3 Pod całym niebem go wypuszcza, a jego błyskawicę – na krańce ziemi.
Ó ṣe ìlànà rẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ọ̀run gbogbo, mọ̀nàmọ́ná rẹ̀ ni ó sì jọ̀wọ́ rẹ̀ lọ́wọ́ dé òpin ilẹ̀ ayé.
4 Po niej huczy grzmot, grzmi głosem swojego majestatu, i nie powstrzymuje ich, gdy słychać jego głos.
Lẹ́yìn mọ̀nàmọ́ná ohùn kan fọ̀ ramúramù; ó sì fi ohùn ọláńlá rẹ̀ sán àrá. Òhun kì yóò sì dá àrá dúró, nígbà tí ó bá ń gbọ́ ohùn rẹ̀.
5 Bóg cudownie grzmi swoim głosem, czyni wielkie rzeczy, których nie możemy zrozumieć.
Ọlọ́run fi ohùn rẹ̀ sán àrá ní ọ̀nà ìyanu; ohùn ńlá ńlá ni í ṣe tí àwa kò le mọ̀.
6 Mówi bowiem do śniegu: Padaj na ziemię, a także do deszczu i do ulewy jego potęgi.
Nítorí tí ó wí fún yìnyín pé, ‘Ìwọ rọ̀ sílẹ̀ ayé,’ àti pẹ̀lú fún ọwọ́ òjò, ‘Fún òjò ńlá agbára rẹ̀.’
7 Pieczętuje rękę każdego człowieka, aby wszyscy ludzie poznali jego dzieło.
Ó fi èdìdì di ọwọ́ gbogbo ènìyàn kí gbogbo wọn kí ó lè mọ iṣẹ́ rẹ̀, ó sì tún dá olúkúlùkù ènìyàn dúró lẹ́nu iṣẹ́ rẹ̀.
8 Wtedy zwierzęta wchodzą do jaskini i zostają w swoich jamach.
Nígbà náà ní àwọn ẹranko wọ inú ihò lọ, wọn a sì wà ni ipò wọn.
9 Od południa przychodzi wicher, a zima od wiatrów północnych.
Láti ìhà gúúsù ni ìjì àjàyíká tí jáde wá, àti òtútù láti inú afẹ́fẹ́ ti tú àwọsánmọ̀ ká.
10 Swoim tchnieniem Bóg czyni lód i ścinają się szerokie wody.
Nípa ẹ̀mí Ọlọ́run a fi ìdí omi fún ni, ibú omi á sì súnkì.
11 Także wilgocią [ziemi] obciąża obłok, rozpędza chmurę swoim światłem.
Pẹ̀lúpẹ̀lú ó fi omi púpọ̀ mú àwọsánmọ̀ wúwo, a sì tú àwọsánmọ̀ ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ ká ara wọn.
12 One krążą według jego rady, aby czyniły wszystko, co rozkazuje na powierzchni okręgu ziemi.
Àwọn wọ̀nyí yí káàkiri nípa ìlànà rẹ̀, kí wọn kí ó lè ṣe ohunkóhun tí ó pàṣẹ fún wọn lórí ilẹ̀ ayé.
13 A on sprawia, że się pojawiają – czy to dla karania, czy dla swojej ziemi, czy dla [okazywania] miłosierdzia.
Ó mú àwọsánmọ̀ wá, ìbá ṣe fún ìkìlọ̀, tàbí omi wá sí ayé láti fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn.
14 Słuchaj tego uważnie, Hiobie; zastanów się i rozważ cudowne dzieła Boga.
“Jobu, dẹtí sílẹ̀ sí èyí; dúró jẹ́ẹ́ kí o sì ro iṣẹ́ ìyanu Ọlọ́run.
15 Czy wiesz, kiedy i [co] postanawia Bóg o tych sprawach albo kiedy rozjaśnia światło swej chmury?
Ṣe ìwọ mọ àkókò ìgbà tí Ọlọ́run ṣe wọ́n lọ́jọ̀, tí ó sì mú ìmọ́lẹ̀ àwọsánmọ̀ rẹ̀ dán?
16 Czy wiesz, jak wiszą chmury – cuda tego, który jest doskonały we wszelkiej wiedzy?
Ṣé ìwọ mọ ìgbà tí àwọsánmọ̀ í fò lọ, iṣẹ́ ìyanu ẹni tí ó pé ní ìmọ̀?
17 [Czy wiesz], jak twoje szaty się rozgrzewają, gdy on uspokaja ziemię wiatrem południowym?
Ìwọ ẹni ti aṣọ rẹ̀ ti máa n gbóná, nígbà tí ó fi atẹ́gùn ìhà gúúsù mú ayé dákẹ́.
18 Czy rozpościerałeś z nim niebiosa, [które są] trwałe i podobne do zwierciadła odlanego?
Ìwọ ha ba tẹ́ pẹpẹ ojú ọ̀run, tí ó dúró ṣinṣin, tí ó sì dàbí dígí tí ó yọ̀ dà?
19 Poucz nas, co mamy mu powiedzieć, [bo] nie możemy ułożyć słów z powodu ciemności.
“Kọ́ wa ní èyí tí a lè wí fún un; nítorí pé àwa kò le wádìí ọ̀rọ̀ náà nítorí òkùnkùn wa.
20 Czy należy go powiadomić, że przemawiam? [Przecież] jeśli ktoś przemówi, zostanie na pewno pożarty.
A ó ha wí fún un pé, èmi fẹ́ sọ̀rọ̀? Tàbí ẹnìkan lè wí pé, ìfẹ́ mi ni pé kí a gbé mi mì?
21 Teraz jednak [ludzie] nie mogą patrzyć na światło, gdy jaśnieje w chmurach, gdy wiatr przechodzi [i] rozprasza je.
Síbẹ̀ nísinsin yìí ènìyàn kò rí oòrùn tí ń dán nínú àwọsánmọ̀, ṣùgbọ́n afẹ́fẹ́ ń kọjá, a sì gbá wọn mọ́.
22 Od północy przychodzi [jakby] złoty [blask, ale] w Bogu jest straszliwy majestat.
Wúrà dídán ti inú ìhà àríwá jáde wá; lọ́dọ̀ Ọlọ́run ni ọláńlá ẹ̀rù ńlá wa.
23 On jest Wszechmocny, nie możemy go doścignąć. On jest wielki w potędze i sądzie i bogaty w sprawiedliwość. Nie uciska [nikogo].
Nípa ti Olódùmarè àwa kò le wádìí rẹ̀, ó rékọjá ní ipá; nínú ìdájọ́ àti títí bi òun kì í ba ẹ̀tọ́ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ òtítọ́ jẹ́.
24 Dlatego boją się go ludzie. On nie ma względu na żadnego, który jest mądry w sercu.
Nítorí náà ènìyàn ha máa bẹ̀rù rẹ̀, òun kì í ṣe ojú sájú ẹnikẹ́ni tí ó gbọ́n ní ayé?”