< Izajasza 7 >
1 Za czasów Achaza, syna Jotama, syna Uzjasza, króla Judy, wyruszył Resin, król Syrii, wraz z Pekachem, synem Remaliasza, królem Izraela, przeciw Jerozolimie, aby z nią walczyć, lecz nie mógł jej zdobyć.
Nígbà tí Ahasi ọmọ Jotamu ọmọ Ussiah jẹ́ ọba Juda, ọba Resini ti Aramu àti Peka ọmọ Remaliah ọba Israẹli gòkè wá láti bá Jerusalẹmu jà, ṣùgbọ́n wọn kò sì le è borí i rẹ̀.
2 I doniesiono domowi Dawida: Syria zmówiła się z Efraimem. Wtedy zadrżało jego serce i serce jego ludu, jak drżą od wiatru drzewa w lesie.
Báyìí, a sọ fún ilé Dafidi pé, “Aramu mà ti lẹ̀dí àpò pọ̀ mọ́ Efraimu”; fún ìdí èyí, ọkàn Ahasi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ wárìrì gẹ́gẹ́ bí igi oko ṣe ń wárìrì níwájú afẹ́fẹ́.
3 Wtedy PAN powiedział do Izajasza: Wyjdź teraz naprzeciw Achaza, ty i Szear-Jaszub, twój syn, na koniec kanału górnej sadzawki przy drodze pola folusznika;
Lẹ́yìn èyí, Olúwa sọ fún Isaiah pé, “Jáde, ìwọ àti ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ Ṣeari-Jaṣubu láti pàdé Ahasi ní ìpẹ̀kun ìṣàn omi ti adágún òkè, ní òpópó ọ̀nà tí ó lọ sí pápá Alágbàfọ̀.
4 I powiedz mu: Uważaj i bądź spokojny; nie bój się i niech twoje serce nie lęka się z powodu dwóch niedopałków dymiących głowni, z powodu zapalczywego gniewu Resina z Syrią oraz syna Remaliasza.
Sọ fún un, ‘Ṣọ́ra à rẹ, fi ọkàn balẹ̀, kí o má ṣe bẹ̀rù. Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí kùkùté igi ìdáná méjèèjì yìí, nítorí ìbínú gbígbóná Resini àti Aramu àti ti ọmọ Remaliah.
5 A ponieważ Syria, Efraim i syn Remaliasza uknuli przeciwko tobie zło, mówiąc:
Aramu, Efraimu àti Remaliah ti dìtẹ̀ ìparun rẹ, wọ́n wí pé,
6 Wyruszmy przeciw Judzie i nastraszmy ją, zróbmy sobie w niej wyłom i ustanówmy w niej królem syna Tabeela;
“Jẹ́ kí a kọlu Juda; jẹ́ kí a fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, kí a sì pín in láàrín ara wa, kí a sì fi ọmọ Tabeli jẹ ọba lórí i rẹ̀.”
7 Tak mówi Pan BÓG: Nie stanie się to i nie dojdzie do tego.
Síbẹ̀ èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èyí kò ní wáyé èyí kò le ṣẹlẹ̀,
8 Głową Syrii bowiem [jest] Damaszek, a głową Damaszku Resin; a po sześćdziesięciu pięciu latach Efraim będzie tak rozbity, że [już] nie będzie ludem.
nítorí Damasku ni orí Aramu, orí Damasku sì ni Resini. Láàrín ọdún márùnlélọ́gọ́ta Efraimu yóò ti fọ́ tí kì yóò le jẹ́ ènìyàn mọ́.
9 A głową Efraima [jest] Samaria, głową zaś Samarii – syn Remaliasza. Jeśli nie uwierzycie, na pewno się nie ostoicie.
Orí Efraimu sì ni Samaria, orí Samaria sì ni ọmọ Remaliah. Bí ẹ̀yin kí yóò bá gbàgbọ́, lóòtítọ́, a kì yóò fi ìdí yín múlẹ̀.’”
10 Ponadto PAN powiedział do Achaza:
Bákan náà Olúwa tún bá Ahasi sọ̀rọ̀,
11 Proś dla siebie o znak od PANA, twego Boga, czy to z głębin, czy wysoko w górze. (Sheol )
“Béèrè fún àmì lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, bóyá ní ọ̀gbun tí ó jì jùlọ tàbí àwọn òkè tí ó ga jùlọ.” (Sheol )
12 Wtedy Achaz odpowiedział: Nie będę prosił PANA ani wystawiał go na próbę.
Ṣùgbọ́n Ahasi sọ pé, “Èmi kì yóò béèrè; Èmi kò ní dán Olúwa wò.”
13 A on powiedział: Posłuchaj teraz, domu Dawida! Czy mało wam naprzykrzać się ludziom, że naprzykrzacie się także mojemu Bogu?
Lẹ́yìn náà Isaiah sọ pé, “Gbọ́ ní ìsinsin yìí, ìwọ ilé Dafidi, kò ha tọ́ láti tán ènìyàn ní sùúrù, ìwọ yóò ha tan Ọlọ́run ní sùúrù bí?
14 Dlatego sam Pan da wam znak. Oto dziewica pocznie i urodzi syna, i nazwie go Emmanuel.
Nítorí náà, Olúwa fúnra ara rẹ̀ ni yóò fún ọ ní àmì kan. Wúńdíá kan yóò lóyún, yóò sì bí ọmọkùnrin kan, yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Emmanueli.
15 Będzie on jadł masło i miód, aż będzie umiał odrzucać zło, a wybierać dobro.
Òun yóò jẹ wàrà àti oyin nígbà tí ó bá ní ìmọ̀ tó láti kọ ẹ̀bi àti láti yan rere.
16 Zanim bowiem to dziecko będzie umiało odrzucać zło i wybierać dobro, ziemia, którą się brzydzisz, zostanie opuszczona przez dwóch swoich królów.
Ṣùgbọ́n kí ọ̀dọ́mọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń kọ ẹ̀bi àti láti yan rere, ilẹ̀ àwọn ọba méjèèjì tí ń bà ọ́ lẹ́rù wọ̀nyí yóò ti di ahoro.
17 PAN sprowadzi na ciebie, na twój lud i na dom twego ojca dni, jakich nie było od dnia, w którym Efraim odstąpił od Judy – za sprawą króla Asyrii.
Olúwa yóò mú àsìkò mìíràn wá fún ọ àti àwọn ènìyàn rẹ àti lórí ilé baba rẹ irú èyí tí kò sí láti ìgbà tí Efraimu ti yà kúrò ní Juda, yóò sì mú ọba Asiria wá.”
18 I stanie się w tym dniu, że PAN zaświszcze na muchy, które są na krańcach rzek Egiptu, i na pszczoły, które są w ziemi Asyrii.
Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò súfèé pe àwọn eṣinṣin láti àwọn odò tó jìnnà ní Ejibiti wá, àti fún àwọn oyin láti ilẹ̀ Asiria.
19 I przybędą, i wszystkie obsiądą puste doliny i rozpadliny skalne, wszelkie krzaki kolczaste i wszelkie krzewy.
Gbogbo wọn yóò sì wá dó sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè àti pàlàpálá òkúta, lára koríko ẹ̀gún àti gbogbo ibi ihò omi.
20 W tym dniu Pan ogoli wynajętą brzytwą – tymi, którzy są za rzeką, [czyli] królem Asyrii – głowę i włosy na nogach, także i brodę obetnie.
Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò lo abẹ fífẹ́lẹ́ tí a yá láti ìkọjá odò Eufurate, ọba Asiria, láti fá irun orí àti ti àwọn ẹsẹ̀ ẹ yín, àti láti mú irùngbọ̀n yín kúrò pẹ̀lú.
21 I stanie się w tym dniu, że człowiek będzie hodował jedną krowę i dwie owce.
Ní ọjọ́ náà, ọkùnrin kan yóò máa sin ọ̀dọ́ abo màlúù kan àti ewúrẹ́ méjì.
22 A dzięki obfitemu udojowi mleka będzie jadł masło. Każdy bowiem, kto pozostanie w ziemi, będzie jadł masło i miód.
Àti nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàrà tí wọn yóò máa fún un, yóò ní wàràǹkàṣì láti jẹ. Gbogbo àwọn tí ó bá kù ní ilẹ̀ náà yóò jẹ wàràǹkàṣì àti oyin.
23 Stanie się też w tym dniu, że każde miejsce, gdzie rosło tysiąc winorośli wartości tysiąca srebrników, zarośnie ostem i cierniem.
Ní ọjọ́ náà, ni gbogbo ibi tí àjàrà tí ó tó ẹgbẹ̀rún ṣékélì fàdákà, ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n nìkan ni yóò wà níbẹ̀.
24 Wtedy ze strzałami i z łukiem będą tam chodzić, bo cała ziemia zarośnie ostem i cierniem.
Àwọn ènìyàn yóò máa lọ síbẹ̀ pẹ̀lú ọrun àti ọfà nítorí pé ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n ni yóò bo gbogbo ilẹ̀ náà.
25 A na wszystkie góry, które uprawiano motyką, nie dojdzie strach przed ostem i cierniem. Ale będą [przeznaczone] na pastwisko dla wołów i do deptania przez trzodę.
Àti ní orí àwọn òkè kéékèèké tí a ti ń fi ọkọ́ ro nígbà kan rí, ẹ kò ní lọ síbẹ̀ mọ́ nítorí ìbẹ̀rù ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n, wọn yóò di ibi tí a ń da màlúù lọ, àti ibi ìtẹ̀mọ́lẹ̀ fún àwọn àgùntàn kéékèèké.