+ Rodzaju 1 >

1 Na początku Bóg stworzył niebo i ziemię.
Ní ìbẹ̀rẹ̀ ohun gbogbo Ọlọ́run dá àwọn ọ̀run àti ayé.
2 A ziemia była bezkształtna i pusta i ciemność była nad głębią, a Duch Boży unosił się nad wodami.
Ayé sì wà ní rúdurùdu, ó sì ṣófo, òkùnkùn sì wà lójú ibú omi, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì ń rábàbà lójú omi.
3 I Bóg powiedział: Niech stanie się światłość. I stała się światłość.
Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ìmọ́lẹ̀ kí ó wà,” ìmọ́lẹ̀ sì wà.
4 Bóg widział, że światłość [była] dobra. I oddzielił Bóg światłość od ciemności.
Ọlọ́run rí i pé ìmọ́lẹ̀ náà dára, ó sì ya ìmọ́lẹ̀ náà sọ́tọ̀ kúrò lára òkùnkùn.
5 I nazwał Bóg światłość dniem, a ciemność nazwał nocą. I nastał wieczór i poranek, dzień pierwszy.
Ọlọ́run sì pe ìmọ́lẹ̀ náà ní “ọ̀sán,” àti òkùnkùn ní “òru.” Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kìn-ín-ní.
6 Potem Bóg powiedział: Niech stanie się firmament pośrodku wód i niech oddzieli wody od wód.
Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí òfúrufú kí ó wà ní àárín àwọn omi, láti pààlà sí àárín àwọn omi.”
7 I uczynił Bóg firmament, i oddzielił wody, które [są] pod firmamentem, od wód, które są nad firmamentem. I tak się stało.
Ọlọ́run sì dá òfúrufú láti ya omi tí ó wà ní òkè òfúrufú kúrò lára omi tí ó wà ní orí ilẹ̀. Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
8 I Bóg nazwał firmament niebem. I nastał wieczór i poranek, dzień drugi.
Ọlọ́run sì pe òfúrufú ní “ọ̀run.” Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kejì.
9 Potem Bóg powiedział: Niech się zbiorą w jednym miejscu wody, [które są] pod niebem, i niech się ukaże sucha [powierzchnia]. I tak się stało.
Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí omi abẹ́ ọ̀run wọ́ papọ̀ sí ojú kan, kí ilẹ̀ gbígbẹ sì farahàn.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
10 I Bóg nazwał suchą [powierzchnię] ziemią, a zbiorowisko wód – morzami. I Bóg widział, że [to było] dobre.
Ọlọ́run sì pe ilẹ̀ gbígbẹ náà ní “ilẹ̀,” àti àpapọ̀ omi ní “òkun.” Ọlọ́run sì rí i wí pé ó dára.
11 Potem Bóg powiedział: Niech ziemia zrodzi trawę, rośliny wydające nasiona i drzewo urodzajne przynoszące owoc według swego rodzaju, którego nasienie będzie w nim na ziemi. I tak się stało.
Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ilẹ̀ kí ó hu ọ̀gbìn: ewéko ti yóò máa mú èso wá àti igi tí yóò máa so èso ní irú tirẹ̀, tí ó ní irúgbìn nínú.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
12 I ziemia wydała trawę, rośliny wydające nasienie według swego rodzaju i drzewo przynoszące owoc, w którym było nasienie według swego rodzaju. I Bóg widział, że to było dobre.
Ilẹ̀ sì hù ọ̀gbìn: ewéko tí ó ń so èso ní irú tirẹ̀, àti igi tí ń so èso, tí ó ní irúgbìn nínú ní irú tirẹ̀. Ọlọ́run sì ri pé ó dára.
13 I nastał wieczór i poranek, dzień trzeci.
Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kẹta.
14 Potem Bóg powiedział: Niech się staną światła na firmamencie nieba, by oddzielały dzień od nocy, i niech stanowią znaki, pory [roku], dni i lata.
Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí ìmọ́lẹ̀ kí ó wà ní ojú ọ̀run, láti pààlà sí àárín ọ̀sán àti òru, kí wọn ó sì máa wà fún àmì láti mọ àwọn àsìkò, àti àwọn ọjọ́ àti àwọn ọdún.
15 I niech będą światłami na firmamencie nieba, aby świeciły nad ziemią. I tak się stało.
Kí wọn ó jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ní ojú ọ̀run láti tan ìmọ́lẹ̀ sí orí ilẹ̀.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
16 I Bóg uczynił dwa wielkie światła: światło większe, aby rządziło dniem, i światło mniejsze, aby rządziło nocą, oraz gwiazdy.
Ọlọ́run dá ìmọ́lẹ̀ ńlá ńlá méjì, ìmọ́lẹ̀ tí ó tóbi láti ṣe àkóso ọ̀sán àti ìmọ́lẹ̀ tí ó kéré láti ṣe àkóso òru. Ó sì dá àwọn ìràwọ̀ pẹ̀lú.
17 I Bóg umieścił je na firmamencie nieba, aby świeciły nad ziemią;
Ọlọ́run sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ sí ojú ọ̀run láti máa tan ìmọ́lẹ̀ si orí ilẹ̀,
18 I żeby rządziły dniem i nocą, i oddzielały światłość od ciemności. I Bóg widział, że to było dobre.
láti ṣàkóso ọ̀sán àti òru àti láti pààlà sí àárín ìmọ́lẹ̀ àti òkùnkùn. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára.
19 I nastał wieczór i poranek, dzień czwarty.
Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kẹrin.
20 Potem Bóg powiedział: Niech wody hojnie wydadzą żywe istoty, a ptactwo niech lata nad ziemią, pod firmamentem nieba.
Ọlọ́run sì wí pé, “Jẹ́ kí omi kí ó kún fún àwọn ohun alààyè, kí àwọn ẹyẹ kí ó sì máa fò ní òfúrufú.”
21 I Bóg stworzył wielkie wieloryby i wszelkie pływające istoty żywe, które hojnie wydały wody, według ich rodzaju oraz wszelkie ptactwo skrzydlate według jego rodzaju. I Bóg widział, że [to było] dobre.
Nítorí náà Ọlọ́run dá àwọn ẹ̀dá alààyè ńlá ńlá sí inú òkun, àwọn ohun ẹlẹ́mìí àti àwọn ohun tí ń rìn ní onírúurú tiwọn, àti àwọn ẹyẹ abìyẹ́ ní onírúurú tiwọn. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára.
22 Bóg błogosławił je, mówiąc: Bądźcie płodne i rozmnażajcie się, i wypełniajcie wody morskie, a ptactwo niech się rozmnaża na ziemi.
Ọlọ́run súre fún wọn, ó sì wí pé, “Ẹ máa bí sí i, ẹ sì máa pọ̀ sí i, ẹ kún inú omi òkun, kí àwọn ẹyẹ náà sì máa pọ̀ sí i ní orí ilẹ̀.”
23 I nastał wieczór i poranek, dzień piąty.
Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ karùn-ún.
24 Bóg powiedział też: Niech ziemia wyda istoty żywe według swego rodzaju: bydło, zwierzęta pełzające i zwierzęta ziemi według swego rodzaju. I tak się stało.
Ọlọ́run sì wí pé, “Kí ilẹ̀ kí ó mú ohun alààyè jáde ní onírúurú wọn: ẹran ọ̀sìn, àwọn ohun afàyàfà àti àwọn ẹran inú igbó, ọ̀kọ̀ọ̀kan ní irú tirẹ̀.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
25 I Bóg uczynił zwierzęta ziemi według swego rodzaju i bydło według swego rodzaju, i wszelkie zwierzęta, które pełzają po ziemi według swego rodzaju. I Bóg widział, że [to było] dobre.
Ọlọ́run sì dá ẹranko inú igbó àti ẹran ọ̀sìn gbogbo ní irú tirẹ̀ àti gbogbo ohun alààyè tí ń rìn ní ilẹ̀ ní irú tirẹ̀. Ọlọ́run sì rí i pé ó dára.
26 Potem Bóg powiedział: Uczyńmy człowieka na nasz obraz według naszego podobieństwa; niech panuje nad rybami morskimi i ptactwem niebieskim, nad bydłem i całą ziemią oraz nad wszelkimi zwierzętami pełzającymi, które pełzają po ziemi.
Lẹ́yìn náà ni Ọlọ́run wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a dá ènìyàn ní àwòrán ara wa, gẹ́gẹ́ bí àwa ti rí, kí wọn kí ó jẹ ọba lórí ẹja òkun, ẹyẹ ojú ọ̀run, ẹran ọ̀sìn, gbogbo ilẹ̀ àti lórí ohun gbogbo tí ń rìn lórí ilẹ̀.”
27 Stworzył więc Bóg człowieka na swój obraz, na obraz Boga go stworzył; stworzył ich mężczyzną i kobietą.
Nítorí náà, Ọlọ́run dá ènìyàn ní àwòrán ara rẹ̀, ní àwòrán Ọlọ́run ni ó dá a, akọ àti abo ni ó dá wọn.
28 I Bóg błogosławił im. Potem Bóg powiedział do nich: Bądźcie płodni i rozmnażajcie się, napełniajcie ziemię i czyńcie ją sobie poddaną; panujcie nad rybami morskimi i nad ptactwem niebieskim, i nad wszelkimi zwierzętami, które poruszają się po ziemi.
Ọlọ́run sì súre fún wọn, Ọlọ́run sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa bí sí i, kí ẹ sì máa pọ̀ sí i, kí ẹ sì gbilẹ̀, kí ẹ ṣe ìkápá ayé. Ẹ ṣe àkóso àwọn ẹja inú òkun, ẹyẹ ojú ọ̀run àti gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ó ń rìn ní orí ilẹ̀.”
29 I Bóg powiedział: Oto dałem wam wszelkie rośliny wydające z siebie nasienie, które są na powierzchni całej ziemi, i wszelkie drzewo mające owoc drzewa, wydające [z siebie] nasienie – będą one dla was pokarmem.
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí pé, “Mo fi gbogbo ohun ọ̀gbìn tí ń so èso fún un yín bí oúnjẹ àti àwọn igi eléso pẹ̀lú. Gbogbo rẹ̀ yóò jẹ́ oúnjẹ fún un yín.
30 I wszelkim zwierzętom ziemi, i wszelkiemu ptactwu niebieskiemu, i wszystkiemu, co pełza po ziemi i [ma] w sobie życie, pokarmem [będą] wszelkie rośliny zielone. I tak się stało.
Àti fún àwọn ẹranko inú igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ohun afàyàfà, gbogbo ohun tó ní èémí ìyè nínú ni mo fi ewéko fún bí oúnjẹ.” Ó sì rí bẹ́ẹ̀.
31 I Bóg widział wszystko, co uczynił, a [było] to bardzo dobre. I nastał wieczór i poranek, dzień szósty.
Ọlọ́run sì rí àwọn ohun gbogbo tí ó dá, ó dára gidigidi. Àṣálẹ́ àti òwúrọ̀ sì jẹ́ ọjọ́ kẹfà.

+ Rodzaju 1 >