< II Samuela 5 >
1 Wtedy wszystkie pokolenia Izraela zeszły się u Dawida w Hebronie i powiedziały: Oto jesteśmy twoją kością i twoim ciałem.
Gbogbo ẹ̀yà Israẹli sì tọ Dafidi wá ní Hebroni, wọ́n sì wí pé, “Ẹran-ara rẹ àti ẹ̀jẹ̀ rẹ ni àwa ń í ṣe.
2 Już dawniej, gdy Saul był królem nad nami, ty wyprowadzałeś i przyprowadzałeś Izraela. I PAN powiedział do ciebie: Ty będziesz pasł mój lud Izraela i ty będziesz wodzem nad Izraelem.
Àti nígbà àtijọ́, nígbà tí Saulu fi jẹ ọba lórí wa, ìwọ ni ẹni tí ó máa ń kó Israẹli jáde, ìwọ sì ni ó máa ń mú wọn bọ̀ wá ilé: Olúwa sì wí fún ọ pé, ‘Ìwọ yóò ṣe olùṣọ́ Israẹli àwọn ènìyàn mi, ìwọ yóò sì jẹ́ olórí fún Israẹli.’”
3 Wszyscy starsi Izraela przyszli więc do króla do Hebronu i król Dawid zawarł z nimi przymierze w Hebronie przed PANEM, a oni namaścili Dawida na króla nad Izraelem.
Gbogbo àgbàgbà Israẹli sì tọ ọba wá ní Hebroni, Dafidi ọba sì bá wọn ṣe àdéhùn kan ní Hebroni, níwájú Olúwa: wọ́n sì fi òróró yan Dafidi ní ọba Israẹli.
4 Dawid miał trzydzieści lat, gdy zaczął królować, a królował czterdzieści lat.
Dafidi sì jẹ́ ẹni ọgbọ̀n ọdún nígbà tí ó jẹ ọba; ó sì jẹ ọba ní ogójì ọdún.
5 W Hebronie królował nad Judą siedem lat i sześć miesięcy, w Jerozolimie zaś królował trzydzieści trzy lata nad całym Izraelem i Judą.
Ó jẹ ọba ní Hebroni ní ọdún méje àti oṣù mẹ́fà lórí Juda, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu ní ọdún mẹ́tàlélọ́gbọ̀n lórí gbogbo Israẹli àti Juda.
6 I król oraz jego ludzie poszli do Jerozolimy przeciw Jebusytom zamieszkującym w tej ziemi, a oni powiedzieli do Dawida: Nie wejdziesz tutaj, dopóki nie wyniesiesz ślepych i chromych. Myśleli [bowiem]: Dawid tu nie wejdzie.
Àti ọba àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì lọ sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ àwọn ará Jebusi, àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà; àwọn tí ó sì ti wí fún Dafidi pé, “Bí kò ṣe pé ìwọ bá mú àwọn afọ́jú àti àwọn arọ kúrò, ìwọ kì yóò wọ ìhín wá.” Wọ́n sì wí pé, “Dafidi kì yóò lè wá síyìn-ín.”
7 Dawid jednak zdobył twierdzę Syjon, to jest miasto Dawida.
Ṣùgbọ́n Dafidi fi agbára gba ìlú odi Sioni: èyí náà ni í ṣe ìlú Dafidi.
8 Dawid powiedział w tym dniu: Ktokolwiek pokona Jebusytów, wchodząc przez kanał, i [zabije] ślepych i chromych, których nienawidzi dusza Dawida, [ustanowię go dowódcą]. Dlatego mówiono: Ślepi i chromi nie wejdą do tego domu.
Dafidi sọ lọ́jọ́ náà pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọlu àwọn ará Jebusi, jẹ́ kí ó gba ojú àgbàrá, kí o sí kọlu àwọn arọ, àti àwọn afọ́jú tí ọkàn Dafidi kórìíra.” Nítorí náà ni wọ́n ṣe wí pé, “Afọ́jú àti arọ wà níbẹ̀, kì yóò lè wọlé.”
9 I tak zamieszkał Dawid w tej twierdzy, i nazwał ją miastem Dawida. Dawid obudował je też wokoło, od Millo i wnętrza.
Dafidi sì jókòó ní ilé àwọn ọmọ-ogun tí ó ní odi, a sì ń pè é ní ìlú Dafidi. Dafidi mọ ògiri yí i ká láti Millo wá, ó sì kọ́ ilé nínú rẹ̀.
10 I Dawid stale wzrastał w potędze, a PAN Bóg zastępów był z nim.
Dafidi sì ń pọ̀ sí i, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
11 Wtedy Hiram, król Tyru, wysłał posłańców do Dawida z drzewem cedrowym, cieślami i murarzami i zbudowali dom dla Dawida.
Hiramu ọba Tire sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dafidi, àti igi kedari, àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àti àwọn tí ń gbẹ́ òkúta, wọ́n kọ́ ilé kan fún Dafidi.
12 I Dawid poznał, że PAN utwierdził go jako króla nad Izraelem i że wywyższył jego królestwo ze względu na swój lud Izraela.
Dafidi sì kíyèsi i pé, Olúwa ti fi ìdí òun múlẹ̀ láti jẹ ọba lórí Israẹli, àti pé, ó gbé ìjọba rẹ̀ ga nítorí Israẹli àwọn ènìyàn rẹ̀.
13 A po przybyciu z Hebronu Dawid wziął sobie jeszcze więcej nałożnic i żon z Jerozolimy. I urodziło się Dawidowi więcej synów i córek.
Dafidi sì tún mú àwọn àlè àti aya sí i láti Jerusalẹmu wá, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti Hebroni bọ̀, wọ́n sì bí ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin fún Dafidi.
14 Oto imiona tych, którzy mu się urodzili w Jerozolimie: Szammua, Szobab, Natan i Salomon;
Èyí sì ni orúkọ àwọn tí a bí fún un ní Jerusalẹmu; Ṣammua, Ṣobabu, Natani àti Solomoni.
15 Jibchar, Eliszua, Nefeg i Jafia;
Àti Ibhari, àti Eliṣua, àti Nefegi, àti Jafia.
16 Eliszama, Eliada i Elifelet.
Àti Eliṣama, àti Eliada, àti Elifeleti.
17 A gdy Filistyni usłyszeli, że Dawid został namaszczony na króla nad Izraelem, wszyscy Filistyni wyruszyli, aby szukać Dawida. Kiedy Dawid o tym usłyszał, zstąpił do twierdzy.
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn Filistini gbọ́ pé, wọ́n ti fi Dafidi jẹ ọba lórí Israẹli, gbogbo àwọn Filistini sì gòkè wá láti wá Dafidi; Dafidi sì gbọ́, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìlú olódi.
18 Wtedy Filistyni przybyli i rozciągnęli się w dolinie Refaim.
Àwọn Filistini sì wá, wọ́n sì tẹ ara wọn ní àfonífojì Refaimu.
19 I Dawid radził się PANA: Czy mam ruszyć na Filistynów? Czy wydasz ich w moje ręce? PAN odpowiedział Dawidowi: Idź, gdyż z całą pewnością wydam Filistynów w twoje ręce.
Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa pé, “Kí èmi ó gòkè tọ àwọn Filistini bí? Ìwọ ó fi wọ́n lé mi lọ́wọ́ bí?” Olúwa sì wí fún Dafidi pé, “Gòkè lọ, nítorí pé dájúdájú èmi ó fi àwọn Filistini lé ọ lọ́wọ́.”
20 Dawid przybył więc do Baal-Perasim i tam ich pobił, i powiedział: PAN rozerwał moich wrogów przede mną jak rwąca woda. Dlatego nazwał to miejsce Baal-Perasim.
Dafidi sì dé Baali-Perasimu, Dafidi sì pa wọ́n níbẹ̀, ó sì wí pé, “Olúwa ti ya lu àwọn ọ̀tá mi níwájú mi, gẹ́gẹ́ bí omi ti ń ya.” Nítorí náà ni òun ṣe pe orúkọ ibẹ̀ náà ni Baali-Perasimu.
21 I porzucili tam swoje bożki, a Dawid i jego ludzie spalili je.
Wọ́n sì fi òrìṣà wọn sílẹ̀ níbẹ̀, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì kó wọn.
22 I Filistyni znowu nadciągnęli, i rozciągnęli się w dolinie Refaim.
Àwọn Filistini sì tún gòkè wá, wọ́n sì tan ara wọn kalẹ̀ ní àfonífojì Refaimu.
23 Gdy Dawid radził się PANA, [PAN] odpowiedział: Nie ruszaj [na nich, lecz] obejdź ich z tyłu i uderz na nich od strony drzew morwowych.
Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, òun sì wí pé, “Má ṣe gòkè lọ; ṣùgbọ́n bù wọ́n lẹ́yìn, kí o sì kọlù wọ́n níwájú àwọn igi Baka.
24 A gdy usłyszysz odgłos kroków [dochodzących] od wierzchołków drzew morwowych, wtedy wyruszysz, gdyż wtedy PAN wyjdzie przed tobą, aby pokonać wojska Filistynów.
Yóò sì ṣe, nígbà tí ìwọ bá gbọ́ ìró ẹsẹ̀ lórí àwọn igi Baka náà, nígbà náà ni ìwọ yóò sì yára, nítorí pé nígbà náà ni Olúwa yóò jáde lọ níwájú rẹ láti kọlù ogun àwọn Filistini.”
25 I Dawid uczynił tak, jak mu PAN rozkazał, i pobił Filistynów od Geba aż do wejścia do Gezer.
Dafidi sì ṣe bẹ́ẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún un; ó sì kọlu àwọn Filistini láti Geba títí dé Geseri.