< Wyjścia 3 >

1 A Mojżesz pasł trzodę Jetra, świekra swego, kapłana Madyjańskiego; i zagnał trzodę na puszczą, a przyszedł do góry Bożej, do Horeb,
Ní ọjọ́ kan nígbà tí Mose ń ṣọ́ agbo ẹran Jetro baba ìyàwó rẹ̀, àlùfáà Midiani. Ó da agbo ẹran náà lọ sí ọ̀nà jíjìn nínú aginjù. Ó dé Horebu, òkè Ọlọ́run.
2 I ukazał mu się Anioł Pański w płomieniu ognistym, z pośrodku krza; i widział, a oto, kierz gorzał ogniem, a on kierz nie zgorzał.
Níbẹ̀ ni angẹli Olúwa ti yọ sí i nínú ọ̀wọ́-iná tí ń jó láàrín igbó. Mose rí i pé iná ń jó nínú igbó ṣùgbọ́n igbó kò run.
3 Tedy rzekł Mojżesz: Pójdę teraz, a oglądam to widzenie wielkie, czemu nie zgore ten kierz.
Nígbà náà ni Mose sọ pé, “Èmi yóò lọ wo ohun ìyanu yìí, ìdí tí iná kò fi jó igbó run.”
4 A widząc Pan, iż szedł patrzać, zawołał nań Bóg z pośrodku onego krza, mówiąc: Mojżeszu, Mojżeszu! A on odpowiedział: Otom ja.
Nígbà tí Olúwa rí i pe Mose ti lọ láti lọ wò ó, Ọlọ́run ké pè é láti àárín igbó náà, “Mose! Mose!” Mose sì dáhùn ó wí pé, “Èmi nìyìí.”
5 Tedy rzekł: Nie przystępuj sam; zzuj buty twe z nóg twoich: albowiem miejsce, na którem ty stoisz, ziemia święta jest.
Olúwa sì wí fún Mose pé, “Má ṣe súnmọ́ ìhín yìí, bọ́ sálúbàtà rẹ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ, nítorí ibi tí ìwọ dúró sí i nì ilẹ̀ mímọ́ ni.”
6 Zatem rzekł: Jam jest Bóg ojca twego, Bóg Abrahamów, Bóg Izaaków, i Bóg Jakóbów; i zakrył Mojżesz oblicze swe, bo się bał patrzać na Boga.
Nígbà náà ní ó wí pé, “Èmi ni Ọlọ́run baba rẹ, Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu.” Nítorí ìdí èyí, Mose sì pa ojú rẹ̀ mọ́, nítorí ó bẹ̀rù láti bojú wo Ọlọ́run.
7 I rzekł Pan: Widząc widziałem utrapienie ludu mojego, który jest w Egipcie, a wołanie ich słyszałem przed przystawy ich; bom doznał boleści jego.
Olúwa si wí pé, “Èmí ti rí ìpọ́njú àwọn ènìyàn mi ní ilẹ̀ Ejibiti, mo sì ti gbọ́ ohùn igbe wọn nítorí àwọn akóniṣiṣẹ́ wọn. Ìyà tí ń jẹ wọ́n sì kan mi lára.
8 Przetoż zstąpiłem, abym go wybawił z ręki Egipskiej i wywiódł go z ziemi tej do ziemi dobrej i przestronnej, do ziemi opływającej mlekiem i miodem, na miejsce Chananejczyka, i Hetejczyka, i Amorejczyka, i Ferezejczyka, i Hewejczyka, i Jebuzejczyka.
Èmi sì ti sọ̀kalẹ̀ wá láti gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti, àti láti mú wọn gòkè kúrò ní ilẹ̀ náà lọ sí ilẹ̀ tí ó dára tí ó sì ní ààyè, àní ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin; ibùgbé àwọn ará Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi.
9 A teraz oto krzyk synów Izraelskich przyszedł przed mię: i widziałem też ich ucisk, którym je Egipczanie uciskają.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, wò ó, igbe àwọn ará Israẹli ti dé ọ̀dọ̀ mi, Èmi sì ti rí bí àwọn ará Ejibiti ti ṣe ń gbà ń jẹ wọ́n ní ìyà.
10 Przetoż teraz, pójdź, a poślę cię do Faraona, abyś wywiódł lud mój, syny Izraelskie z Egiptu.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, lọ, èmi yóò rán ọ sí Farao láti kó àwọn ènìyàn Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.”
11 I rzekł Mojżesz do Boga: Któżem ja, abym szedł do Faraona, a wywiódł syny Izraelskie z Egiptu?
Ṣùgbọ́n Mose wí fún Ọlọ́run pé, “Ta ni èmi, tí èmi yóò tọ Farao lọ, ti èmi yóò sì kó àwọn ará Israẹli jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti?”
12 I rzekł Bóg: Oto, będę z tobą, a to miej na znak, żem cię ja posłał: Gdy wywiedziesz ten lud z Egiptu, będziecie służyć Bogu na tej górze.
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún Mose pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èyí ni yóò jẹ́ àmì fún ọ, tí yóò fihàn pé, èmi ni ó rán ọ lọ, nígbà tí ìwọ bá kó àwọn ènìyàn náà jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ẹ̀yin yóò sin Ọlọ́run ni orí òkè yìí.”
13 I rzekł Mojżesz do Boga: Oto, ja pójdę do synów Izraelskich, i rzekę im: Bóg ojców waszych posłał mię do was: Jeźli mi rzeką: Które jest imię jego? Cóż im odpowiem?
Mose sì wí fún Ọlọ́run pé, “Bí mo bá tọ àwọn ará Israẹli lọ tí mo sì sọ fún wọn pé, ‘Ọlọ́run àwọn baba yín ni ó rán mi sí i yín,’ tí wọ́n sì béèrè lọ́wọ́ mi pé, ‘Kí ni orúkọ rẹ̀?’ Kí ni èmi yóò sọ fún wọn ní ìgbà náà?”
14 Tedy rzekł Bóg do Mojżesza: Będę który Będę. I rzekł: Tak powiesz synom Izraelskim: Będę posłał mię do was.
Ọlọ́run sì sọ fún Mose pé, “èmi ni ti ń jẹ́ èmi ni. Èyí ni ìwọ yóò sọ fún àwọn ará Israẹli: ‘èmi ni ni ó rán mi sí i yín.’”
15 I mówił jeszcze Bóg do Mojżesza: Tak rzeczesz do synów Izraelskich: Pan, Bóg ojców waszych, Bóg Abrahamów, Bóg Izaaków, i Bóg Jakóbów posłał mię do was; toć imię moje na wieki, i to pamiętne moje od narodu do narodu;
Ọlọ́run sì wí fún Mose pẹ̀lú pé, “Báyìí ni kí ìwọ sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín; Ọlọ́run Abrahamu, Ọlọ́run Isaaki àti Ọlọ́run Jakọbu; ni ó rán mi sí i yín.’ “Èyí ni orúkọ mi títí ayérayé, orúkọ ti ẹ ó fi máa rántí mi láti ìran dé ìran.
16 Idźże, a zgromadź starsze Izraelskie, i mów do nich: Pan, Bóg ojców waszych, ukazał mi się, Bóg Abrahamów, Izaaków i Jakóbów, mówiąc: Wspominając wspomniałem na was, i widziałem, co się wam działo w Egipcie.
“Lọ, kó àwọn àgbàgbà Israẹli jọ, kí o sì wí fún wọn pé, ‘Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín, Ọlọ́run Abrahamu, ti Isaaki, àti ti Jakọbu; ni ó farahàn mi, ó sì wí pé, lóòótọ́ èmi ti ń bojú wò yín, èmi sì ti rí ohun tí wọ́n ṣe sí i yín ni ilẹ̀ Ejibiti.
17 I rzekłem: Wyprowadzę was z utrapienia Egipskiego do ziemi Chananejczyka, i Hetejczyka, i Amorejczyka, i Ferezejczyka, i Hewejczyka, i Jebuzejczyka, do ziemi opływającej mlekiem i miodem.
Èmi sì ti ṣe ìlérí láti mú un yín jáde kúrò nínú ìpọ́njú yín ni ilẹ̀ Ejibiti wá sí ilẹ̀ Kenaani, ará Hiti, Amori, Peresi, Hifi àti Jebusi; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.’
18 Tedy usłuchają głosu twego, a pójdziesz ty i starsi Izraelscy do króla Egipskiego, i rzeczecie do niego: Pan, Bóg Hebrajczyków, zabieżał nam; przetoż teraz niech pójdziemy proszę w drogę trzech dni na puszczą, abyśmy ofiarowali Panu, Bogu naszemu.
“Àwọn àgbàgbà Israẹli yóò fetísílẹ̀ sí ohùn rẹ. Nígbà náà ni ìwọ, àti àwọn àgbàgbà yóò jọ tọ ọba Ejibiti lọ, ẹ ó sì wí fún un pé, ‘Olúwa, Ọlọ́run àwọn ará Heberu ti pàdé wa. Jẹ́ kí a lọ ni ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sí inú aginjù láti lọ rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run.’
19 Ale ja wiem, że wam nie pozwoli król Egipski odejść, jedno przez możną rękę.
Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé ọba Ejibiti kò ní jẹ́ kí ẹ lọ bí kò ṣe pé ọwọ́ ńlá Ọlọ́run wà ni ara rẹ̀.
20 A tak wyciągnę rękę moję, i uderzę Egipt wszystkiemi cudami mojemi, które będę czynił w pośrodku jego: a potem wypuści was.
Nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mí láti lu àwọn ará Ejibiti pẹ̀lú gbogbo ohun ìyanu tí èmi yóò ṣe ni àárín wọn. Lẹ́yìn náà, òun yóò jẹ́ kí ẹ máa lọ.
21 I dam łaskę ludowi temu w oczach Egipczanów: i stanie się, gdy wychodzić będziecie, że nie wynijdziecie próżni.
“Èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ bá ojúrere àwọn ará Ejibiti pàdé. Tí yóò fi jẹ́ pé ti ẹ̀yin bá ń lọ, ẹ kò ní lọ ní ọwọ́ òfo.
22 Ale wypożyczy niewiasta u sąsiadki swojej, i u gospodyni domu swego, naczynia srebrnego, i naczynia złotego, i szat; i włożycie je na syny wasze, i na córki wasze, i złupicie Egipt.
Gbogbo àwọn obìnrin ni ó ní láti béèrè lọ́wọ́ àwọn aládùúgbò wọn àti gbogbo àwọn obìnrin ti ń gbé nínú ilé rẹ fún ohun fàdákà àti wúrà àti fún aṣọ, èyí ti ẹ̀yin yóò wọ̀ sí ọrùn àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti obìnrin. Báyìí ni ẹ̀yin yóò sì kó ẹrù àwọn ará Ejibiti.”

< Wyjścia 3 >