< Thaburi 35 >
1 Thaburi ya Daudi Wee Jehova, hũũrana na arĩa marahũũrana na niĩ; rũa na arĩa mararũa na niĩ.
Ti Dafidi. Olúwa, gbógun ti àwọn tí ń gbóguntì mí; kí o sì kọ ojú ìjà sí àwọn tí ó ń bá mi í jà!
2 Oya ngo nene na gako kanini; arahũka ũũke ũndeithie.
Di asà àti àpáta mú, kí o sì dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi!
3 Hiũria itimũ na mĩcengi, ũũkĩrĩre arĩa maathingatĩte. Ĩra ngoro yakwa atĩrĩ, “Niĩ nĩ niĩ ũhonokio waku.”
Fa idà àti ọ̀kọ̀ yọ kí o sì dojúkọ àwọn tí ń lé mi. Sọ fún ọkàn mi pé, “Èmi ni ìgbàlà rẹ.”
4 Andũ arĩa mendaga kũnduta muoyo maroconorithio na maagithio gĩtĩĩo, arĩa mathugundaga kũnyũnũha marocookio na thuutha mamakĩte.
Kí wọn kí ó dààmú, kí a sì ti àwọn tí ń lépa ọkàn mi lójú; kí a sì mú wọn padà, kí a sì dààmú àwọn tí ń gbèrò ìpalára mi.
5 Marohaana ta mahuti mombũrĩtwo nĩ rũhuho, na mũraika wa Jehova amaingatithĩtie;
Jẹ́ kí wọn dàbí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́, kí angẹli Olúwa kí ó máa lé wọn kiri.
6 njĩra yao ĩrogĩa nduma na ĩtendere, nake mũraika wa Jehova ahanyũkanie nao.
Jẹ́ kí ọ̀nà wọn kí ó ṣókùnkùn, kí ó sì máa yọ́, kí angẹli Olúwa kí ó máa lépa wọn!
7 Kuona atĩ nĩmahithĩire wabu wa kũndega hatarĩ gĩtũmi, na makanyenjera irima hatarĩ gĩtũmi,
Nítorí pé, ní àìnídìí ni wọ́n dẹ àwọ̀n wọn sílẹ̀ fún mi, ní àìnídìí ni wọ́n wa kòtò sílẹ̀ fún ọkàn mi.
8 marokorererwo nĩ mwanangĩko matehaarĩirie, wabu ũcio manyambĩire ũromanyiita o ene, marogwa irima rĩu manyenjeire.
Kí ìparun kí ó wá sí orí rẹ̀ ní òjijì. Àwọ̀n rẹ̀ tí ó dẹ, kí ó mú òun tìkára rẹ̀; kí wọn ṣubú sínú kòtò sí ìparun ara rẹ̀.
9 Hĩndĩ ĩyo ngoro yakwa ĩgaacanjamũka nĩ ũndũ wa Jehova, na ĩkenagĩre ũhonokio wake.
Nígbà náà ni ọkàn mi yóò yọ̀ nínú Olúwa, àní, yóò sì máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ̀.
10 Nĩngwanĩrĩra na ngoro yakwa yothe, njũũrie atĩrĩ, “Nũũ ũhaana tawe, Wee Jehova? O Wee ũhatũraga andũ arĩa athĩĩni harĩ arĩa marĩ hinya kũmakĩra, ũkahatũra athĩĩni na abatari harĩ arĩa mamatunyaga indo.”
Gbogbo egungun mi yóò wí pé, “Ta ni ó dàbí ì ìwọ Olúwa? O gba tálákà lọ́wọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ, tálákà àti aláìní lọ́wọ́ ẹni tí ń fi ṣe ìkógun?”
11 Nĩkuumĩrĩte aira a maheeni, makanjũũria ũhoro wa maũndũ itooĩ.
Àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde; wọ́n ń bi mi ní ohun tí èmi kò mọ̀.
12 Wega wakwa mandĩhaga na ũũru, magatiga ngoro yakwa ĩrĩ na ihooru.
Wọ́n fi búburú san ìre fún mi; láti sọ ọkàn mi di òfo.
13 No rĩrĩa o maarĩ arũaru, niĩ ndehumbire nguo ya ikũnia, na ngĩĩnyiihia na ũndũ wa kwĩhinga kũrĩa irio. Rĩrĩa mahooya makwa maagire macookio-rĩ,
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni, nígbà tí wọn ń ṣe àìsàn, mo wọ aṣọ ọ̀fọ̀; mo fi àwẹ̀ pọ́n ara mi lójú. Mo gba àdúrà pẹ̀lú ìtẹríba ní oókan àyà mi;
14 ndaikarire ngĩcakayaga, o taarĩ mũrata wakwa kana mũrũ wa maitũ ndaacakayagĩra. Ndethikĩire ndĩ na ihooru, o taarĩ mũndũ ũracakaĩra nyina.
èmí ń lọ kiri bí ẹni ń ṣọ̀fọ̀ bí i ẹni wí pé fún ọ̀rẹ́ tàbí ẹ̀gbọ́n mi ni. Èmí tẹríba nínú ìbànújẹ́ bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ìyà rẹ̀.
15 No rĩrĩa ndahĩngirwo ngĩgwa, o moonganire hamwe mangenerere; atharĩkĩri makĩũngana maatharĩkĩre itekũmenya. Manjaambirie mategũtigithĩria.
Ṣùgbọ́n nínú ìkọ̀sẹ̀ mi wọ́n sì yọ̀, wọ́n sì kó ara wọn jọ; wọ́n kó ara wọn jọ sí mi; àní àwọn tí èmi kò mọ̀. Wọ́n fà mí ya wọ́n kò sì dákẹ́.
16 Maanyũrũragia ta andũ matooĩ Ngai, makaahagaranĩria magego mao.
Bí àwọn àgàbàgebè tí ń ṣe ẹlẹ́yà ní àpèjẹ wọ́n pa eyín wọn keke sí mi.
17 Wee Jehova-rĩ, nĩ nginya rĩ ũgũikara wĩroreire? Hatũra muoyo wakwa kuuma harĩ wanangi wao, ũhatũre muoyo wakwa wa goro kuuma harĩ mĩrũũthi ĩno.
Yóò ti pẹ́ tó Olúwa, tí ìwọ yóò máa wò wọ́n lọ? Yọ mí kúrò nínú ìparun wọn, àní ẹ̀mí ì mi kúrò lọ́wọ́ kìnnìún.
18 Nĩ niĩ ngũgũcookeria ngaatho kĩũngano-inĩ kĩrĩa kĩnene; ndĩkũgoocaga ndĩ gatagatĩ ka andũ aingĩ.
Nígbà náà ni èmi yóò ṣọpẹ́ fún Ọ nínú àjọ ńlá; èmi yóò máa yìn Ọ́ ní àwùjọ ọ̀pọ̀ ènìyàn.
19 Ndũkareke arĩa maathũire tũhũ mangũũrĩre maitho, mangenerere; kana acio maamenete hatarĩ gĩtũmi moinanĩre maitho.
Má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi kí ó yọ̀ lórí ì mi; bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe àwọn tí ó kórìíra mi ní àìnídìí máa ṣẹ́jú sí mi.
20 Matiaragia ndeto cia thayũ, no mathugundaga maũndũ ma maheeni, ma gũũkĩrĩra andũ arĩa maikaraga na thayũ bũrũri-inĩ.
Nítorí pé wọn kò sọ ọ̀rọ̀ àlàáfíà, ṣùgbọ́n wọ́n lóyún ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn sí àwọn ènìyàn dídákẹ́ ilẹ̀ náà.
21 Manjathamagĩria tũnua twao makoiga atĩrĩ, “Haiya! Haiya! Maitho maitũ nĩmeyoneire ũguo.”
Wọ́n ya ẹnu wọn gbòòrò sí mi; wọ́n wí pé, “Háà! Háà! Ojú wa sì ti rí i.”
22 Wee Jehova, nĩwĩoneire ũguo; tiga gũkira. Wee Mwathani-rĩ, ndũgaikare haraaya na niĩ.
Ìwọ́ ti rí i Olúwa; má ṣe dákẹ́! Olúwa má ṣe jìnnà sí mi!
23 Arahũka, ũkĩra ũngitĩre! Hũũranĩra, Wee Ngai wakwa na Mwathani wakwa.
Dìde! ru ara rẹ̀ sókè fún ààbò mi, àti sí ọ̀ràn mi, Ọlọ́run mi àti Olúwa mi!
24 Wee Jehova, nduĩra kũringana na ũthingu waku, Wee Ngai wakwa; ndũkareke mangũũrĩre maitho, mangenerere.
Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa Ọlọ́run mi, gẹ́gẹ́ bí òdodo rẹ, kí o má sì ṣe jẹ́ kí wọn kí ó yọ̀ lórí mi!
25 Ndũkareke meciirie atĩrĩ, “Haiya, ũguo noguo tũrendaga gwĩkĩke!” Kana moige atĩrĩ, “Nĩtũmũmeretie.”
Má ṣe jẹ́ kí wọn wí nínú ara wọn pé, “Háà! A ti rí ohun tí ọkàn wa ń fẹ́!” Má ṣe jẹ́ kí wọn kí ó wí pé, “A ti gbé e mì.”
26 Arĩa othe mangũũragĩra maitho mangenerere nĩ ũndũ wa mĩnyamaro yakwa maroconorithio na manyiitwo nĩ kĩrigiicano; arĩa othe metũũgagĩria igũrũ rĩakwa maroconorithio na maagithio gĩtĩĩo.
Kí ojú kí ó tì wọ́n, kí wọn kí ó sì dààmú pọ̀, àní àwọn tí ń yọ̀ sí ìyọnu mi kí a fi ìtìjú àti àbùkù wọ̀ wọ́n ní aṣọ tí ń gbéraga sí mi.
27 Arĩa makenaga ndaatuĩrwo ciira na kĩhooto, nĩmanĩrĩre na gĩkeno na gũcanjamũka; nĩmatũũre moigaga atĩrĩ, “Jehova arotũgĩrio, o we ũkenagĩra ũgaacĩru wa ndungata yake.”
Jẹ́ kí àwọn tí ó fẹ́ ìdáláre mi fò fún ayọ̀ àti ìdùnnú; kí wọn máa sọ ọ́ títí lọ, “Pé gbígbéga ni Olúwa, sí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ̀.”
28 Rũrĩmĩ rwakwa rũrĩaragia ũhoro wa ũthingu waku, na ngũgoocage mũthenya wothe.
Nígbà náà ni ahọ́n mi yóò máa sọ̀rọ̀ òdodo rẹ, àti ìyìn rẹ ní gbogbo ọjọ́.