< Gũcookerithia 9 >

1 Ta thikĩrĩria wee Isiraeli. Rĩu ũrorete kũringa Rũũĩ rwa Jorodani ũthiĩ ũgatunye ndũrĩrĩ nene na irĩ hinya gũgũkĩra, bũrũri ũrĩ na matũũra manene mũno mathiũrũrũkĩirio na thingo ikinyĩte o igũrũ.
Gbọ́, ìwọ Israẹli. Báyìí, ẹ̀yin ti gbáradì láti la Jordani kọjá, láti lọ gba ilẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè tí wọ́n tóbi, tí wọ́n sì lágbára jù yín lọ, tí wọ́n ní àwọn ìlú ńlá ńlá, tí odi wọn kan ọ̀run.
2 Andũ akuo marĩ hinya na nĩ araihu, nĩo Aanaki! Nĩũũĩ ũhoro wao, na nĩũiguĩte gũkĩĩrwo atĩrĩ: “Nũũ ũngĩhota gwĩtiiria andũ a Anaki?”
Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga àní àwọn ọmọ Anaki ni wọ́n. Ẹ gbọ́ nípa wọn, ẹ sì gbọ́ tí àwọn ènìyàn ń sọ nípa wọn pé, “Ta ni ó le è dojú ìjà kọ àwọn ọmọ Anaki (òmíràn)?”
3 No menya wega ũmũthĩ atĩ Jehova Ngai waku nĩwe ũkũringa athiĩ mbere yaku ahaana ta mwaki wa kũniinana. Nĩakamaniina; amatoorie mbere yaku. Nawe nĩũkamarutũrũra ũmaniine biũ o narua, o ta ũrĩa Jehova aakwĩrĩire.
Ṣùgbọ́n kí ó dá a yín lójú lónìí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni ó ń ṣáájú u yín lọ gẹ́gẹ́ bí iná ajónirun. Yóò jó wọn run, yóò sì tẹ orí wọn ba níwájú yín. Ẹ̀yin yóò sì lé wọ́n jáde, ẹ̀yin yóò sì run wọ́n kíákíá, bí Olúwa ti ṣèlérí fún un yín.
4 Jehova Ngai waku aarĩkia kũmaingata mehere mbere yaku-rĩ, ndũkaneĩĩre atĩrĩ, “Jehova andehete gũkũ ndĩĩgwatĩre bũrũri ũyũ nĩ ũndũ wa ũthingu wakwa.” Aca, ti ũguo, no nĩ tondũ wa waganu wa ndũrĩrĩ icio, nĩkĩo Jehova egũciingata ciehere mbere yaku.
Lẹ́yìn tí Olúwa Ọlọ́run yín bá ti lé wọn jáde níwájú u yín, ẹ má ṣe wí fún ara yín pé, “Torí òdodo mi ní Olúwa ṣe mú mi wá síbí láti gba ilẹ̀ náà.” Rárá, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa yóò ṣe lé wọn jáde níwájú u yín.
5 Ti ũthingu waku o na kana ũrũngĩrĩru waku ũgũtũma ũkegwatĩre bũrũri wacio; no nĩ tondũ wa waganu wa ndũrĩrĩ icio-rĩ, Jehova Ngai waku nĩekũmarutũrũra mehere mbere yaku nĩguo ahingie ũrĩa eehĩtire kũrĩ maithe maku, nĩo Iburahĩmu, na Isaaka, na Jakubu.
Kì í ṣe nítorí òdodo yín, tàbí ìdúró ṣinṣin ni ẹ ó fi wọ ìlú wọn lọ láti gba ilẹ̀ wọn, ṣùgbọ́n nítorí ìwà búburú àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí ni Olúwa Ọlọ́run yín yóò fi lé wọn jáde kúrò níwájú u yín láti lè mú ohun tí ó búra fún àwọn baba ṣẹ: fún Abrahamu, Isaaki àti Jakọbu.
6 Nĩ ũndũ ũcio, kĩmenye atĩ ti ũthingu waku ũtũmĩte Jehova Ngai waku akũhe bũrũri ũcio mwega ũwĩgwatĩre ũtuĩke waku, nĩgũkorwo inyuĩ mũrĩ andũ momĩtie ngingo.
Ṣùgbọ́n kí ó yé yín pé kì í ṣe nítorí òdodo yín ni Olúwa Ọlọ́run yín fi ń fún un yín ní ilẹ̀ rere náà, láti ní, nítorí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle ni ẹ jẹ́.
7 Ririkanaga na ndũkanariganĩrwo nĩ ũrĩa warakaririe Jehova Ngai waku kũu werũ-inĩ. Kuuma mũthenya ũrĩa woimire bũrũri wa Misiri nginya rĩrĩa mwakinyire gũkũ, mũkoretwo mũkĩremera Jehova.
Ẹ rántí, ẹ má sì ṣe gbàgbé bí ẹ̀yin ti mú Olúwa Ọlọ́run yín bínú ní aginjù. Láti ọjọ́ ti ẹ tí kúrò ní Ejibiti ni ẹ̀yin ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa títí tí ẹ̀yin fi dé ìhín yìí.
8 Mũrĩ kũu Horebu nĩmwatũmire marakara ma Jehova maarahũke akĩrakara nginya akĩenda kũmũniina.
Ní Horebu ẹ̀yin ti mú kí Olúwa bínú, títí dé bi pé ó fẹ́ run yín.
9 Rĩrĩa ndaambatire kĩrĩma-inĩ nganengerwo ihengere cia mahiga, ihengere iria ciandĩkĩtwo kĩrĩkanĩro kĩrĩa Jehova aarĩkanĩire na inyuĩ, nĩndaikarire kũu kĩrĩma igũrũ matukũ mĩrongo ĩna, mũthenya na ũtukũ; ndiarĩire irio kana ngĩnyua maaĩ.
Nígbà tí mo gòkè lọ láti lọ gba wàláà òkúta, wàláà májẹ̀mú ti Olúwa ti bá a yín dá. Ogójì ọ̀sán àti òru ni mo fi wà lórí òkè náà, èmi kò fẹnu kan oúnjẹ bẹ́ẹ̀ ni ń kò mu omi.
10 Jehova nĩanengerire ihengere igĩrĩ cia mahiga ciandĩkĩtwo na kĩara kĩa Ngai. Ciandĩkĩtwo maathani mothe marĩa Jehova aamwarĩirie kũu kĩrĩma-inĩ arĩ thĩinĩ wa mwaki, mũthenya ũrĩa mwagomanĩte.
Olúwa fún mi ní wàláà òkúta méjì tí a fi ìka Ọlọ́run kọ. Lórí wọn ni a kọ àwọn òfin tí Ọlọ́run sọ fún un yín lórí òkè láàrín iná, ní ọjọ́ ìpéjọpọ̀ sí.
11 Hĩndĩ ĩrĩa matukũ macio mĩrongo ĩna, mũthenya na ũtukũ, maathirire-rĩ, Jehova nĩanengerire ihengere icio igĩrĩ cia mahiga, ihengere icio cia kĩrĩkanĩro.
Lópin ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí, Olúwa fún mi ní sílétì òkúta méjì, wàláà òkúta májẹ̀mú náà.
12 Jehova agĩcooka akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Ikũrũka narua uume gũkũ nĩ ũndũ andũ aku arĩa warutire bũrũri wa Misiri nĩmethũkĩtie. Nĩmagarũrũkĩte o na ihenya magatiganĩria maathani marĩa ndamaathire na nĩmethondekeire mũhianano wa gũtwekio.”
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ̀kalẹ̀ kúrò níhìn-ín kíákíá, torí pé àwọn ènìyàn rẹ tí o mú jáde láti Ejibiti ti hùwà ìbàjẹ́. Wọ́n ti yípadà kúrò, nínú ọ̀nà mi, wọ́n sì ti ṣe ère dídá fún ara wọn.”
13 Ningĩ Jehova akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Andũ aya nĩndĩmoonete, ngoona atĩ nĩ andũ momĩtie ngingo mũno!
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Mo ti rí àwọn ènìyàn wọ̀nyí pé ènìyàn ọlọ́rùn líle gbá à ni wọ́n.
14 Ndekereria, nĩguo ndĩmaniine na tharie rĩĩtwa rĩao gũkũ thĩ mũhuro wa riũa. Thuutha wa ũguo njooke ngũtue rũrĩrĩ rũrĩ hinya na rũrĩ na andũ aingĩ kũmakĩra.”
Fi mí sílẹ̀, jẹ́ kí n run wọ́n, kí n sì pa orúkọ wọn rẹ́ kúrò lábẹ́ ọ̀run. Èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè tí ó lágbára tí ó sì pọ̀jù wọ́n lọ.”
15 Nĩ ũndũ ũcio ngĩhũndũka ngĩikũrũka kuuma kĩrĩma igũrũ o gĩkĩrĩrĩmbũkaga mwaki. Nacio ihengere icio igĩrĩ cia kĩrĩkanĩro ciarĩ moko-inĩ makwa.
Báyìí ni mo yípadà, tí mó sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè náà wá, orí òkè tí o ń yọ iná. Àwọn wàláà májẹ̀mú méjèèjì sì wà lọ́wọ́ mi.
16 Rĩrĩa ndaacũthĩrĩirie, nĩndonire atĩ nĩmwehĩirie Jehova Ngai wanyu; nĩ mwethondekeire mũhianano wa gũtwekio ũhaana ta njaũ. Nĩmwagarũrũkĩte o narua mũgatiga kũrũmĩrĩra njĩra ĩrĩa Jehova aamwathĩte mũrũmagĩrĩre.
Ìgbà tí mo ṣàkíyèsí, mo rí i pé ẹ ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ ti ṣe ère òrìṣà ní ìrí ọ̀dọ́ màlúù, fún ara yín. Ẹ ti yípadà kánkán kúrò nínú ọ̀nà tí Olúwa ti pàṣẹ fún un yín.
17 Nĩ ũndũ ũcio ngĩnyiita ihengere icio igĩrĩ ngĩcirekania kuuma moko-inĩ makwa, nacio ikĩenyũkanga icunjĩ mũkĩĩonagĩra na maitho manyu.
Bẹ́ẹ̀ ni mó ju wàláà méjèèjì náà mọ́lẹ̀, mo sì fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́ lójú u yín.
18 Ningĩ ngĩĩgũithia thĩ mbere ya Jehova matukũ mĩrongo ĩna, mũthenya na ũtukũ; ndiigana kũrĩa irio kana ngĩnyua maaĩ, nĩ ũndũ wa mehia marĩa mothe mwekĩte, mũgeeka maũndũ mooru maitho-inĩ ma Jehova, mũgĩtũma arakare.
Lẹ́yìn náà mo tún wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi kò jẹ oúnjẹ kankan bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu omi, nítorí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ tí dá, tí ẹ sì ń ṣe búburú lójú Olúwa, tí ẹ sì ń mú u bínú.
19 Nĩndetigagĩra marakara na mangʼũrĩ ma Jehova, nĩgũkorwo nĩamũrakarĩire o kũigana ũndũ angĩamũniinire. No Jehova nĩathikĩrĩirie o rĩngĩ.
Mo bẹ̀rù ìbínú àti ìrunú Olúwa, nítorí pé inú bí i sí i yín dé bi wí pé ó fẹ́ pa yín run. Ṣùgbọ́n Olúwa tún fetí sí mi lẹ́ẹ̀kan sí i.
20 Nake Jehova nĩarakarĩire Harũni o kũigana ũndũ angĩamũniinire, no ihinda rĩu, nĩndahooeire Harũni o nake.
Inú sì bí Olúwa sí Aaroni láti pa á run, nígbà náà ni mo tún gbàdúrà fún Aaroni náà.
21 Ningĩ ngĩcooka ngĩoya kĩndũ kĩu kĩanyu kĩa wĩhia, nakĩo nĩkĩo njaũ ĩyo mwathondekete, na ngĩmĩcina na mwaki. Ngĩcooka ngĩmĩthethera ngĩmĩthĩa ĩgĩtuĩka mũtutu mũhinyu ta rũkũngũ, naruo rũkũngũ rũu ngĩrũikia karũũĩ gaathereraga koimĩte kĩrĩma-inĩ.
Bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú ohun tí ó mú un yín dẹ́ṣẹ̀, àní ère ẹgbọrọ màlúù tí ẹ ti ṣe, mo sì fi iná sun ún, bẹ́ẹ̀ ni mo gún un, mo sì lọ̀ ọ́ lúúlúú bí eruku lẹ́búlẹ́bú, mo sì da ẹ̀lọ̀ rẹ̀ sínú odò tí ń sàn nísàlẹ̀ òkè.
22 O na ningĩ nĩmwarakaririe Jehova mũrĩ kũu Tabera, na Masa, na Kibirothu-Hataava.
Ẹ̀yin tún mú Olúwa bínú ní Tabera, Massa àti ní Kibirotu-Hattaafa.
23 Na rĩrĩa Jehova aamũtũmire kuuma Kadeshi-Barinea, aamwĩrire atĩrĩ, “Ambatai mũthiĩ mũkegwatĩre bũrũri ũrĩa ndĩmũheete.” No nĩ mwaremeire watho wa Jehova Ngai wanyu. Mũtiigana kũmwĩhoka kana kũmwathĩkĩra.
Nígbà tí Olúwa ran an yín jáde ní Kadeṣi-Barnea, Ó wí pé, “Ẹ gòkè lọ, kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín.” Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa Ọlọ́run yín. Ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé e, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò gbọ́ tirẹ̀.
24 Kuuma rĩrĩa ndamũmenyire, mũtũũraga mũremeire Jehova.
Láti ìgbà tí mo ti mọ̀ yín ni ẹ ti ń ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa.
25 Nĩndegũithirie thĩ mbere ya Jehova matukũ macio mĩrongo ĩna, mũthenya na ũtukũ, tondũ Jehova nĩoigĩte atĩ nĩekũmũniina.
Mo ti wólẹ̀ níwájú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti òru wọ̀nyí nítorí pé Olúwa sọ pé Òun yóò pa yín run.
26 Ngĩhooya Jehova, ngĩmwĩra atĩrĩ, “Wee Mwathani Jehova, tiga kũniina andũ aya aku, o aya igai rĩaku kĩũmbe arĩa wakũũrire na ũndũ wa hinya waku mũnene, ũkĩmaruta bũrũri wa Misiri na guoko gwaku kwa hinya.
Mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé, “Olúwa Olódùmarè, má ṣe run àwọn ènìyàn rẹ, àní ogún rẹ tí o ti rà padà, nípa agbára rẹ tí o sì fi agbára ńlá mú wọn jáde láti Ejibiti wá.
27 Ririkana ndungata ciaku Iburahĩmu, na Isaaka, na Jakubu. Tiga kũrora ũmũ wa ngoro cia andũ aya, na waganu wao, o na mehia mao.
Rántí àwọn ìránṣẹ́ rẹ Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu. Fojú fo orí kunkun àwọn ènìyàn yìí, pẹ̀lú ìwà búburú àti ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
28 Kwaga ũguo, bũrũri ũrĩa wee watũrutire ũkoiga atĩrĩ, ‘Tondũ Jehova ndangĩahotire kũmakinyia bũrũri ũrĩa aamerĩire, na nĩ tondũ nĩamamenete-rĩ, nĩkĩo aamatwarire werũ-inĩ amooragĩre kuo.’
Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti mú wa jáde wá yóò wí pé, ‘Torí pé Olúwa kò lè mú wọn lọ sí ilẹ̀ náà tí ó ti ṣèlérí fún wọn, àti pé ó ti kórìíra wọn, ni ó fi mú wọn jáde láti pa wọ́n ní aginjù.’
29 No andũ aya nĩ aku, o igai rĩaku kĩumbe, arĩa warutire kũu na ũndũ wa hinya waku mũnene, na guoko gwaku gũtambũrũkĩtio.”
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn rẹ ni wọ́n, ogún rẹ tí o ti fi ọwọ́ agbára rẹ àti nínà ọwọ́ rẹ mú jáde.”

< Gũcookerithia 9 >