< Nombres 12 >

1 Or Marie et Aaron parlèrent contre Moïse à cause de sa femme l’Éthiopienne,
Miriamu àti Aaroni sọ̀rọ̀-òdì sí Mose nítorí pé ó fẹ́ obìnrin ará Etiopia.
2 Et dirent: Est-ce par le seul Moïse qu’a parlé le Seigneur? Ne nous a-t-il pas également parlé? Ce qu’ayant entendu le Seigneur,
Wọ́n sì wí pé, “Nípa Mose nìkan ni Olúwa ti sọ̀rọ̀ bí, kò ha ti ipa wa sọ̀rọ̀ bí?” Olúwa sì gbọ́ èyí.
3 (Car Moïse était l’homme le plus doux de tous les hommes qui demeuraient sur la terre)
(Mose sì jẹ́ ọlọ́kàn tútù ju gbogbo ènìyàn tó wà lórí ilẹ̀ ayé lọ).
4 Il dit aussitôt à Moïse, à Aaron et à Marie: Sortez, vous trois seulement, pour aller au tabernacle d’alliance. Et lorsqu’ils furent sortis,
Lẹ́ẹ̀kan náà ni Olúwa sọ fún Mose, Aaroni àti Miriamu pé, “Ẹ̀yin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, jáde wá sínú àgọ́ ìpàdé.” Àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì jáde síta.
5 Le Seigneur descendit dans une colonne de nuée, et se tint à l’entrée du tabernacle, appelant Aaron et Marie. Lorsqu’ils furent venus,
Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú ọ̀wọ́n ìkùùkuu, ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, ó ké sí Aaroni àti Miriamu. Àwọn méjèèjì sì bọ́ síwájú,
6 Il leur dit: Ecoutez mes paroles: Si quelqu’un parmi vous est prophète du Seigneur, je lui apparaîtrai dans la vision, ou je lui parlerai en songe.
Ó wí pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, “Bí wòlíì Olúwa bá wà láàrín yín, Èmi Olúwa a máa fi ara à mi hàn án ní ojúran, Èmi a máa bá a sọ̀rọ̀ nínú àlá.
7 Mais tel n’est pas mon serviteur Moïse, qui est très fidèle dans toute ma maison;
Ṣùgbọ́n èyí kò rí bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú Mose ìránṣẹ́ mi; ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo ilé mi.
8 Car c’est bouche à bouche que je lui parle, et c’est clairement et non en énigmes et en figures qu’il voit le Seigneur. Pourquoi donc n’avez-vous pas craint de décrier mon serviteur Moïse?
Mo sì ń bá a sọ̀rọ̀ ní ojúkojú, ọ̀rọ̀ yékéyéké tí kì í ṣe òwe, ó rí àwòrán Olúwa. Kí ló wá dé tí ẹ̀yin kò ṣe bẹ̀rù láti sọ̀rọ̀-òdì sí Mose ìránṣẹ́ mi?”
9 Et, irrité contre eux, il s’en alla.
Ìbínú Olúwa sì ru sókè sí wọn Olúwa sì fi wọ́n sílẹ̀.
10 La nuée aussi qui était sur le tabernacle se retira: et voilà que Marie parut blanche de lèpre comme la neige. Or Aaron l’ayant regardée, et l’ayant vue couverte de lèpre,
Nígbà tí ìkùùkuu kúrò lórí àgọ́ lójijì ni Miriamu di adẹ́tẹ̀, ó funfun bí i yìnyín. Aaroni sì padà wo Miriamu ó sì rí i pé ó ti di adẹ́tẹ̀,
11 Dit à Moïse: Je vous conjure, mon seigneur, ne nous imposez point un péché que nous avons commis follement;
Aaroni sì wí fún Mose pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀, èyí tí a fi ìwà òmùgọ̀ dá sí wa lọ́rùn.
12 Que celle-ci ne devienne pas comme morte, et comme l’avorton qui est rejeté du sein de sa mère; voilà que déjà la moitié de sa chair a été dévorée par la lèpre.
Má ṣe jẹ́ kí ó dàbí òkú ọmọ tí a bí, tí ìdajì ara rẹ̀ ti rà dànù.”
13 Moïse donc cria au Seigneur, disant: Dieu, je vous conjure, guérissez-la.
Torí èyí Mose sì kígbe sí Olúwa, “Ọlọ́run, jọ̀wọ́, mú un láradá!”
14 Le Seigneur lui répondit: Si son père eût craché sur sa face, n’eût-elle pas dû être au moins pendant sept jours couverte de honte? Qu’elle soit séparée durant sept jours hors du camp, et après cela elle sera rappelée.
Olúwa sì dá Mose lóhùn, “Bí baba rẹ̀ bá tutọ́ sí i lójú, ojú kò wa ní í tì í fún ọjọ́ méje? Dá a dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, lẹ́yìn èyí ki a tó ó le mú wọlé.”
15 C’est pourquoi Marie fut exclue du camp durant sept jours; et le peuple ne sortit pas de ce lieu, jusqu’à ce que Marie fut rappelée.
Miriamu sì dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, àwọn ènìyàn kò sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn títí tí Miriamu fi wọ inú ibùdó padà.
16 Après cela le peuple partit d’Haséroth, et planta ses tentes dans le désert de Pharan.
Lẹ́yìn èyí, àwọn ènìyàn kúrò ní Haserotu, wọ́n sì pa ibùdó sí aginjù Parani.

< Nombres 12 >