< Daniel 10 >
1 Dans la troisième année de Cyrus, roi de Perse, une révélation fut faite à Daniel, qui avait reçu le surnom de Beltchaçar; véridique était cette révélation et à longue portée. Il s’appliqua à s’en rendre compte et eut la claire intelligence de la vision:
Ní ọdún kẹta Kirusi ọba Persia, a fi ìran kan hàn Daniẹli (ẹni tí à ń pè ní Belteṣassari). Òtítọ́ ni ọ̀rọ̀ ìran náà, ó sì ní í ṣe pẹ̀lú àsìkò ìpọ́njú ńlá, òye ọ̀rọ̀ náà wá bá a nínú ìran.
2 "En ces temps-là, moi Daniel, je fus plongé dans le deuil durant trois semaines complètes.
Ní àsìkò náà, èmi Daniẹli ṣọ̀fọ̀ fún ọ̀sẹ̀ mẹ́ta.
3 Je ne mangeai point d’aliment de choix, ni viande ni pain n’entrèrent dans ma bouche, et je ne me frottai d’aucune huile jusqu’à ce que fussent révolues trois semaines complètes.
Èmi kì í jẹ oúnjẹ tí ó dára, èmi kò fi ẹran tàbí wáìnì kan ẹnu mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi òróró para títí ọ̀sẹ̀ mẹ́ta fi kọjá.
4 Le vingt-quatrième jour du premier mois, je me trouvais au bord du grand fleuve, le Tigre.
Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù àkọ́kọ́, bí mo ti dúró sí etí i bèbè odò ńlá Tigirisi,
5 Je levai les yeux et regardai, et je vis soudain un personnage, vêtu de lin et ayant autour des reins une ceinture d’or pur.
mo wo òkè, mo rí ọkùnrin kan tí ó wọ aṣọ àlà, ẹ̀gbẹ́ ẹni tí a fi wúrà Upasi dáradára dì ní àmùrè.
6 Son corps était pareil au Tarchich, sa face brillait comme l’éclair et ses yeux comme des torches enflammées; ses bras et ses pieds avaient l’aspect de l’airain poli, et le son de ses paroles éclatait comme, le bruit d’une multitude.
Ara rẹ̀ dàbí berili, ojú u rẹ̀ dàbí mọ̀nàmọ́ná, ẹyin ojú u rẹ̀ dàbí iná àtẹ̀tàn, apá àti ẹsẹ̀ rẹ̀ dàbí ìtànná ìmọ́lẹ̀ tí o kún fún idẹ, àti ohùn rẹ̀ dàbí i ti ìjọ ènìyàn púpọ̀.
7 Moi Daniel, je fus seul à voir l’apparition; les hommes qui étaient avec moi ne la voyaient point; mais, une grande frayeur s’étant emparée d’eux, ils s’enfuirent pour se cacher.
Èmi Daniẹli, ni ẹnìkan tí ó rí ìran náà, àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú u mi, wọn kò rí i, ṣùgbọ́n ìpayà ńlá dà bò wọ́n, wọ́n sálọ wọ́n sì fi ara pamọ́.
8 Je demeurai donc seul, et, à la vue de cette grande apparition, mes forces m’abandonnèrent, mon visage s’altéra jusqu’à en devenir livide, et je tombai dans un état de faiblesse.
Ó sì ku èmi nìkan, tí mo rí ìran ńlá yìí, kò sì ku okun kankan fún mi, ojú u mi sì rẹ̀wẹ̀sì gidigidi, n kò sì ní agbára mọ́.
9 J’Entendis le son de ses paroles, et dès que j’entendis le son de ses paroles je tombai, tout étourdi la face contre terre.
Nígbà náà, ni mo gbọ́ tí ó ń sọ̀rọ̀, bí mo ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí i, mo sùn lọ fọnfọn, ní ìdojúbolẹ̀.
10 Mais voilà qu’une main m’effleura et me releva chancelant sur mes genoux et la paume de mes mains.
Ọwọ́ kan kàn mí, ó gbé mi dìde ní ìwárìrì lórí ọwọ́ àti eékún mi.
11 Il me dit: "Daniel, homme de prédilection, saisis bien le sens des paroles que je t’adresse et remets-toi d’aplomb, car présentement j’ai été dépêché vers toi." Tandis qu’il me tenait ce discours, je me relevai en tremblant.
Ó sọ pé, “Daniẹli ẹni tí a yàn fẹ́ gidigidi gba ọ̀rọ̀ tí mo fẹ́ bá ọ sọ yìí yẹ̀ wò dáradára, kí o sì dìde, nítorí tí a rán mi sí ọ.” Bí ó ṣe sọ èyí fún mi, mo dìde ní ìwárìrì.
12 Il ajouta encore: "N’Aie pas peur, Daniel, car dès le premier jour où tu as pris à cœur de te rendre compte et de te mortifier devant ton Dieu, tes paroles ont été entendues, et c’est attiré par tes paroles que je suis venu à toi.
Nígbà náà ni ó tẹ̀síwájú, pé, “Má ṣe bẹ̀rù Daniẹli. Láti ọjọ́ àkọ́kọ́ tí ìwọ ti fi ọkàn rẹ sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run rẹ, a gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ, mo sì wá nítorí ọ̀rọ̀ náà.
13 Or, le prince de l’empire de Perse m’a tenu tête durant vingt-et-un jours; mais enfin Mikhaël, l’un des princes supérieurs, est venu me prêter main-forte; de la sorte je me suis trouvé retenu auprès des rois de Perse.
Ṣùgbọ́n ọmọ-aládé ìjọba Persia dá mi dúró fún ọjọ́ mọ́kànlélógún. Nígbà náà ni Mikaeli, ọ̀kan lára ìjòyè àwọn ọmọ-aládé, wá láti ràn mi lọ́wọ́, nítorí a dá mi dúró níbẹ̀ pẹ̀lú ọba Persia.
14 Et maintenant j’arrive pour t’exposer clairement ce qui adviendra à ton peuple à la fin des jours, car cette vision aussi se rapporte à des temps éloignés.
Ní ìsinsin yìí mo wá láti ṣàlàyé ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú, nítorí ìran náà ń sọ nípa ọjọ́ iwájú.”
15 Tandis qu’il s’adressait à moi en ces termes, j’abaissais mes regards vers la terre et demeurais muet.
Bí ó sì ti ń sọ nǹkan wọ̀nyí fún mi, mo sì dorí kodò mo sì dákẹ́.
16 Mais alors un personnage qui avait une forme humaine toucha mes lèvres; j’ouvris la bouche pour parler et je dis à celui qui se tenait en face de moi: "Mon Seigneur, par suite de l’apparition, de poignantes angoisses m’ont saisi, et mes forces m’ont abandonné;
Nígbà náà, ni ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kan ètè mi, mo la ẹnu mi, mo sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọ ọ̀rọ̀, mo sọ fún ẹni tí ó dúró níwájú mi, “Ìrònú sì mú mi, nítorí ìran náà, olúwa mi, n kò sì ní okun.
17 et comment le serviteur de mon Seigneur pourrait-il parler à mon Seigneur, alors que nulle force ne subsiste en moi et qu’il ne me reste plus de souffle?"
Ǹjẹ́ báwo ni èmi ìránṣẹ́ ẹ̀ rẹ ṣe lè bá ọ sọ̀rọ̀, olúwa mi? Agbára mi ti lọ, agbára káká ni mo fi ń mí.”
18 De nouveau une forme humaine me toucha et me rendit des forces.
Ẹ̀wẹ̀, ẹnìkan tí ó rí bí ènìyàn fi ọwọ́ kàn mí, ó sì fún mi ní agbára.
19 II me dit: "N’Aie pas peur, homme de prédilection! Que la paix soit avec toi! Prends courage et sois fort!" Comme II me parlait, je repris courage et je dis: "Que mon seigneur parle, car tu m’as réconforté!"
Ó sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ ọkùnrin olùfẹ́ gidigidi. Àlàáfíà ni fún ọ, mú ara le, àní mú ara le.” Nígbà tí ohun bá mi sọ̀rọ̀, a sì mú mi lára le. “Mo sì wí pé, kí olúwa mi kí ó máa sọ̀rọ̀, níwọ̀n ìgbà tí ìwọ ti mú mi ní ara le.”
20 II me répliqua: "Sais-tu pourquoi je suis venu à toi? A présent, il faut que je m’en retourne lutter contre le prince de Perse, et quand j’en aurai fini avec lui, ce sera au tour du prince de la Grèce de venir.
Nígbà náà, ni ó wí pé, “Ṣé o mọ ìdí tí mo fi tọ̀ ọ́ wá? Láìpẹ́ èmi yóò yípadà lọ bá àwọn ọmọ-aládé Persia jà, nígbà tí mo bá lọ àwọn ọmọ-aládé Giriki yóò wá;
21 Mais j’ai à te révéler d’abord ce qui est consigné dans un écrit véridique: personne ne me soutient dans ma lutte contre ceux-ci, sauf Mikhaël, votre prince à vous."
ṣùgbọ́n ní àkọ́kọ́, èmi yóò sọ ohun tí wọ́n kọ sínú ìwé òtítọ́ fún ọ. (Kò sí ẹni tí ó kún mi lọ́wọ́ fún nǹkan wọ̀nyí bí kò ṣe Mikaeli, ọmọ-aládé e yín.