< Joshua 20 >
1 Then Yahweh said to Joshua,
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Joṣua pé,
2 “Speak to the people of Israel, saying, 'Appoint the cities of refuge of which I spoke to you by the hand of Moses.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn yan àwọn ìlú ààbò, gẹ́gẹ́ bí mo ti pàṣẹ fún ọ láti ẹnu Mose,
3 Do this so that one who unintentionally kills a person can go there. These cities will be a place of refuge from anyone who seeks to avenge the blood of a person who was killed.
kí ẹni tí ó bá ṣèèṣì pa ènìyàn tàbí tí ó bá pa ènìyàn láìmọ̀-ọ́n-mọ̀ lè sálọ sí ibẹ̀, fún ààbò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó pa.
4 He will run to one of those cities and will stand at the entrance of the city gate, and explain his case to the elders of that city. Then they will take him into the city and give him a place for him to live among them.
Nígbà tí ó bá sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú wọ̀nyí, yóò sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àtiwọ ibodè ìlú, kí ó sì ṣe àlàyé ara rẹ̀ ní iwájú àwọn àgbàgbà ìlú náà. Nígbà náà ni wọn yóò gbà á sí ìlú wọn, wọn yóò sì fun ní ibùgbé láàrín wọn.
5 If one of them comes to try to avenge the blood of the person who was killed, then the people of the city must not hand the one who killed him over to the authorities. They must not do this because he killed his neighbor unintentionally, and he had no hatred toward him in the past.
Bí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ bá ń lépa rẹ̀, wọn kò gbọdọ̀ fi àwọn ọ̀daràn náà lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí ó pa aládùúgbò rẹ̀ láìmọ̀, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí.
6 He must stay in that city until he has stood before the assembly for judgment, until the death of the one who was serving as high priest in those days. Then the one who had accidentally killed the person may return to his own town and his own home, to the town from which he fled.'”
Òun ó sì máa gbé inú ìlú náà, títí yóò fi jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn àti títí ikú olórí àlùfáà tí ó ń ṣiṣẹ́ ìsìn nígbà náà. Nígbà náà ó lè padà sí ilé rẹ̀ ní ìlú tí ó ti sá wá.”
7 So the Israelites selected Kedesh in Galilee in the hill country of Naphtali, Shechem in the hill country of Ephraim, and Kiriath Arba (the same as Hebron) in the hill country of Judah.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yan Kedeṣi ní Galili ní ìlú òkè Naftali, Ṣekemu ní ìlú òkè Efraimu, àti Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) ní ìlú òkè Juda.
8 Beyond the Jordan east of Jericho, they selected Bezer in the wilderness on the plateau from the tribe of Reuben; Ramoth Gilead, from the tribe of Gad; and Golan in Bashan, from the tribe of Manasseh.
Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani ti Jeriko, wọ́n ya Beseri ní aginjù ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ẹ̀yà Reubeni, Ramoti ní Gileadi ní ẹ̀yà Gadi, àti Golani ní Baṣani ní ẹ̀yà Manase.
9 These were the cities selected for all the people of Israel and for the foreigners residing among them, so that anyone who killed a person unintentionally could run to them for safety. This person would not die by the hand of the one who wanted to avenge the blood that was shed, until the accused person would first stand before the assembly.
Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé ní àárín wọn tí ó ṣèèṣì pa ẹnìkan lè sálọ sí àwọn ìlú tí a yà sọ́tọ̀ wọ̀nyí, kí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má sì ṣe pa á kí ó to di àkókò tí yóò jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn.