< Ezekiel 27 >
1 Yahweh said this to me:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé:
2 “You human, sing a funeral song about Tyre.
“Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún fún Tire.
3 [The city of] is located [on an island] at the edge of the sea, and their merchants (traded/bought and sold goods) with people-groups [who live] along many seacoasts. This is what [I], Yahweh the Lord, say [that you should tell them]: ‘You [people of] Tyre said that your [city] was very beautiful.
Sọ fún Tire, tí a tẹ̀dó sí ẹnu-bodè Òkun, oníṣòwò àwọn orílẹ̀-èdè fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ erékùṣù. ‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Ìwọ Tire wí pé, “Ẹwà mi pé.”
4 You controlled what was bought and sold by people who lived along the sea. Those who built your [city] caused it to become very beautiful.
Ààlà rẹ wà ní àárín Òkun; àwọn ọ̀mọ̀lé rẹ ti mú ẹwà rẹ pé.
5 You were like [SIM] a huge ship that was built from the from pine/cypress [trees] on Hermon [Mountain]. Then they took cedar [wood] from Lebanon to make a mast for the ship.
Wọn ṣe gbogbo pákó rẹ ní igi junifa láti Seniri; wọ́n ti mú igi kedari láti Lebanoni wá láti fi ṣe òpó ọkọ̀ fún ọ.
6 They carved your oars from oak trees from the Bashan [region]. They made the deck from cypress/pine wood from Cyprus [island], and they covered [the decks] with ivory.
Nínú igi óákù ti Baṣani ní wọn ti fi gbẹ́ ìtukọ̀ ọ̀pá rẹ̀; ìjókòó rẹ ni wọn fi eyín erin ṣe pẹ̀lú igi bokisi láti erékùṣù Kittimu wá.
7 The sails for the ship were made from fine embroidered linen from Egypt, and those sails were like flags that people could see [far away]. For shade they [hung pieces of] blue and purple cloth [brought] from [people living on] Cyprus [island].
Ọ̀gbọ̀ dáradára aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́ láti Ejibiti wá ni èyí tí ìwọ ta láti fi ṣe àsíá ọkọ̀ rẹ; aṣọ aláró àti elése àlùkò láti erékùṣù ti Eliṣa ni èyí tí a fi bò ó.
8 Men from Sidon and Arvad [cities] pulled the oars; the men who steered the boat were skilled men from Tyre.
Àwọn ará ìlú Sidoni àti Arfadi ni àwọn atukọ̀ rẹ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n ẹ̀rọ rẹ, ìwọ Tire, ni àwọn atukọ̀ rẹ.
9 Experienced craftsmen from Byblos [city on the coast] (did the caulking/filled the spaces between the planks in the sides) of the ship. Sailors from many countries came in their ships to buy and sell goods there.
Àwọn àgbàgbà Gebali, àti àwọn ọlọ́gbọ́n ibẹ̀, wà nínú ọkọ̀ bí òṣìṣẹ́ atukọ̀ rẹ, gbogbo ọkọ̀ ojú Òkun àti àwọn atukọ̀ Òkun wá pẹ̀lú rẹ láti dòwò pọ̀ pẹ̀lú rẹ̀.
10 Men from [as far away as] Persia, Lydia, and Libya were [soldiers] in your army. They hung their shields and helmets on [the walls of] your [city], and that caused people to admire your city.
“‘Àwọn ènìyàn Persia, Ludi àti Puti wà nínú jagunjagun rẹ àwọn ẹgbẹ́ ọmọ-ogun rẹ. Wọ́n gbé asà àti àṣíborí wọn ró sára ògiri rẹ, wọn fi ẹwà rẹ hàn.
11 Men from Arvad and Helech [cities were watchmen] on the walls [of your city]; men from Gammad [town] were in your towers. They [also] hung their shields on your walls; they also caused your [city] to be very beautiful.
Àwọn ènìyàn Arfadi àti Heleki wà lórí odi rẹ yíká; àti àwọn akọni Gamadi, wà nínú ilé ìṣọ́ rẹ. Wọ́n fi àwọn asà wọn kọ ara odi rẹ; wọn ti mú ẹwà rẹ pé.
12 Because of the many things that you had [to trade], men from Tarshish [in Spain] sent merchants who brought silver, iron, tin, and lead to trade for things that you had.
“‘Tarṣiṣi ṣòwò pẹ̀lú rẹ torí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ tí ó ní; wọn ṣe ìpààrọ̀ fàdákà, irin idẹ àti òjé fún ọjà títà rẹ̀.
13 [Merchants from] Greece, Tubal, and Meshech brought slaves and things made from bronze to trade for things that you had.
“‘Àwọn ará Giriki, Tubali, Jafani àti Meṣeki, ṣòwò pẹ̀lú rẹ, wọ́n fi ẹrù àti ohun èlò idẹ ṣe pàṣípàrọ̀ fún ọrọ̀ rẹ.
14 [Men from] Beth-Togarmah [in Armenia] brought work horses, war horses, and mules to trade for things that you had.
“‘Àwọn ti ilé Beti-Togarma ṣe ìpààrọ̀ ẹṣin-ìṣiṣẹ́, ẹṣin ogun àti ìbáaka ṣòwò ní ọjà rẹ.
15 Merchants came to you from Rhodes [island]. [People from] nations along the coast traded with you; they brought (ivory/elephant tusks) and [valuable black] ebony [wood] to trade for things that you had.
“‘Àwọn ènìyàn Dedani ni àwọn oníṣòwò rẹ, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ erékùṣù ni wọ́n jẹ́ oníbàárà rẹ̀; wọ́n mú eyín erin àti igi eboni san owó rẹ.
16 Because you had very many things [to trade], people from Syria brought to you valuable turquoise stones, purple [cloth], embroidered [cloth], fine linen [cloth], and [jewelry made from] coral and rubies to trade for your things.
“‘Aramu ṣòwò pẹ̀lú nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ iṣẹ́ òwò rẹ̀; wọn ṣe ìpààrọ̀ òkúta iyebíye, òwú elése àlùkò, aṣọ iṣẹ́ ọnà abẹ́rẹ́, aṣọ ọ̀gbọ̀ dáradára, ìlẹ̀kẹ̀ iyùn pupa fún ọjà títà rẹ.
17 Men from Judah and Israel brought wheat from Minnith [city in Ammon], and figs, honey, [olive] oil, and ointment to trade for your things.
“‘Juda àti Israẹli, àwọn ni oníṣòwò rẹ; wọn ṣe ìpààrọ̀ ọkà, Minniti, àkàrà àdídùn; oyin, epo àti ìkunra olóòórùn dídùn ni wọ́n fi ná ọjà rẹ.
18 Because you had very many things [to trade], men from Damascus brought wine from Helbon [town] and white wool from the Zahar [area] to trade for many things that you had.
“‘Damasku ni oníṣòwò rẹ, nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ọjà tí ó ṣe àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀; ní ti ọtí wáìnì tí Helboni, àti irun àgùntàn funfun láti Sahari,
19 Greek men from the Uzal [area] brought things made of iron, and cassia [spice], and [fragrant] calamus [seeds] to trade for things that you had.
àti ìdẹ̀ ọtí wáìnì láti Isali, ohun wíwọ̀: irin dídán, kasia àti kálàmù ni àwọn ohun pàṣípàrọ̀ fún ọjà rẹ.
20 [Merchants came from] Dedan [in southern Edom] bringing saddle blankets to trade for things that you had.
“‘Dedani ni oníṣòwò rẹ ní aṣọ ìjókòó-lẹ́sin fún ẹṣin-gígùn.
21 Men from Arabia and all the rulers of the Kedar [region] sent merchants to trade lambs and rams and male goats for things that you had.
“‘Àwọn ará Arabia àti gbogbo àwọn ọmọ-aládé ìlú Kedari àwọn ni àwọn oníbàárà rẹ; ní ti ọ̀dọ́-àgùntàn, àgbò àti ewúrẹ́, nínú ìwọ̀nyí ni wọ́n ti jẹ́ oníbàárà rẹ.
22 Merchants from Sheba and Raamah [in Arabia] brought many kinds of very good spices and jewels and gold to exchange for things that you had.
“‘Àwọn oníṣòwò ti Ṣeba àti Raama, àwọn ni oníṣòwò rẹ; wọ́n ta onírúurú tùràrí olóòórùn dídùn dáradára ní ọjà rẹ, àti àwọn òkúta iyebíye àti wúrà.
23 [Men came from] Haran, Canneh, Eden, Sheba, Asshur and Kilmad [in Mesopotamia] with their goods.
“‘Harani àti Kanneh àti Edeni, àwọn oníṣòwò Ṣeba, Asiria àti Kilmadi, ni àwọn oníṣòwò rẹ.
24 They brought pretty things to trade: Blue cloth, embroidered cloth, and rugs of [many] colors that were [rolled up and] tied with ropes.
Wọ̀nyí ní oníbàárà rẹ ní onírúurú nǹkan: aṣọ aláró, àti oníṣẹ́-ọnà àti àpótí aṣọ olówó iyebíye, tí a fi okùn dì, tí a sì fi igi kedari ṣe, nínú àwọn ilé-ìtajà rẹ.
25 Cargo ships from Tarshish carried [all] those things that you traded; and the warehouses on your island were full of all those things.’”
“‘Àwọn ọkọ̀ Tarṣiṣi ní èrò ní ọjà rẹ a ti mú ọ gbilẹ̀ a sì ti ṣe ọ́ lógo ní àárín gbùngbùn Òkun.
26 “‘The men who row your boats took [the ships full of] cargo out on the stormy seas. But the strong east wind wrecked those cargo boats.
Àwọn atukọ̀ rẹ ti mú ọ wá sínú omi ńlá. Ṣùgbọ́n afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn yóò fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ ní àárín gbùngbùn Òkun.
27 Everything in the boats (was lost/sank to the bottom of the sea)— all the valuable cargo [DOU] and [many of] [HYP] the sailors and ship pilots, the ship workers and merchants and soldiers. On the day that the ships were wrecked, many of those on the ships sank to the bottom of the sea.
Ọrọ̀ rẹ, ọjà rẹ àti àwọn ohun títà rẹ, àwọn ìṣúra rẹ, òṣìṣẹ́ ìtukọ̀ rẹ. Àwọn oníbàárà rẹ àti gbogbo àwọn jagunjagun rẹ, tí ó wà nínú rẹ, àti nínú gbogbo ẹgbẹ́ rẹ tí ó wà ní àárín rẹ yóò rì sínú àárín gbùngbùn Òkun ní ọjọ́ ìparun rẹ.
28 [The people in cities along] the coast trembled when they heard your ship pilots cry out.
Ilẹ̀ etí Òkun yóò mì nítorí ìró igbe àwọn atukọ̀ rẹ.
29 All the men who remained who pulled the oars left the ships; the sailors and pilots [go to the shore and] stand on the beach.
Gbogbo àwọn alájẹ̀, àwọn atukọ̀ Òkun àti àwọn atọ́kọ̀ ojú Òkun; yóò sọ̀ kálẹ̀ kúrò nínú ọkọ̀ wọn, wọn yóò dúró lórí ilẹ̀.
30 They cry aloud because of [what has happened to] your [wealth], and they weep bitterly. They throw dirt on their heads and roll around in ashes.
Wọn yóò jẹ́ kí a gbọ́ ohùn wọn lòdì sí ọ wọn yóò sì sọkún kíkorò lé ọ lórí wọn yóò ku eruku lé orí ara wọn wọn yóò sì yí ara wọn nínú eérú.
31 They shave their heads to show that they are very sad because of [what has happened to] you, and they put on rough sackcloth. They weep for you very bitterly and mourn for you.
Wọn yóò fá irun orí wọn nítorí rẹ wọn yóò wọ aṣọ yíya wọn yóò pohùnréré ẹkún pẹ̀lú ìkorò ọkàn nítorí rẹ pẹ̀lú ohùn réré ẹkún kíkorò.
32 While they wail and mourn because of what has happened to you, they sing this sad funeral song: “There was certainly never [RHQ] a city like Tyre that now is silent, covered by the waves of the sea.”
Àti nínú arò wọn ni wọn yóò sì pohùnréré ẹkún fún ọ wọn yóò sì pohùnréré ẹkún sórí rẹ, wí pé: “Ta ni ó dàbí Tire èyí tí ó parun ní àárín Òkun?”
33 The goods that your merchants traded were things that pleased the people of many countries. Kings in very distant places became rich from the wealth that they obtained from trading with you.
Nígbà tí ọjà títà rẹ ti Òkun jáde wá ìwọ tẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè lọ́rùn ìwọ fi ọrọ̀ tí ó pọ̀ àti àwọn ọjà títà rẹ sọ àwọn ọba ayé di ọlọ́rọ̀.
34 But now your city is like a ship [MET] that is wrecked in the sea, and everything that was in it is broken, at the bottom of the sea. All of your cargo and your sailors have sunk to the bottom of the sea along with the ships.
Ní ìsinsin yìí tí Òkun fọ ọ túútúú nínú ibú omi; nítorí náà òwò rẹ àti gbogbo ẹgbẹ́ rẹ ní àárín rẹ, ni yóò ṣubú.
35 All the people who live along the seacoast are appalled/horrified because of what has happened to you. Their kings are very horrified, [causing] their faces to be twisted [as they watch].
Ẹnu yóò ya gbogbo àwọn ti ń gbé ní erékùṣù náà sí ọ jìnnìjìnnì yóò bo àwọn ọba wọn, ìyọnu yóò sì han ní ojú wọn.
36 The merchants of the [other] nations shake their heads [because it is difficult for them to believe what has happened]; your city has disappeared, and it will not exist any more.’”
Àwọn oníṣòwò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè dún bí ejò sí ọ ìwọ yóò sì jẹ́ ẹ̀rù ìwọ kì yóò sì ṣí mọ́ láéláé.’”