< Deuteronomy 1 >

1 These are the words which Moses [Drawn out] spoke to all Israel [God prevails] beyond the Jordan [Descender] in the wilderness, in the Arabah over against Suf, between Paran, Tophel, Laban [White], Hazeroth, and Dizahab.
Wọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Mose sọ fún gbogbo Israẹli ní aginjù, aginjù ìlà-oòrùn Jordani, ni Arabah, ní òdìkejì Ṣufi, ní àárín Parani àti Tofeli, Labani, Haserotu àti Disahabu.
2 It is eleven days’ journey from Horeb [Desert] by the way of Mount Seir to Kadesh Barnea [Consecrated Son-inconstant].
(Ọjọ́ mọ́kànlá ni ó gbà láti rin ìrìnàjò láti Horebu dé Kadeṣi-Barnea, bí a bá gba ọ̀nà òkè Seiri.)
3 In the fortieth year, in the eleventh month Shevat ·Staff / Rod / Royal scepter·, on the first day of the month, Moses [Drawn out] spoke to the children of Israel [God prevails], according to all that Adonai had given Moses [Drawn out], words of enjoinings to them;
Ní ìgbà tí ó pé ogójì ọdún, ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kọ́kànlá, Mose sọ ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ nípa àwọn ọmọ Israẹli fún wọn.
4 after he had struck Sihon the king of the Amorites [Descendants of Talkers], who lived in Heshbon, and Og the king of Bashan, who lived in Ashtaroth, at Edrei.
Èyí ṣẹlẹ̀ lẹ́yìn ìgbà tí ó ti ṣẹ́gun Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani ni ó ṣẹ́gun ní Edrei, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu.
5 Beyond the Jordan [Descender], in the land of Moab [From father], Moses [Drawn out] began to declare this Torah ·Teaching·, saying,
Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani tí ó wà nínú ilẹ̀ Moabu ni Mose bẹ̀rẹ̀ sísọ àsọyé òfin wọ̀nyí wí pé:
6 “Yahweh Eloheikhem [Yahweh our God] spoke to us in Horeb [Desert], saying, ‘You have lived long enough at this mountain.
Olúwa Ọlọ́run wa bá wa sọ̀rọ̀ ní Horebu pé, “Ẹ ti dúró ní orí òkè yìí pẹ́ tó.
7 Turn, and take your journey, and go to the hill country of the Amorites [Descendants of Talkers], and to all the places near there, in the Arabah, in the hill country, and in the lowland, and in the South, and by the seashore, the land of the Canaanites [Descendants of Humbled], and Lebanon, as far as the great river, the river Euphrates [Fruitful].
Ẹ yípadà kí ẹ sì tẹ̀síwájú ní ìrìnàjò yín lọ sí ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, ẹ tọ gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń gbé Arabah lọ ní aginjù, ní àwọn orí òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀, ní gúúsù àti ní etí Òkun, lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kenaani àti lọ sí Lebanoni, títí fi dé odò ńlá Eufurate.
8 Behold, I have set the land before you. Go in and possess the land which Adonai swore to your fathers, to Abraham [Father of a multitude], to Isaac [Laughter], and to Jacob [Supplanter], to give to them and to their offspring after them.’”
Wò ó, èmi tí fi ilẹ̀ yí fún un yín, ẹ wọ inú rẹ̀ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà tí Olúwa ti búra wí pé òun yóò fún àwọn baba yín: fún Abrahamu, Isaaki, àti Jakọbu, àti fún àwọn àrọ́mọdọ́mọ wọn.”
9 I spoke to you at that time, saying, “I am not able to bear you myself alone.
Mo wí fún un yín nígbà náà pé, “Èmi nìkan kò lè dá ẹrù u yín gbé.
10 Adonai your God has multiplied you, and behold, you are today as the stars of the sky for multitude.
Olúwa Ọlọ́run yín ti sọ yín di púpọ̀ lónìí, ẹ̀yin sì ti pọ̀ bí ìràwọ̀ ní ojú ọ̀run.
11 Adonai, the God of your fathers, make you a thousand times as many as you are, and bless you, as he has promised you!
Kí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín sọ yín di púpọ̀ ní ọ̀nà ẹgbẹ̀rún sí i, kí ó sì bùkún un yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí.
12 How can I myself alone bear your problems, your burdens, and your strife?
Báwo ni èmi nìkan ṣe lè máa ru àjàgà àti ìṣòro yín àti èdè-àìyedè yín?
13 Take wise men of understanding and well known according to your tribes, and I will make them heads over you.”
Ẹ yan àwọn ọlọ́gbọ́n, olóye àti àwọn ẹni àpọ́nlé, láti inú ẹ̀yà yín kọ̀ọ̀kan, èmi yóò sì fi wọ́n ṣe olórí yín.”
14 You answered me, and said, “The thing which you have spoken is good to do.”
Ẹ̀yin sì dá mi lóhùn wí pé, “Ohun tí ìwọ ti gbèrò láti ṣe nì dára.”
15 So I took the heads of your tribes, wise men, and known, and made them heads over you, captains of thousands, and captains of hundreds, and captains of fifties, and captains of tens, and officers, according to your tribes.
Bẹ́ẹ̀ ni mo yan olórí àwọn ẹ̀yà yín, àwọn ọlọ́gbọ́n ọkùnrin, ẹni àpọ́nlé, mo sì fi jẹ olórí yín, olórí ẹgbẹẹ̀rún, olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún, olórí àràádọ́ta, àti olórí mẹ́wàá mẹ́wàá gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹ̀yà yín.
16 I enjoined your judges at that time, saying, “Sh'ma ·Hear obey· cases between your brothers, and judge righteously between a man and his brother, and the foreigner who is living with him.
Mo sì kìlọ̀ fún àwọn onídàájọ́ yín nígbà náà pé, ẹ gbọ́ èdè-àìyedè tí ó wà láàrín àwọn ènìyàn an yín kí ẹ sì ṣe ìdájọ́ òdodo, bóyá ẹjọ́ tí ó ṣẹlẹ̀ láàrín Israẹli sí Israẹli ni tàbí láàrín Israẹli kan sí àlejò.
17 You shall not show partiality in judgment; you shall sh'ma ·hear obey· the small and the great alike. You shall not be afraid of the face of man, for the judgment is God’s. The case that is too hard for you, you shall bring to me, and I will sh'ma ·hear obey· it.”
Ẹ má sì ṣe ojúsàájú ní ìdájọ́. Ẹ ṣe ìdájọ́ ẹni ńlá àti kékeré bákan náà. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹnikẹ́ni torí pé ti Ọlọ́run ni ìdájọ́. Ẹjọ́ tí ó bá le jù fún un yín ni kí ẹ mú wá fún mi. Èmi yóò sì gbọ́ ọ.
18 I enjoined you at that time all the things which you should do.
Nígbà náà ni èmi yóò sọ ohun tí ẹ ó ṣe fún un yín.
19 We traveled from Horeb [Desert], and went through all that great and terrible wilderness which you saw, by the way to the hill country of the Amorites [Descendants of Talkers], as Yahweh Eloheikhem [Yahweh our God] enjoined us; and we came to Kadesh Barnea [Consecrated Son-inconstant].
Nígbà náà ní a gbéra láti Horebu, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wá, a sì la àwọn ilẹ̀ lókè Amori kọjá lọ dé gbogbo aginjù ńlá tí ó ba ni lẹ́rù nì tí ẹ̀yin ti rí, bẹ́ẹ̀ ni a sì dé Kadeṣi-Barnea.
20 I said to you, “You have come to the hill country of the Amorites [Descendants of Talkers], which Yahweh Eloheikhem [Yahweh our God] gives to us.
Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ ti dé ilẹ̀ òkè àwọn ará Amori, èyí tí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.
21 Behold, Adonai your God has set the land before you. Go up, take possession, as Adonai, the God of your fathers, has spoken to you. Don’t be afraid, neither be dismayed.”
Ẹ kíyèsi i, Olúwa Ọlọ́run yín ló ni ilẹ̀ náà. Ẹ lọ kí ẹ sì gba ilẹ̀ náà bí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín tí sọ fún un yín. Ẹ má bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà.”
22 You came near to me, everyone of you, and said, “Let us send men before us, that they may search the land for us, and bring us word again of the way by which we must go up, and the cities to which we shall come.”
Nígbà náà ni gbogbo yín tọ̀ mí wá wí pé, “Jẹ́ kí a yan àwọn ayọ́lẹ̀wò láti yọ́ ilẹ̀ náà wò fún wa, kí wọn sì fún wa ní ìròyìn àwọn ọ̀nà tí a ó gbà àti àwọn ìlú tí a ó bá pàdé.”
23 The thing pleased me well. I took twelve men of you, one man for every tribe.
Èrò náà sì dára lójú mi, torí èyí ni mo ṣe yan àwọn ènìyàn méjìlá nínú yín, ẹnìkan láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.
24 They turned and went up into the hill country, and came to the valley of Eshcol, and spied it out.
Wọ́n sì gòkè lọ sí ilẹ̀ òkè náà, wọ́n sì wá sí àfonífojì Eṣkolu, wọ́n sì yẹ̀ ẹ́ wò.
25 They took some of the fruit of the land in their hands, and brought it down to us, and brought us word again, and said, “It is a good land which Yahweh Eloheikhem [Yahweh our God] gives to us.”
Wọ́n sì mú lára èso ilẹ̀ náà wá fún wa pé, “Ilẹ̀ tí ó dára ni Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
26 Yet you wouldn’t go up, but rebelled against the order of Adonai your God.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́ gòkè lọ; ẹ ṣọ̀tẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín.
27 You murmured in your tents, and said, “Because Adonai hated us, he has brought us out of the land of Egypt [Abode of slavery], to deliver us into the hand of the Amorites [Descendants of Talkers], to destroy us.
Ẹ kùn nínú àgọ́ ọ yín, ẹ sì wí pé, “Olúwa kórìíra wa, torí èyí ló fi mú wa jáde láti Ejibiti láti fi wá lé àwọn ará Amori lọ́wọ́ láti pa wá run.
28 Where are we going up? Our brothers have made our heart melt, saying, ‘The people are greater and taller than we. The cities are great and fortified up to the sky. Moreover we have seen the sons of the Anakim there!’”
Níbo la ó lọ? Àwọn arákùnrin wa ti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa nípa sísọ pé, ‘Àwọn ènìyàn náà lágbára wọ́n sì ga jù wá lọ; àwọn ìlú náà tóbi jọjọ bẹ́ẹ̀ ni odi wọn ga kan ọ̀run. A tilẹ̀ rí àwọn òmíràn (ìran Anaki) níbẹ̀.’”
29 Then I said to you, “Don’t dread, neither be afraid of them.
Nígbà náà ni mo sọ fún un yín pé, “Ẹ má ṣojo, ẹ kò sì gbọdọ̀ bẹ̀rù wọn.
30 Adonai your God who goes before you, he will fight for you, according to all that he did for you in Egypt [Abode of slavery] before your eyes,
Olúwa Ọlọ́run yín, tí ń ṣáájú yín yóò jà fún un yín; bí ó ti ṣe fún un yín ní Ejibiti lójú ẹ̀yin tìkára yín
31 and in the wilderness, where you have seen how that Adonai your God bore you, as a man does bear his son, in all the way that you went, until you came to this place.”
àti ní aginjù. Níbẹ̀ ni ẹ ti rí i bí Olúwa Ọlọ́run yín ti gbé yín, bí baba ti í gbé ọmọ rẹ̀, ní gbogbo ọ̀nà tí ẹ lọ títí ẹ fi padà dé ibí yìí.”
32 Yet in this thing you didn’t trust Adonai your God,
Pẹ̀lú gbogbo èyí tí mo wí, ẹ kò gbẹ́kẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run yín,
33 who went before you on the way, to seek out a place for you to pitch your tents in, in fire by night, to show you by what way you should go, and in the cloud by day.
tí ń ṣáájú u yín lọ ní gbogbo ọ̀nà yín, nípa fífi iná ṣe amọ̀nà yín ní òru àti ìkùùkuu ní ọ̀sán, láti fi àwọn ibi tí ẹ lè tẹ̀dó sí hàn yín àti àwọn ọ̀nà tí ẹ ó rìn.
34 Adonai sh'ma ·heard obeyed· the voice of your words, and was angry, and swore, saying,
Nígbà tí Olúwa gbọ́ ohun tí ẹ sọ, inú bí i, ó sì búra wí pé,
35 “Surely not one of these men of this evil generation shall see the good land, which I swore to give to your fathers,
“Kò sí ọ̀kan nínú ìran búburú yìí tí yóò dé ilẹ̀ rere tí mo ti búra láti fún àwọn baba ńlá a yín.
36 except Caleb [Dog] the son of Jephunneh. He shall see it. I will give the land that he has trodden on to him, and to his children, because he has wholly followed Adonai.”
Bí kò ṣe Kalebu ọmọ Jefunne. Òun ni yóò wọ̀ ọ́. Èmi yóò sì fún òun àti àwọn ìran rẹ̀ ní ilẹ̀ náà tí ó ti fi ẹsẹ̀ rẹ̀ tẹ̀; torí pé ó fi gbogbo ọkàn rẹ̀ tẹ̀lé Olúwa.”
37 Also Adonai was angry with me for your sakes, saying, “You also shall not go in there.
Torí i tiyín ni Olúwa fi bínú sí mi wí pé, “Ìwọ náà kì yóò wọ ibẹ̀ bákan náà,
38 Joshua [Yah Salvation] the son of Nun, who stands before you, shall go in there. Encourage him, for he shall cause Israel [God prevails] to inherit it.
ṣùgbọ́n Joṣua ọmọ Nuni tí ń ṣe olùrànlọ́wọ́ rẹ ni yóò wọ ibẹ̀. Mú un, ní ọkàn le torí pé, òun yóò ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli láti gba ilẹ̀ náà.
39 Moreover your little ones, whom you said should be captured or killed, and your children, who today have no knowledge of good or evil, they shall go in there, and I will give it to, and they shall possess it.
Àwọn èwe yín tí ẹ sọ pé wọn yóò kó lẹ́rú. Àwọn ọmọ yín tí ko tí ì mọ rere yàtọ̀ sí búburú ni yóò wọ ilẹ̀ náà.
40 But as for you, turn, and take your journey into the wilderness by the way to the Sea of Suf [Reed Sea].”
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin, ẹ yí padà sí aginjù tí ó wà ní ọ̀nà tí ó lọ sí Òkun Pupa.”
41 Then you answered and said to me, “We have sinned ·deviated (from the standard goal)· against Adonai, we will go up and fight, according to all that Yahweh Eloheikhem [Yahweh our God] enjoined us.” Every man of you put on his weapons of war, and presumed to go up into the hill country.
Nígbà náà ni ẹ fèsì wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí Olúwa. A ó sì gòkè lọ láti jà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run wa ti pàṣẹ fún wa.” Torí náà gbogbo yín ẹ mú ohun ìjà a yín, ẹ rò pé ó rọrùn láti gòkè lọ sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè náà.
42 Adonai said to me, “Tell them, ‘Don’t go up, neither fight; for I am not among you; lest you be struck before your enemies.’”
Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún mi pé, “Sọ fún wọn, ‘Ẹ má ṣe gòkè lọ láti jà torí pé èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín. Àwọn ọ̀tá a yín yóò sì ṣẹ́gun yín.’”
43 So I spoke to you, and you didn’t sh'ma ·hear obey·; but you rebelled against the order of Adonai, and were presumptuous, and went up into the hill country.
Bẹ́ẹ̀ ni mo sọ fún yín, ẹ̀yin kò sì gbọ́, ẹ̀yin ṣọ̀tẹ̀ sí òfin Olúwa, pẹ̀lú ìgbéraga yín, ẹ gòkè lọ sí ìlú olókè náà.
44 The Amorites [Descendants of Talkers], who lived in that hill country, came out against you, and chased you, as bees do, and beat you down in Seir, even to Hormah.
Àwọn ará Amori tí ń gbé ní àwọn òkè náà, dojúkọ yín bí àgbájọpọ̀ oyin. Wọ́n sì lù yín bolẹ̀ láti Seiri títí dé Horma.
45 You made teshuvah ·complete return· and wept before Adonai; but Adonai didn’t sh'ma ·hear obey· unto your voice, nor turn his ear to you.
Ẹ padà, ẹ sì sọkún níwájú Olúwa, òun kò sì fetí sí igbe ẹkún yín, Ó sì kọ etí dídi sí i yín.
46 So you stayed in Kadesh many days, according to the days that you remained.
Báyìí ni ẹ sì dúró ní Kadeṣi fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ti ṣe.

< Deuteronomy 1 >