< Exodus 1 >
1 Now these are the names of the children of Israel, which came into Egypt (euery man and his housholde came thither with Iaakob)
Ìwọ̀nyí ni àwọn orúkọ ọmọ Israẹli tí wọ́n bá Jakọbu lọ sí Ejibiti, ẹnìkọ̀ọ̀kan pẹ̀lú ìdílé rẹ̀:
2 Reuben, Simeon, Leui, and Iudah,
Reubeni, Simeoni, Lefi àti Juda;
3 Issachar, Zebulun, and Beniamin,
Isakari, Sebuluni àti Benjamini;
4 Dan, and Naphtali, Gad, and Asher.
Dani àti Naftali; Gadi àti Aṣeri.
5 So al the soules, that came out of the loines of Iaakob, were seuentie soules: Ioseph was in Egypt already.
Àwọn ìran Jakọbu sì jẹ́ àádọ́rin ní àpapọ̀; Josẹfu sì ti wà ní Ejibiti.
6 Nowe Ioseph died and all his brethren, and that whole generation.
Wàyí o, Josẹfu àti gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìran náà kú,
7 And the children of Israel brought foorth fruite and encreased in aboundance, and were multiplied, and were exceeding mightie, so that the land was full of them.
ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ń bí sí i, wọ́n ń pọ̀ sí i gidigidi, wọ́n kò sì ní òǹkà tí ó fi jẹ́ pé wọ́n kún ilẹ̀ náà.
8 Then there rose vp a newe King in Egypt, who knewe not Ioseph.
Nígbà náà ni ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
9 And he sayde vnto his people, Beholde, the people of the children of Israel are greater and mightier then we.
Ó sọ fún àwọn ènìyàn rẹ̀, “Ẹ wò ó, àwọn ará Israẹli ti pọ̀ ní iye àti agbára jù fún wa.
10 Come, let vs worke wisely with them, least they multiplie, and it come to passe, that if there be warre, they ioyne them selues also vnto our enemies, and fight against vs, and get them out of the land.
Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lo ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yí láti dá wọn lẹ́kun, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ wọn yóò túbọ̀ máa pọ̀ sí i. Bí ogun bá sì bẹ́ sílẹ̀, wọn yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ọ̀tá wa, wọn yóò sì da ojú ìjà kọ wá, wọn yóò sì sá àsálà kúrò ní ilẹ̀ yìí.”
11 Therefore did they set taskemasters ouer them, to keepe the vnder with burdens: and they built the cities Pithom and Raamses for the treasures of Pharaoh.
Nítorí náà, wọ́n yan àwọn ọ̀gá akóniṣiṣẹ́ lé wọn lórí láti máa ni wọ́n lára pẹ̀lú iṣẹ́ àṣekára. Wọ́n sì kọ́ Pitomi àti Ramesesi gẹ́gẹ́ bí ìlú ìṣúra pamọ́ sí fún Farao.
12 But the more they vexed them, the more they multiplied and grewe: therefore they were more grieued against the children of Israel.
Ṣùgbọ́n bí a ti ń ni wọ́n lára tó, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń pọ̀ sí i, tí wọ́n sì ń tànkálẹ̀. Nítorí náà, àwọn ará Ejibiti bẹ̀rù nítorí àwọn ará Israẹli.
13 Wherefore the Egyptians by crueltie caused the children of Israel to serue.
Àwọn ará Ejibiti sì mú àwọn ọmọ Israẹli sìn ní àsìnpa.
14 Thus they made them weary of their liues by sore labour in clay and in bricke, and in al worke in the fielde, with all maner of bondage, which they layde vpon them most cruelly.
Wọ́n mú wọn gbé ìgbé ayé kíkorò nípa iṣẹ́ bíríkì àti àwọn onírúurú iṣẹ́ oko; àwọn ará Ejibiti ń lò wọ́n ní ìlòkulò.
15 Moreouer the King of Egypt commanded ye midwiues of the Ebrewe women, (of which the ones name was Shiphrah, and the name of the other Puah)
Ọba Ejibiti sọ fún àwọn agbẹ̀bí Heberu ti orúkọ wọn ń jẹ́ Ṣifura àti Pua pé,
16 And sayde, When ye doe the office of a midwife to the women of the Ebrewes, and see them on their stooles, if it be a sonne, then yee shall kill him: but if it be a daughter, then let her liue.
“Nígbà ti ẹ̀yin bá ń gbẹ̀bí àwọn obìnrin Heberu, tí ẹ sì kíyèsi wọn lórí ìkúnlẹ̀ ìrọbí wọn, bí ó bá jẹ́ ọkùnrin ni ọmọ náà, ẹ pa á; ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ obìnrin, ẹ jẹ́ kí ó wà láààyè.”
17 Notwithstanding ye midwiues feared God, and did not as the King of Egypt commanded them, but preserued aliue the men children.
Ṣùgbọ́n àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, wọn kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọba Ejibiti ti wí fún wọn; wọ́n jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wà láààyè.
18 Then the King of Egypt called for the midwiues, and sayde vnto them, Why haue yee done thus, and haue preserued aliue the men children?
Ọba Ejibiti pe àwọn agbẹ̀bí ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí? Èéṣe tí ẹ̀yin fi dá àwọn ọmọkùnrin si?”
19 And the midwiues answered Pharaoh, Because the Ebrewe women are not as the women of Egypt: for they are liuely, and are deliuered yer the midwife come at them.
Àwọn agbẹ̀bí náà sì dá Farao lóhùn pé, “Àwọn obìnrin Heberu kò rí bí àwọn obìnrin Ejibiti, wọ́n ní agbára, wọ́n sì ti máa ń bí ọmọ kí àwọn agbẹ̀bí tó dé ọ̀dọ̀ wọn.”
20 God therefore prospered the midwiues, and the people multiplied and were very mightie.
Nítorí náà Ọlọ́run ṣàánú fún àwọn agbẹ̀bí náà, àwọn ọmọ Israẹli sì ń le sí i, wọ́n sì ń pọ̀ sí i jọjọ.
21 And because ye midwiues feared God, therefore he made them houses.
Nítorí pé àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, Ọlọ́run sì fún wọn ni ìdílé tiwọn.
22 Then Pharaoh charged all his people, saying, Euery man childe that is borne, cast yee into the riuer, but reserue euery maide childe aliue.
Nígbà náà ni Farao pàṣẹ yìí fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ pé, “Gbogbo ọmọkùnrin tí a bí ni kí ẹ gbé jù sínú odò Naili, ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọbìnrin ni kí ẹ jẹ́ kí wọn ó wà láààyè.”