< Ezekiel 35 >

1 Og Herrens Ord kom til mig saaledes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Du Menneskesøn! vend dit Ansigt imod Seirs Bjerg og spaa imod det!
“Ọmọ ènìyàn kọjú sí òkè Seiri; sọtẹ́lẹ̀ sí i,
3 Og du skal sige til det: Saa siger den Herre, Herre: Se, jeg kommer imod dig, Seirs Bjerg! og jeg vil udrække min Haand imod dig og gøre dig til en Ødelæggelse og en Ørk.
kí o sì sọ wí pé, ‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmí lòdì sí ọ, òkè Seiri, Èmi yóò sì na ọwọ́ mi síta ní ìlòdì sí ọ, èmi yóò sì mú kí ó di ahoro.
4 Dine Stæder vil jeg gøre øde, og du selv skal vorde en Ødelæggelse; og du skal fornemme, at jeg er Herren.
Èmi yóò pa àwọn ìlú rẹ run, ìwọ yóò sì di ahoro. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
5 Fordi du nærer et evigt Fjendskab og overgav Israels Børn i Sværdets Vold, i deres Trængsels Tid, den Tid, da Misgerningen medførte Enden:
“‘Nítorí ìwọ dá ààbò bo ọ̀tẹ̀ àtayébáyé, tí ìwọ sì fi Israẹli lé idà lọ́wọ́, ní àsìkò ìdààmú wọn, ní àsìkò tí ìjìyà wọn dé góńgó,
6 Derfor, saa sandt jeg lever, siger den Herre, Herre, vil jeg gøre dig til Blod, og Blod skal forfølge dig, efterdi du ikke har hadet Blod, skal Blod forfølge dig.
nítorí náà bi mo ti wà láààyè, ni Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò fi ọ kalẹ̀ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ. Níwọ́n ìgbà tí ìwọ kò ti kórìíra ìtàjẹ̀ sílẹ̀, ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò sì lépa rẹ.
7 Og jeg vil gøre Seirs Bjerg til en Ødelæggelse og en Ørk; og jeg vil udrydde deraf enhver, som drager frem og tilbage.
Èmi yóò mú kí òkè Seiri di ahoro; ọ̀fọ̀ gbogbo àwọn tí ó ń lọ tí ó ń bọ̀ ní èmi yóò gé kúrò lára rẹ.
8 Og jeg vil fylde Bjergene der med deres ihjelslagne; paa dine Høje og i dine Dale og i alle dine Flodlejer, der falde de, som ere ihjelslagne med Sværd.
Èmi yóò fi àwọn tí a pa kún orí òkè rẹ, àwọn tí a fi idà pa yóò ṣubú ní orí òkè rẹ, àti ní àárín àwọn òkè rẹ.
9 Jeg vil gøre dig til evige Ørkener, og dine Stæder skulle ikke bebos; og I skulle fornemme, at jeg er Herren.
Èmi yóò mú kí ó di ahoro títí láé, kò ní sí olùgbé ní ìlú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.
10 Fordi du siger: De tvende Folk og de tvende Lande skulle være mine, og vi ville tage dem i Eje, da dog Herren var der:
“‘Nítorí tí ìwọ sọ pé, “Àwọn orílẹ̀-èdè àti ilẹ̀ méjì wọ̀nyí yóò jẹ́ tiwa, àwa yóò sì gbà wọ́n ní ìní,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, Èmi Olúwa wà níbẹ̀,
11 Derfor, saa sandt jeg lever, siger den Herre, Herre, vil jeg gøre efter din Vrede og efter din Nid, som du har udvist formedelst dit Had imod dem, og jeg vil give mig til Kende hos dem, naar jeg dømmer dig.
nítorí náà níwọ̀n ìgbà tí mo ti wà láààyè, ní Olúwa Olódùmarè wí, èmi yóò hùwà sí ọ ní ìbámu pẹ̀lú ìbínú àti owú tí o fihàn nínú ìkórìíra rẹ sí wọn, èmi yóò fi ara mi hàn ní àárín wọn, nígbà tí mo bá ṣe ìdájọ́ rẹ.
12 Og du skal fornemme, at jeg er Herren, jeg har hørt alle dine Bespottelser, som du har sagt imod Israels Bjerge, idet du sagde: De ere ødelagte, os ere de givne til Føde.
Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti gbọ́ gbogbo ohun ẹ̀gàn tí ìwọ ti sọ lòdì sí àwọn òkè Israẹli náà. Ìwọ wí pé, “A sọ wọ́n di ahoro, a sì fi wọ́n fún wa láti run.”
13 Og I have gjort eder store imod mig med eders Mund og brugt mange overflødige Ord imod mig; jeg har hørt det.
Ìwọ lérí sí mi, ó sì sọ̀rọ̀ lòdì sí mí láìsí ìdádúró, èmi sì gbọ́ ọ.
14 Saa siger den Herre, Herre: Naar hele Jorden glæder sig, vil jeg gøre dig øde.
Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nígbà tí gbogbo ayé bá ń yọ̀, èmi yóò mú kí ó di ahoro.
15 Ligesom du har glædet dig over Israels Hus's Arv, fordi den blev ødelagt, saaledes vil jeg gøre imod dig; du Seirs Bjerg og hele Edom alt sammen skal vorde øde; og de skulle fornemme, at jeg er Herren.
Nítorí pé ìwọ ń yọ̀ nígbà tí ìní ilé Israẹli di ahoro, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni èmi yóò ṣe hùwà sí ọ. Ìwọ yóò di ahoro, ìwọ òkè Seiri, ìwọ àti gbogbo ará Edomu. Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”

< Ezekiel 35 >