< Žalmy 69 >

1 Přednímu z kantorů na šošannim, žalm Davidův. Vysvoboď mne, ó Bože, neboť jsou dosáhly vody až k duši mé.
Fún adarí orin. Tí ohùn “Àwọn Lílì.” Ti Dafidi. Gbà mí, Ọlọ́run, nítorí omi ti kún dé ọrùn mi.
2 Pohřížen jsem v hlubokém bahně, v němž dna není; všel jsem do hlubokosti vod, jejichž proud zachvátil mne.
Mo ń rì nínú irà jíjìn, níbi tí kò sí ibi ìfẹsẹ̀lé. Mo ti wá sínú omi jíjìn; ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀.
3 Ustal jsem, volaje, vyschlo hrdlo mé, zemdlely oči mé od ohlídání se na tě Boha svého.
Agara dá mi, mo ń pè fún ìrànlọ́wọ́; ọ̀fun mí gbẹ, ojú mi ṣú, nígbà tí èmi dúró de Ọlọ́run mi.
4 Více jest těch, kteříž mne nenávidí bez příčiny, než vlasů hlavy mé; zmocnili se ti, kteříž mne vyhladiti usilují, a jsou nepřátelé moji bez mého provinění; to, čehož jsem nevydřel, nahražovati jsem musil.
Àwọn tí ó kórìíra mi láìnídìí wọ́n ju irun orí mi lọ, púpọ̀ ni àwọn ọ̀tá mi láìnídìí, àwọn tí ń wá láti pa mí run. A fi ipá mú mi láti san ohun tí èmi kò jí.
5 Bože, ty znáš sám nemoudrost mou, a výstupkové moji nejsou skryti před tebou.
Ìwọ mọ òmùgọ̀ mi, Ọlọ́run; ẹ̀bi mi kò pamọ́ lójú rẹ.
6 Nechť nebývají zahanbeni příčinou mou ti, kteříž na tě očekávají, Pane, Hospodine zástupů; nechť nepřicházejí skrze mne k hanbě ti, kteříž tě hledají, ó Bože Izraelský.
Má ṣe dójútì àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ nítorí mi, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun; má ṣe jẹ́ kí àwọn tó ń wá ọ dààmú nítorí mi, Ọlọ́run Israẹli.
7 Neboť pro tebe snáším pohanění, a stud přikryl tvář mou.
Nítorí rẹ ni mo ń ru ẹ̀gàn, ìtìjú sì bo ojú mi.
8 Cizí učiněn jsem bratřím svým, a cizozemec synům matky své,
Mo jẹ́ àjèjì si àwọn arákùnrin mi; àlejò sí àwọn arákùnrin ìyá mi;
9 Proto že horlivost domu tvého snědla mne, a hanění hanějících tě na mne připadla.
nítorí ìtara ilé rẹ jẹ mí run, àti ẹ̀gàn àwọn tí ń gàn ọ́ ṣubú lù mí.
10 Když jsem plakal, postem trápiv duši svou, bylo mi to ku potupě obráceno.
Nígbà tí mo sọkún tí mo sì ń fi àwẹ̀ jẹ ara mi ní ìyà èyí náà sì dín ẹ̀gàn mi kù;
11 Když jsem bral na se pytel místo roucha, tehdy jsem jim byl za přísloví.
nígbà tí mo wọ aṣọ àkísà, àwọn ènìyàn ń pa òwe mọ́ mi.
12 Pomlouvali mne, sedíce v bráně, a písničkou byl jsem těm, kteříž pili víno.
Àwọn tí ó jókòó ní ẹnu ibodè ń bú mi, mo sì di orin àwọn ọ̀mùtí.
13 Já pak modlitbu svou k tobě odsílám, Hospodine, časť jest dobré líbeznosti tvé. Ó Bože, vedlé množství milosrdenství svého vyslyš mne, pro pravdu svou spasitelnou.
Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni ìwọ ni èmi ń gbàdúrà mi sí Olúwa, ní ìgbà ìtẹ́wọ́gbà Ọlọ́run, nínú ìfẹ́ títóbi rẹ, dá mi lóhùn pẹ̀lú ìgbàlà rẹ tí ó dájú.
14 Vytrhni mne z bláta, abych nebyl pohřížen; nechť jsem vytržen od těch, kteříž mne nenávidí, jako z hlubokostí vod,
Gbà mí kúrò nínú ẹrẹ̀, má ṣe jẹ́ kí n rì; gbà mí lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra mi, kúrò nínú ibú omi.
15 Aby mne nezachvátili proudové vod, a nesehltila hlubina, ani se nade mnou zavřela prohlubně.
Má ṣe jẹ́ kí ìkún omi bò mí mọ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni má ṣe jẹ́ kí ọ̀gbìn gbé mi mì kí o má sì ṣe jẹ́ kí ihò pa ẹnu rẹ̀ dé mọ́ mi.
16 Vyslyšiž mne, Hospodine, neboť jest dobré milosrdenství tvé; vedlé množství slitování svých vzhlédniž na mne.
Dá mí lóhùn, Olúwa, nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ; nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ yípadà sí mi.
17 A neskrývej tváři své od služebníka svého, neboť mám úzkost; rychle vyslyš mne.
Má ṣe pa ojú rẹ mọ́ fún ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ: yára dá mi lóhùn, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú.
18 Přibliž se k duši mé, a vyprosť ji; pro nepřátely mé vykup mne.
Súnmọ́ tòsí kí o sì gbà mí là; rà mí padà nítorí àwọn ọ̀tá mi.
19 Ty znáš pohanění mé, a zahanbení mé, i potupu mou, před tebouť jsou všickni nepřátelé moji.
Ìwọ ti mọ ẹ̀gàn mi, ìtìjú mi àti àìlọ́lá; gbogbo àwọn ọ̀tá mi wà níwájú rẹ.
20 Pohanění potřelo srdce mé, pročež jsem byl v žalosti. Očekával jsem, zdali by mne kdo politoval, ale žádného nebylo, zdali by kdo potěšiti chtěli, ale nedočkal jsem.
Ẹ̀gàn ba ọkàn mi jẹ́, wọ́n fi mí sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́; mo ń wá aláàánú, ṣùgbọ́n kò sí, mo ń wá olùtùnú, ṣùgbọ́n n kò rí ẹnìkankan.
21 Nýbrž místo pokrmu poskytli mi žluči, a v žízni mé napájeli mne octem.
Wọ́n fi òróró fún mi pẹ̀lú ohun jíjẹ mi, àti ní òùngbẹ mi, wọ́n fi ọtí kíkan fún mi.
22 Budiž jim stůl jejich před nimi za osídlo, a pokojný způsob jejich místo síti.
Jẹ́ kí tábìlì wọn kí ó di ìkẹ́kùn ní iwájú wọn, kí ó sì di okùn dídẹ fún àwọn tó wà ní àlàáfíà.
23 Ať se zatmí oči jejich, aby viděti nemohli, a bedra jejich k stálému přiveď zemdlení.
Kí ojú wọn kì í ó ṣókùnkùn, kí wọn má ṣe ríran, kí ẹ̀yin wọn di títẹ̀ títí láé.
24 Vylí na ně rozhněvání své, a prchlivost hněvu tvého ať je zachvátí.
Tú ìbínú rẹ jáde sí wọn; kí ìbínú gbígbóná rẹ bò wọ́n mọ́lẹ̀.
25 Budiž příbytek jejich pustý, v staních jejich kdo by obýval, ať není žádného.
Kí ibùjókòó wọn di ahoro; kí ẹnikẹ́ni má ṣe gbé nínú wọn.
26 Nebo se tomu, jehož jsi ty zbil, protiví, a o bolesti zraněných tvých rozmlouvají.
Nítorí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí ẹni tí ìwọ ti lù, àti ìrora àwọn tí ó ti ṣèṣe.
27 Přilož nepravost k nepravosti jejich, a ať nepřicházejí k spravedlnosti tvé.
Fi ẹ̀sùn kún ẹ̀sùn wọn; Má ṣe jẹ́ kí wọn pín nínú ìgbàlà rẹ.
28 Nechť jsou vymazáni z knihy živých, a s spravedlivými ať nejsou zapsáni.
Jẹ́ kí a yọ wọ́n kúrò nínú ìwé ìyè kí á má kà wọ́n pẹ̀lú àwọn olódodo.
29 Já pak ztrápený jsem, a bolestí sevřený, ale spasení tvé, ó Bože, na místě bezpečném postaví mne.
Ṣùgbọ́n tálákà àti ẹni-ìkáàánú ni èmí, Ọlọ́run, jẹ́ kí ìgbàlà rẹ gbé mi lékè.
30 I buduť chváliti jméno Boží s prozpěvováním, a velebiti je s děkováním.
Èmi yóò fi orin gbé orúkọ Ọlọ́run ga èmi yóò fi ọpẹ́ gbé orúkọ rẹ̀ ga.
31 A bude to příjemnější Hospodinu nežli vůl, neb volek rohatý s rozdělenými kopyty.
Eléyìí tẹ́ Olúwa lọ́rùn ju ọ̀dá màlúù lọ ju akọ màlúù pẹ̀lú ìwo rẹ̀ àti bàtà rẹ̀.
32 To když uhlédají tiší, radovati se budou, hledajíce Boha, a ožive srdce jejich.
Àwọn òtòṣì yóò rí, wọn yóò sì yọ̀: ẹ̀yin yóò wá Ọlọ́run, ọkàn yín yóò sì wà láààyè!
33 Neboť vyslýchá chudé Hospodin, a vězni svými nezhrzí.
Olúwa, gbọ́ ti aláìní, kì ó sì kọ àwọn ìgbèkùn sílẹ̀.
34 Chvaltež ho nebesa a země, moře i všeliký hmyz jejich.
Kí ọ̀run àti ayé yìn ín, òkun àti àwọn tí ń gbé inú rẹ̀,
35 Bůhť zajisté zachová Sion, a vzdělá města Judská, i budou tu bydliti, a zemi tu dědičně obdrží.
nítorí tí Ọlọ́run yóò gba Sioni là yóò sì tún àwọn ìlú Juda wọ̀nyí kọ́. Kí wọn ó lè máa gbé ibẹ̀, kí wọn ó lè máa ní ní ilẹ̀ ìní;
36 Tolikéž i símě služebníků jeho dědičně jí vládnouti budou, a milující jméno jeho v ní přebývati.
àwọn ọmọ ọmọ ọ̀dọ̀ ni yóò máa jogún rẹ̀, àwọn tí ó fẹ́ orúkọ rẹ ni yóò máa gbé inú rẹ̀.

< Žalmy 69 >