< Žalmy 48 >

1 Píseň žalmu synů Chóre. Veliký jest Hospodin, a převelmi chvalitebný v městě Boha našeho, na hoře svatosti své.
Orin. Saamu ti àwọn ọmọ Kora. Ẹni ńlá ní Olúwa, tí ó sì yẹ láti máa yìn ní ìlú Ọlọ́run wa, lórí òkè mímọ́ rẹ̀.
2 Ozdoba krajiny, útěcha vší země jestiť hora Sion, k straně půlnoční, město krále velikého.
Ó dára nínú ipò ìtẹ́ rẹ̀, ayọ̀ gbogbo ayé, òkè Sioni, ní ìhà àríwá ní ìlú ọba ńlá.
3 Bůh na palácích jeho, a znají ho býti vysokým hradem.
Ọlọ́run wà nínú ààbò ààfin rẹ̀; ó fi ara rẹ̀ hàn láti jẹ́ odi alágbára.
4 Nebo aj, králové když se shromáždili a spolu táhli,
Nígbà tí àwọn ọba kógun jọ pọ̀, wọ́n jùmọ̀ ń kọjá lọ.
5 Sami to uzřevše, velmi se divili, a předěšeni byvše, náhle utíkali.
Wọn rí i, bẹ́ẹ̀ ni ẹnu sì yà wọ́n, a yọ wọ́n lẹ́nu, wọ́n yára lọ.
6 Tuť jest je strach popadl, a bolest jako ženu rodící.
Ẹ̀rù sì bà wọ́n níbẹ̀, ìrora gẹ́gẹ́ bí obìnrin tí ó wà nínú ìrọbí.
7 Větrem východním rozrážíš lodí Tarské.
Ìwọ bà wọ́n jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọkọ̀ orí omi Tarṣiṣi, wọ́n fọ́nká láti ọwọ́ ìjì ìlà-oòrùn.
8 Jakž jsme slýchali, tak jsme spatřili, v městě Hospodina zástupů, v městě Boha našeho. Bůh upevní je až na věky.
Gẹ́gẹ́ bí a ṣe gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwa rí, ní inú Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ìlú Ọlọ́run wa, Ọlọ́run jẹ́ kí ó wà ní abẹ́ ààbò títí láéláé. (Sela)
9 Rozjímáme, ó Bože, milosrdenství tvé u prostřed chrámu tvého.
Láàrín tẹmpili rẹ, Ọlọ́run, àwa ti ń sọ ti ìṣeun ìfẹ́ rẹ.
10 Jakož jméno tvé, Bože, tak i chvála tvá až do končin země; pravice tvá zajisté plná jest spravedlnosti.
Gẹ́gẹ́ bí orúkọ rẹ Ọlọ́run, ìyìn rẹ̀ dé òpin ayé, ọwọ́ ọ̀tún rẹ kún fún òdodo.
11 Raduj se, horo Sione, plésejte, dcery Judské, z příčiny soudů Božích.
Jẹ́ kí òkè Sioni kí ó yọ̀ kí inú àwọn ọmọbìnrin Juda kí ó dùn nítorí ìdájọ́ rẹ.
12 Obejděte Sion, a obstupte jej, sečtěte věže jeho.
Rìn Sioni kiri lọ yíká rẹ̀, ka ilé ìṣọ́ rẹ̀.
13 Přiložte mysl svou k ohradě, popatřte na paláce jeho, abyste uměli vypravovati věku potomnímu,
Kíyèsi odi rẹ̀, kíyèsi àwọn ààfin rẹ̀ kí ẹ̀yin lè máa wí fún ìran tí ń bọ̀.
14 Že tento Bůh jest Bůh náš na věčné věky, a že on vůdce náš bude až do smrti.
Nítorí Ọlọ́run yìí Ọlọ́run wà ní títí ayé, Òun ni yóò ṣe amọ̀nà wa títí dè òpin ayé.

< Žalmy 48 >