< Žalmy 34 >

1 Davidův, když proměnil oblíčej svůj před Abimelechem; pročež jsa od něho vyhnán, odšel. Dobrořečiti budu Hospodinu každého času, vždycky chvála jeho v ústech mých.
Tí Dafidi. Nígbà tí ó díbọ́n bí ẹni tí ń ṣe wèrè níwájú Abimeleki, ẹni tí ó lé e lọ, ó sì jáde lọ. Èmi yóò máa fi ìbùkún fún Olúwa nígbà gbogbo; ìyìn rẹ̀ yóò máa wà ní ẹnu mi títí láé.
2 V Hospodinu chlubiti se bude duše má, což uslyšíc tiší, budou se veseliti.
Ọkàn mí yóò máa ṣògo nínú Olúwa; jẹ́ kí àwọn onírẹ̀lẹ̀ gbọ́ kí inú wọn kí ó sì máa dùn.
3 Zvelebujtež se mnou Hospodina, a jméno jeho společně vyvyšujme.
Gbé Olúwa ga pẹ̀lú mi; kí ẹ sì jẹ́ kí a jọ gbé orúkọ rẹ̀ lékè.
4 Hledal jsem Hospodina, a vyslyšel mne, a ze všech přístrachů mých vytrhl mne.
Èmi wá Olúwa, ó sì dá mi lóhùn; Ó sì gbà mí kúrò nínú ìbẹ̀rù mi gbogbo.
5 Pročež k němu patřiti budou, a sbíhati se, a nebudou zahanbeny tváři jejich, ale řkou:
Wọ́n wò ó, ìmọ́lẹ̀ sì mọ́ wọn; ojú kò sì tì wọ́n.
6 Tento chudý volal a Hospodin vyslyšel, i ze všech úzkostí jeho vysvobodil jej.
Ọkùnrin olùpọ́njú yí kígbe, Olúwa sì gbóhùn rẹ̀; ó sì gbà á là kúrò nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
7 Vojensky se klade anděl Hospodinův okolo těch, kteříž se ho bojí, a zastává jich.
Angẹli Olúwa yí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ká ó sì gbà wọ́n.
8 Okuste a vizte, jak dobrý jest Hospodin. Blahoslavený člověk, kterýž doufá v něho.
Tọ́ ọ wò kí o sì rí i wí pé Olúwa dára; ẹni ayọ̀ ni ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé ààbò nínú rẹ̀.
9 Bojtež se Hospodina svatí jeho; neboť nemívají nedostatku ti, kdož se ho bojí.
Ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ̀yin ènìyàn rẹ̀ mímọ́, nítorí pé kò sí àìní fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
10 Lvíčátka nedostatek a hlad trpívají, ale ti, kteříž hledají Hospodina, nemívají nedostatku ve všem dobrém.
Àwọn ọmọ kìnnìún a máa ṣe aláìní ebi a sì máa pa wọ́n; ṣùgbọ́n àwọn tí ó wá Olúwa kì yóò ṣe aláìní ohun tí ó dára.
11 Poďtež, dítky, poslouchejte mne, bázni Hospodinově vyučovati vás budu.
Wá, ẹ̀yin ọmọ mi, fi etí sí mi; èmi yóò kọ́ ọ yín ní ẹ̀rù Olúwa.
12 Který člověk žádostiv jest života, a miluje dny, aby užíval dobrých věcí?
Ta ni nínú yín tí ń fẹ́ ìyè, tí ó sì ń fẹ́ ọjọ́ púpọ̀; kí ó lè gbádùn ọjọ́ rere?
13 Zdržuj jazyk svůj od zlého, a rty své od mluvení lsti.
Pa ahọ́n rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi àti ètè rẹ̀ kúrò ní ẹ̀tàn sísọ.
14 Odstup od zlého, a čiň dobré, hledej pokoje, a stíhej jej.
Yà kúrò nínú ibi kí o sì ṣe rere; wá àlàáfíà, kí o sì lépa rẹ̀.
15 Oči Hospodinovy obrácené jsou k spravedlivým, a uši jeho k volání jejich:
Ojú Olúwa ń bẹ lára àwọn olódodo; etí i rẹ̀ sì ṣí sí ẹkún wọn.
16 Ale zůřivý oblíčej Hospodinův proti těm, kteříž páší zlé věci, aby vyplénil z země památku jejich.
Ojú Olúwa korò sí àwọn tí ń ṣe búburú; láti ké ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
17 Volají-li spravedliví, Hospodin vyslýchá, a ze všech jejich úzkostí je vytrhuje.
Nígbà tí olódodo bá ké fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa a máa gbọ́, a sì yọ wọ́n jáde láti inú gbogbo wàhálà wọn.
18 Nebo blízko jest Hospodin těm, kteříž jsou srdce skroušeného, a potřeným v duchu spomáhá.
Olúwa súnmọ́ etí ọ̀dọ̀ àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn; ó sì gba irú àwọn tí í ṣe oníròra ọkàn là.
19 Mnohé úzkosti jsou spravedlivého, ale Hospodin ze všech jej vytrhuje.
Ìpọ́njú àwọn olódodo pọ̀, ṣùgbọ́n Olúwa gbà wọ́n kúrò nínú gbogbo rẹ̀.
20 Onť ostříhá všech kostí jeho, žádná z nich nebývá zlámána.
Ó pa gbogbo egungun wọn mọ́; kò sí ọ̀kan tí ó dá nínú wọn.
21 Bezbožníka zahubí zlost, a ti, kteříž nenávidí spravedlivého, zkaženi budou.
Ibi ni ó mú ikú ìkà wá, àti àwọn tí ó kórìíra olódodo ni yóò jẹ̀bi.
22 Služebníků pak svých duše vykoupí Hospodin, a nebudou zkaženi, kteříž doufají v něho.
Olúwa ra ọkàn àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ padà; kò sí ọ̀kan nínú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé tí yóò jẹ̀bi.

< Žalmy 34 >