< 4 Mojžišova 1 >

1 Mluvil pak Hospodin k Mojžíšovi na poušti Sinai, v stánku úmluvy, prvního dne měsíce druhého, léta druhého po vyjití jejich z země Egyptské, řka:
Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ní aginjù Sinai nínú àgọ́ àjọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì ní ọdún kejì tí àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ó wí pé,
2 Sečtěte summu všeho množství synů Izraelských po čeledech jejich, a po domích otců jejich, vedlé počtu jmen každého pohlaví mužského po hlavách jejich,
“Ka gbogbo àgbájọ ènìyàn Israẹli nípa ẹbí wọn, àti nípa ìdílé baba wọn, to orúkọ wọn olúkúlùkù ọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
3 Od dvadcítiletých a výše všecky, kteříž by mohli jíti k boji v Izraeli, sečtěte je po houfích jejich, ty a Aron.
Ìwọ àti Aaroni ni kí ẹ kà gbogbo ọmọkùnrin Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn láti ọmọ ogún ọdún sókè, àwọn tí ó tó lọ sójú ogun.
4 A bude s vámi z každého pokolení jeden muž, kterýž by přední byl v domě otců svých.
Kí ẹ mú ọkùnrin kọ̀ọ̀kan láti inú olúkúlùkù ẹ̀yà kí ó sì wá pẹ̀lú yín, kí olúkúlùkù jẹ́ olórí ilé àwọn baba rẹ̀.
5 Tato pak jsou jména mužů, kteříž stanou s vámi: Z pokolení Rubenova Elisur, syn Sedeurův;
“Orúkọ àwọn ọkùnrin tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nìyí: “Láti ọ̀dọ̀ Reubeni, Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
6 Z Simeonova Salamiel, syn Surisaddai;
Láti ọ̀dọ̀ Simeoni, Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
7 Z Judova Názon, syn Aminadabův;
Láti ọ̀dọ̀ Juda, Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
8 Z Izacharova Natanael, syn Suar;
Láti ọ̀dọ̀ Isakari, Netaneli ọmọ Suari.
9 Z Zabulonova Eliab, syn Helonův;
Láti ọ̀dọ̀ Sebuluni, Eliabu ọmọ Heloni.
10 Z synů Jozefových, z pokolení Efraimova Elisama, syn Amiudův; z Manassesova Gamaliel, syn Fadasurův;
Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Josẹfu: láti ọ̀dọ̀ Efraimu, Eliṣama ọmọ Ammihudu. Láti ọ̀dọ̀ Manase, Gamalieli ọmọ Pedasuri.
11 Z Beniaminova Abidan, syn Gedeonův;
Láti ọ̀dọ̀ Benjamini, Abidani ọmọ Gideoni.
12 Z pokolení Dan Ahiezer, syn Amisaddai;
Láti ọ̀dọ̀ Dani, Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
13 Z Asser Fegiel, syn Ochranův;
Láti ọ̀dọ̀ Aṣeri, Pagieli ọmọ Okanri.
14 Z pokolení Gád Eliazaf, syn Duelův;
Láti ọ̀dọ̀ Gadi, Eliasafu ọmọ Deueli.
15 Z Neftalímova Ahira, syn Enanův.
Láti ọ̀dọ̀ Naftali, Ahira ọmọ Enani.”
16 Ti jsou slovoutní z lidu, knížata pokolení otců svých, ti jako hlavy tisíců Izraelských budou.
Àwọn wọ̀nyí ni wọ́n yàn nínú àwùjọ ènìyàn, olórí àwọn ẹ̀yà baba wọn. Àwọn ni olórí àwọn ẹbí Israẹli.
17 Vzal tedy Mojžíš a Aron muže ty, kteříž jmenováni byli,
Mose àti Aaroni mú àwọn ènìyàn tí a dárúkọ wọ̀nyí
18 A shromáždili všecko množství prvního dne měsíce druhého, kteříž přiznávali se k rodům svým po čeledech svých, po domích otců svých, a vedlé počtu jmen, od dvadcítiletých a výše po osobách svých.
wọ́n sì pe gbogbo àwùjọ ènìyàn Israẹli jọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì. Àwọn ènìyàn sì dárúkọ baba ńlá wọn nípa ẹbí àti ìdílé wọn. Wọ́n sì ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọmọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan láti ọmọ ogún ọdún sókè,
19 Jakož byl přikázal Hospodin Mojžíšovi, tak sčetl je na poušti Sinai.
gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose. Bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe kà wọ́n nínú aginjù Sinai.
20 I bylo synů Rubena prvorozeného Izraelova, rodiny jejich, po čeledech jejich, po domích otců jejich, a podlé počtu jmen, po hlavách jejich, všech pohlaví mužského, od dvadcítiletých a výše, všech, kteříž mohli jíti k boji,
Láti ìran Reubeni tí í ṣe àkọ́bí Israẹli, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn, lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
21 A načteno jich z pokolení Rubenova čtyřidceti šest tisíců a pět set.
Àwọn tí a kà ní ẹ̀yà Reubeni jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlélógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
22 Z synů Simeonových, rodiny jejich, po čeledech jejich, po domích otců jejich, sečtených jeho vedlé počtu jmen, po hlavách jejich, všech pohlaví mužského od dvadcítiletých a výše, všech, kteříž mohli jíti k boji,
Láti ìran Simeoni, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n kà, wọ́n sì to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
23 Načteno jich z pokolení Simeonova padesáte devět tisíců a tři sta.
Iye àwọn tí á kà nínú ẹ̀yà Simeoni jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ó lé ọ̀ọ́dúnrún.
24 Z synů Gádových, rodiny jejich, po čeledech jejich, po domích otců jejich, podlé počtu jmen, od dvadcítiletých a výše, všech, kteříž mohli bojovati,
Láti ìran Gadi, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí ẹbí àti ìdílé wọn.
25 Načteno jich z pokolení Gádova čtyřidceti pět tisíců, šest set a padesát.
Iye àwọn tí a kà nínú ẹ̀yà Gadi jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé àádọ́talélẹ́gbẹ̀jọ.
26 Z synů Judových, rodiny jejich, po čeledech jejich, po domích otců jejich, vedlé počtu jmen, od dvadcíti let a výše, všech, kteříž mohli jíti k boji,
Láti ìran Juda, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
27 Načteno jich z pokolení Judova sedmdesáte čtyři tisíce a šest set.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Juda jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógójì ó lé ẹgbẹ̀ta.
28 Z synů Izacharových, rodiny jejich, po čeledech jejich, po domích otců jejich, podlé počtu jmen, od dvadcítiletých a výše, všech, kteříž mohli jíti k boji,
Láti ìran Isakari, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
29 Načteno jich z pokolení Izacharova padesáte čtyři tisíce a čtyři sta.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Isakari jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
30 Z synů Zabulonových, rodiny jejich, po čeledech jejich, po domích otců jejich, podlé počtu jmen, od dvadcítiletých a výše, všech, kteříž mohli jíti k boji,
Láti ìran Sebuluni, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
31 Načteno jich z pokolení Zabulonova padesáte sedm tisíců a čtyři sta.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Sebuluni jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
32 Z synů Jozefových, a nejprv, synů Efraimových, rodiny jejich, po čeledech jejich, po domích otců jejich, podlé počtu jmen, od dvadcítiletých a výše, všech, kteříž mohli jíti k boji,
Láti inú àwọn ọmọ Josẹfu. Láti ìran Efraimu, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọ́n jẹ́ ogún ọdún sókè tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
33 Načteno jich z pokolení Efraimova čtyřidceti tisíc a pět set.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Efraimu jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
34 Potom z synů Manassesových, rodiny jejich, po čeledech jejich, po domích otců jejich, vedlé počtu jmen, od dvadcítiletých a výše, všech, kteříž vycházeli k boji,
Láti ìran Manase, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
35 Načteno jich z pokolení Manassesova třidceti dva tisíce a dvě stě.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Manase jẹ́ ẹgbàá ẹẹ́rìndínlógún ó lé igba.
36 Z synů Beniaminových, rodiny jejich, po čeledech jejich, po domích otců jejich, vedlé počtu jmen, od dvadcítiletých a výše, všech, kteříž mohli jíti do boje,
Láti ìran Benjamini, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
37 Načteno jich z pokolení Beniaminova třidceti pět tisíců a čtyři sta.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Benjamini jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógún ó lé egbèje.
38 Z synů Dan, rodiny jejich, po čeledech jejich, po domích otců jejich, vedlé počtu jmen, od dvadcítiletých a výše, všech, kteříž vycházeli k boji,
Láti ìran Dani, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ọmọ ogún ọdún sókè, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
39 Načteno jich z pokolení Dan šedesáte dva tisíce a sedm set.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Dani jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
40 Z synů Asser, rodiny jejich, po čeledech jejich, po domích otců jejich, vedlé počtu jmen, od dvadcítiletých a výše, všech, kteříž mohli jíti na vojnu,
Láti ìran Aṣeri, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún sókè, tí wọ́n le lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
41 Načteno jich z pokolení Asser čtyřidceti jeden tisíců a pět set.
Iye tí a kà nínú ẹ̀yà Aṣeri jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
42 Z synů Neftalímových, rodiny jejich, po čeledech jejich, po domích otců jejich, vedlé počtu jmen, od dvadcítiletých a výše, všech, kteříž mohli jíti k boji,
Láti ìran Naftali, gbogbo ọmọkùnrin tí ọjọ́ orí wọn jẹ́ ogún ọdún ó lé, tí wọ́n lè lọ sójú ogun ni wọ́n to orúkọ wọn lẹ́yọ kọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí àkọsílẹ̀ ẹbí àti ìdílé wọn.
43 Načteno jich z pokolení Neftalímova padesáte tři tisíce a čtyři sta.
Iye àwọn tí a kà nínú ẹ̀yà Naftali jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
44 Ten jest počet těch, kteréž sečtl Mojžíš a Aron a knížata Izraelská, dvanácte mužů, kteříž byli vybráni po jednom z domů otců svých.
Wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn tí Mose àti Aaroni kà, pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn olórí méjìlá fún Israẹli, tí ẹnìkọ̀ọ̀kan ṣojú fún ìdílé rẹ̀.
45 I bylo všech sečtených synů Izraelských po domích otců jejich, od dvadcítiletých a výše, všech, kteříž mohli vycházeti k boji v Izraeli,
Gbogbo ọmọkùnrin Israẹli tó jẹ́ ọmọ ogún ọdún sókè, tó sì lè lọ sójú ogun ni wọ́n kà gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
46 Všech sečtených bylo šestkrát sto tisíc, a tři tisíce, pět set a padesáte.
Àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé egbèjìdínlógún dín làádọ́ta.
47 Levítové pak vedlé pokolení otců svých nejsou počítáni mezi ně.
A kò ka àwọn ìdílé ẹ̀yà Lefi mọ́ àwọn ìyókù.
48 Nebo byl mluvil Hospodin k Mojžíšovi, řka:
Nítorí Olúwa ti sọ fún Mose pé,
49 Pokolení Levítského nebudeš počítati, a nepřičteš jich k synům Izraelským,
“Ìwọ kò gbọdọ̀ ka ẹ̀yà Lefi, tàbí kí o kà wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Israẹli.
50 Ale ustanovíš Levíty nad příbytkem svědectví, a nade vším nádobím jeho, a nade všemi věcmi, kteréž přináležejí k němu. Oni nositi budou příbytek i všecka nádobí jeho, oni přisluhovati budou jemu, a vůkol příbytku klásti se budou.
Dípò èyí yan àwọn ọmọ Lefi láti jẹ́ alábojútó àgọ́ ẹ̀rí, lórí gbogbo ohun èlò àti ohun gbogbo tó jẹ́ ti àgọ́ ẹ̀rí. Àwọn ni yóò máa gbé àgọ́ àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, wọn ó máa mójútó o, kí wọn ó sì máa pàgọ́ yí i ká.
51 Když se pak s místa bude míti hýbati příbytek, složí jej Levítové; a když se bude klásti příbytek, vyzdvihnou jej Levítové. Kdož by koli cizí přistoupil, umře.
Ìgbàkígbà tí àgọ́ yóò bá tẹ̀síwájú, àwọn ọmọ Lefi ni yóò tú palẹ̀, nígbàkígbà tí a bá sì tún pa àgọ́, àwọn ọmọ Lefi náà ni yóò ṣe é. Àlejò tó bá súnmọ́ tòsí ibẹ̀, pípa ni kí ẹ pa á
52 I budouť se klásti synové Izraelští, jeden každý v ležení svém, a jeden každý pod praporcem svým, a po houfích svých.
kí àwọn ọmọ Israẹli pa àgọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn olúkúlùkù ní ibùdó tirẹ̀ lábẹ́ ọ̀págun tirẹ̀.
53 Levítové pak klásti se budou vůkol příbytku svědectví, aby nepřišlo rozhněvání mé na shromáždění synů Izraelských; i budou Levítové držeti stráž u příbytku svědectví.
Àwọn ọmọ Lefi yóò jẹ́ alábojútó àti olùtọ́jú àgọ́ ẹ̀rí náà, kí ìbínú má ba à sí lára ìjọ àwọn ọmọ Israẹli; kí àwọn ọmọ Lefi sì máa ṣe ìtọ́jú àgọ́ ẹ̀rí náà.”
54 Učinili tedy to synové Izraelští; všecko, jakž přikázal Hospodin Mojžíšovi, tak učinili.
Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun gbogbo gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.

< 4 Mojžišova 1 >