< Izaiáš 61 >

1 Duch Panovníka Hospodina jest nade mnou, proto že pomazal mne Hospodin, abych kázal evangelium tichým. Poslal mne, abych uvázal rány skroušených srdcem, abych vyhlásil jatým svobodu, a vězňům otevření žaláře,
Ẹ̀mí Olúwa Olódùmarè wà lára mi nítorí Olúwa ti fi àmì òróró yàn mí láti wàásù ìyìnrere fún àwọn tálákà. Ó ti rán mi láti ṣe àwòtán oníròbìnújẹ́ láti kéde ìdásílẹ̀ fún àwọn ìgbèkùn àti ìtúsílẹ̀ kúrò nínú òkùnkùn fún àwọn ẹlẹ́wọ̀n,
2 Abych vyhlásil léto milostivé Hospodinovo, a den pomsty Boha našeho, abych těšil všecky kvílící,
láti kéde ọdún ojúrere Olúwa àti ọjọ́ ẹ̀san ti Ọlọ́run wa, láti tu àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú,
3 Abych způsobil radost kvílícím Sionským, a dal jim okrasu místo popela, olej veselé místo smutku, oděv chvály místo ducha sevřeného. I nazvání budou stromové spravedlnosti, štípení Hospodinovo, abych oslavován byl.
àti láti pèsè fún àwọn tí inú wọn bàjẹ́ ní Sioni láti dé wọn ládé ẹwà dípò eérú, òróró ayọ̀ dípò ọ̀fọ̀, àti aṣọ ìyìn dípò ìpòrúru ọkàn. A ó sì pè wọ́n ní igi óákù òdodo, irúgbìn Olúwa láti fi ọláńlá rẹ̀ hàn.
4 Tedy vzdělají pustiny starodávní, pouště staré spraví, a obnoví města zpuštěná, pustá po mnohé národy.
Wọn yóò tún àwọn ahoro àtijọ́ kọ́ wọn yóò sì mú àwọn ibi ìparun àtijọ́-tijọ́ náà bọ̀ sípò; wọn yóò jí àwọn ahoro ìlú náà padà tí a ti parun láti ìrandíran sẹ́yìn.
5 Nebo postaví se cizozemci, a pásti budou stáda vaše, a synové cizozemců oráči vaši a vinaři vaši budou.
Àwọn àjèjì ni yóò máa da ọ̀wọ́ ẹran rẹ; àwọn àlejò yóò sì ṣiṣẹ́ nínú oko àti ọgbà àjàrà rẹ.
6 Vy pak kněží Hospodinovi nazváni budete, služebníci Boha našeho slouti budete, zboží pohanů užívati budete, a v slávě jejich zvýšeni budete.
A ó sì máa pè yín ní àlùfáà Olúwa, a ó pè yín ní ìránṣẹ́ Ọlọ́run wa. Ẹ ó máa jẹ nínú ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè àti nínú ọrọ̀ wọn ni ẹ̀yin yóò máa ṣògo.
7 Za dvojnásobní zahanbení vaše a pohanění prozpěvovati budete, z podílu jejich a v zemi jejich dvojnásobní dědictví obdržíte, a tak veselé věčné míti budete.
Dípò àbùkù wọn àwọn ènìyàn mi yóò gba ìlọ́po méjì, àti dípò àbùkù wọn wọn yóò yọ̀ nínú ìní wọn; bẹ́ẹ̀ ni wọn yóò sì jogún ìlọ́po méjì ní ilẹ̀ wọn, ayọ̀ ayérayé yóò sì jẹ́ tiwọn.
8 Já zajisté Hospodin miluji soud, a nenávidím loupeže při oběti, a protož způsobím, aby skutkové jejich dáli se v pravdě, a smlouvu věčnou s nimi učiním.
“Nítorí Èmi, Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òdodo; mo kórìíra olè jíjà àti ẹ̀ṣẹ̀. Ní òtítọ́ mi èmi yóò sẹ̀san fún wọn èmi yóò sì dá májẹ̀mú ayérayé pẹ̀lú wọn.
9 I vejdeť v známost mezi pohany símě jejich, a potomci jejich u prostřed národů. Všickni, kteříž je uzří, poznají je, že jsou símě, jemuž požehnal Hospodin.
A ó mọ ìrandíran wọn láàrín àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ìran wọn láàrín àwọn ènìyàn. Gbogbo àwọn tí ó bá rí wọn yóò mọ̀ pé wọ́n jẹ́ àwọn ènìyàn tí Olúwa ti bùkún.”
10 Velice se budu radovati v Hospodinu, a plésati bude duše má v Bohu mém; nebo mne oblékl v roucho spasení, a pláštěm spravedlnosti přioděl mne jako ženicha, kterýž se strojí ozdobně, a jako nevěstu okrašlující se ozdobami svými.
Èmi yọ̀ gidigidi nínú Olúwa; ọkàn mi yọ̀ nínú Ọlọ́run mi. Nítorí ó ti wọ̀ mí ní aṣọ ìgbàlà ó sì ṣe mí lọ́ṣọ̀ọ́ nínú aṣọ òdodo; gẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ti ṣe orí rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ bí àlùfáà, àti bí ìyàwó ṣe ń ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́.
11 Nebo jakož země vydává zrostlinu svou, a jakož zahrada símě své vyvodí, tak Panovník Hospodin vyvede spravedlnost a chválu přede všemi národy.
Gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ti í mú irúgbìn jáde àti bí ọgbà ṣe ń mú irúgbìn dàgbà, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè yóò ṣe mú òdodo àti ìyìn kí ó ru sókè níwájú gbogbo orílẹ̀-èdè.

< Izaiáš 61 >