< Ester 6 >

1 Té noci král nemoha spáti, rozkázal přinésti knihy pamětné, kroniky, kteréž čteny byly před králem.
Ní òru ọjọ́ náà ọba kò le è sùn; nítorí náà, ó pàṣẹ kí wọn mú ìwé ìrántí wá, àkọsílẹ̀ ìjọba rẹ̀, wọ́n mú un wá wọ́n sì kà á sí létí.
2 I našli zapsáno, že pověděl Mardocheus na Bigtana a Teresa, dva komorníky královské z těch, jenž ostříhali prahu, že ukládali vztáhnouti ruku na krále Asvera.
Wọ́n rí àkọsílẹ̀ níbẹ̀ pé Mordekai tí sọ àṣírí Bigitana àti Tereṣi, àwọn ìjòyè ọba méjì tí wọ́n ń ṣọ́ ẹnu-ọ̀nà, tí wọ́n ń gbèrò láti pa ọba Ahaswerusi.
3 Tedy řekl král: Èím jest poctěn, neb jak zveleben Mardocheus za to? Odpověděli služebníci královští, dvořané jeho: Není jemu nic dáno.
Ọba béèrè pé, “Kí ni ọlá àti iyì tí Mordekai ti gbà fún èyí?” Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì dáhùn pé, “Kò tí ì sí ohun tí a ṣe fún un.”
4 I řekl král: Kdo jest v síni? (Aman pak byl přišel do síně domu královského zevnitřní, mluviti s králem, aby oběšen byl Mardocheus na šibenici, kterouž jemu připravil.)
Ọba wí pé, “Ta ni ó wà nínú àgbàlá?” Nísinsin yìí, Hamani ṣẹ̀ṣẹ̀ wọ àgbàlá ìta ààfin ni láti sọ fún ọba nípa síso Mordekai lórí igi tí ó ti rì fún un.
5 Odpověděli králi služebníci jeho: Aj, Aman stojí v síni. Řekl král: Nechť vejde sem.
Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì dáhùn pé, “Hamani ni ó wà níbẹ̀ ó dúró sí inú àgbàlá.” Ọba pàṣẹ pé, “Ẹ mú un wọlé wá.”
6 Takž všel Aman. Jemuž řekl král: Co sluší učiniti muži tomu, kteréhož by chtěl král ctíti? (Aman řekl sám v sobě: Kohož by jiného chtěl král více ctíti, nežli mne?)
Nígbà tí Hamani wọlé, ọba béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni kí a ṣe fún ọkùnrin tí inú ọba dùn sí láti bu ọlá fún?” Nísinsin yìí Hamani sì ro èyí fúnra rẹ̀ pé, “Ta ni ó wà níbẹ̀ tí ọba fẹ́ dá lọ́lá ju èmi lọ?”
7 Odpověděl Aman králi: Muži tomu, jehož král ctíti chce,
Nítorí náà Hamani dá ọba lóhùn pé, “Fún ọkùnrin tí inú ọba dùn sí láti dá lọ́lá,
8 Ať přinesou roucho královské, do kteréhož se král obláčí, a přivedou koně, na kterémž jezdí král, a vstaví korunu královskou na hlavu jeho.
jẹ́ kí wọn kí ó mú aṣọ ọba èyí tí ọba ń wọ̀ àti ẹṣin tí ọba máa ń gùn, pẹ̀lú ọ̀kan lára adé ọba kí a fi dé e ní orí.
9 A dadouce roucho to i koně toho v ruku některého z nejznamenitějších knížat královských, ať oblekou muže toho, jehož král chce ctíti, a ať jej vodí na koni po ulici města, a volají před ním: Tak se má státi muži tomu, jehož král ctíti chce.
Jẹ́ kí a fi aṣọ àti ẹṣin lé ọ̀kan lára àwọn ìjòyè ọba tí ó ga jùlọ lọ́wọ́, kí wọn wọ aṣọ náà fún ọkùnrin tí inú ọba dùn sí láti dá lọ́lá, kí wọn sì sìn ín gun ẹṣin jákèjádò gbogbo ìgboro ìlú, kí wọn máa kéde níwájú rẹ̀ pé, ‘Èyí ni a ṣe fún ọkùnrin náà ẹni tí inú ọba dùn sí láti dá lọ́lá!’”
10 Tedy řekl král Amanovi: Pospěš, vezmi to roucho a koně, jakž jsi řekl, a učiň to Mardocheovi Židu, kterýž sedí v bráně královské. Nepomíjejž ničeho ze všeho toho, což jsi mluvil.
Ọba pàṣẹ fún Hamani pé, “Lọ lẹ́sẹ̀kan náà. Mú aṣọ náà àti ẹṣin kí o sì ṣe gẹ́gẹ́ bí o ṣe sọ fún Mordekai ará a Júù, ẹni tí ó jókòó sí ẹnu-ọ̀nà ọba. Má ṣe fi ohunkóhun sílẹ̀ nínú ohun tí o ti yàn.”
11 Protož vzav Aman roucho i koně, oblékl Mardochea, a vedl jej na koni po ulici města, volaje před ním: Tak se má státi muži tomu, jehož král ctíti chce.
Bẹ́ẹ̀ ni Hamani ṣe mú aṣọ àti ẹṣin náà. Ó fi wọ Mordekai, Mordekai sì wà lórí ẹṣin jákèjádò gbogbo ìgboro ìlú, ó sì ń kéde níwájú rẹ̀ pé, “Èyí ni a ó ṣe fún ọkùnrin náà ẹni tí inú ọba dùn sí láti dá lọ́lá!”
12 Potom navrátil se Mardocheus k bráně královské. Aman pak rychle pospíšil do domu svého, smuten jsa, s zakrytou hlavou.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí Mordekai padà sí ẹnu-ọ̀nà ọba. Ṣùgbọ́n Hamani sáré lọ ilé, ó sì bo orí rẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́,
13 I vypravoval Aman Zeres ženě své a všechněm přátelům svým všecko, což se mu přihodilo. I řekli jemu mudrci jeho i Zeres žena jeho: Poněvadž z národu Židovského jest Mardocheus, před jehož oblíčejem počal jsi klesati, neodoláš jemu, ale jistě padneš před oblíčejem jeho.
Hamani sì sọ ohun gbogbo tí ó ṣẹlẹ̀ sí i fún Sereṣi ìyàwó rẹ̀ àti àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀. Àwọn olùbádámọ̀ràn rẹ̀ àti ìyàwó o rẹ̀ sọ fún un pé, “Níwọ́n ìgbà tí Mordekai ti jẹ́ ẹ̀yà Júù, níwájú ẹni tí ìṣubú rẹ̀ ti bẹ̀rẹ̀, ìwọ kò lè rí ẹ̀yìn in rẹ̀—dájúdájú ìwọ yóò parun!”
14 A když oni ještě mluvili s ním, komorníci královští přišli, a rychle vzali Amana na hody, kteréž připravila Ester.
Bí wọ́n ṣe ń bá a sọ̀rọ̀, àwọn ìwẹ̀fà ọba wọlé, wọ́n sì kán Hamani lójú láti lọ sí ibi àsè tí Esteri ti pèsè.

< Ester 6 >