< 5 Mojžišova 15 >

1 Každého léta sedmého odpouštěti budeš.
Ní òpin ọdún méje méje, ẹ̀yin gbọdọ̀ máa yọ̀ǹda àwọn gbèsè.
2 Tento pak bude způsob odpuštění, aby odpustil každý věřitel, kterýž rukou svou půjčil to, čehož půjčil bližnímu svému; nebude upomínati bližního svého aneb bratra svého, nebo vyhlášeno jest odpuštění Hospodinovo.
Báyìí ni kí ẹ máa ṣe é. Gbogbo ẹni tí wọ́n jẹ ní gbèsè gbọdọ̀ fojú fo gbèsè tí ó ti yá ará Israẹli ènìyàn rẹ̀. Kò gbọdọ̀ béèrè ohun náà, lọ́dọ̀ ará Israẹli ènìyàn rẹ̀ tàbí lọ́dọ̀ arákùnrin rẹ̀: nítorí pé a ti kéde àkókò Olúwa láti fojú fo gbèsè.
3 Cizozemce upomínati budeš, ale to, což bys měl u bratra svého, propustí ruka tvá.
Ẹ lè béèrè ìsanpadà lọ́dọ̀ àjèjì. Ṣùgbọ́n ẹ fa igi lé gbèsè yówù kó jẹ́ tí arákùnrin yín jẹ yín.
4 Toliko aby nuzným někdo nebyl příčinou tvou, poněvadž hojně požehná tobě Hospodin v zemi, kterouž Hospodin Bůh tvůj dá tobě v dědictví, abys jí dědičně vládl:
Ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò tọ́ sí nínú yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín yóò bùkún un yín lọ́pọ̀lọ́pọ̀ nínú ilẹ̀ náà tí ó ń mú un yín lọ láti gbà bí ìní yín.
5 Jestliže však pilně poslouchati budeš hlasu Hospodina Boha svého, tak abys hleděl činiti každé přikázaní toto, kteréž já tobě dnes přikazuji.
Kìkì bí ẹ bá gbọ́rọ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run yín tí ẹ sì kíyèsára láti máa rìn nínú gbogbo àṣẹ wọ̀nyí, tí èmi ń pa fún un yín lónìí.
6 Hospodin zajisté Bůh tvůj požehná tobě, jakož mluvil tobě, tak že budeš moci půjčovati národům mnohým, tobě pak nebude potřeba vypůjčovati; i budeš panovati nad národy mnohými, ale oni nad tebou nebudou panovati.
Nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín yóò bùkún un yín bí ó ti ṣèlérí, ẹ̀yin yóò sì máa yá ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ẹ kì yóò sì tọrọ. Ẹ ó ṣàkóso ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n kò sí orílẹ̀-èdè tí yóò lè jẹ ọba lé e yín lórí.
7 Byl-li by u tebe nuzný někdo z bratří tvých, v některém městě tvém, v zemi tvé, kterouž Hospodin Bůh tvůj dá tobě, nezatvrdíš srdce svého, a nezavřeš ruky své před nuzným bratrem svým:
Bí tálákà kan bá wà láàrín àwọn arákùnrin yín ní èyíkéyìí àwọn ìlú, ilẹ̀ náà tí Olúwa yín yóò fún un yín. Ẹ má ṣe ṣe àìláàánú, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe háwọ́ sí arákùnrin yín tí ó jẹ́ tálákà.
8 Ale štědře otevřeš jemu ruku svou, a ochotně půjčíš jemu, jakž by mnoho potřeboval toho, v čemž by nouzi měl.
Ṣùgbọ́n ẹ lawọ́ kí ẹ sì fi tọkàntọkàn yá wọn ní ohun tí wọ́n nílò.
9 Vystříhej se, aby nebylo něco nepravého v srdci tvém, a řekl bys: Blíží se rok sedmý, jenž jest rok odpuštění, a bylo by nešlechetné oko tvé k bratru tvému nuznému, tak že bys neudělil jemu, pročež by volal proti tobě k Hospodinu, a byl by na tobě hřích:
Ẹ ṣọ́ra kí èrò búburú kan má ṣe sí nínú àyà rẹ wí pé, “Ọdún keje tí í ṣe ọdún ìyọ̀ǹda gbèsè ti súnmọ́,” nípa bẹ́ẹ̀, ojú rẹ a sì burú sí arákùnrin rẹ tálákà, tí ìwọ kò sì fun ní nǹkan, o kò sì fun ní nǹkan kan. Òun a si kígbe pe Olúwa nítorí rẹ, a si di ẹ̀ṣẹ̀ fún ọ.
10 Ale ochotně dáš jemu, a nebude srdce tvé neupřímé, když bys dával jemu; nebo tou příčinou požehná tobě Hospodin Bůh tvůj ve všech skutcích tvých a ve všem díle, k kterémuž bys vztáhl ruku svou.
Fún un tọkàntọkàn, láìsí ìkùnsínú, nítorí èyí, Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò bùkún fún ọ nínú iṣẹ́ ọwọ́ rẹ, àti gbogbo ìdáwọ́lé rẹ.
11 Nebo nebudete bez chudých v zemi vaší; protož přikazuji tobě, řka: Abys ochotně otvíral ruku svou bratru svému, chudému svému a nuznému svému v zemi své.
A kò lè fẹ́ tálákà kù ní ilẹ̀ náà ní ìgbà gbogbo, mo pàṣẹ fún un yín láti lawọ́ sí àwọn arákùnrin yín, sí àwọn tálákà àti sí àwọn aláìní, ní ilẹ̀ ẹ yín.
12 Jestliže by prodán byl tobě bratr tvůj Žid aneb Židovka, a sloužil by tobě za šest let, sedmého léta propustíš jej od sebe svobodného.
Bí Heberu ara yín kan, yálà ọkùnrin tàbí obìnrin bá ta ara rẹ̀ fún ọ, tí ó sì sìn ọ́ fún ọdún mẹ́fà. Ní ọdún keje, jẹ́ kí ó di òmìnira.
13 A když jej propustíš svobodného od sebe, nepustíš ho prázdného.
Nígbà tí ó bá dá a sílẹ̀ má ṣe jẹ́ kí ó lọ lọ́wọ́ òfo.
14 Štědře darovati jej budeš dary z dobytka svého, z stodoly a z vinice své; v čemž požehnal tobě Hospodin Bůh tvůj, z toho dáš jemu.
Fi tọkàntọkàn fún un láti inú agbo ewúrẹ́ rẹ, ilẹ̀ ìpakà rẹ, àti ibi ìfúntí rẹ. Fún un gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti bùkún fún ọ tó.
15 A pamatuj, že jsi služebníkem byl v zemi Egyptské, a že tě vykoupil Hospodin Bůh tvůj, protož já to dnes tobě přikazuji.
Ẹ rántí pé ẹ ti fi ìgbà kan jẹ́ ẹrú ní Ejibiti, Olúwa Ọlọ́run yín sì rà yín padà, ìdí nìyí tí mo fi pa àṣẹ yìí fún un yín lónìí.
16 Pakliť by řekl: Nepůjdu od tebe, proto že by tě miloval i dům tvůj, a že mu dobře u tebe,
Ṣùgbọ́n bí ìránṣẹ́ rẹ bá sọ fún ọ pé, “Èmi kò fẹ́ fi ọ́ sílẹ̀,” nítorí pé ó fẹ́ràn ìwọ àti ìdílé rẹ, tí ó sì tẹ́ ọ lọ́rùn,
17 Tedy vezma špici, probodneš ucho jeho na dveřích, a bude u tebe služebníkem na věky. Takž podobně i děvce své učiníš.
kí ìwọ kí ó mú ìlu kan lu etí rẹ̀ mọ́ ara ìlẹ̀kùn, yóò sì di ẹrú rẹ láéláé. Bẹ́ẹ̀ náà ni kí o ṣe sí ìránṣẹ́ ẹrúbìnrin rẹ.
18 Nechť není za těžké před očima tvýma, když bys ho svobodného propustil od sebe, nebo dvojnásob více, než ze mzdy nájemník, sloužil tobě šest let; i požehná tobě Hospodin ve všech věcech, kteréž činiti budeš.
Má ṣe kà á sí ohun ìnira láti dá ẹrú rẹ sílẹ̀, nítorí ìsìnrú rẹ̀ fún ọ, ní ọdún mẹ́fà náà tó ìlọ́po méjì iṣẹ́ alágbàṣe, Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò bùkún fún ọ nínú gbogbo ìdáwọ́lé rẹ.
19 Všeho prvorozeného, což se narodí z skotů tvých neb z bravů tvých, samce posvětíš Hospodinu Bohu svému. Nebudeš dělati prvorozeným volkem svým, a nebudeš holiti prvorozených ovec svých.
Gbogbo àkọ́bí tí o jẹ́ akọ nínú agbo màlúù rẹ ni kí o yà sọ́tọ̀ fún Olúwa, àti nínú agbo ewúrẹ́ bákan náà. Ẹ má ṣe fi àkọ́bí màlúù yín ṣiṣẹ́ rárá. Má ṣe rẹ́ irun àkọ́bí àgùntàn rẹ pẹ̀lú.
20 Před Hospodinem Bohem svým budeš je jísti na každý rok na místě, kteréž by vyvolil Hospodin, ty i čeled tvá.
Ní ọdọọdún ni kí ìwọ àti ìdílé rẹ máa jẹ ẹ́ níwájú Olúwa Ọlọ́run yín níbi tí Òun yóò yàn.
21 Pakliť by na něm byla vada, že by kulhavé aneb slepé bylo, aneb mělo by jakoukoli škodlivou vadu, nebudeš ho obětovati Hospodinu Bohu svému.
Bí ẹran ọ̀sìn kan bá ní àbùkù: bóyá ó yarọ, tàbí fọ́jú, tàbí tí ó ní èyíkéyìí àbùkù tó burú. Ẹ kò gbọdọ̀ fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run yín.
22 V branách svých budeš je jísti, buďto čistý neb nečistý, rovně jako srnu aneb jelena;
Ẹ jẹ ẹ́ ní ìlú u yín. Àti ẹni tí a kà sí mímọ́ àti aláìmọ́ ni ó lè jẹ ẹ́ bí ìgbà tí a ń jẹ èsúró tàbí àgbọ̀nrín.
23 Toliko krve jeho nebudeš jísti, ale na zem vycedíš ji jako vodu.
Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ jẹ ẹ̀jẹ̀, ẹ dà á síta bí omi.

< 5 Mojžišova 15 >