< Nambar 12 >
1 Mosi mah Ethiopia tanu to zu haih moe, Ethiopia nongpata to zu ah a lak pongah, Miriam hoi Aaron mah Mosi to kasae thuih hoi.
Miriamu àti Aaroni sọ̀rọ̀-òdì sí Mose nítorí pé ó fẹ́ obìnrin ará Etiopia.
2 Nihnik mah, Angraeng mah Mosi khae khue ah maw lokthuih? Aicae khaeah doeh lokthui ai maw? tiah a thuih hoi. To lok to Angraeng mah thaih.
Wọ́n sì wí pé, “Nípa Mose nìkan ni Olúwa ti sọ̀rọ̀ bí, kò ha ti ipa wa sọ̀rọ̀ bí?” Olúwa sì gbọ́ èyí.
3 (To naah Mosi loe long pum ah kaom kaminawk boih pongah doeh, poek panaemhaih tawn kami ah oh.)
(Mose sì jẹ́ ọlọ́kàn tútù ju gbogbo ènìyàn tó wà lórí ilẹ̀ ayé lọ).
4 Angraeng mah, Mosi, Aaron hoi Miriam khaeah, Nangcae long thumto amkhuenghaih im ah angzo oh, tiah a naa. To pongah nihcae loe caeh o.
Lẹ́ẹ̀kan náà ni Olúwa sọ fún Mose, Aaroni àti Miriamu pé, “Ẹ̀yin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta, jáde wá sínú àgọ́ ìpàdé.” Àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì jáde síta.
5 To naah Angraeng loe tamai thung hoiah angzoh tathuk, kahni im thok taengah angdoet moe, Aaron hoi Miriam to kawk; nihnik loe hmabang ah tacawt hoi.
Nígbà náà ni Olúwa sọ̀kalẹ̀ nínú ọ̀wọ́n ìkùùkuu, ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́, ó ké sí Aaroni àti Miriamu. Àwọn méjèèjì sì bọ́ síwájú,
6 Anih mah, Ka lok hae tahngai hoih; Nangcae salakah Angraeng ih tahmaa to om nahaeloe, anih khaeah hnuksakhaih hoiah kam tueng moe, anih khaeah amang ah lok ka thuih pae.
Ó wí pé, “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, “Bí wòlíì Olúwa bá wà láàrín yín, Èmi Olúwa a máa fi ara à mi hàn án ní ojúran, Èmi a máa bá a sọ̀rọ̀ nínú àlá.
7 Toe ka tamna Mosi loe to tiah om ai; anih loe ka imthung takoh boih ah oep thok koek kami ah oh.
Ṣùgbọ́n èyí kò rí bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú Mose ìránṣẹ́ mi; ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo ilé mi.
8 Anih hoi lok ka thuih naah, mikhmai kangtong ah ni lok ka thuih han, thaih karai lok hoiah ka thui mak ai; anih mah Angraeng ih krang to hnu tih; tikhoe ka tamna Mosi ih lok aek hanah zithaih na tawn hoi ai loe? tiah a naa.
Mo sì ń bá a sọ̀rọ̀ ní ojúkojú, ọ̀rọ̀ yékéyéké tí kì í ṣe òwe, ó rí àwòrán Olúwa. Kí ló wá dé tí ẹ̀yin kò ṣe bẹ̀rù láti sọ̀rọ̀-òdì sí Mose ìránṣẹ́ mi?”
9 Angraeng palungphuihaih mah nihnik to kangh, to pacoengah anih mah caehtaak.
Ìbínú Olúwa sì ru sókè sí wọn Olúwa sì fi wọ́n sílẹ̀.
10 Tamai mah kahni im to caehtaak pacoengah, khenah, Miriam loe dantui kanglung baktiah ngansae man khrung; Aaron mah Miriam to khet naah, anih loe ngansae man kami ah a hnuk.
Nígbà tí ìkùùkuu kúrò lórí àgọ́ lójijì ni Miriamu di adẹ́tẹ̀, ó funfun bí i yìnyín. Aaroni sì padà wo Miriamu ó sì rí i pé ó ti di adẹ́tẹ̀,
11 To naah Aaron mah Mosi khaeah, Ka angraeng, amthuhaih hoiah ni hmuen hae ka sak hoi moeng boeh, tahmenhaih hoiah hae zaehaih hae kai hnik nuiah amtii hmah raeh, tiah a naa.
Aaroni sì wí fún Mose pé, “Jọ̀wọ́ olúwa mi, má ṣe ka ẹ̀ṣẹ̀, èyí tí a fi ìwà òmùgọ̀ dá sí wa lọ́rùn.
12 Anih hae amno ih zok thung hoiah tacawt naah kakoep ai kami, takpum ahap kadueh kami baktiah omsak hmah, tiah a naa.
Má ṣe jẹ́ kí ó dàbí òkú ọmọ tí a bí, tí ìdajì ara rẹ̀ ti rà dànù.”
13 To pongah Mosi mah Angraeng khaeah, Aw Sithaw, tahmenhaih hoiah anih hae vaihi ngantuisak rae ah, tiah a hangh.
Torí èyí Mose sì kígbe sí Olúwa, “Ọlọ́run, jọ̀wọ́, mú un láradá!”
14 Angraeng mah Mosi khaeah, ampa mah Miriam ih mikhmai ah pathoih nahaeloe, anih loe ni sarihto thung azathaih hoiah om mak ai maw? Anih to na oh o haih ahmuen tasa bangah ni sarihto thung suem ah, to pacoengah a thungah akunsak let ah, tiah a naa.
Olúwa sì dá Mose lóhùn, “Bí baba rẹ̀ bá tutọ́ sí i lójú, ojú kò wa ní í tì í fún ọjọ́ méje? Dá a dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, lẹ́yìn èyí ki a tó ó le mú wọlé.”
15 To pongah Miriam to ataihaih im tasa bangah ni sarihto thung a suek o; Miriam a thungah akun o sak let ai karoek to, kaminawk loe kholong caeh o ai.
Miriamu sì dúró sí ẹ̀yìn ibùdó fún ọjọ́ méje, àwọn ènìyàn kò sì tẹ̀síwájú nínú ìrìnàjò wọn títí tí Miriamu fi wọ inú ibùdó padà.
16 To pacoengah kaminawk loe, Hazeroth ahmuen ah angpuen o moe, Paran praezaek ah ohhaih ahmuen takhawh o.
Lẹ́yìn èyí, àwọn ènìyàn kúrò ní Haserotu, wọ́n sì pa ibùdó sí aginjù Parani.