< Псалми 90 >
1 Молитва на Божия човек Моисей. Господи, Ти си бил нам обиталище из род в род,
Àdúrà Mose ènìyàn Ọlọ́run. Olúwa, ìwọ ti jẹ́ ibùgbé wa ní gbogbo ìran dé ìran.
2 Преди да се родят планините, И да си дал съществувание на земята и вселената, От века и до века Ти си Бог.
Kí a tó bí àwọn òkè ńlá àti kí ìwọ tó dá ilẹ̀ àti ayé, láti ayérayé dé ayérayé ìwọ ni Ọlọ́run.
3 Обръщаш човека на пръст, И казваш: Върнете се човешки чада.
Ìwọ yí ènìyàn padà sí erùpẹ̀, wí pé, “Padà sí erùpẹ̀, ìwọ ọmọ ènìyàn.”
4 Защото хиляда години са пред Тебе Като вчерашния ден, който е преминал, И като нощна стража.
Nítorí pé ìgbà tí ẹgbẹ̀rún ọdún bá kọjá lójú rẹ, bí àná ni ó rí, bí ìgbà ìṣọ́ kan lóru.
5 Като с порой ги завличаш; те стават като сън; Заран са като трева, която пораства;
Ìwọ gbá ènìyàn dànù nínú oorun ikú; wọ́n dàbí koríko tuntun ní òwúrọ̀.
6 Заран цъфти и пораства; Вечер се окосява и изсъхва.
Lóòtítọ́, ní òwúrọ̀, ó yọ tuntun ní àṣálẹ́ ni yóò gbẹ, tí yóò sì rẹ̀ dànù.
7 Защото довършваме се от Твоя гняв, И от негодуванието Ти сме смутени.
A pa wá run nípa ìbínú rẹ nípa ìbínú rẹ ara kò rọ̀ wá.
8 Положил си беззаконията ни, пред Себе Си, Скришните ни грехове в светлината на лицето Си
Ìwọ ti gbé ẹ̀ṣẹ̀ wa ka iwájú rẹ, àti ohun ìkọ̀kọ̀ wa nínú ìmọ́lẹ̀ iwájú rẹ.
9 Понеже всичките ни дни преминават с гнева Ти. Свършваме годините си като въздишка.
Gbogbo ọjọ́ wa ń kọjá lọ lábẹ́ ìbínú rẹ; àwa ń lo ọjọ́ wa lọ bí àlá tí à ń rọ́.
10 Дните на живота ни са естествено седемдесет години Или даже, гдето има сила, осемдесет години, Но най-добрите от тях са труд и скръб, Защото скоро прехождат и ние отлитаме.
Àádọ́rin ọdún ni iye ọjọ́ ọdún wá, bi ó sì ṣe pé nípa agbára tí wọn bá tó ọgọ́rin ọdún, agbára nínú làálàá pẹ̀lú ìbànújẹ́ ni, nítorí pé a kò ní pẹ́ gé e kúrò, àwa a sì fò lọ.
11 Кой знае силата на гнева Ти И на негодуванието Ти според дължимия на Тебе страх?
Ta ni ó mọ agbára ìbínú rẹ? Gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú rẹ.
12 Научи ни така да броим дните си Щото да си придобием мъдро сърце.
Kọ́ wa bí a ti ń kaye ọjọ́ wa dáradára, kí àwa ba à lè fi ọkàn wa sípa ọgbọ́n.
13 Върни се, Господи; до кога? И дано се разкаеш за скърбите на слугите Си.
Yípadà, Olúwa! Yóò ti pẹ́ tó? Ṣàánú fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ.
14 Насити ни рано с милостта Си, За да се радваме и веселим през всичките си дни.
Tẹ́ wa lọ́rùn ní òwúrọ̀ nínú ìṣeun ìfẹ́ rẹ, kí àwa kí ó lè kọrin fún ayọ̀ kí inú wa sì dùn ní gbogbo ọjọ́.
15 Развесели ни съразмерно с дните, в които си ни наскърбявал. И с годините, в които сме виждали зло.
Mú inú wa dùn bí ọjọ́ tí ìwọ ti pọ́n wa lójú, fún ọjọ́ púpọ̀ tí àwa ti rí wàhálà.
16 Нека се яви Твоето дело на слугата Ти, И Твоята слава върху чадата им.
Jẹ́ kí a fi iṣẹ́ rẹ̀ han àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ògo rẹ̀ sí àwọn ọmọ wọn.
17 И нека бъде върху нас благоволението на Господа нашия Бог, да ни ръководи; И утвърждавай за нас делото на ръцете ни; Да! делото на ръцете ни утвърждавай го.
Jẹ́ kí ẹwà Olúwa Ọlọ́run wa wà lára wa; fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀ lára wa, bẹ́ẹ̀ ni, kí ó sì fi ìdí iṣẹ́ ọwọ́ wa múlẹ̀.