< Еремия 10 >
1 Слушайте словото, което Господ говори вам, доме Израилев:
Gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ fún yín ẹ̀yin ilé Israẹli.
2 Така казва Господ: Не учете пътя на народите, И не се плашете от небесните знамения, По причина, че народите се плаша от тях.
Báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe kọ́ ìwà àwọn kèfèrí, kí àmì ọ̀run kí ó má sì dààmú yín, nítorí pé wọ́n ń dààmú orílẹ̀-èdè.
3 Защото обичаите на племената са суетни; Понеже само дърво е това, което секат от гората, Нещо издялано от дърводелски ръце с брадва;
Nítorí pé asán ni àṣà àwọn ènìyàn, wọ́n gé igi láti inú igbó, oníṣọ̀nà sì gbẹ́ ẹ pẹ̀lú àáké rẹ̀.
4 Украсяват го със сребро и злато, Закрепват го с гвоздеи и чукове, За да не се клати;
Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́. Wọ́n fi òòlù kàn án àti ìṣó kí ó má ba à ṣubú.
5 Те стоят прави като плашило в бостан, Но не говорят, Трябва да се носят, Защото не могат да ходят. Не бойте се от тях, защото не могат да докарат някакво зло, Нито им е възможно да докарат някакво добро.
Wọ́n wé mọ́ igi bí ẹ̀gúnsí inú oko, òrìṣà wọn kò le è fọhùn. Wọ́n gbọdọ̀ máa gbé wọn nítorí pé wọn kò lè rìn. Má ṣe bẹ̀rù wọn; wọn kò le è ṣe ibi kankan bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si lè ṣe rere kan.”
6 Няма подобен на тебе, Господи; Велик си, и велико е името Ти в сила.
Kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ Olúwa; o tóbi orúkọ rẹ sì tóbi lágbára.
7 Кой не би се боял от тебе, Царю на Народите? Защото на Тебе се пада това, Понеже между всичките мъдри на народите, И във всичко, що мъдростта им владее, няма подобен на тебе.
Ta ni kò yẹ kí ó bẹ̀rù rẹ? Ọba àwọn orílẹ̀-èdè? Nítorí tìrẹ ni. Láàrín àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní orílẹ̀-èdè àti gbogbo ìjọba wọn, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ.
8 Но всички ония са скотски и безумни; Суетно е учението им; то е само дърво.
Gbogbo wọn jẹ́ aláìlóye àti aṣiwèrè, wọ́n ń kọ́ ẹ̀kọ́ àwọn ère igi tí kò níláárí.
9 Сребро, изковано в плочи, се донася от Тарсис, И злато от Офир, Изделие на художник и на златарски ръце, - Синьо и мораво за облеклото им, Всецяло изработка на изкусни хора.
Fàdákà tí a ti kàn ni a mú wá láti Tarṣiṣi, àti wúrà láti Upasi. Èyí tí àwọn oníṣọ̀nà àti alágbẹ̀dẹ ṣe tí wọ́n kùn ní àwọ̀ aró àti elése àlùkò, èyí jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n oníṣọ̀nà.
10 Но Господ е истинският Бог, Живият Бог и вечният Цар; От Неговия гняв земята се тресе, И народите не могат да устоят пред негодуванието му.
Ṣùgbọ́n Olúwa ni Ọlọ́run tòótọ́, òun ni Ọlọ́run alààyè, ọba ayérayé. Nígbà tí ó bá bínú, ayé yóò wárìrì; orílẹ̀-èdè kò lè fi ara da ìbínú rẹ̀.
11 (Така ще им речете: Ония богове, които не са направили небето и земята, Да! те ще изчезнат от земята и изпод това небе.)
“Sọ èyí fún wọn: ‘Àwọn ọlọ́run kéékèèké tí kò dá ọ̀run àti ayé ni yóò ṣègbé láti ayé àti ní abẹ́ ọ̀run.’”
12 Той направи земята със силата Си, Утвърди света с мъдростта Си, И разпростря небето с разума Си.
Ọlọ́run dá ayé pẹ̀lú agbára rẹ̀, ó dá àgbáyé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, ó mú kí ọ̀run kí ó fẹ̀ síta nípa òye rẹ̀.
13 Когато издава гласа Си водите на небето шумят. И Той издига пари от краищата на земята; Прави светкавици за дъжда, И изважда вятър от съкровищницата Си.
Nígbà tí ó bá sán àrá, àwọn omi lọ́run a sì pariwo; ó mú kí ìkùùkuu ru sókè láti òpin ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì ń mú afẹ́fẹ́ wá láti ilé ìṣúra rẹ̀.
14 Всеки човек е твърде скотски, за да знае; Всеки златар се посрамва от кумира си, Защото леяното от него е лъжа, В което няма дишане.
Gbogbo ènìyàn jẹ́ aṣiwèrè àti aláìnímọ̀, ojú ti gbogbo alágbẹ̀dẹ níwájú ère rẹ̀, nítorí ère dídá rẹ̀ èké ni, kò sì ṣí ẹ̀mí nínú rẹ̀.
15 Суета са те, дело на заблуда; Във времето на наказанието им те ще загинат,
Asán ni wọ́n, iṣẹ́ ìṣìnà; nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn yóò ṣègbé.
16 Оня, който е делът на Якова, не е като тях, Защото Той е Създател на всичко; Израил е племето, което е наследството Му; Господ на Силите е името Му.
Ẹni tí ó bá jẹ́ ìpín Jakọbu kò sì dàbí èyí, nítorí òun ni ó ṣẹ̀dá ohun gbogbo àti Israẹli tí ó jẹ́ ẹ̀yà ìjogún rẹ̀. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
17 Събери от земята стоката си, Ти, която живееш в крепостта.
Kó ẹrù rẹ kúrò láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀ ìwọ tí o ń gbé ní ìlú tí a dó tì.
18 Защото така казва Господ: Ето, Аз в това време ще изхвърля като с прашка жителите на тая страна, И ще ги утесня, та да почувствуват злото.
Nítorí èyí ni Olúwa wí: “Ní àkókò yìí, èmi yóò gbọn àwọn tí ó ń gbé ilẹ̀ náà jáde. Èmi yóò mú ìpọ́njú bá wọn, kí wọn kí ó lè rí wọn mú.”
19 Горко ми, поради болежа ми! Раната ми е люта; но аз рекох: Наистина тая болка ми се пада, и трябва да я търпя.
Ègbé ni fún mi nítorí ìpalára mi! Ọgbẹ́ mi jẹ́ èyí tí kò lè sàn, bẹ́ẹ̀ ni mọ sọ fún ara mi, “Èyí ni àìsàn mi, mo sì gbọdọ̀ fi orí tì í.”
20 Шатърът ми се развали, и всичките ми въжета се скъсаха; Чадата ми излязоха от мене, и ги няма; Няма вече кой да разпъне шатъра ми И да окачи завесите ми.
Àgọ́ mi bàjẹ́, gbogbo okùn rẹ̀ sì já. Àwọn ọmọ mi ti lọ lọ́dọ̀ mi, wọn kò sì sí mọ́, kò sí ẹnìkankan tí yóò na àgọ́ mi ró mọ́, tàbí yóò ṣe ibùgbé fún mi.
21 Понеже овчарите станаха като скотове И не потърсиха Господа, Затова не са успявали, И всичките им стада са разпръснати.
Àwọn olùṣọ́-àgùntàn jẹ́ aṣiwèrè, wọn kò sì wá Olúwa: nítorí náà wọn kì yóò ṣe rere àti pé gbogbo agbo wọn ni yóò túká.
22 Слушай! шум! ето, иде, И голям глъч от северната страна, За да обърна Юдовите градове в пустиня, Жилище на чакали.
Fetísílẹ̀! ariwo igbe ń bọ̀, àti ìdàrúdàpọ̀ ńlá láti ilẹ̀ àríwá wá! Yóò sì sọ ìlú Juda di ahoro, àti ihò ọ̀wàwà.
23 Господи, познавам, че пътят на човека не зависи от него; Не е дадено на човека, който ходи, да управя стъпките си.
Èmi mọ̀ Olúwa wí pé ọ̀nà ènìyàn kì í ṣe ti ara rẹ̀, kì í ṣe fún ènìyàn láti tọ́ ìgbésẹ̀ ara rẹ̀.
24 Господи, наказвай ме, но с мярка, Не в гнева Си, да не би да ме довършиш.
Tún mi ṣe Olúwa, pẹ̀lú ìdájọ́ nìkan kí o má sì ṣe é nínú ìbínú rẹ, kí ìwọ má ṣe sọ mí di òfo.
25 Изливай яростта Си върху народите, които не Те познават, И върху родовете, които не призовават Твоето име; Защото те изпоядоха Якова, Дори го погълнаха и го довършиха, И опустошиха жилището му.
Tú ìbínú rẹ jáde sórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò mọ̀ ọ́n, sórí àwọn ènìyàn tí wọn kò pe orúkọ rẹ. Nítorí pé wọ́n ti jẹ Jakọbu run, wọ́n ti jẹ ẹ́ run pátápátá, wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ̀ di ahoro.