< Исая 30 >

1 Горко на непокорните чада, казва Господ, Които се съветват, но не с Мене, И които сключват договори, но не чрез Моя Дух, Та притурят грях на грях;
“Ègbé ni àwọn ọmọ fún orílẹ̀-èdè alágídí,” ni Olúwa wí, “Fún àwọn tí ó gbé ètò jáde tí kì í ṣe tèmi, tí wọ́n ń gbìmọ̀ pọ̀, ṣùgbọ́n kì í ṣe nípa Ẹ̀mí mi, tí wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ lórí ẹ̀ṣẹ̀;
2 Които отиват за да слязат в Египет Без да се допитват до Моите уста, За да се закрепят със силата на Фараона, И да прибягнат под сянката на Египет!
tí wọ́n lọ sí Ejibiti láìṣe fún mi, tí ó ń wá ìrànlọ́wọ́ lọ́dọ̀ Farao fún ààbò, sí òjìji Ejibiti fún ibi ìsádi.
3 Затова Фараоновата сило ще ви бъде за срам, И прибягването под египетската сянка за смущение.
Ṣùgbọ́n ààbò Farao yóò jásí ìtìjú fún un yín, òjìji Ejibiti yóò mú àbùkù bá a yín.
4 Защото началниците му отидоха в Танис, И посланиците му дойдоха в Ханес.
Bí àwọn olórí rẹ tilẹ̀ wà ní Ṣoani, tí àwọn ikọ̀ wọn sì ti dé sí Hanisi,
5 Та всички ще се срамуват поради люде, които не могат да ги ползват Нито да бъдат помощ или полза, Но са за срам и дори за укор.
gbogbo wọn ni a ó dójútì, nítorí àwọn ènìyàn kan tí kò wúlò fún wọn, tí kò mú ìrànlọ́wọ́ tàbí àǹfààní wá, bí kò ṣe àbùkù àti ìdójúti ni.”
6 Наложеното за южните животни пророчество: През наскърбителната и мъчителна земя, Дето има лъвица и як лъв, Ехидна и горителна хвърката змия, Занасят богатството си на плещите на оселчетата, И съкровищата си на гърбицата на камилите, При люде, които няма да го ползуват,
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ sí àwọn ẹranko tí ó wà ní gúúsù. Láàrín ilẹ̀ ìnira àti ìpọ́njú, ti kìnnìún àti abo kìnnìún ti paramọ́lẹ̀ àti ejò olóró, àwọn ikọ̀ náà kó ẹrù àti ọrọ̀ wọn lẹ́yìn àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ohun ìní wọn ní orí àwọn ìbákasẹ, sí orílẹ̀-èdè aláìlérè,
7 Защото помощта от Египет ще бъде суетна и безполезна; Затова го нарекох: Рахав, който бездействува.
sí Ejibiti tí ìrànlọ́wọ́ rẹ̀ kò wúlò rárá. Nítorí náà mo pè é ní Rahabu aláìlẹ́ṣẹ̀ nǹkan kan.
8 Сега иди, напиши това пред тях на дъсчица, И забележи го в книга, Та да остане за бъдещето време за свидетелство до века,
Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọ ọ́ sí ara wàláà fún wọn, tẹ̀ ẹ́ sí ara ìwé kíká, pé fún àwọn ọjọ́ tí ó ń bọ̀ kí ó sì lè jẹ́ ẹ̀rí ayérayé.
9 Че те са непокорни люде, чада лъжци, Чада, които не искат да слушат поуката Господна,
Àwọn wọ̀nyí jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn àti ẹlẹ́tanu ọmọ, àwọn ọmọ tí wọn kò ṣetán láti tẹ́tí sí ìtọ́ni Olúwa.
10 Които казват на гледачите: Не гледайте, И на пророците: Не ни пророкувайте правото, Но говорете ни ласкателно, пророкувайте измами,
Wọ́n sọ fún àwọn aríran pé, “Ẹ má ṣe rí ìran mọ́!” Àti fún àwọn wòlíì, “Ẹ má ṣe fi ìran ohun tí ó tọ́ hàn wá mọ́! Ẹ sọ ohun tí ó tura fún wa, ẹ sàsọtẹ́lẹ̀ ẹ̀tàn.
11 Отстъпете от пътя, Отклонете се от пътеката, Махнете от пред нас Светия Израилев.
Ẹ fi ọ̀nà yìí sílẹ̀, ẹ kúrò ní ọ̀nà yìí ẹ dẹ́kun à ń dojú ìjà kọ wá pẹ̀lú Ẹni Mímọ́ Israẹli!”
12 Затова, така казва Светият Израилев: Понеже презирате това слово, И уповавате на насилството и на извратеността, И се опирате на тях,
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Ẹni Mímọ́ Israẹli wí: “Nítorí pé ẹ ti kọ ọ̀rọ̀ yìí sílẹ̀, ẹ gbára lé ìnilára kí ẹ sì gbẹ́kẹ̀lé ẹ̀tàn,
13 По тая причина това беззаконие ще ви бъде Като разпукната част издута във висока стена И готова да падне, Чието рухване става внезапно в един миг.
ẹ̀ṣẹ̀ yìí yóò rí fún ọ gẹ́gẹ́ bí ògiri gíga, tí ó sán tí ó sì fì tí ó sì wó lójijì, àti ní ìṣẹ́jú kan.
14 И Той ще я разломи, строшавайки я безпощадно, както се чупи грънчарски съд, Така щото между частите му да се не намира черепчица, С която да вземе някой огън от огнището, Или да гребне вода от щерната.
Yóò sì fọ́ ọ sí wẹ́wẹ́ bí àpáàdì tí a fọ́ pátápátá àti pé a kò ní rí ẹ̀rún kan nínú àfọ́kù rẹ̀, fún mímú èédú kúrò nínú ààrò tàbí gbígbọ́n omi jáde kúrò nínú àmù.” (questioned)
15 Затова така казва Господ Иеова Светият Израилев: Чрез завръщане и почиване ще се избавите, В безумие и увереност ще бъде, силата ви; Но вие не искахте това;
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè, Ẹni Mímọ́ ti Israẹli wí: “Nínú ìrònúpìwàdà àti ìsinmi ni ìgbàlà rẹ wà, ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ àti ìgbẹ́kẹ̀lé ni agbára rẹ wà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò ní ọ̀kankan nínú wọn.
16 А рекохте: Не, но ще побегнем с коне; Затова ще бягате; И: Ще яздим на бързи животни; Затова, и ония, които ви гонят ще бъдат бързи.
Ẹ̀yin wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò sálọ lórí ẹṣin.’ Nítorí náà ẹ̀yin yóò sá! Ẹ̀yin wí pé, ‘Àwa yóò gun àwọn ẹṣin tí ó yára lọ.’ Nítorí náà àwọn tí ń lé e yín yóò yára!
17 Ще бягате, хиляда души от заплашването на едного Или от заплашването на петима, Догдето останете като разголено дърво на планински връх, И като знаме на хълм.
Ẹgbẹ̀rún yóò sá nípa ìdẹ́rùbà ẹnìkan; nípa ìdẹ́rùbà ẹni márùn-ún gbogbo yín lẹ ó sálọ, títí a ó fi yín sílẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí igi àsíá ní orí òkè, gẹ́gẹ́ bí àsíá lórí òkè.”
18 По тая причина Господ ще чака, за да се смили за вас, И по тая причина ще се превъзнесе за да ви пожали; Защото Господ е Бог правосъден; Блажени всички, които Го чакат.
Síbẹ̀síbẹ̀ Olúwa sì fẹ́ síjú àánú wò ọ́; ó dìde láti ṣàánú fún ọ. Nítorí Olúwa jẹ́ Ọlọ́run ìdájọ́. Ìbùkún ni fún gbogbo àwọn tí ó dúró dè é!
19 О люде, които живеете, в Сион, в Ерусалим, Вие няма да плачете вече; Той наистина ще се смили за тебе при гласа на вопъла ти; Когато го чуе ще ти отговори.
Ẹ̀yin ènìyàn Sioni, tí ń gbé ní Jerusalẹmu, ìwọ kì yóò sọkún mọ́. Báwo ni àánú rẹ̀ yóò ti pọ̀ tó nígbà tí ìwọ bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́! Bí ó bá ti gbọ́, òun yóò dá ọ lóhùn.
20 И ако Господ и да ви даде Хляб на скръб и вода на утеснение, Пак учителите ти няма да бъдат скрити вече, Но очите ти ще гледат учителите ти;
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa fún ọ ní àkàrà ìyà àti omi ìpọ́njú, àwọn olùkọ́ rẹ kì yóò fi ara sin mọ́; pẹ̀lú ojú rẹ ni ìwọ ó rí wọn.
21 И ушите ти ще слушат зад тебе слово, което, Когато се отклонявате на дясно И когато се отклонявате на ляво, Ще казва: Тоя е пътят, ходете по него.
Bí o bá yí sápá ọ̀tún tàbí apá òsì, etí rẹ yóò máa gbọ́ ohùn kan lẹ́yìn rẹ, wí pé, “Ọ̀nà nìyìí, máa rìn nínú rẹ̀.”
22 Тогава вие ще имате за гнусота Среброто, с което са обковани изваяните ти идоли, И златото, с което са облечени леяните ти идоли; Ще ги отхвърлиш като нечисто нещо, Ще речеш на всеки от тях: Махни се от тук.
Lẹ́yìn náà ni ẹ ó ba àwọn ère yín jẹ́ àwọn tí ẹ fi fàdákà bò àti àwọn ère tí ẹ fi wúrà bò pẹ̀lú, ẹ ó sọ wọ́n nù bí aṣọ tí obìnrin fi ṣe nǹkan oṣù ẹ ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ kúrò níbí!”
23 И Господ ще даде дъжд за семето ти, С което ще посееш нивата си, И хляб от земната производителност, Който ще бъде хранителен и изобилен; И в онова време добитъкът ти ще пасе в широки паши,
Òun yóò sì rọ òjò fún un yín sí àwọn irúgbìn tí ẹ gbìn sórí ilẹ̀, oúnjẹ tí yóò ti ilẹ̀ náà wá yóò ní ọ̀rá yóò sì pọ̀. Ní ọjọ́ náà ni àwọn ẹran ọ̀sìn yín yóò máa jẹ koríko ní pápá oko tútù tí ó tẹ́jú.
24 Също и воловете и оселчетата, които работят земята, Ще ядат вкусна зоб веяна с лопата и веяло.
Àwọn màlúù àti àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó ń tú ilẹ̀ yóò jẹ oúnjẹ àdídùn tí a fi àmúga àti ṣọ́bìrì fọ́nkálẹ̀.
25 И ще има на всяка висока планина И на всяко високо бърдо Реки и водни потоци, В деня на голямото клане. Когато кулите паднат.
Ní ọjọ́ tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ yóò sọ ẹ̀mí wọn nù nígbà tí ilé ìṣọ́ yóò wó lulẹ̀, odò omi yóò sàn lórí òkè gíga àti lórí àwọn òkè kékeré.
26 При това, светлината на луната ще бъде като светлината на слънцето, И светлината на слънцето ще бъде седмократна - като светлината на седем дни, В деня, когато Господ превързва струпея на людете Си, И изцелява раната от удара им.
Òṣùpá yóò sì tàn bí oòrùn, àti ìtànṣán oòrùn yóò mọ́lẹ̀ ní ìlọ́po méje, gẹ́gẹ́ bí ìmọ́lẹ̀ odidi ọjọ́ méje, nígbà tí Olúwa yóò di ojú ọgbẹ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ tí yóò sì wo ọgbẹ́ tí ó ti dá sí wọn lára sàn.
27 Ето, името на Господа иде от далеч; Гневът Му е пламнал, и гъстият Му дим се издига; Устните Му са пълни с негодувание, Езикът Му е като поглъщащ огън,
Kíyèsi i, orúkọ Olúwa ti òkèèrè wá pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti kurukuru èéfín tí ó nípọn; ètè rẹ̀ kún fún ìbínú ahọ́n rẹ̀ sì jẹ́ iná ajónirun.
28 И дишането Му като прелял поток, Който достига дори до шия; За да пресее народите в ситото на погублението: И в челюстите на племената ще има юзда, Която ще ги накара да се заблуждават.
Èémí rẹ̀ sì dàbí òjò alágbára, tí ó rú sókè dé ọ̀run. Ó jọ àwọn orílẹ̀-èdè nínú kọ̀ǹkọ̀sọ̀; ó sì fi sí ìjánu ní àgbọ̀n àwọn ènìyàn láti ṣì wọ́n lọ́nà.
29 У вас ще има песен както в нощта на тържествен празник, И сърдечна веселба както, когато тръгват със свирки, За да отидат при канарата Израилева, в Господния хълм.
Ẹ̀yin ó sì kọrin gẹ́gẹ́ bí i ti alẹ́ tí ẹ̀ ń ṣe àjọyọ̀ àpéjọ mímọ́, ọkàn yín yóò yọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí àwọn ènìyàn gòkè lọ pẹ̀lú fèrè sí orí òkè Olúwa, àní sí àpáta Israẹli.
30 И Господ ще направи да се чуе славния Му глас, И да се види тежкото слагане на мишцата Му, С гневно негодувание и с пламък на поглъщащ огън, С буен дъжд, с буря и с едър град.
Olúwa yóò jẹ́ kí wọn ó gbọ́ ohùn ògo rẹ̀ yóò sì jẹ́ kí wọ́n rí apá rẹ̀ tí ó ń bọ̀ wálẹ̀ pẹ̀lú ìbínú gbígbóná àti iná ajónirun, pẹ̀lú mọ̀nàmọ́ná, àrá àti yìnyín.
31 Защото асириецът, който с жезъл удря, Ще бъде смазан чрез гласа Господен.
Ohùn Olúwa yóò fọ́ Asiria túútúú, pẹ̀lú ọ̀pá aládé rẹ̀ ni yóò lù wọ́n bolẹ̀.
32 И всеки удар със съдбоносния жезъл. Който Господ ще сложи върху него, Ще бъде със тъпанчета и арфи; И с потресающи боеве ще воюват против тях.
Ẹgba kọ̀ọ̀kan tí Olúwa bá gbé lé wọn pẹ̀lú ọ̀pá ìjẹníyà rẹ̀ yóò jẹ́ ti ṣaworo àti ti dùùrù, gẹ́gẹ́ bí ó ti ń bá wọn jà lójú ogun pẹ̀lú ìkùùkuu láti apá rẹ̀.
33 Защото Тофет отдавна е приготвен, Да! За царя приготвен; Той да го направи дълбок и широк; Куп огън има в него и много дърва; Дишането Господно, като поток от сяра, ще го запали.
A ti tọ́jú Tofeti sílẹ̀ tipẹ́tipẹ́, a ti tọ́jú rẹ̀ sílẹ̀ fún ọba. Ojú ààrò rẹ̀ ni a ti gbẹ́ jì tí ó sì fẹ̀, pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ iná àti igi ìdáná; èémí Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìṣàn sulfuru ń jó ṣe mú un gbiná.

< Исая 30 >